< 3 Mosebog 22 >

1 Og Herren talede til Mose og sagde:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Sig til Aron og til hans Sønner, at de afholde sig fra Israels Børns hellige Ting og ikke vanhellige mit hellige Navn, naar disse hellige mig noget; jeg er Herren.
“Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ kí wọ́n fi ọ̀wọ̀ fún ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli yà sọ́tọ̀ fún mi, kí wọ́n má ba à ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́. Èmi ni Olúwa.
3 Sig til dem: Hvilken som helst Mand i eders Slægter af al eders Sæd, der kommer nær til de hellige Ting, som Israels Børn hellige Herren, og hans Urenhed er paa ham, han skal udryddes fra at være for mit Ansigt; jeg er Herren.
“Sọ fún wọn pé, ‘Fún àwọn ìran tí ń bọ̀. Bí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ yín tí kò mọ́ bá wá sí ibi ọrẹ mímọ́ tí àwọn ara Israẹli ti yà sọ́tọ̀ fún Olúwa, kí ẹ yọ ẹni náà kúrò nínú iṣẹ́ àlùfáà ní iwájú mi. Èmi ni Olúwa.
4 Hvo som helst af Arons Sæd, der er spedalsk eller har Flod, han skal ikke æde af de hellige Ting, indtil han vorder ren; og den ikke heller, som rører ved nogen, der er uren formedelst Lig, eller den Mand, fra hvem der gaar Sæd,
“‘Bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Aaroni bá ní ààrùn ara tí ń ran ni, tàbí ìtújáde nínú ara. Ó lè má jẹ ọrẹ mímọ́ náà títí di ìgbà tí a ó fi wẹ̀ ẹ́ mọ́. Òun tún lè di aláìmọ́ bí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí òkú nǹkan bá sọ di àìmọ́ tàbí bí ó bá farakan ẹnikẹ́ni tí ó ní ìtújáde.
5 eller den Mand, som rører ved noget Kryb, som man kan blive uren af, eller ved et Menneske, som man kan blive uren af, hvad Slags Urenhed det end er;
Tàbí bí ó bá fọwọ́ kan èyíkéyìí nínú ohun tí ń rákò, tí ó sọ ọ́ di aláìmọ́, tàbí ẹnikẹ́ni tí ó sọ ọ́ di àìmọ́, ohunkóhun yówù kí àìmọ́ náà jẹ́.
6 den Person, som rører ved det, skal være uren indtil Aftenen, og han skal ikke æde af de hellige Ting, men bade sit Legeme i Vand.
Ẹni náà tí ó fọwọ́ kan irú nǹkan bẹ́ẹ̀ yóò di aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́. Kò gbọdọ̀ jẹ èyíkéyìí nínú ọrẹ mímọ́ àyàfi bí ó bá wẹ ara rẹ̀.
7 Og naar Solen gaar ned, saa er han ren, og siden maa han æde af de hellige Ting; thi det er hans Mad.
Bí oòrùn bá wọ̀, ẹni náà di mímọ́, lẹ́yìn náà ni ó tó le jẹ ọrẹ mímọ́, torí pé wọ́n jẹ́ oúnjẹ rẹ̀.
8 Han skal ikke æde Aadsel eller det, som er sønderrevet, at blive uren paa det; jeg er Herren.
Kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti kú sílẹ̀, tàbí tí ẹranko fàya, kí ó sì tipa bẹ́ẹ̀ di aláìmọ́. Èmi ni Olúwa.
9 Og de skulle holde det, jeg vil have holdt, og de skulle ikke bære Synd for den Sags Skyld og dø derfor, naar de vanhellige det; jeg er Herren, som helliger dem.
“‘Kí àwọn àlùfáà pa ìlànà mi mọ́, kí wọn má ba à jẹ̀bi, kí wọn sì kú nítorí pé wọ́n ṣe ọrẹ wọ̀nyí pẹ̀lú fífojútẹ́ńbẹ́lú wọn. Èmi ni Olúwa tí ó sọ wọ́n di mímọ́.
10 Og ingen fremmed skal æde det hellige; den, som bor hos Præsten, og en Daglønner skal ikke æde af det hellige.
“‘Kò sí ẹnikẹ́ni lẹ́yìn ìdílé àlùfáà tí ó le jẹ ọrẹ mímọ́ náà, bẹ́ẹ̀ ni, àlejò àlùfáà tàbí alágbàṣe rẹ̀ kò le jẹ ẹ́.
