< Jeremias 32 >
1 Det Ord, som kom til Jeremias fra Herren i Judas Konge Zedekias's tiende Aar; det Aar er Nebukadnezars attende Aar;
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọdún kẹwàá Sedekiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kejìdínlógún ti Nebukadnessari.
2 — og dengang belejrede Kongen af Babels Hær Jerusalem; men Profeten Jeremias var indelukket i Forgaarden til Fængselet, som var i Judas Konges Hus;
Àwọn ogun ọba Babeli ìgbà náà há Jerusalẹmu mọ́. A sì sé wòlíì Jeremiah mọ́ inú túbú tí wọ́n ń ṣọ́ ní àgbàlá ilé ọba Juda.
3 hvor Zedekias, Judas Konge, havde indelukket ham og sagt: Hvorfor spaar du og siger: Saa sagde Herren: Se, jeg giver denne Stad i Kongen af Babels Haand, at han skal indtage den,
Nítorí Sedekiah ọba Juda ti há a mọ́lé síbẹ̀; pé, “Kí ló dé tí ìwọ fi ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀? Tí o sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Èmi ń bọ̀ wá fi ìlú yìí fún ọba Babeli, tí yóò sì gbà á.
4 og Zedekias, Judas Konge, skal ikke undkomme fra Kaldæernes Haand; men han skal visselig gives i Kongen af Babels Haand, og hans Mund skal tale med hans Mund, og hans Øjne skulle se hans Øjne;
Sedekiah ọba Juda kò lè bọ́ lọ́wọ́ àwọn Kaldea, ṣùgbọ́n à ó mú fún ọba Babeli, yóò sì bá sọ̀rọ̀ ní ojúkojú; yóò sì rí pẹ̀lú ojú rẹ̀.
5 og han skal føre Zedekias til Babel, og han skal blive der, indtil jeg ser til ham, siger Herren; thi om I end stride imod Kaldæerne, skulle I ikke have Lykke. —
Yóò mú Sedekiah lọ sí Babeli tí yóò wà títí èmi yóò fi bẹ̀ ọ́ wò ni Olúwa wí. Tí ẹ̀yin bá bá àwọn ará Kaldea jà, ẹ̀yin kì yóò borí wọn.’”
6 Og Jeremias sagde: Herrens Ord er kommet til mig saalunde:
Jeremiah wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
7 Se, Hanameel, din Farbroder, Sallums Søn, kommer til dig og siger: Køb dig min Ager, som er i Anathoth; thi du har Løsningsretten, at du kan købe den.
Hanameli ọmọkùnrin Ṣallumu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ yóò tọ̀ ọ́ wá pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti; nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹni tó súnmọ́ wọn, ẹ̀tọ́ àti ìṣe rẹ ní láti rà á.’
8 Og Hanameel, min Farbroders Søn, kom til mig efter Herrens Ord til Fængselets Forgaard og sagde til mig: Kære, køb min Ager, som er i Anathoth, i Benjamins Land; thi du har Arveretten, og du har Løsningsretten, køb dig den; da fornam jeg, at det var Herrens Ord.
“Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ, Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi tọ̀ mí wá ní àgbàlá túbú wí pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti tí ó wà ní ilẹ̀ Benjamini, èyí tí ó jẹ́ pé ẹ̀tọ́ rẹ ni láti gbà á àti láti ni, rà á fún ara rẹ.’ “Nígbà náà ni èmi mọ̀ wí pé ọ̀rọ̀ Olúwa ni èyí.
9 Og jeg købte af Hanameel, min Farbroders Søn, Ageren, som var i Anathoth, og vejede ham Pengene til, sytten Sekel Sølv.
Bẹ́ẹ̀ ni; èmi ra pápá náà ní Anatoti láti ọwọ́ Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi. Mo sì wọn ìwọ̀n ṣékélì àti fàdákà mẹ́tàdínlógún fún un.
10 Og jeg skrev det i Brevet og forseglede det og tog Vidner dertil og vejede Pengene i Vægtskaalerne:
Mo fọwọ́ sínú ìwé, mo sì dì í pa. Mo pe ẹlẹ́rìí sí i, mo sì wọn fàdákà náà lórí òsùwọ̀n.
11 Og jeg tog Købebrevet, det som var forseglet og indeholdt, hvad der var bestemt og fastsat, og det, som var aabent.
Mo mú ìwé tí mo fi rà á, èyí tí a di pa nípa àṣẹ àti òfin wa, àti èyí tí a kò lẹ̀.
