< Jeremias 34 >
1 Det Ord, som kom til Jeremias fra Herren, der Nebukadnezar, Kongen af Babel, og al hans Hær og alle Jordens Riger, som vare under hans Haands Herredømme, og alle Folkene strede imod Jerusalem og imod alle dens Stæder; det lød:
Nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti àwọn ènìyàn ní ilẹ̀ ọba tí ó jẹ ọba lé lórí ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn ìlú tí ó yíká, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa pé:
2 Saa siger Herren, Israels Gud: Gak og sig til Zedekias, Judas Konge, ja, sig til ham: Saa siger Herren: Se, jeg giver denne Stad i Kongen af Babels Haand, og han skal opbrænde den med Ild.
“Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ọmọ-ogun wí: Lọ sí ọ̀dọ̀ Sedekiah ọba Juda kí o sì sọ fún un pé, ‘Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí: Èmi fẹ́ fa ìlú yìí lé ọba Babeli lọ́wọ́, yóò sì jó palẹ̀.
3 Og du skal ikke undkomme fra hans Haand, men du skal visselig gribes og gives i hans Haand, og dine Øjne skulle se Kongen af Babels Øjne, og hans Mund skal tale til din Mund, og du skal komme til Babel.
Ìwọ kò ní sá àsálà, ṣùgbọ́n à ó mú ọ, bẹ́ẹ̀ ni a ó sì fà ọ́ lé e lọ́wọ́. Ìwọ yóò rí ọba Babeli pẹ̀lú ojú ara rẹ; yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ lójúkojú; ìwọ yóò sì lọ sí Babeli.
4 Men hør kun Herrens Ord, Zedekias, Judas Konge! saa siger Herren om dig: Du skal ikke dø for Sværdet.
“‘Síbẹ̀, gbọ́ ìlérí Olúwa, ìwọ Sedekiah ọba Juda. Èyí ni ohun tí Ọlọ́run wí nípa rẹ; ìwọ kì yóò ti ipa idà kú;
5 Du skal dø i Fred, og som man har brændt Baal over dine Fædre, de første Konger, som have været før dig, saa skulle de brænde Baal for dig og sørge over dig med et: „Ak Herre!‟ thi jeg har talt Ordet, siger Herren.
ìwọ yóò kú ní àlàáfíà. Bí àwọn ènìyàn sì ti ń ṣe iná ìsìnkú ní ọlá fún àwọn baba rẹ, ọba tí ó jẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò ṣe iná ní ọlá rẹ, wọn ó sì pohùnréré pé, “Yé, olúwa!” Èmi fúnra mi ni ó ṣèlérí yìí ni Olúwa wí.’”
6 Og Profeten Jeremias talte til Zedekias, Judas Konge, alle disse Ord i Jerusalem.
Nígbà náà ni Jeremiah wòlíì sọ gbogbo nǹkan yìí fún Sedekiah ọba Juda ní Jerusalẹmu.
7 Og Kongen af Babels Hær stred imod Jerusalem og imod alle Judas Stæder, som vare blevne tilovers, imod Lakis og imod Aseka; thi disse vare blevne tilovers iblandt Judas Stæder som faste Stæder.
Nígbà tí ogun ọba Babeli ń bá Jerusalẹmu jà, àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù ní Juda, Lakiṣi, Aseka; àwọn nìkan ni ìlú olódi tí ó kù ní Juda.
8 Det Ord, som kom til Jeremias fra Herren, efter at Kong Zedekias havde sluttet en Overenskomst med alt Folket, som var i Jerusalem, om at udraabe Frihed iblandt dem:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá lẹ́yìn ìgbà tí ọba Sedekiah ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn ní Jerusalẹmu láti polongo ìtúsílẹ̀ fún àwọn ẹrú.
9 At enhver skulde lade sin Tjener og enhver sin Tjenestepige, naar det var en Hebræer eller en Hebræerinde, gaa ud som fri; at ingen skulde bruge sin Broder, naar det var en Jøde, til at trælle.
Kí oníkálùkù lè jẹ́ kí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin tí í ṣe Heberu lọ lọ́fẹ̀ẹ́, kí ẹnikẹ́ni kí ó má mú ará Juda arákùnrin rẹ̀ sìn.
10 Og deri adløde alle Fyrsterne og alt Folket, som havde indgaaet denne Overenskomst, at enhver skulde lade sin Tjener og enhver sin Tjenestepige gaa ud som fri, saa at de ikke mere vilde bruge dem til at trælle, ja, de adløde og lode dem fare;
Nítorí náà, gbogbo àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn tí wọ́n fi ọwọ́ sí májẹ̀mú náà láti dá ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin sílẹ̀ kí wọ́n sì má ṣe fi wọ́n sínú ìgbèkùn mọ́. Wọ́n sì gbà, wọ́n sì jẹ́ kí wọn lọ lọ́fẹ̀ẹ́.
11 men derefter gjorde de det om og toge de Tjenere og de Tjenestepiger, som de havde givet fri, tilbage, og de tvang dem til at være Tjenere og Tjenestepiger.
Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, wọ́n yí ọkàn wọn padà; wọ́n sì mú àwọn ẹrú tí wọ́n ti dá sílẹ̀ padà láti tún máa sìn wọ́n.
