< 3 Mosebog 16 >

1 Og Herren talede til Mose, efter at de to af Arons Sønner vare døde, der de vare gangne frem for Herrens Ansigt og vare døde.
Olúwa sọ fún Mose lẹ́yìn ikú àwọn ọmọ Aaroni méjèèjì tí wọ́n kú nígbà tí wọ́n súnmọ́ Olúwa.
2 Og Herren sagde til Mose: Sig til Aron, din Broder, at han ikke til enhver Tid maa gaa ind i Helligdommen inden for Forhænget lige for Naadestolen, som er paa Arken, at han ikke dør; thi jeg vil ses i Skyen over Naadestolen.
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Kìlọ̀ fún Aaroni arákùnrin rẹ pé kí ó má ṣe máa wá nígbà gbogbo sí Ibi Mímọ́ Jùlọ tí ó wà lẹ́yìn aṣọ títa ní ibi tí àpótí ẹ̀rí àti ìtẹ́ àánú wà, kí ó má ba à kú nítorí pé Èmi ó farahàn nínú ìkùùkuu lórí ìtẹ́ àánú.
3 Med dette skal Aron komme til Helligdommen: Med en ung Tyr til Syndoffer og en Væder til Brændoffer.
“Báyìí ni Aaroni yóò ṣe máa wá sí Ibi Mímọ́ Jùlọ pẹ̀lú ọ̀dọ́ akọ màlúù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti àgbò fún ẹbọ sísun.
4 Han skal iføre sig en hellig linned Kjortel og have linnede Underklæder paa sin Krop og ombinde sig med et linned Bælte, og med en linned Præstehue skal han bedække sig; disse ere de hellige Klæder, og han skal bade sit Legeme i Vand og iføre sig dem.
Òun yóò sì wọ aṣọ funfun mímọ́ pẹ̀lú àwọ̀tẹ́lẹ̀ funfun, yóò sì fi àmùrè funfun mímọ́ dì í, yóò sì dé fìlà funfun, àwọn aṣọ mímọ́ nìwọ̀nyí. Òun yóò sì fi omi wẹ̀, kí ó tó wọ̀ wọ́n.
5 Og han skal tage af Israels Børns Menighed to Gedebukke til Syndoffer og en Væder til Brændoffer.
Òun yóò sì mú ọmọ ewúrẹ́ méjì láti ọ̀dọ̀ gbogbo àgbájọpọ̀ àwọn ọmọ Israẹli láti fi ṣe ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ wọ́n, àti àgbò kan fún ẹbọ sísun.
6 Og Aron skal ofre Syndofrets Tyr, som er for ham selv, og gøre Forligelse for sig og for sit Hus.
“Aaroni yóò sì fi akọ màlúù rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ èyí tí ṣe ti ara rẹ̀ òun yóò sì ṣe ètùtù fún ara rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀.
7 Og han skal tage de to Bukke, og han skal stille dem for Herrens Ansigt, for Forsamlingens Pauluns Dør.
Lẹ́yìn náà yóò sì mú ewúrẹ́ méjì náà wá sí iwájú Olúwa ní ibi ìlẹ̀kùn àgọ́ ìpàdé.
8 Og Aron skal kaste Lod over de to Bukke, een Lod for Herren og een Lod for Asasel.
Aaroni yóò sì dìbò ní ti àwọn ewúrẹ́ méjèèjì náà, ìbò àkọ́kọ́ fún ti Olúwa, àti èkejì fún ewúrẹ́ ìpààrọ̀.
9 Og Aron skal ofre den Buk, paa hvilken Lodden kom ud for Herren, og berede den til Syndoffer.
Aaroni yóò sì mú ewúrẹ́ tí ìbò Olúwa mú, yóò sì fi rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
10 Men den Buk, paa hvilken Lodden for Asasel er falden, skal stilles levende for Herrens Ansigt, at der ved den skal gøres Forligelse, at man skal sende den bort til Asasel til Ørken.
