< Dommer 8 >

1 Og Mændene af Efraim sagde til ham: Hvad er det for en Ting, du har gjort os, at du ikke kaldte os, der du gik at stride imod Midianiterne? og de kivede stærkt med ham.
Àwọn àgbàgbà ẹ̀yà Efraimu sì bínú gidigidi sí Gideoni wọ́n bi í léèrè pé, kí ló dé tí o fi ṣe irú èyí sí wa? Èéṣe tí ìwọ kò fi pè wá nígbà tí ìwọ kọ́kọ́ jáde lọ láti bá àwọn ará Midiani jagun? Ohùn ìbínú ni wọ́n fi bá a sọ̀rọ̀.
2 Og han sagde til dem: Hvad har jeg nu gjort som I? er ikke Efraims Efterhøst bedre end Abiesers Vinhøst?
Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Àṣeyọrí wo ni mo ti ṣe tí ó tó fiwé tiyín? Àṣàkù àjàrà Efraimu kò ha dára ju gbogbo ìkórè àjàrà Abieseri lọ bí?
3 Gud har givet Midianiternes Fyrster, Oreb og Seeb, i eders Haand, og hvad formaar jeg at gøre som I? Der han havde sagt det Ord, da lod deres Vrede af fra ham.
Ọlọ́run ti fi Orebu àti Seebu àwọn olórí àwọn ará Midiani lé yín lọ́wọ́. Kí ni ohun tí Mose ṣe tí ó tó fiwé e yín tàbí tí ó tó àṣeyọrí i yín?” Nígbà tí ó wí èyí ríru ìbínú wọn rọlẹ̀.
4 Der Gideon kom til Jordanen, gik han over og de tre Hundrede Mænd, som vare med ham, trætte af at forfølge.
Gideoni àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ̀síwájú láti lépa àwọn ọ̀tá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti rẹ̀ wọ́n, wọ́n dé Jordani wọ́n sì kọjá sí òdìkejì.
5 Og han sagde til Mændene i Sukot: Kære, giver det Folk, som er i Følge med mig, nogle Brød; thi de ere trætte, og jeg forfølger Seba og Zalmuna, Midianiternes Konger.
Ó wí fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Ẹ fún àwọn ọmọ-ogun mi ní oúnjẹ díẹ̀, nítorí ó ti rẹ̀ wọ́n, èmi sì ń lépa Seba àti Salmunna àwọn ọba Midiani.”
6 Men de Øverste i Sukot sagde: Er da Sebas og Zalmunas Haand nu i din Haand, at vi skulle give din Hær Brød?
Ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Sukkoti fèsì pé ṣé ọwọ́ rẹ ti tẹ Seba àti Salmunna náà ni? Èéṣe tí àwa yóò ṣe fún àwọn ológun rẹ ní oúnjẹ?
7 Og Gideon sagde: Derfor naar Herren giver Seba og Zalmuna i min Haand, da vil jeg tærske eders Kød med Torne af Ørken og med Tidsler.
Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Ó dára, nígbà tí Olúwa bá fi Seba àti Salmunna lé mi lọ́wọ́ tán èmi yóò fi ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún òṣùṣú ya ẹran-ara yín.”
8 Og han drog derfra op til Pnuel og talede til dem paa samme Maade; og Mændene i Pnuel svarede ham, ligesom Mændene i Sukot svarede.
Láti ibẹ̀, ó lọ sí Penieli ó sì bẹ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ṣùgbọ́n àwọn náà dá a lóhùn bí àwọn ará Sukkoti ti dá a lóhùn.
9 Og han sagde ogsaa til Mændene i Pnuel saalunde: Naar jeg kommer tilbage med Fred, da vil jeg nedbryde dette Taarn.
Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ọkùnrin Penieli pé, “Nígbà tí mo bá ṣẹ́gun tí mo sì padà dé ní àlàáfíà, èmi yóò wó ilé ìṣọ́ yìí.”
10 Men Seba og Zalmuna vare i Karkor og med dem deres Lejr ved femten Tusinde, som vare alle de overblevne af den ganske Lejr af Folkene i Østen; men der var falden hundrede og tyve Tusinde Mænd, som kunde drage Sværd.
Ní àsìkò náà Seba àti Salmunna wà ní Karkori pẹ̀lú ọmọ-ogun wọn tí ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ọkùnrin, àwọn wọ̀nyí ni ó ṣẹ́kù nínú gbogbo ogun àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn, nítorí ọ̀kẹ́ mẹ́fà ọkùnrin tí ó fi idà jà ti kú ní ojú ogun.
11 Og Gideon drog op ad deres Vej, som bo i Telte, Østen for Noba og Jogbea; og han slog den Lejr, thi Lejren var tryg.
Gideoni gba ọ̀nà tí àwọn darandaran máa ń rìn ní apá ìhà ìlà-oòrùn Noba àti Jogbeha ó sì kọjú ogun sí àwọn ọmọ-ogun náà nítorí wọ́n ti túra sílẹ̀.