12 Og Herrens Ord kom til Jeremias, fra Herren, saaledes:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
13 Saa siger Herren, Israels Gud: Jeg sluttede en Pagt med eders Fædre den Dag, jeg udførte dem af Ægyptens Land, af Trælles Hus, og sagde:
“Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí pé: Mo dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín nígbà tí mo mú wọn kúrò ní Ejibiti; kúrò ní oko ẹrú. Mo wí pé,
14 Naar syv Aar ere til Ende, skulle I frigive hver sin Broder, naar det er en Hebræer, som sælger sig til dig og skal tjene dig i seks Aar, for at du da skal lade ham drage fra dig som fri; men eders Fædre hørte mig ikke og bøjede ikke deres Øre dertil.
‘Ní ọdún keje, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ tú àwọn Heberu tí wọ́n ti ta ara wọn fún un yín sílẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti sìn yín fún ọdún mẹ́fà. Ẹ gbọdọ̀ jẹ́ kí wọn kí ó lọ’; ṣùgbọ́n àwọn baba yín kò gbọ́; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí mi.
15 Men I omvendte eder i Dag og gjorde det, som var ret for mine Øjne, ved at udraabe Frihed hver for sin Næste; og I gjorde en Pagt for mig i det Hus, som er kaldet efter mit Navn.
Láìpẹ́ yìí ẹ ti ronúpìwàdà, ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ́ lójú mi, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín sì ṣe ìtúsílẹ̀ fún àwọn ènìyàn. Ẹ sì tún bá mi dá májẹ̀mú ní àwọn ilé tí a ti ń pe orúkọ mi.
16 Dog gjorde I det om og vanhelligede mit Navn og tilbagetoge hver sin Tjener og hver sin Tjenestepige, hvilke I havde givet fri til at gøre, hvad de vilde, og I tvang dem til at være eders Tjenere og Tjenestepiger.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin yípadà, ẹ sì sọ orúkọ mi di èérí, olúkúlùkù sì mú kí àwọn ẹni rẹ tí ó ti sọ di òmìnira bí ọkàn wọn ti fẹ́ padà; ẹ̀yin sì tún fi wọ́n ṣe ẹrú.
17 Derfor siger Herren saaledes: I hørte mig ikke om at udraabe Frihed, hver for sin Broder og hver for sin Næste: Se, jeg udraaber Frihed for eder, siger Herren, til Sværdet, til Pesten og til Hungeren, og jeg vil gøre eder til en Gru for alle Riger paa Jorden.
“Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: Ẹ̀yin kò fetí sí mi nípa ọ̀rọ̀ òmìnira láàrín ẹ̀gbọ́n sí àbúrò, láàrín ẹnìkan sí èkejì rẹ̀. Wò ó, èmi yóò kéde òmìnira fún un yín ni Olúwa wí. Sí idà, sí àjàkálẹ̀-ààrùn, àti sí ìyàn, èmi ó sì fi yín fún ìwọ̀sí ní gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé.
18 Og jeg vil give de Mænd, som overtraadte min Pagt og ikke holdt Pagtens Ord, som de sluttede for mit Ansigt, Pagten ved Kalven, hvilken de huggede i to Stykker og gik imellem dens Stykker,
Èmi ó ṣe àwọn ọkùnrin náà tí ó da májẹ̀mú mi, tí kò tẹ̀lé májẹ̀mú tí wọ́n ti dá níwájú mi bí ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n gé sí méjì, tí ó sì kọjá láàrín ìpín méjì náà.
19 nemlig Judas Fyrster, Jerusalems Fyrster, Hofmændene og Præsterne og det ganske Folk i Landet, som gik imellem Kalvens Stykker:
Àwọn ìjòyè Juda àti àwọn ti Jerusalẹmu, àwọn aláṣẹ àti àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó kọjá láàrín àwọn ìpín méjèèjì ẹgbọrọ màlúù náà.
20 Dem vil jeg give i deres Fjenders Haand og i deres Haand, som søge efter deres Liv; og deres døde Kroppe skulle være til Føde for Fuglene under Himmelen og for Dyrene paa Jorden.
Èmi ó fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́. Òkú wọn yóò jẹ́ oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún àwọn ẹranko igbó.
21 Og Zedekias, Judas Konge, og hans Fyrster vil jeg give i deres Fjenders Haand og i deres Haand, som søge efter deres Liv, og i Haanden paa Kongen af Babels Hær, som er draget op fra eder.
“Sedekiah ọba àti àwọn ìjòyè rẹ̀ ní Juda ni èmí yóò fi lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àti àwọn tí ń wá ẹ̀mí wọn àti lé ọwọ́ ogun Babeli tí ó ti lọ kúrò lọ́dọ̀ yín.
22 Se, jeg befaler det, siger Herren, og jeg vil føre dem til denne Stad igen, og de skulle stride imod den og indtage den og opbrænde den med Ild; og jeg vil gøre Judas Stæder til en Ødelæggelse, saa at ingen bor der.
Wò ó èmi ó pàṣẹ ni Olúwa wí, èmi ó sì mú wọn padà sí ìlú yìí, wọn ó sì bá a jà, wọn ó sì kó o, wọn ó fi iná jó o. Èmi ó sì sọ ìlú Juda dí ahoro.”