< 4 Mosebog 6 >

1 Og Herren talede til Mose og sagde:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Tal til Israels Børn, og du skal sige til dem: Naar en Mand eller Kvinde lover et særligt Løfte om at blive Nasiræer, om at være afholdende for Herren,
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ pàtàkì, ẹ̀jẹ́ ìyara-ẹni-sọ́tọ̀ sí Olúwa nípa àìgé irun orí (Nasiri),
3 da skal han holde sig fra Vin og stærk Drik; han skal ikke drikke Vineddike eller Eddike af stærk Drik, og han skal ingen Saft drikke af Druer, han skal hverken æde friske eller tørre Druer.
irú ẹni bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ yàgò fún wáìnì tàbí ọtí líle, ọtí wáìnì kíkan àti àwọn ohun mímu mìíràn tó bá kan. Kò gbọdọ̀ mu èso àjàrà tàbí kí ó jẹ èso àjàrà tútù tàbí gbígbẹ.
4 Alle hans Afholdenheds Dage skal han ikke æde noget, som beredes af Vinstokken, hverken Kerne eller Skal.
Níwọ́n ìgbà tí ó sì jẹ́ Nasiri, ní kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi èso àjàrà ṣe, ìbá à ṣe kóró tàbí èèpo rẹ̀.
5 Alle de Dage, som hans Afholdenheds Løfte varer, skal der ikke komme Ragekniv over hans Hoved; indtil de Dage ere opfyldte, i hvilke han er afholdende for Herren, skal han være hellig og lade sit Hovedhaar vokse frit.
“‘Ní gbogbo ìgbà ẹ̀jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ yìí, kí abẹ kankan má ṣe kàn án ní orí. Ó gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ títí tí àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Olúwa yóò fi pé; ó gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí rẹ̀ gùn.
6 Alle de Dage, han har lovet at være afholdende for Herren, skal han ikke komme til noget Lig.
“‘Ní gbogbo àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Olúwa kò gbọdọ̀ súnmọ́ òkú ènìyàn.
7 Han skal ikke gøre sig uren ved sin Fader eller ved sin Moder, ved sin Broder eller ved sin Søster, naar de dø; thi hans Af holdenhedsmærke for Gud er paa hans Hoved.
Ìbá à ṣe òkú baba, àti ìyá rẹ̀, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin tàbí obìnrin tàbí àbúrò rẹ̀, kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nítorí wọn, nítorí pé àmì ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Ọlọ́run wà ní orí rẹ̀.
8 Alle hans Afholdenheds Dage skal han være Herren hellig.
Ní gbogbo àsìkò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ yìí, ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
9 Og dør nogen meget pludselig hos ham og gør hans Hoved med Afholdenhedsmærket urent, da skal han rage sit Hoved paa sin Renselsesdag, paa den syvende Dag skal han rage det.
“‘Bí ẹnìkan bá kú ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní òjijì, tí ó sì ba irun rẹ̀ tó yà sọ́tọ̀ jẹ́; ó gbọdọ̀ gé irun rẹ̀ ní ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀ èyí tí í ṣe ọjọ́ keje.
10 Og paa den ottende Dag skal han bringe to Turtelduer eller to Dueunger til Præsten, til Forsamlingens Pauluns Dør.
Ní ọjọ́ kẹjọ, yóò mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé méjì wá sọ́dọ̀ àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
11 Og Præsten skal lave een til et Syndoffer og een til et Brændoffer og gøre Forligelse for ham, fordi han har syndet ved Liget, og han skal hellige sit Hoved paa den samme Dag.
Àlùfáà yóò fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun láti fi ṣe ètùtù fún un nítorí pé ó ti ṣẹ̀ nípa wíwà níbi tí òkú ènìyàn wà. Yóò sì ya orí rẹ̀ sí mímọ́ ní ọjọ́ náà gan an.
12 Og han skal paa ny være afholdende for Herren sine Afholdenheds Dage og fremføre et aargammelt Lam til Skyldoffer; og de første Dage skulle falde hen, fordi hans Afholdenhed blev uren.
Ó gbọdọ̀ ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ sí Olúwa fún àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀, ó sì gbọdọ̀ mú akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀bi. Kò sì ní í ka àwọn ọjọ́ ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ ti tẹ́lẹ̀ nítorí pé ó tí ba ara rẹ̀ jẹ́ ní àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀.