12 Og jeg gav Baruk, en Søn af Neria, som var en Søn af Mahasia, Købebrevet for Hanameels, min Farbroders Søns, Øjne og for de Vidners Øjne, som havde underskrevet Købebrevet, for alle de Jøders Øjne, som sade i Fængselets Forgaard.
Èmi sì fi èyí fún Baruku, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, ní ojú Hanameli, ọmọ ẹ̀gbọ́n mi àti níwájú àwọn ẹlẹ́rìí tí ó ti fi ọwọ́ sí ìwé àti ní ojú àwọn Júù gbogbo tí wọ́n jókòó ní àgbàlá ilé túbú.
13 Og jeg befalede Baruk for deres Øjne og sagde:
“Ní ojú wọn ni èmi ti pàṣẹ fún Baruku pé,
14 Saa siger den Herre Zebaoth, Israels Gud: Tag disse Breve, dette Købebrev, baade dette forseglede og dette aabne Brev, og læg dem i et Lerkar, at de maa holde sig mange Dage.
èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; mú àwọn ìwé tí a fi rà á wọ̀nyí, àti èyí tí a lẹ̀ àti èyí tí a kò lẹ̀, kí o wá gbé wọn sínú ìkòkò amọ̀, kí wọn ó lè wà ní ọjọ́ púpọ̀.
15 Thi saa siger den Herre Zebaoth, Israels Gud: Endnu skal der købes Huse og Agre og Vingaarde i dette Land.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; àwọn ilẹ̀, pápá àti ọgbà àjàrà ni à ó tún rà padà nílẹ̀ yìí.
16 Og jeg bad til Herren, efter at jeg havde overgivet Baruk, Nerias Søn, Købebrevet og sagde:
“Lẹ́yìn tí mo ti fi ìwé rírà náà fún Baruku ọmọkùnrin Neriah, mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé:
17 Ak, Herre, Herre! se, du har skabt Himmelen og Jorden ved din store Kraft og ved din udrakte Arm; der er ingen Ting underlig for dig,
“Háà! Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí o dá ọ̀run àti ayé pẹ̀lú títóbi agbára rẹ àti gbogbo ọ̀rọ̀ apá rẹ. Kò sí ohun tí ó ṣòro fún ọ láti ṣe.
18 du, som gør Miskundhed imod tusinde og som betaler Fædrenes Misgerning i deres Børns Barm efter dem, du store, du vældige Gud, hvis Navn er Herren Zebaoth,
O fi ìfẹ́ hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n o gbé ìyà ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba lé àwọn ọmọ lẹ́yìn wọn. Ọlọ́run títóbi àti alágbára, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ.
19 stor i Raad og mægtig i Gerning; thi dine Øjne ere opladte over alle Menneskens Børns Veje til at give hver efter hans Veje og efter hans Idrætters Frugt!
Títóbi ni ìgbìmọ̀, àti alágbára ní í ṣe, ojú rẹ̀ ṣì sí gbogbo ọ̀nà àwọn ọmọ ènìyàn; láti fi fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ ọ̀nà rẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí èso iṣẹ́ rẹ̀.
20 Du, som har gjort Tegn og underlige Ting i Ægyptens Land, indtil denne Dag, baade iblandt Israel og iblandt andre Mennesker, og har indlagt dig et Navn, som det er paa denne Dag;
O ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá ní Ejibiti. O sì ń ṣe é títí di òní ní Israẹli àti lára ọmọ ènìyàn tí ó sì ti gba òkìkí tí ó jẹ́ tìrẹ.
21 og du udførte dit Folk Israel af Ægyptens Land, ved Tegn og ved underlige Ting og ved en stærk Haand og ved en udrakt Arm og ved stor Forfærdelse;
O kó àwọn Israẹli ènìyàn rẹ jáde láti Ejibiti pẹ̀lú iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu nínú ọwọ́ agbára àti nína apá rẹ pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá.
22 og du gav dem dette Land, som du tilsvor deres Fædre at ville give dem, et Land, som flyder med Mælk og Honning;
Ìwọ fún wọn nílẹ̀ yìí, èyí tí o ti ṣèlérí fún àwọn baba ńlá wọn; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
23 og de kom og toge det i Eje, men de hørte ikke din Røst og vandrede ikke efter din Lov; alt det, som du bød dem at gøre, gjorde de ikke; og du lod al denne Ulykke møde dem.
Wọ́n wá, wọ́n sì gba ilẹ̀ náà ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ tàbí tẹ̀lé òfin rẹ. Wọn kò ṣe ohun tí o pàṣẹ fún wọn, nítorí náà ìwọ mú àwọn ibi yìí wá sórí wọn.
