< Salme 59 >

1 Til Sangmesteren; „fordærv ikke”; af David; „et gyldent Smykke”; der Saul sendte hen, og de toge Vare paa Huset for at slaa ham ihjel.
Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run; dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.
2 Min Gud! fri mig fra mine Fjender, sæt mig paa et højt Sted imod dem, som staa op imod mig.
Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.
3 Fri mig fra dem, som gøre Uret, og frels mig fra blodgerrige Mænd!
Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí! Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.
4 Thi se, de lure efter min Sjæl, de stærke holde sammen imod mig, uden min Overtrædelse og uden min Synd, o Herre!
Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí. Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.
5 Uden min Skyld storme de frem og stille sig op; vaagn op at møde mig og se til!
Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli, dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí; má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. (Sela)
6 Ja, du, Herre, Gud Zebaoth! Israels Gud, vaagn op at hjemsøge alle Hedningerne! vær ingen naadig af alle de troløse Niddinger! (Sela)
Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọ́n ń gbó bí àwọn ajá, wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.
7 De komme igen imod Aftenen, de tude som Hunde og løbe omkring i Staden.
Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu: wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn, wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”
8 Se, de udgyde Ord af deres Mund, der er Sværd paa deres Læber; thi „hvo hører det?”
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín, Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.
9 Men du, Herre! du ler ad dem, du spotter alle Hedningerne.
Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ; nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,
10 Imod hans Styrke vil jeg vogte paa dig, thi Gud er min Befæstning.
Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi. Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi. Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.
11 Gud, som beviser mig Miskundhed, skal komme mig i Møde; Gud skal lade mig se med Lyst paa mine Fjender.
Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa, kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé. Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri, kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
12 Slaa dem ikke ihjel, at mit Folk ikke skal glemme det; lad dem vanke hid og did for din Magt, og lad dem styrte, Herre, vort Skjold.
Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn, ní ọ̀rọ̀ ètè wọn, kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn. Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,
13 Deres Læbers Ord er Synd i deres Mund; lad dem gribes i deres Hovmod og for den Forbandelse og Løgn, som de udsige.
pa wọ́n run nínú ìbínú, run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́. Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. (Sela)
14 Gør Ende paa dem i din Vrede, gør Ende paa dem, at de ikke ere mere til; og de skulle vide, at Gud er den, som hersker i Jakob indtil Jordens Ender. (Sela)
Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọn ń gbó bí àwọn ajá wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.
15 Og de skulle komme igen om Aftenen, tude som Hunde og løbe omkring i Staden.
Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.
16 De skulle vanke hid og did efter Føde og overnatte, uden at de blive mætte.
Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ, n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀; nítorí ìwọ ni ààbò mi, ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.
17 Men jeg vil synge om din Styrke, jeg vil synge med Fryd om din Miskundhed om Morgenen; thi du var mig en Befæstning og en Tilflugt paa min Nøds Dag. Min Styrke! for dig vil jeg synge, thi Gud er min Befæstning, Gud, som beviser mig Miskundhed.
Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ; ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.

< Salme 59 >