11 Men naar Præsten har købt nogen for sine Penge til Ejendom, da maa denne æde deraf; og hver den, som er født i hans Hus, de maa æde af hans Brød.
Ṣùgbọ́n bí àlùfáà bá ra ẹrú, pẹ̀lú owó, tàbí tí a bí ẹrú kan nínú ìdílé rẹ̀, ẹrú náà lè jẹ oúnjẹ rẹ̀.
12 Men naar en Præsts Datter bliver en fremmed Mands Hustru, da skal hun ikke æde af de hellige Ting, som ere en Gave.
Bí ọmọbìnrin àlùfáà bá fẹ́ ẹni tí kì í ṣe àlùfáà, kò gbọdọ̀ jẹ nínú èyíkéyìí nínú ohun ọrẹ mímọ́.
13 Men naar en Præsts Datter bliver Enke eller forskudt, og hun har ingen Afkom, og hun vender tilbage til sin Faders Hus, ligesom i hendes Ungdom, da maa hun æde af sin Faders Brød; men ingen fremmed maa æde deraf.
Ṣùgbọ́n bí ọmọbìnrin àlùfáà bá jẹ́ opó tàbí tí a ti kọ ọ́ sílẹ̀, ṣùgbọ́n tí kò lọ́mọ tí ó sì padà sínú ilé baba rẹ̀ láti máa gbé bẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀, ó le jẹ oúnjẹ baba rẹ̀. Bí ó ti wù kí ó rí, àlejò tí kò lẹ́tọ̀ọ́ kò gbọdọ̀ jẹ èyíkéyìí nínú oúnjẹ náà.
14 Men æder nogen af det hellige uvitterlig, da skal han lægge den femte Del deraf dertil og give Præsten det tillige med det hellige.
“‘Bí ẹnikẹ́ni bá ṣèèṣì jẹ ọrẹ mímọ́ kan, ó gbọdọ̀ ṣe àtúnṣe lórí ẹbọ náà fún àlùfáà, kí ó sì fi ìdámárùn-ún ohun tí ọrẹ náà jẹ́ kún un.
15 Og de skulle ikke vanhellige Israels Børns hellige Ting, dem, som de bringe til Gave for Herren,
Àwọn àlùfáà kò gbọdọ̀ sọ ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli mú wá síwájú Olúwa di àìmọ́.
16 og ikke belade sig med Misgerning og Skyld, naar de æde deres hellige Ting; thi jeg er Herren, som helliger dem.
Nípa fífi ààyè fún wọn láti jẹ ọrẹ mímọ́ náà, kí wọ́n sì tipa bẹ́ẹ̀ mú ẹ̀bi tí wọn yóò san nǹkan fún wá sórí wọn. Èmi ni Olúwa, tí ó sọ wọ́n di mímọ́.’”
17 Og Herren talede til Mose og sagde:
Olúwa sọ fún Mose pé,
18 Tal til Aron og til hans Sønner og til alle Israels Børn, og sig til dem: Naar nogen som helst af Israels Hus eller af de fremmede i Israel vil ofre sit Offer, enten det er efter deres Løfte, eller deres frivillige Offer, som de ville ofre Herren til et Brændoffer,
“Sọ fún Aaroni, àwọn ọmọ rẹ̀ àti fún gbogbo Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Bí ẹnikẹ́ni nínú yín yálà ọmọ Israẹli ni tàbí àlejò tí ń gbé ní Israẹli bá mú ẹ̀bùn wá fún ọrẹ ẹbọ sísun sí Olúwa, yálà láti san ẹ̀jẹ́ tàbí ọrẹ àtinúwá.
19 da skal det, for at blive til en Behagelighed for eder, være uden Lyde, en Han af stort Kvæg, af Faarene eller af Gederne.
Ẹ gbọdọ̀ mú akọ láìní àbùkù láti ara màlúù, àgùntàn tàbí ewúrẹ́, kí ó ba à lè jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
20 I skulle intet ofre af det, som der er Lyde paa; thi det bliver ikke til en Behagelighed for eder.
Ẹ má ṣe mú ohunkóhun tí ó ní àbùkù wá, torí pé kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
21 Og naar nogen vil ofre et Takoffer for Herren til at indfrie et Løfte eller til et frivilligt Offer af stort Kvæg eller smaat Kvæg, da skal det være uden Lyde, at det kan være til en Behagelighed; der skal slet ingen Lyde være paa det.