Ṣùgbọ́n ewúrẹ́ tí ìbò bá mú gẹ́gẹ́ bí ewúrẹ́ ìpààrọ̀ ni a ó mú wá láààyè síwájú Olúwa láti fi ṣe ètùtù sí i àti láti jẹ́ kí ó lọ lọ́fẹ̀ẹ́, sí aginjù.
11 Og Aron skal ofre Syndofrets Tyr, som er for ham selv, og gøre Forligelse for sig selv og for sit Hus, og han skal slagte Syndofrets Tyr, som er for ham.
“Aaroni yóò sì mú akọ màlúù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ wá láti ṣe ètùtù fún ara rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀. Yóò sì pa akọ màlúù náà fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tirẹ̀.
12 Saa skal han tage et Ildkar fuldt af Gløder af Ilden fra Alteret for Herrens Ansigt, og sine Hænder fulde af stødt Røgelse af vellugtende Urter, og han skal bære det inden for Forhænget.
Yóò sì mú àwo tùràrí tí ó kún fún èédú tí a ti sun pẹ̀lú iná láti orí pẹpẹ wá síwájú Olúwa: àti ẹ̀kúnwọ́ méjì tùràrí tí a gún kúnná yóò sì mú un wá sí ẹ̀yìn aṣọ títa.
13 Og han skal komme Røgelsen paa Ilden for Herrens Ansigt, saa at en Sky af Røgelsen skjuler Naadestolen, som er over Vidnesbyrdet, at han ikke dør.
Yóò sì fi tùràrí náà lé orí iná níwájú Olúwa: kí èéfín tùràrí náà ba à le bo ìtẹ́ àánú tí ó wà ní orí àpótí ẹ̀rí kí o má ba à kú.
14 Og han skal tage af Tyrens Blod og stænke med sin Finger mod Naadestolen for til, og han skal stænke syv Gange med sin Finger af Blodet for Naadestolen.
Yóò sì mú nínú ẹ̀jẹ̀ ọmọ màlúù náà yóò sì fi ìka rẹ̀ wọ́n ọn, ní iwájú ìtẹ́ àánú, yóò sì fi ìka rẹ̀ wọ́n ọn nígbà méje níwájú ìtẹ́ àánú.
15 Og han skal slagte Syndofrets Buk, som er for Folket, og bære dens Blod inden for Forhænget og gøre med dens Blod, ligesom han gjorde med Tyrens Blod, og stænke det mod Naadestolen og for Naadestolen.
“Nígbà yìí ni yóò pa ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó wà fún àwọn ènìyàn yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wá sí ẹ̀yìn aṣọ títa, bí ó ti ṣe ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù náà ni yóò ṣe ti ewúrẹ́ yìí, yóò sì wọ́n ọn sórí ìtẹ́ ètùtù àti síwájú ìtẹ́ ètùtù.
16 Og han skal gøre Forligelse for Helligdommen og rense den fra Israels Børns Urenheder og fra deres Overtrædelser i alle deres Synder; og saaledes skal han gøre ved Forsamlingens Paulun, som staar hos dem midt iblandt deres Urenheder.
Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún Ibi Mímọ́ Jùlọ nítorí àìmọ́ àwọn ará Israẹli àti nítorí gbogbo ìrékọjá wọn àti ìṣọ̀tẹ̀ wọn nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn gbogbo, bákan náà ni yóò sì ṣe fún àgọ́ ìpàdé, èyí tí ó wà láàrín wọn nínú àìmọ́ wọn.
17 Og intet Menneske skal være i Forsamlingens Paulun, naar han kommer at gøre Forligelse i Helligdommen, indtil han gaar ud; og han skal gøre Forligelse for sig og for sit Hus og for hele Israels Menighed.
Kí ó má ṣe sí ẹyọ ènìyàn kan nínú àgọ́ ìpàdé nígbà tí òun bá wọ Ibi Mímọ́ Jùlọ lọ láti ṣe ètùtù, títí di ìgbà tí yóò fi jáde lẹ́yìn tí ó ba ṣe ètùtù fúnra rẹ̀ fún ìdílé rẹ̀ àti fún gbogbo àgbájọpọ̀ Israẹli.
