< Jeremias 3 >
1 Man siger: Dersom en Mand lader sin Hustru fare, og hun gaar fra ham og bliver en anden Mands, mon han da maa vende tilbage til hende igen? mon ikke dette Land vilde blive besmittet derved? Men du har bedrevet Hor med mange Bolere, og du skulde komme til mig igen? siger Herren.
“Bí ọkùnrin kan bá sì kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ tí obìnrin náà sì lọ fẹ́ ọkọ mìíràn, ǹjẹ́ ọkùnrin náà tún lè tọ̀ ọ́ wá? Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kò ní di aláìmọ́ bí? Ṣùgbọ́n ìwọ ti gbé pẹ̀lú onírúurú panṣágà gẹ́gẹ́ bí olùfẹ́, ṣé ìwọ yóò tún padà sọ́dọ̀ mi bí?” ni Olúwa wí.
2 Opløft dine Øjne til de nøgne Høje, og se, hvor er du ikke skændet? du sad ved Vejene for dem, som en Araber i Ørken, og du besmittede Landet med dine Horerier og med din Ondskab.
“Gbé ojú rẹ sókè sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, kí o sì wò ó ibi kan ha wà tí a kò bà ọ́ jẹ́? Ní ojú ọ̀nà, ìwọ jókòó de àwọn olólùfẹ́, bí i ará Arabia kan nínú aginjù, ìwọ sì ti ba ilẹ̀ náà jẹ́ pẹ̀lú ìwà àgbèrè àti ìwà búburú rẹ.
3 Derfor ere Regndraaberne tilbageholdte, og sildig Regn kom ikke; men du har en Horkvindes Pande, du vil ikke skamme dig.
Nítorí náà, a ti fa ọ̀wààrà òjò sẹ́yìn, kò sì ṣí òjò àrọ̀kúrò. Síbẹ̀ ìwọ ní ojú líle ti panṣágà, ìwọ sì kọ̀ láti ní ìtìjú.
4 Har du ikke fra nu af raabt til mig: Min Fader! min Ungdoms Leder er du.
Ǹjẹ́ ìwọ kò ha a pè mí láìpẹ́ yìí pé, ‘Baba mi, ìwọ ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.
5 Mon han vil beholde Vrede evindelig? eller bevare den til evig Tid? se, du har talt, men du gjorde disse onde Ting og satte dem igennem.
Ìwọ yóò ha máa bínú títí? Ìbínú rẹ yóò ha máa lọ títí láé?’ Báyìí ni o ṣe ń sọ̀rọ̀ ìwọ ṣe gbogbo ibi tí ìwọ le ṣe.”
6 Og Herren sagde til mig i Kong Josias's Dage: Har du set, hvad det frafaldne Israel har gjort? Hun gik paa alle høje Bjerge og hen under alle grønne Træer og bedrev der Hor.
Ní àkókò ìjọba Josiah ọba, Olúwa wí fún mi pé, “Ṣé o ti rí nǹkan tí àwọn Israẹli aláìnígbàgbọ́ ti ṣe? Wọ́n ti lọ sí àwọn òkè gíga àti sí abẹ́ àwọn igi, wọ́n sì ti ṣe àgbèrè níbẹ̀.
7 Og jeg sagde: Efter at hun havde gjort alt dette, vil hun omvende sig til mig; men hun omvendte sig ikke. Og hendes troløse Søster Juda saa det.
Mo rò pé nígbà tí wọ́n ti ṣe èyí wọn yóò padà, wọn kò padà, Juda aláìgbàgbọ́ arábìnrin rẹ̀ náà sì rí i.
8 Og jeg saa, da jeg formedelst alt det, at det frafaldne Israel havde bedrevet Hor, lod hende fare og gav hende hendes Skilsmissebrev, at dog det troløse Juda, hendes Søster, ikke frygtede, men gik bort og bedrev ogsaa Hor.
