< Romerne 4 >
1 Hvad skulle vi da sige, at vor Stamfader Abraham har vundet efter Kødet?
Ǹjẹ́ kín ni àwa ó ha wí nípa Abrahamu, baba wa ti o ṣàwárí èyí? Májẹ̀mú láéláé jẹ́rìí sí i wí pé, a gba Abrahamu là nípa ìgbàgbọ́.
2 Thi dersom Abraham blev retfærdiggjort af Gerninger, har han Ros, men ikke for Gud.
Nítorí bí a bá dá Abrahamu láre nípa iṣẹ́, ó ní ohun ìṣògo; ṣùgbọ́n kì í ṣe níwájú Ọlọ́run.
3 Thi hvad siger Skriften? „Og Abraham troede Gud, og det blev regnet ham til Retfærdighed.”
Ìwé Mímọ́ ha ti wí? “Abrahamu gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.”
4 Men den, som gør Gerninger, tilregnes Lønnen ikke som Naade, men som Skyldighed;
Ǹjẹ́ fún ẹni tí ó ṣiṣẹ́, a kò ka èrè náà sí oore-ọ̀fẹ́ bí kò ṣe sí ẹ̀tọ́ rẹ̀.
5 den derimod, som ikke gør Gerninger, men tror paa ham, som retfærdiggør den ugudelige, regnes hans Tro til Retfærdighed;
Ṣùgbọ́n fún ẹni tí kò ṣiṣẹ́, tí ó sì ń gba ẹni tí ó ń dá ènìyàn búburú láre gbọ́, a ka ìgbàgbọ́ rẹ̀ sí òdodo.
6 ligesom ogsaa David priser det Menneske saligt, hvem Gud tilregner Retfærdighed uden Gerninger:
Gẹ́gẹ́ bí Dafidi pẹ̀lú ti pe olúwa rẹ̀ náà ní ẹni ìbùkún, ẹni tí Ọlọ́run ka òdodo fún láìsí ti iṣẹ́.
7 „Salige de, hvis Overtrædelser ere forladte, og hvis Synder ere skjulte;
Wí pé, “Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí a dárí ìrékọjá wọn jì, tí a sì bo ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀.
8 salig den Mand, hvem Herren ikke vil tilregne Synd.”
Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà ẹni tí Olúwa kò ka ẹ̀ṣẹ̀ sí lọ́rùn.”
9 Gælder da denne Saligprisning de omskaarne eller tillige de uomskaarne? Vi sige jo: Troen blev regnet Abraham til Retfærdighed.
Ìbùkún yìí ha jẹ́ ti àwọn akọlà nìkan, tàbí ti àwọn aláìkọlà pẹ̀lú? Nítorí tí a wí pé, Abrahamu gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.
10 Hvorledes blev den ham da tilregnet? da han var omskaaren, eller da han havde Forhud? Ikke da han var omskaaren, men da han havde Forhud.
Báwo ni a ṣe kà á sí i? Nígbà tí ó wà ní ìkọlà tàbí ní àìkọlà? Kì í ṣe ni ìkọlà, ṣùgbọ́n ní àìkọlà ni.
11 Og han fik Omskærelsens Tegn som et Segl paa den Troens Retfærdighed, som han havde som uomskaaren, for at han skulde være Fader til alle dem, som tro uden at være omskaarne, for at Retfærdighed kan blive dem tilregnet,
Ó sì gbé àmì ìkọlà àti èdìdì òdodo ìgbàgbọ́ tí ó ní nígbà tí ó wà ní àìkọlà kí ó lè ṣe baba gbogbo àwọn tí ó gbàgbọ́, bí a kò tilẹ̀ kọ wọ́n ní ilà kí a lè ka òdodo sí wọn pẹ̀lú.
12 og Fader til omskaarne, til dem, som ikke alene have Omskærelse, men ogsaa vandre i den Tros Spor, hvilken vor Fader Abraham havde som uomskaaren.
Àti baba àwọn tí ìkọlà tí kì í ṣe pé a kàn kọlà fún nìkan, ṣùgbọ́n tiwọn ń tẹ̀lé àpẹẹrẹ ìgbàgbọ́ tí baba wa Abrahamu ní, kí a tó kọ ọ́ nílà.
13 Thi ikke ved Lov fik Abraham eller hans Sæd den Forjættelse, at han skulde være Arving til Verden, men ved Tros-Retfærdighed.
Ìlérí fún Abrahamu àti fún irú-ọmọ rẹ̀, ni pé, wọn ó jogún ayé, kì í ṣe nípa òfin bí kò ṣe nípa òdodo ti ìgbàgbọ́.