18 Og han skal gaa ud til Alteret, som er for Herrens Ansigt, og gøre Forligelse for det, og han skal tage af Tyrens Blod og af Bukkens Blod og komme det paa Alterets Horn rundt omkring.
“Lẹ́yìn náà òun yóò lọ sí ibi pẹpẹ tí ó wà níwájú Olúwa, yóò sì ṣe ètùtù fún pẹpẹ náà. Yóò sì mú nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù àti nínú ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ náà, yóò sì fi sí orí ọ̀kọ̀ọ̀kan ìwo pẹpẹ náà yíká.
19 Og han skal stænke paa det af Blodet med sin Finger syv Gange, og han skal rense det og hellige det fra Israels Børns Urenheder.
Lẹ́yìn náà, òun yóò wọ́n ẹ̀jẹ̀ náà sórí rẹ̀ pẹ̀lú ìka rẹ̀ nígbà méje láti wẹ̀ ẹ́ mọ́ àti láti sọ ọ́ dí mímọ́ kúrò nínú àìmọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
20 Og naar han har fuldkommet at gøre Forligelse for Helligdommen og for Forsamlingens Paulun og for Alteret, da skal han føre den levende Buk frem.
“Lẹ́yìn ti Aaroni ti parí ṣíṣe ètùtù ti Ibi Mímọ́ Jùlọ, ti àgọ́ ìpàdé àti ti pẹpẹ, òun yóò sì mú ààyè ewúrẹ́ wá.
21 Og Aron skal lægge begge sine Hænder paa den levende Buks Hoved og over den bekende alle Israels Børns Misgerninger og alle deres Overtrædelser i alle deres Synder, og han skal lægge dem paa Bukkens Hoved og sende den bort til Ørken ved en Mand, som er skikket dertil.
Aaroni yóò sì gbé ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì lé orí ààyè ewúrẹ́ náà, yóò sì jẹ́wọ́ gbogbo ìwà búburú àti ìṣọ̀tẹ̀ àwọn ara Israẹli lé e lórí. Gbogbo ìrékọjá wọn àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn ni yóò sì gbé ka orí ewúrẹ́ náà. Yóò sì rán an lọ sí ijù láti ọwọ́ ẹni tí a yàn fún iṣẹ́ náà.
22 Og Bukken skal bære alle deres Misgerninger paa sig til et udyrket Land, og han skal lade Bukken løs i Ørken.
Ewúrẹ́ náà yóò sì ru gbogbo àìṣedéédéé wọn lọ sí ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé. Òun yóò sì jọ̀wọ́ ewúrẹ́ náà lọ́wọ́ lọ sínú ijù.
23 Saa skal Aron gaa ind i Forsamlingens Paulun og afføre sig Linklæderne, som han iførte sig, da han gik ind i Helligdommen, og han skal lade dem ligge der.
“Aaroni yóò sì padà wá sí ibi àgọ́ ìpàdé, yóò sì bọ́ aṣọ ọ̀gbọ̀ wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀, tí ó wọ̀ nígbà tí ó lọ sí Ibi Mímọ́ Jùlọ, yóò sì fi wọ́n sílẹ̀ níbẹ̀.
24 Og han skal bade sin Krop i Vand paa et helligt Sted og iføre sig sine andre Klæder, og han skal gaa ud og gøre sit Brændoffer og Folkets Brændoffer og gøre Forligelse for sig og for Folket.
Yóò sì fi omi wẹ ara rẹ̀ ní ibi mímọ́ kan, yóò sì wọ aṣọ rẹ̀ yóò sì wá ṣí iwájú, yóò sì rú ẹbọ sísun ti ara rẹ̀ àti ẹbọ sísun ti àwọn ènìyàn láti ṣe ètùtù fún ara rẹ̀ àti fún àwọn ènìyàn.
25 Og han skal gøre et Røgoffer af Syndofrets Fedt paa Alteret.
Òun yóò sì sun ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ náà lórí pẹpẹ.
26 Men den, som førte Bukken bort til Asasel, skal to sine Klæder og bade sin Krop i Vand, og derefter maa han komme til Lejren.
