< Zakarias 1 >

1 I den ottende Maaned, i Darius's andet Aar, kom Herrens Ord til Profeten Sakarias, en Søn af Berekias, en Sønnesøn af Iddo, saaledes:
Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:
2 Herren har været højlig fortørnet paa eders Fædre.
“Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
3 Og du skal sige til dem: Saa siger den Herre Zebaoth: Vender om til mig, siger den Herre Zebaoth, saa vil jeg vende om til eder, siger den Herre Zebaoth.
Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ mi,’ báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
4 Værer ikke som eders Fædre, til hvilke de forrige Profeter raabte og sagde: Saa siger den Herre Zebaoth: Vender dog om fra eders onde Veje og eders onde Idrætter; men de hørte ikke og gave ikke Agt paa mig, siger Herren.
Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé, báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.
5 Eders Fædre, hvor ere de? og Profeterne, mon de leve til evig Tid?
Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé?
6 Dog, mine Ord og mine Bestemmelser, som jeg meddelte mine Tjenere, Profeterne, have de ikke rammet eders Fædre, saa de vendte om og sagde: Ligesom den Herre Zebaoth havde tænkt at gøre imod os efter vore Veje og efter vore Idrætter, saaledes har han gjort imod os.
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín? “Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’”
7 Paa den fire og tyvende Dag i den ellevte Maaned, det er Maaneden Sebat, i Darius's andet Aar, kom Herrens Ord til Profeten Sakarias, Berekias's Søn, Iddos Sønnesøn, saaledes:
Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Berekiah ọmọ Iddo wá, pé.
8 Jeg saa om Natten, og se, en Mand, der red paa en rød Hest, og han holdt stille imellem Myrtetræerne, som vare i Dalen, og bag ham var der røde, graa og hvide Heste.
Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.
9 Og jeg sagde: Hvad betyde disse, min Herre? Og Engelen, som talte med mig, sagde til mig: Jeg vil lade dig se, hvad disse betyde.
Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?” Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”
10 Og den Mand, som holdt stille imellem Myrtetræerne, svarede og sagde: Det er dem, som Herren har sendt til at vandre Jorden rundt.
Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”
11 Og de svarede Herrens Engel, som stod imellem Myrtetræerne, og sagde: Vi have vandret Jorden rundt, og se, hele Jorden nyder Ro og Hvile.
Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”
12 Da svarede Herrens Engel og sagde: Herre Zebaoth! hvor længe varer det, inden du vil forbarme dig over Jerusalem og over Judas Stæder, paa hvilke du har været vred nu i halvfjerdsindstyve Aar?
Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?”
13 Og Herren svarede Engelen, som talte med mig, med gode Ord, med trøstende Ord.
Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.
14 Og Engelen, som talte med mig, sagde til mig: Raab og sig: Saa siger den Herre Zebaoth: Jeg har været nidkær for Jerusalem og for Zion med en stor Nidkærhed.
Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni.
15 Men med en stor Fortørnelse er jeg fortørnet paa Hedningerne, som ere saa trygge; thi da jeg en liden Stund havde været fortørnet, saa hjalp de til Ulykken.
Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’
16 Derfor, saa siger Herren, har jeg atter vendt mig til Jerusalem med Barmhjertighed, mit Hus skal bygges derudi, siger den Herre Zebaoth, og Maalesnoren skal udstrækkes over Jerusalem.
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’
17 Raab fremdeles, og sig: Saa siger den Herre Zebaoth: Mine Stæder skulle endnu strømme over af gode Ting, og Herren skal endnu trøste Zion og endnu udvælge Jerusalem.
“Máa ké síbẹ̀ pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’”
18 Og jeg opløftede mine Øjne og saa, og se, fire Horn!
Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin.
19 Og jeg sagde til Engelen, som talte med mig: Hvad betyde disse? og han sagde til mig: Disse ere de Horn, som adspredte Juda, Israel og Jerusalem.
Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?” Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”
20 Da lod Herren mig se fire Smede.
Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
21 Og jeg sagde: Hvad komme disse for at gøre? og han sagde: Hine ere de Horn, som adspredte Juda paa den Maade, at ingen opløftede sit Hoved; men saa kom disse for at forfærde dem, for at nedslaa de Hedningers Horn, som rejste Horn imod Judas Land, for at adsprede det.
Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?” O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”

< Zakarias 1 >