14 Thi dersom de, der ere af Loven, ere Arvinger, da er Troen bleven tom, og Forjættelsen gjort til intet.
Nítorí bí àwọn tí ń ṣe ti òfin bá jẹ ajogún, ìgbàgbọ́ di asán, ìlérí sì di aláìlágbára.
15 Thi Loven virker Vrede; men hvor der ikke er Lov, er der heller ikke Overtrædelse.
Nítorí òfin ń ṣiṣẹ́ ìbínú, ṣùgbọ́n ní ibi tí òfin kò bá sí, ìrúfin kò sí níbẹ̀.
16 Derfor er det af Tro, for at det skal være som Naade, for at Forjættelsen maa staa fast for den hele Sæd, ikke alene for den af Loven, men ogsaa for den af Abrahams Tro, han, som er Fader til os alle
Nítorí náà ni ó ṣe gbé e ka orí ìgbàgbọ́, kí ìlérí náà bá a lè sinmi lé oore-ọ̀fẹ́, kí a sì lè mú un dá gbogbo irú-ọmọ lójú, kì í ṣe fún àwọn tí ń pa òfin mọ́ nìkan, ṣùgbọ́n bí kò ṣe pẹ̀lú fún àwọn ti ó pín nínú ìgbàgbọ́ Abrahamu, ẹni tí í ṣe baba gbogbo wa pátápátá,
17 (som der er skrevet: „Jeg har sat dig til mange Folkeslags Fader”), over for Gud, hvem han troede, ham, som levendegør de døde og kalder det, der ikke er, som om det var.
Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Mo ti fi ọ́ ṣe baba orílẹ̀-èdè púpọ̀.” Níwájú Ọlọ́run ẹni tí òun gbàgbọ́, ẹni tí ó sọ òkú di ààyè, tí ó sì pè àwọn ohun tí kò sí bí ẹni pé wọ́n wà.
18 Og han troede imod Haab med Haab paa, at han skulde blive mange Folkeslags Fader, efter det, som var sagt: „Saaledes skal din Sæd være;”
Nígbà tí ìrètí kò sí mọ́, Abrahamu gbàgbọ́ nínú ìrètí bẹ́ẹ̀ ni ó sì di baba orílẹ̀-èdè púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí èyí tí a wí fún un pé, “Báyìí ni irú-ọmọ rẹ̀ yóò rí.”
19 og uden at blive svag i Troen saa han paa sit eget allerede udlevede Legeme (han var nær hundrede Aar) og paa, at Saras Moderliv var udlevet;
Ẹni tí kò rẹ̀wẹ̀sì nínú ìgbàgbọ́, nígbà tí ó mọ pe ara òun tìkára rẹ̀ tí ó ti kú tan, nítorí ó tó bí ẹni ìwọ̀n ọgọ́rùn-ún ọdún, àti nígbà tí ó ro ti yíyàgàn inú Sara.
20 men om Guds Forjættelse tvivlede han ikke i Vantro, derimod blev han styrket i Troen, idet han gav Gud Ære
Kò fi àìgbàgbọ́ ṣiyèméjì nípa ìlérí Ọlọ́run; ṣùgbọ́n ó lágbára sí i nínú ìgbàgbọ́ bí ó ti fi ògo fún Ọlọ́run,
21 og var overbevist om, at hvad han har forjættet, er han mægtig til ogsaa at gøre.
pẹ̀lú ìdánilójú kíkún pé, Ọlọ́run lè ṣe ohun tí ó ti ṣe ìlérí rẹ̀.
22 Derfor blev det ogsaa regnet ham til Retfærdighed.
Nítorí náà ni a sì ṣe kà á sí òdodo fún un.
23 Men det blev ikke skrevet for hans Skyld alene, at det blev ham tilregnet,
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ náà, “A kà á sí òdodo fún un,” ni a kọ kì í ṣe nítorí tirẹ̀ nìkan.
24 men ogsaa for vor Skyld, hvem det skal tilregnes, os, som tro paa ham, der oprejste Jesus, vor Herre, fra de døde,
Ṣùgbọ́n nítorí tiwa pẹ̀lú. A ó sì kà á sí fún wa, bí àwa bá gba ẹni tí ó gbé Jesu Olúwa wa dìde kúrò nínú òkú gbọ́.
25 ham, som blev hengiven for vore Overtrædelsers Skyld og oprejst for vor Retfærdiggørelses Skyld.
Ẹni tí a pa fún ẹ̀ṣẹ̀ wa, tí a sì jí dìde nítorí ìdáláre wa.