Bí ẹnikẹ́ni bá mú ọrẹ àlàáfíà wá láti inú agbo màlúù tàbí ti àgùntàn, fún Olúwa láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí fún ọrẹ àtinúwá. Ó gbọdọ̀ jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà láìní àbùkù.
22 Det, som er blindt eller benbrudt eller lemlæstet, eller som har flydende Saar eller Skurv eller Fnat, det skulle I ikke ofre Herren, og I skulle ikke bringe Ildoffer deraf paa Alteret til Herren.
Ẹ má ṣe fi ẹranko tí ó fọ́jú, tí ó fi ara pa, tí ó yarọ, tí ó ní kókó, tí ó ní èkúkú, èépá àti egbò kíkẹ̀ rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ kò gbọdọ̀ gbé èyíkéyìí nínú wọn sórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bi ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.
23 Baade en Okse og et Faar, som har et Lem for stort eller for lidet, deraf maa du gøre et frivilligt Offer; men til et Løfte kan det ikke vorde behageligt.
Ẹ le mú màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù tàbí tí ó yọ iké wá fún ọrẹ àtinúwá, ṣùgbọ́n kò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún ọrẹ ẹ̀jẹ́.
24 Og I skulle ikke ofre Herren noget, som er blevet krystet eller stødt eller sønderrevet eller afskaaret, og I skulle ikke gøre sligt i eders Land.
Ẹ má ṣe fi ẹranko tí kóró ẹpọ̀n rẹ̀ fọ́ tàbí tí a tẹ̀, tàbí tí a yà tàbí tí a là rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí ní ilẹ̀ yín.
25 Og I skulle heller ikke ofre af en fremmeds Haand eders Guds Brød af noget af disse Ting; thi der er Skade paa dem, der er Lyde paa dem; de skulle ikke blive behagelige for eder.
Ẹ kò gbọdọ̀ gba irú ẹranko bẹ́ẹ̀ lọ́wọ́ àlejò kankan láti fi rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ sí Ọlọ́run yín. A kò nígbà wọ́n fún yín nítorí pé wọ́n ní àbùkù, wọ́n sì díbàjẹ́.’”
26 Og Herren talede til Mose og sagde:
Olúwa sọ fún Mose pé,
27 Naar en Okse eller et Faar eller en Ged fødes, da skal den være i syv Dage hos sin Moder, og fra den ottende Dag og derefter skal den være behagelig til et Ildoffer for Herren.
“Nígbà tí màlúù bá bímọ, tí àgùntàn bímọ, tí ewúrẹ́ sì bímọ, ọmọ náà gbọdọ̀ wà pẹ̀lú ìyá rẹ̀ fún ọjọ́ méje. Láti ọjọ́ kẹjọ ni ó ti di ìtẹ́wọ́gbà fún ọrẹ àfinásun sí Olúwa.
28 Hvad enten det er Okse eller Faar, da skal man ikke slagte det paa een Dag med dets Affødning.
Ẹ má ṣe pa màlúù àti ọmọ rẹ̀ tàbí àgùntàn àti ọmọ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà.
29 Men naar I slagte Herren et Lovoffer, skulle I slagte det for eder til en Behagelighed.
“Nígbà tí ẹ bá rú ẹbọ ọpẹ́ sí Olúwa, ẹ rú u ní ọ̀nà tí yóò fi jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
30 Det skal ædes paa den samme Dag, I skulle ikke levne deraf til om Morgenen; jeg er Herren.
Ẹ gbọdọ̀ jẹ ẹ́ ní ọjọ́ náà gan an, ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan kù di àárọ̀. Èmi ni Olúwa.
31 Derfor skulle I holde mine Bud og gøre dem; jeg er Herren.
“Ẹ pa òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Èmi ni Olúwa.
32 Og I skulle ikke vanhellige mit hellige Navn, at jeg maa vorde helliget midt iblandt Israels Børn. Jeg er Herren, som helliger eder,
Ẹ má ṣe ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́. Àwọn ọmọ Israẹli gbọdọ̀ mọ̀ mí ní mímọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
33 og som udførte eder af Ægyptens Land, at være eders Gud; jeg er Herren.
Tí ó sì mú yín jáde láti Ejibiti wá láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa.”

< 3 Mosebog 22 >