< Salme 69 >

1 Til Sangmesteren; til „Lillierne”; af David.
Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
2 Gud frels mig; thi Vandene ere komne indtil Sjælen.
Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
3 Jeg er sunken i Dybets Dynd, hvor man ej kan fæste Fod; jeg er kommen i Vandenes Dyb, og Strømmen overskyller mig.
Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
4 Jeg er bleven træt af det, jeg har raabt, min Strube er hæs; mine Øjne ere fortærede, idet jeg venter paa min Gud.
Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
5 Flere end Haar paa mit Hoved ere de, som hade mig uden Aarsag; mægtige ere de, som søge at udrydde mig, mine Fjender uden Skel; jeg maa gengive det, jeg ikke har røvet.
Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
6 Gud! du ved min Daarlighed, og min Skyld er ikke dulgt for dig.
Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
7 Lad ikke dem, som bie efter dig, Herre, Herre Zebaoth! beskæmmes ved mig; lad ikke dem, som søge dig, Israels Gud, blive forhaanede ved mig.
Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
8 Thi jeg bærer Forhaanelse for din Skyld; Skændsel har skjult mit Ansigt.
Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
9 Jeg er bleven fremmed for mine Brødre og en Udlænding for min Moders Børn.
nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
10 Thi Nidkærhed for dit Hus har fortæret mig, og deres Forhaanelser, som dig forhaane, ere faldne paa mig.
Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
11 Og jeg græd min Sjæl ud under Faste; men det blev mig til Forhaanelser.
nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
12 Og jeg brugte Sæk til mit Klædebon, og jeg blev dem til et Ordsprog.
Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
13 De, som sidde i Porten, snakke om mig, og de, som drikke stærk Drik, synge Viser om mig.
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
14 Men jeg henflyr med min Bøn til dig, Herre! i Naadens Tid, o Gud! efter din megen Miskundhed: Bønhør mig for din Frelses Sandheds Skyld!
Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
15 Frels mig af Dyndet, at jeg ikke synker; lad mig frelses fra mine Avindsmænd og fra Vandenes Dyb!
Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
16 Lad Vandstrømmene ikke overskylle mig, ej heller Dybet sluge mig; lad og I ikke Hulen lukke sin Mund over mig!
Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
17 Bønhør mig, Herre! thi din Miskundhed er god; vend dit Ansigt til mig efter din store Barmhjertighed!
Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
18 Og skjul ikke dit Ansigt for din Tjener; thi jeg er angest, skynd dig, bønhør mig!
Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
19 Hold dig nær til min Sjæl, genløs den, udfri mig for mine Fjenders Skyld!
Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
20 Du kender min Forhaanelse og min Skam og min Skændsel; alle mine Modstandere ere aabenbare for dig.
Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
21 Forhaanelse har brudt mit Hjerte, og jeg blev svag; og jeg ventede paa Medynk, men der var ingen, og paa Trøstere; men jeg fandt ikke nogen.
Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
22 Og de gave mig Galde at æde og Eddike at drikke i min Tørst.
Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
23 Deres Bord blive foran dem til en Strikke og til en Snare, naar de ere trygge.
Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
24 Lad deres Øjne formørkes, at de ikke se, og lad deres Lænder altid rave!
Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
25 Udøs din Harme over dem, og lad din brændende Vrede gribe dem!
Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
26 Deres Bolig vorde øde; ingen være, som bor i deres Telte.
Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
27 Thi de forfølge den, som du har slaget, og de fortælle om deres Pine, som du har saaret.
Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
28 Læg Skyld til deres Skyld, og lad dem ikke komme til din Retfærdighed!
Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
29 Lad dem udslettes af de levendes Bog, og lad dem ikke opskrives med de retfærdige!
Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
30 Dog, jeg er elendig og har Smerte; Gud! lad din Frelse ophøje mig.
Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
31 Jeg vil love Guds Navn med Sang, og jeg vil storlig ære ham med Taksigelse.
Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
32 Og det skal bedre behage Herren end en ung Okse med Horn og Klove.
Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
33 De sagtmodige have set det, de skulle glæde sig; I, som søge Gud — og eders Hjerte leve op!
Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
34 Thi Herren hører de fattige og foragter ikke sin bundne.
Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
35 Himmel og Jord skulle love ham, Havet og alt det, som vrimler derudi!
nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
36 Thi Gud skal frelse Zion og bygge Judas Stæder, og man skal bo der og eje det. Og hans Tjeneres Sæd skal arve det, og de, som elskede hans Navn, skulle bo derudi.
àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.

< Salme 69 >