12 Og Seba og Zalmuna flyede, men han forfulgte dem; og han greb de to Midianiternes Konger, Seba og Zalmuna, og forfærdede den ganske Lejr.
Seba àti Salmunna, àwọn ọba Midiani méjèèjì sá, ṣùgbọ́n Gideoni lépa wọn ó sì mú wọn, ó run gbogbo ogun wọn.
13 Men der Gideon, Joas's Søn, kom tilbage fra Krigen fra Opgangen til Heres,
Gideoni ọmọ Joaṣi gba ọ̀nà ìgòkè Heresi padà sẹ́yìn láti ojú ogun.
14 da greb han en ung Karl af Mændene i Sukot og adspurgte ham; og denne skrev op for ham de Øverste i Sukot og de Ældste sammesteds, halvfjerdsindstyve og syv Mænd.
Ó mú ọ̀dọ́mọkùnrin kan ará Sukkoti, ó sì béèrè àwọn ìbéèrè ní ọwọ́ rẹ̀, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì kọ orúkọ àwọn ìjòyè Sukkoti mẹ́tàdínlọ́gọ́rin fún un tí wọ́n jẹ́ àgbàgbà ìlú náà.
15 Og han kom til Mændene i Sukot og sagde: Se, her er Seba og Zalmuna, med hvilke I forhaanede mig og sagde: Er da Sebas og Zalmunas Haand nu i din Haand, at vi skulle give dine Folk, som ere trætte, Brød?
Nígbà náà ni Gideoni wá ó sọ fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Seba àti Salmunna nìwọ̀nyí nípa àwọn tí ẹ̀yin fi mí ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ẹ wí pé, ‘Ṣé ó ti ṣẹ́gun Seba àti Salmunna? Èéṣe tí àwa ó fi fún àwọn ọmọ-ogun rẹ tí ó ti rẹ̀ ní oúnjẹ?’”
16 Og han tog de Ældste af Staden og Torne af Ørken og Tidsler og lod Folket i Sukot faa Forstand ved dem.
Ó mú àwọn àgbàgbà ìlú náà, ó sì fi kọ́ àwọn Sukkoti lọ́gbọ́n nípa jíjẹ wọ́n ní yà pẹ̀lú àwọn ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún ọ̀gàn.
17 Og Pnuels Taarn nedbrød han, og han ihjelslog Mændene i Staden.
Ó wó ilé ìṣọ́ Penieli, ó sì pa àwọn ọkùnrin ìlú náà.
18 Og han sagde til Seba og til Zalmuna: Hvordan vare de Mænd, som I sloge ihjel ved Thabor? og de sagde: Som du, saa vare de, hver af dem saa ud som en Kongesøn.
Gideoni bi Seba àti Salmunna pé, “Irú ọkùnrin tí ẹ pa ní Tabori, báwo ni wọ́n ṣe rí?” “Àwọn ọkùnrin náà dàbí rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dàbí ọmọ ọba,” ní ìdáhùn wọn.
19 Og han sagde: De vare mine Brødre, min Moders Sønner: Saa vist som Herren lever, dersom I havde ladet dem leve, da vilde jeg ikke slaget eder ihjel.
Gideoni dáhùn pé, “Arákùnrin mi ni wọ́n, àwọn ọmọ ìyá mi. Mo fi Olúwa búra, bí ó bá ṣe pé ẹ dá ẹ̀mí wọn sí, èmi náà ò nípa yín.”
20 Og han sagde til Jether, sin førstefødte: Staa op, slaa dem ihjel; men Drengen drog ikke sit Sværd ud, thi han frygtede, efterdi han var endnu en Dreng.
Ó yí padà sí Jeteri, ọmọ rẹ̀ tí ó dàgbà jùlọ, ó wí fún un pé, “Pa wọ́n!” Ṣùgbọ́n Jeteri kò fa idà rẹ̀ yọ láti pa wọ́n nítorí ó jẹ́ ọ̀dọ́mọdé ẹ̀rù sì bà á láti pa wọ́n.
21 Men Seba og Zalmuna sagde: Staa du op og fald an paa os, thi som Manden er, saa er hans Styrke; saa stod Gideon op og slog Seba og Zalmuna ihjel og toge de Halvmaaner, som vare paa deres Kamelers Halse.
Seba àti Salmunna dá Gideoni lóhùn pé, “Wá pa wá fún raàrẹ, ‘Nítorí bí ènìyàn bá ti rí bẹ́ẹ̀ ni agbára rẹ̀ yóò rí.’” Gideoni bọ́ síwájú ó sì pa wọ́n, ó sì mú ohun ọ̀ṣọ́ tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
22 Da sagde hver Mand i Israel til Gideon: Hersk over os, baade du og saa din Søn, saa og din Søns Søn, efterdi du har frelst os af Midianiternes Haand.
Àwọn ará Israẹli wí fún Gideoni pé, “Jọba lórí wa—ìwọ, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ pẹ̀lú, nítorí tí ìwọ ti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ará Midiani.”
