< Dommer 21 >
1 Og Israels Mænd havde svoret i Mizpa og sagt: Der skal ingen af os give Benjamin sin Datter til Hustru.
Àwọn ọkùnrin Israẹli ti búra ní Mispa pé, “Kò sí ẹnìkan nínú wa tí yóò fi ọmọ obìnrin rẹ̀ fún ẹ̀yà Benjamini ní ìyàwó.”
2 Og Folket kom til Guds Hus, og de bleve der indtil Aftenen for Guds Ansigt; og de opløftede deres Røst og græd med en stor Graad.
Àwọn ènìyàn náà lọ sí Beteli: ilé Ọlọ́run, níbi tí wọ́n jókòó níwájú Ọlọ́run títí di àṣálẹ́, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún kíkorò.
3 Og de sagde: Herre, Israels Gud! hvorfor er dette sket i Israel, at i Dag een Stamme savnes af Israel?
Wọ́n sọkún wí pé, “Háà! Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èéṣe tí nǹkan yìí fi ṣẹlẹ̀ sí Israẹli? Èéṣe tí ẹ̀yà kan yóò fi run nínú Israẹli lónìí?”
4 Og det skete den anden Dag, da stod Folket aarle op, og de byggede der et Alter, og de ofrede Brændofre og Takofre.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì àwọn ènìyàn náà mọ pẹpẹ kan wọ́n sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà.
5 Og Israels Børn sagde: Hvo er den, som ikke er kommen med op til Forsamlingen af alle Israels Stammer til Herren? Thi der var svoret en høj Ed imod den, som ikke kom op til Herren i Mizpa, saa der sagdes: Han skal visseligen dødes.
Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè wí pé, “Èwo nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti péjọ síwájú Olúwa?” Torí pé wọ́n ti fi ìbúra ńlá búra pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti péjọ níwájú Olúwa ní Mispa pípa ni àwọn yóò pa á.
6 Og det gjorde Israels Børn ondt for deres Broder Benjamin, og de sagde: I Dag er een Stamme afhuggen af Israel.
Àwọn ọmọ Israẹli sì banújẹ́ fún àwọn arákùnrin wọn, àwọn ẹ̀yà Benjamini. Wọ́n wí pé, “A ti ké ẹ̀yà kan kúrò lára Israẹli lónìí.”
7 Hvad ville vi gøre dem, som ere overblevne, at de kunne faa Hustruer? thi vi have svoret ved Herren, at vi ikke ville give dem af vore Døtre til Hustruer.
Báwo ni a yóò ṣe rí aya fún àwọn tí ó ṣẹ́kù, nítorí àwa ti fi Olúwa búra láti má fi ọ̀kankan nínú àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya.
8 Og de sagde: Hvad er det for en af Israels Stammer, som ikke er kommen op til Herren i Mizpa? Og se, der var ingen Mand kommen til Lejren fra Jabes i Gilead til Forsamlingen.
Wọ́n sì béèrè wí pé, “Èwo ni nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti bá àwọn ènìyàn péjọ níwájú Olúwa ní Mispa?” Wọ́n rí i pé kò sí ẹnikẹ́ni tí ó wa láti Jabesi Gileadi tí ó wá sí ibùdó fún àjọ náà.
9 Thi Folket blev talt; og se, da var der ingen af Indbyggerne fra Jabes i Gilead.
Nítorí pé nígbà tí wọ́n ka àwọn ènìyàn, wọ́n rí i pé kò sí ẹnìkankan láti inú àwọn ará Jabesi Gileadi tí ó wà níbẹ̀.
10 Da sendte de derhen af Menigheden tolv Tusinde Mand af Stridsfolkene; og de bøde dem og sagde: Gaar hen og slaar Indbyggerne i Jabes i Gilead med skarpe Sværd, samt Hustruerne og de smaa Børn.
Àwọn ìjọ ènìyàn náà sì rán ẹgbàá mẹ́fà àwọn jagunjagun ọkùnrin, lọ sí Jabesi Gileadi wọ́n fún wọn ní àṣẹ pé, ẹ lọ fi idà kọlu gbogbo àwọn tí ó wà níbẹ̀, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
11 Og denne er den Gerning, som I skulle gøre: Alt Mandkøn og alle Kvinder, som have haft Samkvem med nogen Mand, skulle I ødelægge.
Wọ́n ní, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe, ẹ pa gbogbo ọkùnrin àti gbogbo obìnrin tí kì í ṣe wúńdíá.”
12 Og de fandt af Indbyggerne i Jabes i Gilead fire Hundrede unge Piger, Jomfruer, som ikke havde kendt nogen Mand og ikke haft Samkvem med nogen Mand, og de førte dem til Lejren i Silo, som er i Landet Kanaan.
Wọ́n rí àwọn irinwó ọ̀dọ́bìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí nínú àwọn olùgbé Jabesi Gileadi, wọ́n sì mú wọn lọ sí ibùdó ní Ṣilo àwọn ará Kenaani.
13 Da sendte den ganske Menighed hen, og de lode tale med Benjamins Børn, som vare paa Klippen Bimmon; og de tilbøde dem Fred.
Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ránṣẹ́ àlàáfíà sí àwọn Benjamini ní ihò àpáta Rimoni.