24 Se, Belejringsvoldene ere komne ind imod Staden til dens Indtagelse, og Staden er given i Kaldæernes Haand, som stride imod den, ved Sværdet og Hungeren og Pesten; og det, som du har talt, er sket, og se, du ser det.
“Wò ó, bí àwọn ìdọ̀tí ṣe kórajọ láti gba ìlú. Nítorí idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, sì fi ìlú lé ọwọ́ àwọn ará Kaldea tí ń gbóguntì wọ́n. Ohun tí ìwọ sọ ṣẹ gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i.
25 Og du, Herre, Herre, har dog sagt til mig: Køb dig Ageren for Penge og tag Vidner derpaa, skønt Staden er given i Kaldæernes Haand.
Síbẹ̀ a ó fi ìlú náà fún àwọn ará Babeli, ìwọ Olúwa Olódùmarè sọ fún mi pé, ‘Ra pápá náà pẹ̀lú owó fàdákà, kí o sì pe ẹlẹ́rìí.’”
26 Og Herrens Ord kom til Jeremias, saa lydende:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá pé:
27 Se, jeg er Herren, alt Køds Gud; mon nogen Ting skulde være underlig for mig?
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run gbogbo ẹran-ara. Ǹjẹ́ ohun kan ha a ṣòro fún mi bí?
28 Derfor, saa siger Herren: Se, jeg giver denne Stad i Kaldæernes Haand og i Nebukadnezar, Kongen af Babels Haand, at han skal indtage den.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí, Èmi ṣetán láti fi ìlú yìí fún àwọn ará Kaldea àti fún Nebukadnessari ọba Babeli ẹni tí yóò kó o.
29 Og Kaldæerne, som stride imod denne Stad, skulle komme og stikke Ild paa denne Stad og opbrænde den og Husene, paa hvis Tage de gjorde Røgelse for Baal og udøste Drikoffer for andre Guder for at opirre mig.
Àwọn ará Kaldea tí ó ń gbógun tí ìlú yóò wọ ìlú. Wọn ó sì fi iná sí ìlú; wọn ó jó o palẹ̀ pẹ̀lú ilé tí àwọn ènìyàn ti ń mú mi bínú, tí wọ́n ń rú ẹbọ tùràrí lórí pẹpẹ fún Baali tiwọn sì ń da ẹbọ ohun mímu fún àwọn ọlọ́run mìíràn.
30 Thi Israels Børn og Judas Børn have kun gjort ondt for mine Øjne fra deres Ungdom af; og Israels Børn have kun opirret mig med deres Hænders Gerning, siger Herren.
“Àwọn ènìyàn Israẹli àti Juda kò ṣe ohun kankan bí kò ṣe ibi lójú mi láti ìgbà èwe wọn. Nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti fi kìkì iṣẹ́ ọwọ́ wọ́n mú mi bínú ni Olúwa wí.
31 Thi til Vrede for mig og til Harme for mig har denne Stad været fra den Dag, da de byggede den, og indtil denne Dag, saa at jeg maa skaffe den bort fra mit Ansigt
Láti ọjọ́ tí wọ́n ti kọ́ ọ, títí di àkókò yìí ni ìlú yìí ti jẹ́ ohun ìbínú àti ìyọnu fún mi tó bẹ́ẹ̀ tí èmi yóò fà á tu kúrò níwájú mi.
32 formedelst al Israels Børns og Judas Børns Ondskab, som de øvede for at opirre mig, de, deres Konger, deres Fyrster, deres Præster og deres Profeter, baade Judas Mænd og Jerusalems Indbyggere.
Àwọn ènìyàn Israẹli àti àwọn ènìyàn Juda ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ìbàjẹ́ tí wọ́n ṣe. Àwọn Israẹli, ọba wọn àti gbogbo ìjòyè, àlùfáà àti wòlíì, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu.
33 Og de vendte Ryggen til mig, og ikke Ansigtet; skønt jeg lærte dem tidligt og ideligt, hørte de dog ikke, saa at de annammede Undervisning.
Wọ́n kọ ẹ̀yìn sí mi, wọ́n sì yí ojú wọn padà. Èmi kọ wọ́n, síbẹ̀ wọn kò fetísílẹ̀ láti gbọ́ ẹ̀kọ́ tàbí kọbi ara sí ìwà ìbàjẹ́.
34 Men de satte deres Vederstyggeligheder i det Hus, som er kaldet efter mit Navn, for at besmitte det.
Wọ́n kó òrìṣà ìríra wọn jọ sí inú ilé tí wọ́n fi orúkọ mi pè, wọ́n sì ṣọ́ di àìmọ́.
