< Josua 1 >
1 Og det skete efter Mose Herrens Tjeners Død, da sagde Herren til Josva, Nuns Søn, som havde tjent Mose, saaledes:
Lẹ́yìn ikú u Mose ìránṣẹ́ Olúwa, Olúwa sọ fún Joṣua ọmọ Nuni, olùrànlọ́wọ́ ọ Mose,
2 Mose, min Tjener, er død; saa gør dig nu rede, drag over denne Jordan, du og alt dette Folk, til det Land, som jeg giver Israels Børn.
“Mose ìránṣẹ́ mi ti kú. Nísinsin yìí, ìwọ àti gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹ múra láti kọjá odò Jordani lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ó fi fún wọn fún àwọn ará Israẹli.
3 Hvert Sted, som eders Fodsaal skal træde paa, det har jeg givet eder, som jeg sagde til Mose;
Èmi yóò fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe ìlérí fún Mose.
4 fra Ørken og dette Libanon og indtil den store Flod, den Flod Frat, alt Hethiternes Land, og indtil det store Hav imod Solens Nedgang, det skal være eders Landemærke.
Ilẹ̀ ẹ yín yóò fẹ̀ láti aginjù Lebanoni, àti láti odò ńlá, ti Eufurate—gbogbo orílẹ̀-èdè Hiti títí ó fi dé Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
5 Ingen Mand skal bestaa for dit Ansigt alle dine Livs Dage; ligesom jeg var med Mose, vil jeg være med dig, jeg vil ikke slippe og ikke forlade dig.
Kì yóò sí ẹnikẹ́ni tí yóò le è dúró níwájú rẹ ní ọjọ́ ayé è rẹ gbogbo. Bí mo ti wà pẹ̀lú u Mose, bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, Èmi kì yóò fi ọ́ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Èmi kì yóò kọ̀ ọ́.
6 Vær frimodig og vær stærk; thi du skal dele Landet til Arv iblandt dette Folk, hvilket jeg tilsvor deres Fædre at ville give dem.
“Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le, nítorí ìwọ ni yóò ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, láti lè jogún ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fi fún wọn.
7 Vær kun saare frimodig og stærk, saa du tager Vare paa at gøre efter al den Lov, som Mose, min Tjener, bød dig; vig ikke fra den til højre eller venstre Side, at du kan handle klogelig paa al den Vej, som du skal vandre paa.
Jẹ́ alágbára, kí o sì mú àyà le gidigidi. Kí o sì ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin tí Mose ìránṣẹ́ mi fún ọ mọ́, má ṣe yà kúrò nínú u rẹ̀ sí ọ̀tún tàbí sí òsì, kí ìwọ kí ó lè ṣe rere níbikíbi tí ìwọ bá ń lọ.
8 Denne Lovs Bog skal ikke vige fra din Mund, men du skal grunde paa den Dag og Nat, paa det du kan tage Vare paa at gøre efter alt det, som er skrevet i den; thi da skal det gaa dig vel i dine Veje, og da skal du handle klogelig.
Má ṣe jẹ́ kí ìwé òfin yìí kúrò ní ẹnu rẹ, máa ṣe àṣàrò nínú u rẹ̀ ní ọ̀sán àti ní òru, kí ìwọ kí ó lè ṣọ́ra láti ṣe gbogbo nǹkan tí a kọ sí inú u rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dára fún ọ, ìwọ yóò sì ní àṣeyọrí.
9 Har jeg ikke befalet dig: Vær frimodig og stærk, forfærdes ikke og ræddes ikke; thi Herren din Gud er med dig paa al den Vej, som du skal vandre paa.
Èmi kò ha ti pàṣẹ fún ọ bí? Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le. Má ṣe bẹ̀rù, má sì ṣe rẹ̀wẹ̀sì, nítorí pé Olúwa à rẹ yóò wà pẹ̀lú rẹ ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”
10 Da bød Josva Folkets Fogeder og sagde:
Báyìí ni Joṣua pàṣẹ fún olórí àwọn ènìyàn rẹ̀,
11 Gaar midt igennem Lejren og byder Folket og siger: Bereder eder Tæring; thi inden tre Dage skulle I gaa over denne Jordan for at komme til at eje Landet, som Herren eders Gud giver eder at eje.
“Ẹ la ibùdó já, kí ẹ sì sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Ẹ pèsè oúnjẹ yín sílẹ̀. Ní ìwòyí ọ̀túnla, ẹ̀yin yóò la Jordani yìí kọjá, láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín láti ní.’”
12 Og til Rubeniterne og til Gaditerne og til Halvdelen af Manasse Stamme sagde Josva:
Ṣùgbọ́n Joṣua sọ fún àwọn ará a Reubeni, àwọn ará Gadi àti fún ìdajì ẹ̀yà Manase pé,
13 Kommer det Ord i Hu, som Mose, Herrens Tjener, bød eder og sagde: Herren eders Gud skaffer eder Rolighed og giver eder dette Land.
“Rántí àṣẹ tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pa fún yín: ‘Olúwa Ọlọ́run yín á fún yin ní ìsinmi, òun yóò sì fún un yín ní ilẹ̀ yìí.’
14 Lader eders Hustruer og eders smaa Børn og eders Kvæg blive i Landet, som Mose har givet eder paa denne Side Jordanen; men I skulle drage over bevæbnede for eders Brødres Ansigt, alle vældige til Strid, og hjælpe dem,
Àwọn ìyàwó yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ẹran ọ̀sìn yín lè dúró ní ilẹ̀ tí Mose fún un yin ní ìlà-oòrùn Jordani; ṣùgbọ́n gbogbo àwọn jagunjagun un yín, pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín. Ẹ̀yin yóò sì rán àwọn arákùnrin yín lọ́wọ́
15 indtil Herren skaffer eders Brødre Rolighed som eder, at ogsaa de kunne eje Landet, som Herren eders Gud skal give dem; saa skulle I vende tilbage til eders Ejendoms Land og eje det, som Mose, Herrens Tjener, gav eder paa denne Side Jordanen mod Solens Opgang.
títí Olúwa yóò fi fún wọn ní ìsinmi, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún un yín, àti títí tí àwọn pẹ̀lú yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún wọn. Lẹ́yìn náà, ẹ̀yin lè padà sí ilẹ̀ ìní in yín, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún un yin ní agbègbè ìlà-oòrùn ti Jordani.”
16 Og de svarede Josva og sagde: Vi ville gøre alt det, som du har budet os, og vi ville gaa til alt, hvortil du vil sende os.
Nígbà náà ni wọ́n dá Joṣua lóhùn pé, “Ohunkóhun tí ìwọ pàṣẹ fún wa ni àwa yóò ṣe, ibikíbi tí ìwọ bá rán wa ni àwa yóò lọ.
17 I alle Ting, ligesom vi hørte Mose, saaledes ville vi og høre dig; vilde kun Herren din Gud være med dig, ligesom han var med Mose!
Gẹ́gẹ́ bí àwa ti gbọ́rọ̀ sí Mose nínú ohun gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò máa gbọ́ tìrẹ. Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà pẹ̀lú u Mose.
18 Hver den, som er genstridig mod din Mund og ikke hører dine Ord i alt det, du byder ham, han skal dø; vær ikkun frimodig og stærk.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá tàpá sí ọ̀rọ̀ rẹ, tí kò sì ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ nínú ohun gbogbo tí ìwọ yóò pàṣẹ fún wọn, pípa ni a ó pa á. Kí ìwọ sá à ṣe gírí, kí ó sì mú àyà le!”