< 4 Mosebog 34 >
1 Og Herren talede til Mose og sagde:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Byd Israels Børn, og du skal sige til dem: Naar I komme til Kanaans Land, da skal dette være det Land, som skal falde eder til Arv, nemlig Kanaans Land efter sine Grænser.
“Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá wọ Kenaani, ilẹ̀ tí a ó fi fún yín, gẹ́gẹ́ bí ogún yín yóò ní ààlà wọn yí:
3 Og den søndre Side skal være eder fra den Ørk Zin til Edom, og eders Landemærke skal være i Sønden fra Enden af Salthavet imod Østen.
“‘Ìhà gúúsù yín yóò bọ́ sí ara aginjù Sini lẹ́bàá Edomu, àti ìlà-oòrùn, ààlà ìhà gúúsù yóò bẹ̀rẹ̀ láti òpin Òkun Iyọ̀,
4 Og eders Landemærke skal gaa omkring hen Sønden om Opgangen til Akrabbim og gaa igennem til Zin, og dets Udgang skal være Sønden for Kades-Barnea, og det skal gaa ud til Hazar-Adar og gaa over til Azmon.
kọjá lọ sí gúúsù Akrabbimu, tẹ̀síwájú lọ si Sini, kó bọ́ si gúúsù Kadeṣi-Barnea, kí o sì dé Hasari-Addari, kí o sì kọjá sí Asmoni.
5 Og Landemærket skal gaa omkring fra Azmon til Ægyptens Bæk, og Udgangen derpaa skal være til Havet.
Kí òpin ilẹ̀ rẹ̀ kí ó sì yíká láti Asmoni lọ dé odò Ejibiti, Òkun Ńlá ni yóò sì jẹ òpin rẹ.
6 Og angaaende Landemærket imod Vesten, da skal det store Hav være eder Landemærke; dette skal være eders Landemærke imod Vesten.
Ìhà ìwọ̀-oòrùn yín yóò jẹ́ òpin lórí Òkun Ńlá. Èyí yóò jẹ́ ààlà yín lórí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
7 Og dette skal være eder Landemærket mod Norden: I skulle sætte Grænsen for eder fra det store Hav til Bjerget Hor.
Fún ààlà ìhà àríwá, fa ìlà láti Òkun Ńlá lọ sí orí òkè Hori,
8 Fra Bjerget Hor skulle I sætte Grænsen hen imod Hamath, og Landemærkets Udgang skal være til Zedad.
àti láti orí òkè Hori sí Lebo-Hamati. Nígbà náà ààlà náà yóò lọ sí Sedadi,
9 Og Landemærket skal gaa ud til Sifron, og dets Udgang skal være ved Hasar-Enan; dette skal være eders Landemærke imod Norden.
tẹ̀síwájú lọ sí Sifroni, kí o sì fò pín si ní Hasari-Enani, èyí yóò jẹ́ ààlà tìrẹ ní ìhà àríwá.
10 Og I skulle maale eders Landemærke mod Østen fra Hasar-Enan til Sefam.
Kí ẹ sì sàmì sí ilẹ̀ tiyín ní ìhà ìlà-oòrùn láti Hasari-Enani lọ dé Ṣefamu.
11 Og Landemærket skal gaa ned fra Sefam til Ribla, Østen for Ain, og Landemærket skal gaa ned og berøre Siden af Kinnereths Hav imod Østen.
Ààlà náà yóò ti Ṣefamu sọ̀kalẹ̀ wá lọ sí Ribla ní ìhà ìlà-oòrùn Aini, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ dé ìhà Òkun Kinnereti ní ìhà ìlà-oòrùn.
12 Og Landemærket skal gaa ned til Jordanen, og dets Udgang skal være ved Salthavet; dette skal være eder Landet med sine Grænser trindt omkring.
Nígbà náà, ààlà náà yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sí apá Jordani, yóò sì dópin nínú Òkun Iyọ̀. “‘Èyí yóò jẹ́ ilẹ̀ yín, pẹ̀lú ààlà tirẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà.’”
13 Og Mose bød Israels Børn og sagde: Dette er det Land, som I skulle tage eder til Arv ved Lodkastning, og som Herren befalede at give de ni Stammer og den halve Stamme;
Mose pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Yan ilẹ̀ yìí pẹ̀lú kèké gẹ́gẹ́ bí ìní ogún: Olúwa ti pàṣẹ láti fi fún ẹ̀yà mẹ́sàn-án, àti ààbọ̀.
14 thi Rubeniternes Børns Stamme efter deres Fædrenehuse, og Gaditernes Børns Stamme efter deres Fædrenehuse, de have faaet, og Manasse halve Stamme, de have faaet deres Arv.
Nítorí ará ilẹ̀ ẹ̀yà ti Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ẹ̀yà ààbọ̀ ti Manase ti gba ogún tiwọn.
15 De to Stammer og den halve Stamme, de have faaet deres Arv paa denne Side Jordanen lige for Jeriko, foran mod Østen.
Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún tiwọn ní ìhà ìhín Jordani létí i Jeriko, ní ìhà ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ Jordani.”
16 Og Herren talede til Mose og sagde:
Olúwa sọ fún Mose pé,
17 Disse ere Navnene paa de Mænd, som skulle dele Landet til Arv mellem eder: Eleasar, Præsten, og Josva, Nuns Søn.
“Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni.
18 Og een Fyrste af hver Stamme skulle I tage til at dele Landet til Arv.
Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
19 Disse ere Navnene paa Mændene: Af Judas Stamme Kaleb, Jefunne Søn;
“Èyí ni orúkọ wọn: “Kalebu ọmọ Jefunne, láti ẹ̀yà Juda;
20 og af Simeons Børns Stamme Semuel, Ammihuds Søn;
Ṣemueli ọmọ Ammihudu, láti ẹ̀yà Simeoni;
21 af Benjamins Stamme Elidad, Kisions Søn;
Elidadi ọmọ Kisloni, láti ẹ̀yà Benjamini;
22 og af Dans Børns Stamme en Fyrste, Bukki, Jogli Søn;
Bukki ọmọ Jogli, láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dani;
23 af Josefs Børn, af Manasse Børns Stamme, en Fyrste, Hanniel, Efods Søn;
Hannieli ọmọ Efodu, láti ẹ̀yà Manase, olórí àwọn ọmọ Josẹfu,
24 og af Efraims Børns Stamme en Fyrste, Kemuel, Siftans Søn;
Kemueli ọmọ Ṣiftani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Efraimu, ọmọ Josẹfu;
25 og af Sebulons Børns Stamme en Fyrste, Elizafan, Parnaks Søn;
Elisafani ọmọ Parnaki, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Sebuluni;
26 og af Isaskars Børns Stamme en Fyrste, Paltiel, Assans Søn;
Paltieli ọmọ Assani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Isakari;
27 og af Asers Børns Stamme en Fyrste, Akihud, Selomi Søn;
Ahihudu ọmọ Ṣelomi, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Aṣeri;
28 og af Nafthali Børns Stamme en Fyrste, Pedahel, Ammihuds Søn.
Pedaheli ọmọ Ammihudu, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Naftali.”
29 Disse ere de, som Herren bød at dele Arven imellem Israels Børn, i Kanaans Land.
Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Israẹli ní ilẹ̀ Kenaani.