35 Og de byggede Baalshøjene, som ere i Ben-Hinnoms Dal, for at ofre deres Sønner og deres Døtre til Molek, hvilket jeg ikke havde befalet dem, og hvilket ikke var kommet mig i Sinde, og for at gøre denne Vederstyggelighed, paa det de maatte faa Juda til at synde.
Wọ́n kọ́ ibi gíga fún Baali ní àfonífojì Hinnomu láti fi ọmọ wọn ọkùnrin àti obìnrin rú ẹbọ sí Moleki. Èmi kò pàṣẹ, fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò wá sí ọkàn mi pé kí wọ́n ṣe ohun ìríra wọ̀nyí tí ó sì mú Juda dẹ́ṣẹ̀.
36 Og nu siger Herren, Israels Gud, derfor saaledes om denne Stad, om hvilken I sige, at den gives i Kongen af Babels Haand, ved Sværdet og ved Hungeren og ved Pesten:
“Ìwọ ń sọ̀rọ̀ nípa ti ìlú yìí pé, ‘Pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn ni à ó fi wọ́n fún ọba Babeli,’ ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ nìyìí,
37 Se, jeg samler dem fra alle Landene, hvorhen jeg fordrev dem i min Vrede og i min Harme og i stor Fortørnelse; og jeg vil føre dem tilbage til dette Sted og lade dem bo tryggelig.
Èmi ó kó wọn jọ láti gbogbo ilẹ̀ tí mo ti lé wọn kúrò ní ìgbà ìbínú àti ìkáàánú ńlá mi. Èmi yóò mú wọn padà wá sí ilẹ̀ yìí; èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó máa gbé láìléwu.
38 Og de skulle være mig et Folk, og jeg vil være dem en Gud.
Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
39 Og jeg vil give dem eet Hjerte og een Vej, at de skulle frygte mig alle Dage, for at det maa gaa dem vel og deres Børn efter dem.
Èmi ó fún wọn ní ọkàn kan àti ìṣe kí wọn kí ó lè máa bẹ̀rù mi fún rere wọn àti fún rere àwọn ọmọ wọn tí ó tẹ̀lé wọn.
40 Og jeg vil slutte en evig Pagt med dem, at jeg ikke vil drage mig tilbage fra dem, med at gøre dem godt; og jeg vil lægge min Frygt i deres Hjerter, at de ikke skulle vige fra mig.
Èmi ò bá wọn dá májẹ̀mú ayérayé, èmi kò ní dúró láti ṣe rere fún wọn, Èmi ó sì jẹ́ kí wọ́n bẹ̀rù mi, wọn kì yóò sì padà lẹ́yìn mi.
41 Og jeg vil glæde mig over dem ved at gøre dem godt; og jeg vil plante dem i dette Land i Sandhed, af mit ganske Hjerte og af min ganske Sjæl.
Lóòtítọ́, èmi ó yọ̀ nípa ṣíṣe wọ́n ní rere, èmi ó sì fi dá wọn lójú nípa gbígbìn wọ́n sí ilẹ̀ yìí tọkàntọkàn mi.
42 Thi saa siger Herren: Ligesom jeg lod al den store Ulykke komme over dette Folk, saaledes vil jeg lade alt det gode komme over dem, som jeg taler over dem.
“Nítorí báyìí ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú gbogbo ibi ńlá yìí wá sórí àwọn ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó mú gbogbo rere tí èmi ti sọ nípa tiwọn wá sórí wọn.
43 Og der skal købes Agre i dette Land, om hvilket I sige: Det er øde, uden Folk og Kvæg, det er givet i Kaldæernes Haand.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, pápá yóò di rírà ní ilẹ̀ yìí tí ìwọ ti sọ pé, ‘Ohun òfò ni tí kò bá sí ọkùnrin tàbí àwọn ẹran, nítorí tí a ti fi fún àwọn ará Babeli.’
44 De skulle købe Agre for Penge og skrive Breve og forsegle dem og tage Vidner derpaa, i Benjamins Land og trindt omkring Jerusalem, og i Judas Stæder og i Stæderne paa Bjerget og i Stæderne i Lavlandet og i Stæderne imod Sønden; thi jeg vil omvende deres Fangenskab, siger Herren.
Wọn ó fi owó fàdákà ra oko, wọn yóò fi ọwọ́ sí ìwé, wọn ó dí pa pẹ̀lú ẹlẹ́rìí láti ilẹ̀ Benjamini àti ní ìlú kéékèèké tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda àti ní ìlú àwọn ìlú orí òkè, àti ni àwọn ẹsẹ̀ òkè, àti ní gúúsù, èmi ó mú ìgbèkùn wọn padà wá, ni Olúwa wí.”