14 Saa kom Benjamin tilbage paa samme Tid, og de gave dem de Hustruer, som de havde ladet leve af Kvinderne fra Jabes i Gilead; og de fandt ikke saaledes nok til dem.
Àwọn ẹ̀yà Benjamini náà sì padà ní àkókò náà, wọ́n sì fún wọn ní àwọn obìnrin Jabesi Gileadi. Ṣùgbọ́n wọn kò kárí gbogbo wọn.
15 Da gjorde det Folket ondt for Benjamin, fordi Herren havde gjort et Skaar i Israels Stammer.
Àwọn ènìyàn náà sì káàánú nítorí ẹ̀yà Benjamini, nítorí Olúwa fi àlàfo kan sílẹ̀ nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
16 Og Menighedens Ældste sagde: Hvad skulle vi gøre ved de overblevne, at de kunne faa Hustruer? thi Kvinderne af Benjamin ere udryddede.
Àwọn olórí ìjọ àwọn ènìyàn náà wí pé, “Kí ni àwa yóò ṣe láti rí aya fún àwọn ọkùnrin tí ó kù nígbà tí a ti pa gbogbo àwọn obìnrin Benjamini run?”
17 Og de sagde: De undkomnes Ejendom skal høre Benjamin til, at ikke een Stamme skal blive udslettet af Israel.
Wọ́n sì wí pé, “Àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n là nínú àwọn ẹ̀yà Benjamini ní láti ní ogún àti àrólé, kí ẹ̀yà kan nínú Israẹli má ṣe di píparun kúrò ní orí ilẹ̀.
18 Men vi kunne ikke give dem Hustruer af vore Døtre; thi Israels Børn have svoret og sagt: Forbandet være den, som giver Benjamin en Hustru!
Àwa kò le fi àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya, nítorí tí àwa ọmọ Israẹli ti ṣe ìbúra yìí pé, ‘Ègún ni fún ẹnikẹ́ni tí ó fi aya fún ẹnikẹ́ni nínú ẹ̀yà Benjamini.’”
19 Og de sagde: Se, der er Aar for Aar Herrens Højtid i Silo, som ligger Nord for Bethel, mod Solens Opgang, paa den alfare Vej, som gaar op fra Bethel til Sikem, og Syd for Lebona.
Wọ́n sì wí pé, “Kíyèsi i ayẹyẹ ọlọ́dọọdún fún Olúwa wà ní Ṣilo ní ìhà àríwá Beteli àti ìhà ìlà-oòrùn òpópó náà tí ó gba Beteli kọjá sí Ṣekemu, àti sí ìhà gúúsù Lebona.”
20 Og de befalede Benjamins Børn og sagde: Gaar hen og lurer i Vingaardene!
Wọ́n sì fi àṣẹ fún àwọn ará Benjamini pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fi ara pamọ́ nínú àwọn ọgbà àjàrà
21 Og I skulle se til, og se, dersom Silos Døtre gaa ud at danse, da maa I gaa ud af Vingaardene og gribe eder hver sin Hustru af Silos Døtre, og I skulle gaa til Benjamins Land.
kí ẹ sì wà ní ìmúrasílẹ̀. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin Ṣilo bá jáde láti lọ darapọ̀ fún ijó, kí ẹ yára jáde láti inú àwọn ọgbà àjàrà wọ̀n-ọn-nì kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbé aya kan nínú àwọn ọmọbìnrin Ṣilo kí ẹ padà sí ilẹ̀ Benjamini.
22 Og det skal ske, naar deres Fædre eller deres Brødre komme at gaa i Rette med os, da ville vi sige til dem: Værer dem naadige for vor Skyld, fordi vi ikke have skaffet dem hver sin Hustru i Krigen; thi I have heller ikke givet dem Hustruer; eller skulle I nu have været skyldige.
Nígbà tí àwọn baba wọn tàbí àwọn arákùnrin wọn bá fi ẹjọ́ sùn wá, àwa yóò wí fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe wá ní oore nípa ríràn wọ́n lọ́wọ́, nítorí àwa kò rí aya fún wọn ní àkókò ogun, ẹ̀yin kò sì ní jẹ̀bi, nítorí pé ẹ̀yin kọ́ ni ó fi àwọn ọmọbìnrin yín fún wọn bí aya.’”
23 Og Benjamins Børn gjorde saaledes og toge Hustruer efter deres Tal af dem, som dansede, hvilke de røvede; og de gik og kom tilbage til deres Arv og byggede Stæderne og boede i dem.
Èyí sì ni ohun tí àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣe. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin náà ń jó lọ́wọ́, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan mú ọmọbìnrin kọ̀ọ̀kan, wọ́n sì gbé e lọ láti di aya rẹ̀. Wọ́n sì padà sí ilẹ̀ ìní wọn, wọ́n sì tún àwọn ìlú náà kọ́, wọ́n sì tẹ̀dó sínú wọn.
24 Saa vandrede Israels Børn derfra paa samme Tid, hver til sin Stamme og til sin Slægt; og de udgik derfra, hver til sin Arv.
Ní àkókò náà, àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ibẹ̀, wọ́n lọ sí ilé àti ẹ̀yà rẹ̀ olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
25 I disse Dage var ingen Konge i Israel; hver gjorde det, som var ret for hans Øjne.
Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, kò sí ọba ní ilẹ̀ Israẹli; olúkúlùkù sì ń ṣe bí ó ti tọ́ ní ojú ara rẹ̀.