Mo fún Israẹli aláìnígbàgbọ́ ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀, mo sì ké wọn kúrò nítorí gbogbo àgbèrè wọn. Síbẹ̀ mo rí pé Juda tí ó jẹ́ arábìnrin rẹ̀ kò bẹ̀rù, òun náà sì jáde lọ láti lọ ṣe àgbèrè.
9 Og det skete for hendes Horeris Letfærdighed, at hun besmittede Landet; thi hun bolede med Sten og med Træ.
Nítorí ìwà èérí Israẹli kò jọ ọ́ lójú, ó ti ba ilẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú òkúta àti igi.
10 Og med alt dette omvendte hendes troløse Søster Juda sig ikke til mig af sit ganske Hjerte, men paa Skrømt, siger Herren.
Látàrí gbogbo nǹkan wọ̀nyí Juda arábìnrin rẹ̀ aláìgbàgbọ́ kò padà tọ̀ mí wá pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀, bí kò ṣe nípa fífarahàn bí olóòtítọ́,” ni Olúwa wí.
11 Og Herren sagde til mig: Det frafaldne Israel har vist sig retfærdigt fremfor det troløse Juda.
Olúwa wí fún mi pé, “Israẹli aláìnígbàgbọ́ ṣe òdodo ju Juda tí ó ní ìgbàgbọ́ lọ.
12 Gak, og raab disse Ord imod Norden, og sig: Omvend dig, du frafaldne Israel! siger Herren, jeg vil ikke lade mit vrede Ansigt falde paa eder; thi jeg er miskundelig, siger Herren, jeg vil ikke beholde Vrede evindelig.
Lọ polongo ọ̀rọ̀ náà, lọ sí ìhà àríwá: “‘Yípadà, Israẹli aláìnígbàgbọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Ojú mi kì yóò korò sí ọ mọ́, nítorí mo jẹ́ aláàánú, ni Olúwa wí. Èmi kì yóò sì bínú mọ́ títí láé.
13 Kend ikkun din Misgerning; thi du har gjort Overtrædelse imod Herren din Gud, og du er løben hid og did paa dine Veje til fremmede Guder under hvert grønt Træ, men paa min Røst have I ikke hørt, siger Herren.
Sá à ti mọ ẹ̀bi rẹ, ìwọ ti ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ ti wá ojúrere rẹ lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì lábẹ́ gbogbo igikígi tí ó gbilẹ̀, ẹ̀yin kò gba ohun mi gbọ́,’” ni Olúwa wí.
14 Omvender eder, I frafaldne Børn! siger Herren; thi jeg er eders Husbonde, og jeg vil tage eder, een af en Stad og to af en Slægt og føre eder til Zion.
“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,” ni Olúwa wí, “nítorí èmi ni ọkọ rẹ. Èmi ó yàn ọ́, ọ̀kan láti ìlú àti méjì láti ẹ̀yà. Èmi ó sì mú ọ wá sí Sioni.
15 Og jeg vil give eder Hyrder efter mit Hjerte; og de skulle føde eder med Kundskab og Forstand.
Lẹ́yìn èyí, èmi ó fún ọ ní àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti inú ọkàn mi, tí wọn yóò ṣáájú yín pẹ̀lú òye àti ìmọ̀.
16 Og det skal ske, naar I ere blevne mange og ere blevne frugtbare i Landet i de Dage, siger Herren, da skulle de ikke mere tale om Herrens Pagts Ark, og den skal ikke mere komme nogen i Tanke, og de skulle ikke komme den i Hu og ikke savne den, og den skal ikke forfærdiges mere.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, tí ẹ̀yin bá pọ̀ sí i lórí ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí, “àwọn ènìyàn kò tún lè sọ pé, ‘Àpótí ẹ̀rí Olúwa.’ Kò ní wá sí ìrántí wọn mọ́, a kì yóò pàdánù rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò sì tún kan òmíràn mọ́.