13 Og dette er Nasiræerloven: Paa den Dag, hans Afholdenheds Dage udløbe, skal han fremføre dette for Forsamlingens Pauluns Dør,
“‘Èyí ni òfin fún Nasiri nígbà tí àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ bá pé. Wọn ó mu wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
14 og han skal ofre som sit Offer for Herren eet aargammelt Væderlam uden Lyde til et Brændoffer og eet aargammelt Gimmerlam uden Lyde til et Syndoffer og een Væder uden Lyde til et Takoffer
Níbẹ̀ ni yóò ti mú ọrẹ wá fún Olúwa, akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan tí kò ní àbùkù fún ẹbọ sísun àti ẹgbọrọ-àgùntàn ọlọ́dún kan, tí kò ní àbùkù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àgbò kan tí kò ní àbùkù fún ọrẹ àlàáfíà,
15 og en Kurv med usyrede Kager af Mel, blandet med Olie, og usyrede tynde Kager, overstrøgne med Olie, og Madofret og Drikofret dertil.
pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu, apẹ̀rẹ̀ àkàrà tí a kò fi ìwúkàrà ṣe, àkàrà tí a fi ìyẹ̀fun dáradára pò mọ́ òróró àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí a fi òróró sọjọ̀ lé lórí.
16 Og Præsten skal ofre det for Herrens Ansigt, og han skal lave hans Syndoffer og hans Brændoffer.
“‘Àlùfáà yóò gbé gbogbo rẹ̀ wá síwájú Olúwa, yóò sì rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ sísun.
17 Og Væderen skal han lave for Herren til Takoffer tillige med Kurven med de usyrede Brød, og Præsten skal lave hans Madoffer og hans Drikoffer.
Àlùfáà yóò fi àgbò náà rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa, pẹ̀lú apẹ̀rẹ̀ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà; yóò rú ẹbọ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu.
18 Og Nasiræeren skal rage Afholdenhedens Mærke af sit Hoved for Forsamlingens Pauluns Dør, og han skal tage Hovedhaaret, som var Mærket paa hans Afholdenhed, og kaste det paa Ilden, som er under Takofret.
“‘Nígbà náà ni Nasiri náà yóò fá irun ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Yóò fi irun náà sínú iná tó wà lábẹ́ ẹbọ àlàáfíà.
19 Og Præsten skal tage den kogte Bov af Væderen og een usyret Kage af Kurven og een usyret tynd Kage, og han skal lægge dem paa Nasiræerens Hænder, efter at han har afraget sit Afholdenheds Mærke.
“‘Lẹ́yìn tí Nasiri bá ti fá irun ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ tan, àlùfáà yóò mú apá àgbò bíbọ̀, àkàrà aláìwú kan àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí kò ní ìwúkàrà láti inú apẹ̀rẹ̀ yóò sì kó gbogbo rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 Og Præsten skal røre dem med en Rørelse for Herrens Ansigt, det er Præsten helliget, tillige med Rørelsesbrystet og tillige med Gaveboven; og derefter maa Nasiræeren drikke Vin.
Àlùfáà yóò fi gbogbo rẹ̀ níwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì, wọ́n jẹ́ mímọ́, wọ́n sì jẹ́ ti àlùfáà pẹ̀lú igẹ̀ tí a fì àti itan tí wọ́n mú wá. Lẹ́yìn èyí, Nasiri náà lè mu wáìnì.
21 Dette er Loven for Nasiræeren, som gør et Løfte, det er hans Offer til Herren for sin Afholdenhed, foruden det som hans Haand ellers formaar; efter hans Løftes Beskaffenhed, som han har lovet, saaledes skal han gøre efter Loven om hans Afholdenhed.
“‘Èyí ni òfin Nasiri tó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ rẹ̀ sí Olúwa, yóò wà ní ìbámu pẹ̀lú ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Nasiri, ní àfikún sí àwọn ohun mìíràn tó lágbára láti mú wá. Ó gbọdọ̀ mú ẹ̀jẹ́ tó jẹ́ ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin Nasiri.’”
22 Og Herren talede til Mose og sagde:
Olúwa sọ fún Mose pé,
23 Tal til Aron og til hans Sønner og sig: Saaledes skulle I velsigne Israels Børn og sige til dem:
“Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé, ‘Báyìí ni kí ẹ ṣe máa súre fún àwọn ọmọ Israẹli. Ẹ sọ fún wọn pé,
24 Herren velsigne dig og bevare dig!
“‘“Kí Olúwa bùkún un yín, kí ó sì pa yín mọ́.
25 Herren lade lyse sit Ansigt over dig og være dig naadig!
Kí Olúwa kí o mú ojú rẹ̀ kí ó mọ́lẹ̀ sí i yín lára. Kí ó sì ṣàánú fún un yín.
26 Herren opløfte sit Ansigt til dig og give dig Fred!
Kí Olúwa bojú wò yín, kí ó sì fún un yín ní àlàáfíà.”’
27 Og de skulle lægge mit Navn paa Israels Børn, og jeg, jeg vil velsigne dem.
“Báyìí ni wọn ó ṣe fi orúkọ mi sára àwọn ọmọ Israẹli, Èmi ó sì bùkún wọn.”

< 4 Mosebog 6 >