< Jeremias 24 >
1 Herren lod mig se et Syn, og se, to Kurve med Figener vare satte foran Herrens Tempel; efter at Nebukadnezar, Kongen af Babel, havde bortført Jekonias, Jojakims Søn, Judas Konge, og Judas Fyrster og Tømmermændene og Smedene fra Jerusalem og ført dem til Babel.
Lẹ́yìn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn oníṣọ̀nà àti oníṣẹ́ ọwọ́ ti Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli tán. Olúwa fi agbọ̀n èso ọ̀pọ̀tọ́ méjì hàn mí tí a gbé sí iwájú pẹpẹ Olúwa.
2 I den ene Kurv vare meget gode Figener som tidligt modne Figener; og i den anden Kurv vare meget slette Figener, som ikke kunde ædes, fordi de vare saa slette.
Agbọ̀n kan ni èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó dára bí èyí tí ó tètè pọ́n; èkejì sì ní èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó burú rékọjá tí kò sì le è ṣe é jẹ.
3 Og Herren sagde til mig: Hvad ser du, Jeremias? og jeg sagde: Figener! de gode Figener ere meget gode, og de slette ere meget slette, saa at de ikke kunne ædes, fordi de ere saa slette.
Nígbà náà ni Olúwa bi mí pé, “Kí ni ìwọ rí Jeremiah?” Mo dáhùn pe, “Èso ọ̀pọ̀tọ́.” Mo dáhùn. “Èyí tí ó dáradára púpọ̀, ṣùgbọ́n èyí tí ó burú burú rékọjá tí kò sì ṣe é jẹ.”
4 Og Herrens Ord kom til mig saaledes:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
5 Saa siger Herren, Israels Gud: Ligesom det er med disse gode Figener, saaledes vil jeg kendes ved de bortførte fra Juda, hvilke jeg sendte fra dette Sted til Kaldæernes Land dem til Baade.
“Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí àwọn èso ọ̀pọ̀tọ́ dáradára yìí ni Èmi yóò ka àwọn tí wọ́n lọ sí ilẹ̀ àjèjì láti Juda sí tí èmi rán jáde kúrò ní ibí yìí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kaldea.
6 Og jeg vil fæste mit Øje paa dem til det gode og føre dem tilbage til dette Land; og jeg vil opbygge og ikke nedbryde dem, og jeg vil plante og ikke oprykke dem.
Ojú mi yóò máa ṣọ́ wọn lọ fún rere, Èmi yóò gbé wọn ró, n kò ní já wọn lulẹ̀. Èmi yóò gbìn wọ́n, n kò sì ní fà wọ́n tu.
7 Og jeg vil give dem Hjerte til at kende mig, at jeg er Herren, og de skulle være mit Folk, og jeg vil være deres Gud; thi de skulle omvende sig til mig af deres ganske Hjerte.
Èmi yóò fún wọn ní ọkàn láti mọ̀ mí pé, “Èmi ni Olúwa.” Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi; Èmi ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn; nítorí pé wọn yóò padà sọ́dọ̀ mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
8 Men ligesom det er med de slette Figener, som ikke kunne ædes, fordi de ere saa slette, — thi saa siger Herren —: Saaledes vil jeg gøre Zedekias, Judas Konge, og hans Fyrster og dem, som ere tilovers af Jerusalem, de overblevne i dette Land, og dem, som bo i Ægyptens Land,
“‘Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí kò dára, tí ó burú tí kò ṣe é jẹ,’ ni Olúwa wí, ‘bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò ṣe pẹ̀lú Sedekiah ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn tí ó yẹ ní Jerusalẹmu, yálà wọ́n wà lórí ilẹ̀ yìí tàbí wọ́n ń gbé Ejibiti.
9 ja, jegvil gøre dem til en Gru, dem til Ulykke, for alle Riger paa Jorden; til Forhaanelse og til et Ordsprog, til Spot og Forbandelse paa alle de Steder, hvorhen jeg vil fordrive dem.
Èmi yóò sọ wọ́n di ìwọ̀sí àti ẹni ibi nínú gbogbo ìjọba ayé, láti di ẹni ìfibú àti ẹni òwe, ẹni ẹ̀sín, àti ẹni ẹ̀gàn ní ibi gbogbo tí Èmi ó lé wọn sí.
10 Og jeg vil sende Sværdet, Hungeren og Pesten over dem, indtil de forsvinde af Landet, som jeg gav dem og deres Fædre.
Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí wọn, títí tí gbogbo wọn yóò parun lórí ilẹ̀ tí a fún wọn àti fún àwọn baba wọn.’”