17 Paa den Tid skulle de kalde Jerusalem Herrens Trone, og alle Hedningerne skulle forsamles til den for Herrens Navns Skyld, i Jerusalem; og de skulle ikke ydermere vandre efter deres onde Hjertes Stivhed.
Ní ìgbà náà, wọn yóò pe Jerusalẹmu ní ìtẹ́ Olúwa gbogbo orílẹ̀-èdè yóò péjọ sí Jerusalẹmu láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ Olúwa, wọn kì yóò sì tún tẹ̀lé àyà líle búburú wọn mọ́.
18 I de Dage skal Judas Hus gaa til Israels Hus, og de skulle komme med hinanden fra et Land af Norden, til Landet, som jeg har givet eders Fædre til Arv.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ni ilé Juda yóò darapọ̀ mọ́ ilé Israẹli. Wọn yóò sì wá láti ilẹ̀ àríwá wá sí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá yín gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní.
19 Og jeg havde sagt: Vil jeg ej sætte dig iblandt Børnene og give dig et kosteligt Land, Folkenes alleryndigste Arv? Og jeg sagde: Min Fader vil du kalde mig og ikke vende dig fra mig.
“Èmi fúnra mi sọ wí pé, “‘Báwo ni inú mi yóò ti dùn tó, kí èmi kí ó tọ́ ọ bí ọmọkùnrin kí n sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó tó.’ Mo rò pé ìwọ yóò pè mí ní ‘Baba mi’ o kò sì ní ṣàì tọ̀ mí lẹ́yìn.
20 Men ligesom en Kvinde bliver troløs imod sin Boler, saaledes ere I af Israels Hus blevne troløse imod mig, siger Herren.
Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí aláìgbàgbọ́ obìnrin sí ọkọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ o jẹ́ aláìgbàgbọ́ sí mi. Ìwọ ilé Israẹli,” ni Olúwa wí.
21 Der er hørt en Røst paa de nøgne Høje, Israels Børns ydmyge Begæringers Graad; thi de have forvendt deres Vej, de have forglemt Herren deres Gud.
A gbọ́ ohùn àgàn láti ibi gíga, ẹkún àti ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí wọ́n ti yí ọ̀nà wọn po, wọ́n sì ti gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn.
22 Saa vender om, I frafaldne Børn! jeg vil læge eders Afvigelser. „Se, her ere vi, vi komme til dig; thi du er Herren vor Gud.
“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́, Èmi ó wo ìpadàsẹ́yìn kúrò ní ọ̀nà títọ́ rẹ sàn.” “Bẹ́ẹ̀, ni a ó wá sọ́dọ̀ rẹ nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run wa.
23 Sandelig, det er idel Bedrageri med Tummelen paa Bjergene; sandelig, Israels Frelse er i Herren vor Gud.
Nítòótọ́, asán ni ìbọ̀rìṣà àti ìrúkèrúdò tí ó wà ní àwọn orí òkè kéékèèké àti àwọn òkè gíga, nítòótọ́, nínú Olúwa Ọlọ́run wa ni ìgbàlà Israẹli wà.
24 Og Skændsel har fortæret vore Fædres Arbejde, fra vor Ungdom af, deres smaa Kvæg og deres store Kvæg, deres Sønner og deres Døtre.
Láti ìgbà èwe wa ni àwọn òrìṣà ìtìjú ti jẹ èso iṣẹ́ àwọn baba wa run, ọ̀wọ́ ẹran wọn àti agbo ẹran wọn, ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
25 Vi maa ligge i vor Skændsel og vor Skam skjule os; thi vi have syndet imod Herren vor Gud, vi og vore Fædre, fra vor Ungdom af og indtil denne Dag; og vi vare ikke Herren vor Guds Røst lydige‟.
Jẹ́ kí a dùbúlẹ̀ nínú ìtìjú wa, kí ìtìjú wa bò wá mọ́lẹ̀. A ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, àwa àti àwọn baba wa, láti ìgbà èwe wa títí di òní a kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”