< Salme 106 >
1 Priser Herren! thi han er god, thi hans Miskundhed varer evindelig.
Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
2 Hvo kan udsige Herrens vældige Gerninger, forkynde al hans Pris?
Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
3 Salige ere de, som holde over Ret, og den, som øver Retfærdighed alle Tider.
Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
4 Herre! kom mig i Hu med din Kærlighed til dit Folk, besøg mig med din Frelse,
Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
5 at jeg maa skue dine udvalgtes Lykke, glæde mig ved dit Folks Glæde, prise mig lykkelig i Samfund med din Arv.
kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
6 Vi have syndet med vore Fædre, vi have handlet ilde og gjort Ugudelighed.
Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
7 Vore Fædre i Ægypten vilde ikke forstaa dine underfulde Gerninger, de kom ikke din store Miskundhed i Hu, men vare genstridige ved Havet, ved det røde Hav.
Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
8 Dog frelste han dem for sit Navns Skyld, for at kundgøre sin Magt.
Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
9 Og han truede det røde Hav, og det blev tørt, og han lod dem gaa igennem Dybet som igennem Ørken.
O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
10 Og han frelste dem af Avindsmandens Haand og genløste dem af Fjendens Haand.
O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
11 Og Vandene skjulte deres Modstandere, der blev ikke een tilovers af dem.
Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
12 Da troede de paa hans Ord, de sang hans Pris.
Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
13 Dog glemte de hans Gerninger snart, de biede ikke paa hans Raad.
Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
14 Men de fik stor Begærlighed i Ørken og fristede Gud i det øde Land.
Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
15 Da gav han dem det, de begærede, men lod deres Liv tæres hen.
Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
16 Og de bare Avind imod Mose i Lejren, imod Aron, Herrens hellige.
Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
17 Jorden oplod sig og opslugte Dathan, og den skjulte Abirams Hob.
Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
18 Og Ild flammede op iblandt deres Hob, en Lue fortærede de ugudelige.
Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
19 De dannede en Kalv ved Horeb og tilbade et støbt Billede.
Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
20 Og de ombyttede deres Herlighed med Billedet af en Okse, som æder Urter.
Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
21 De glemte Gud, deres Frelser, som havde gjort store Ting i Ægypten,
Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
22 underfulde Gerninger i Kams Land, forfærdelige Ting ved det røde Hav.
iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
23 Og han sagde, at han vilde ødelægge dem; dersom Mose, hans udvalgte, ikke havde stillet sig i Gabet for hans Ansigt, at afvende hans Vrede fra at ødelægge dem —!
Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
24 De foragtede ogsaa det yndige Land, de troede ikke hans Ord.
Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
25 Men de knurrede i deres Telte, de hørte ikke paa Herrens Røst.
Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
26 Og han svor dem med oprakt Haand, at han vilde lade dem falde i Ørken,
Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
27 og at han vilde lade deres Afkom falde iblandt Hedningerne og bortstrø dem i Landene.
láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
28 Og de bandt sig til Baal-Peor og aade af Ofrene til de døde Afguder.
Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
29 Og de opirrede ham med deres Idrætter, saa at en Plage brød løs paa dem,
wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
30 Da stod Pinehas frem og holdt Dom, og Plagen hørte op.
Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
31 Og det blev regnet ham til Retfærdighed fra Slægt til Slægt evindelig.
A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
32 De fortørnede ham ogsaa ved Meribas Vand, og det gik Mose ilde for deres Skyld.
Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
33 Thi de vare genstridige imod hans Aand, og han talte ubetænksomt med sine Læber.
Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
34 De ødelagde ikke Folkene, om hvilke Herren havde sagt det til dem.
Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
35 Men de blandede sig med Hedningerne og lærte deres Gerninger.
Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
36 Og de tjente deres Afguder, og disse bleve dem til en Snare.
Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
37 Og de ofrede deres Sønner og deres Døtre til Magterne.
Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
38 Og de udøste uskyldigt Blod, deres Sønners og deres Døtres Blod, som de ofrede til Kanaans Afguder, og Landet vanhelligedes af Blodet.
Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
39 Og de besmittede sig ved deres Gerninger, og de bolede ved deres Idrætter.
Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
40 Da optændtes Herrens Vrede imod hans Folk, og han fik en Vederstyggelighed til sin Arv.
Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
41 Og han gav dem i Hedningernes Haand, og deres Avindsmænd herskede over dem.
Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
42 Og deres Fjender trængte dem, og de bleve ydmygede under deres Haand.
Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
43 Han friede dem mange Gange; men de satte sig op imod ham i deres Raad, og de bleve nedtrykte for deres Misgerningers Skyld.
Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
44 Dog saa han til dem, da de vare i Angest, idet han hørte deres Raab.
Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
45 Og han kom sin Pagt i Hu, dem til Bedste, og det angrede ham efter hans store Miskundhed.
ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
46 Og han lod dem finde Barmhjertighed hos alle dem, som havde bortført dem.
Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
47 Frels os, Herre, vor Gud! og saml os fra Hedningerne, at vi kunne takke dit hellige Navn, rose os af din Pris!
Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
48 Lovet være Herren, Israels Gud, fra Evighed og indtil Evighed; og alt Folket siger: Amen. Halleluja!
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!