“Ẹni tí ó tú ewúrẹ́ ìpààrọ̀ náà sílẹ̀ yóò sì fọ aṣọ rẹ̀, yóò sì wẹ ara rẹ̀ nínú omi, lẹ́yìn èyí ó lè wá sí ibùdó.
27 Og Syndofrets Tyr og Syndofrets Buk, hvis Blod bliver baaret ind i Helligdommen til at gøre Forligelse, skal man føre ud uden for Lejren, og man skal opbrænde deres Hutl og deres Kød og deres Møg med Ild.
Ọ̀dọ́ akọ màlúù àti ewúrẹ́ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tí a ti mú ẹ̀jẹ̀ wọn wá sí Ibi Mímọ́ Jùlọ ni kí a gbe jáde kúrò ní ibùdó. Awọ wọn ni a ó fi iná sun bákan náà.
28 Og den, som opbrænder dem, skal to sine Klæder og bade sit Legeme i Vand, og derefter maa han komme til Lejren.
Ẹni tí ó sun wọ́n yóò sì fọ aṣọ rẹ̀, yóò sì wẹ ara rẹ̀, lẹ́yìn èyí ni ó tó le wọ ibùdó.
29 Og det skal være eder til en evig Skik: I den syvende Maaned, paa den tiende Dag i Maaneden, skulle I ydmyge eders Sjæle og ingen Gerning gøre, hverken den indfødte eller den fremmede, som opholder sig iblandt eder.
“Èyí ni yóò jẹ́ ìlànà títí láé fún un yín, pé ní ọjọ́ kẹwàá oṣù keje ni ẹ gbọdọ̀ ṣẹ́ ara yín, kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ kankan, yálà onílé tàbí àlejò tí ó ń gbé pẹ̀lú yín.
30 Thi paa denne Dag skal man gøre Forligelse for eder til at rense eder; af alle eders Synder skulle I vorde rene for Herrens Ansigt.
Torí pé ní ọjọ́ yìí ni àlùfáà yóò ṣe ètùtù fún yín láti sọ yín di mímọ́, kí ẹ̀yin bá à le mọ́ níwájú Olúwa yín kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín gbogbo.
31 Dette skal være eder en Sabbats Hvile, og I skulle ydmyge eders Sjæle til en evig Skik.
Ọjọ́ yìí yóò jẹ́ ọjọ́ ìsinmi pátápátá fún un yín, ẹ̀yin yóò sì ṣẹ́ ara yín. Èyí yóò sì jẹ́ ìlànà títí láé.
32 Og Præsten, som man salver, og hvis Haand man fylder til at gøre Præstetjeneste i hans Faders Sted, skal gøre Forligelse, og han skal iføre sig Linklæderne, de hellige Klæder.
Àlùfáà náà tí a ti fi òróró yàn tí a sì ti sọ di mímọ́ láti máa ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ilé ìsìn ní ipò baba rẹ̀, òun ni kí ó ṣe ètùtù, yóò sì wọ aṣọ funfun gbòò àní aṣọ mímọ́ náà, òun yóò sì ṣe ètùtù.
33 Og han skal gøre Forligelse for Hellighedens Helligdom, baade for Forsamlingens Paulun og for Alteret skal han gøre Forligelse, og for Præsterne og for al Menighedens Folk skal han gøre Forligelse.
Yóò sì ṣe ètùtù fún Ibi Mímọ́ Jùlọ, fún ìpàdé àti fún pẹpẹ, yóò sì ṣe ètùtù fún àlùfáà àti fún gbogbo àgbájọpọ̀ àwọn ènìyàn náà.
34 Og dette skal være eder til en evig Skik, at gøre Forligelse for Israels Børn for alle deres Synder een Gang om Aaret. Og han gjorde det, ligesom Herren havde befalet Mose.
“Èyí ni yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún yín: láti máa ṣe ètùtù fún àwọn ará Israẹli fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wọn lẹ́ẹ̀kan lọ́dún.” Ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

< 3 Mosebog 16 >