23 Og Gideon sagde til dem: Jeg vil ikke herske over eder; og min Søn skal ikke herske over eder; Herren skal herske over eder.
Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Èmi kì yóò jẹ ọba lórí yín, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ mi kì yóò jẹ ọba lórí yín. Olúwa ni yóò jẹ ọba lórí yín.”
24 Og Gideon sagde til dem: Jeg har en Begæring til eder: Hver give mig dog en Bing af hans Bytte; thi hine havde Guldringe, eftersom de vare Ismaeliter.
Gideoni sì wí pé, “Mo ní ẹ̀bẹ̀ kan tí mo fẹ́ bẹ̀ yín kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín fún mi ní yẹtí kọ̀ọ̀kan láti inú ohun ti ó kàn yín láti inú ìkógun.” (Àṣà àwọn ará Iṣmaeli ni láti máa fi yẹtí wúrà sétí.)
25 Og de sagde: Vi ville gerne give, og de bredte et Klæde ud; og de kastede hver en Bing af sit Bytte derpaa.
Wọ́n dáhùn pé, “Tayọ̀tayọ̀ ni àwa yóò fi wọ́n sílẹ̀.” Wọ́n tẹ́ aṣọ kan sílẹ̀ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan sì ń sọ yẹtí kọ̀ọ̀kan tí ó kàn wọ́n láti ibi ìkógun síbẹ̀.
26 Og Vægten af de Guldringe, som han begærede, var tusinde og syv Hundrede Sekel Guld, foruden de Halvmaaner og de Halskæder og de Purpurklæder, som Midianiternes Konger havde paa sig, og foruden de Kæder, som vare om deres Kamelers Halse.
Ìwọ̀n òrùka wúrà tí ó béèrè fún tó ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ìwọ̀n ṣékélì, láìka àwọn ohun ọ̀ṣọ́ àti ohun sísorọ̀ tí ó wà lára ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn àti aṣọ elése àlùkò tí àwọn ọba Midiani ń wọ̀ tàbí àwọn ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
27 Og Gideon anvendte det til en Livkjortel og henlagde den i sin Stad udi Ofra, og al Israel bolede med den; og det blev Gideon og hans Hus til en Snare.
Gideoni fi àwọn wúrà náà ṣe efodu èyí tí ó gbé kalẹ̀ ní Ofira ìlú rẹ̀. Àwọn ọmọ Israẹli sì sọ ara wọn di àgbèrè nípa sínsin-ín ní ibẹ̀. Ó sì di ìdẹ̀kùn fún Gideoni àti ìdílé rẹ̀.
28 Saa bleve Midianiterne ydmygede for Israels Børn og bleve ikke ved at opløfte deres Hoved, og Landet havde Bo fyrretyve Aar i Gideons Dage.
Báyìí ni a ṣe tẹrí àwọn ará Midiani ba níwájú àwọn ọmọ Israẹli bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tún gbé orí mọ́. Ní ọjọ́ Gideoni, Israẹli wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún.
29 Og Jerub-Baal, Joas's Søn, gik bort og boede i sit Hus.
Jerubbaali ọmọ Joaṣi padà lọ láti máa gbé ní ìlú rẹ̀.
30 Og Gideon havde halvfjerdsindstyve Sønner, som vare udkomne af hans Lænd; thi han havde mange Hustruer.
Àádọ́rin ọmọ ni Gideoni bí, nítorí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìyàwó.
31 Og hans Medhustru, som var i Sikem, fødte ham ogsaa en Søn; og han gav ham Navnet Abimelek.
Àlè rẹ̀, tó ń gbé ní Ṣekemu, pàápàá bí ọmọkùnrin kan fún un tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Abimeleki.
32 Og Gideon, Joas's Søn, døde i en god Alderdom, og han blev begraven udi sin Faders, Abiesriteren Joas's, Grav i Ofra.
Gideoni ọmọ Joaṣi kú ní ògbólógbòó ọjọ́ rẹ̀, ó sì pọ̀ ní ọjọ́ orí, wọ́n sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀ ní Ofira ti àwọn ará Abieseri.
33 Og det skete, der Gideon var død, da vendte Israels Børn om og bolede med Baalerne; og de gjorde sig Baal-Berith til en Gud.
Láìpẹ́ jọjọ lẹ́yìn ikú Gideoni ni àwọn ará Israẹli ṣe àgbèrè tọ Baali lẹ́yìn, wọ́n fi Baali-Beriti ṣe òrìṣà wọn.
34 Og Israels Børn kom ikke Herren, deres Gud, i Hu, som havde friet dem af alle deres Fjenders Haand trindt omkring.
Wọn kò sì rántí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn gbogbo tí ó wà ní gbogbo àyíká wọn.
35 Og de viste ikke Kærlighed mod Jerub-Baals, det er Gideons Hus, efter alt det gode, som han havde gjort mod Israel.
Wọ́n kùnà láti fi inú rere hàn sí ìdílé Jerubbaali (èyí ni Gideoni) fún gbogbo oore tí ó ṣe fún wọn.

< Dommer 8 >