< Esajas 59 >
1 Se, Herrens Haand er ikke forkortet, at han ikke kunde frelse; og hans Øre er ikke tunghørende, at han ikke kunde høre.
Lódodo ọwọ́ Olúwa kò kúrú láti gbàlà, tàbí kí etí rẹ̀ wúwo láti gbọ́.
2 Men eders Misgerninger gøre Skilsmisse imellem eder og imellem eders Gud; og eders Synder gøre, at han skjuler Ansigtet for eder, saa at han ikke hører.
Ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ yín ló ti yà yín kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run yín; ẹ̀ṣẹ̀ yín ti fi ojú u rẹ̀ pamọ́ fún un yín tó bẹ́ẹ̀ tí òun kò fi le gbọ́.
3 Thi eders Hænder ere besmittede med Blod og eders Fingre med Misgerning; eders Læber tale Løgn, eders Tunge udsiger Uret.
Nítorí ọwọ́ yín di aláìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀, àti ìka ọwọ́ yín fún ẹ̀bi. Ètè yín ń pa irọ́ púpọ̀, ahọ́n yín sì ń sọ̀rọ̀ nǹkan ibi.
4 Der er ingen, som paakalder i Retfærdighed, og ingen, som gaar i Rette med Redelighed; man forlader sig paa Tomhed og taler Løgn, undfanger Uret og føder Udaad.
Kò sí ẹni tí ó béèrè fún ìdájọ́ òdodo; kò sí ẹni tí ó ro ẹjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú òtítọ́. Wọ́n gbẹ́kẹ̀lé àwíjàre asán àti ọ̀rọ̀ irọ́; wọ́n lóyún ìkà, wọn sì bí wàhálà.
5 De udruge Basiliskæg og væve Spindelvæv; hvo, som æder af deres Æg, maa dø, og trykkes et i Stykker, udfarer der en Øgle.
Wọn ń pa ẹ̀yin paramọ́lẹ̀ wọn sì ń ta owú aláǹtakùn. Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹyin wọn yóò kú, àti nígbà tí a pa ọ̀kan, paramọ́lẹ̀ ni ó jáde.
6 Deres Væv skal ikke blive til Klæder, og man kan ikke skjule sig med deres Arbejde, deres Arbejder ere uretfærdige Arbejder, og der er Voldsgerning i deres Hænder.
Òwú wọn kò wúlò fún aṣọ rírán; wọn kò lè fi aṣọ tí wọ́n hun bo ara wọn. Iṣẹ́ wọn jẹ́ ti ibi, ìwà jàǹdùkú sì kún ọwọ́ wọn.
7 Deres Fødder løbe efter det onde og haste efter at udgyde uskyldigt Blod, deres Tanker ere uretfærdige Tanker; der er Ødelæggelse og Forstyrrelse paa deres Veje.
Ẹsẹ̀ wọn yára bọ́ sínú ẹ̀ṣẹ̀; wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀. Èrò wọn sì jẹ́ èrò ibi; ìparun àti ìdahoro ni ó wà ní ṣíṣe àmì ọ̀nà wọn.
8 Fredens Vej kende de ikke, og der er ingen Ret i deres Spor; deres Stier gøre de krogede for sig selv, hver den, som betræder dem, ved ikke af Fred.
Ọ̀nà àlàáfíà èyí ni wọn kò mọ̀; kò sí òdodo ní ojú ọ̀nà wọn wọ́n ti sọ wọ́n dì ọ̀nà kọ́rọkọ̀rọ, kò sí ẹni tí ó tọ ọ̀nà yìí tí yóò rí àlàáfíà.
9 Derfor er Retten langt fra os, og Retfærdigheden naar ikke til os; vi forvente Lys, og se, der er Mørke; vi vente idel Solskin, og se, vi vandre i Mulm.
Nítorí èyí ni ẹ̀tọ́ fi jìnnà sí wa, àti tí òdodo kò fi tẹ̀ wá lọ́wọ́. A ń wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n gbogbo rẹ̀ jẹ́ òkùnkùn; ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n à ń rìn nínú òjìji.
10 Vi famle som de blinde efter en Væg, ja, vi famle som de, der ikke have Øjne; vi støde os om Middagen som i Tusmørket, vi ere paa de øde Steder som de døde.
Gẹ́gẹ́ bí afọ́jú à ń táràrà lọ lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri tí a ń wá ọ̀nà wa gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí kò ní ojú. Ní ọ̀sán gangan ni à ń kọsẹ̀ bí ẹni pé alẹ́ ni; láàrín alágbára àwa dàbí òkú.
11 Vi brumme alle sammen som Bjørne og kurre som Duer; vi bie efter Ret, og den kommer ikke, efter Frelse, og den er langt borte fra os.
Gbogbo wa là ń ké bí i beari; àwa pohùnréré ẹkún bí àdàbà. A ń wá ìdájọ́ òdodo ṣùgbọ́n kò sí; à ń wọ́nà fún ìtúsílẹ̀, ṣùgbọ́n ó jìnnà réré.
12 Thi vore Overtrædelser ere mange for dig, og vore Synder vidne imod os; thi vore Overtrædelser følge os, og vi kende vore Misgerninger:
Nítorí àwọn àṣìṣe wa pọ̀ níwájú rẹ, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa sì ń jẹ́rìí takò wá. Àwọn àìṣedéédéé wa sì wà pẹ̀lú wa, àwa pẹ̀lú sì mọ àìṣedéédéé wa,
13 At vi have gjort Overtrædelser og fornægtet Herren, og at vi have vendt os bort fra vor Gud, at vor Tale gik ud paa Undertrykkelse og Frafald, at vi have undfanget og udtalt falske Ord af vort Hjerte.
ọ̀tẹ̀ àti àrékérekè wa sí Olúwa, kíkọ ẹ̀yìn wa sí Ọlọ́run, dídá yánpọnyánrin àti ìnilára sílẹ̀, pípààrọ̀ tí ọkàn wa ti gbèrò síta.
14 Retten er vegen tilbage, og Retfærdigheden staar langt borte, thi Sandheden støder an paa Gaden, og Retten finder ingen Indgang.
Nítorí èyí ni a ṣe lé ìdájọ́ òdodo sẹ́yìn, àti ti òdodo dúró lókèèrè; òtítọ́ ti ṣubú ní òpópó ọ̀nà, òdodo kò sì le è wọlé.
15 Og Sandheden er borte, og den, som viger fra det onde, bliver et Rov. Og Herren saa det, og det var ondt for hans Øjne, at der ingen Ret var.
A kò rí òtítọ́ mọ́, àti ẹni tí ó bá sá fun ibi tì di ìjẹ. Olúwa wò ó ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ pé kò sí ìdájọ́ òdodo.
16 Og han saa, at der ingen var, og han undrede sig saare, at der var ingen Midler; men hans egen Arm hjalp ham, og hans Retfærdighed stod ham bi.
Òun rí i pé kò sí ẹnìkan, àyà fò ó pé kò sí ẹnìkan láti ṣèrànwọ́; nítorí apá òun tìkára rẹ̀ ló ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún ara rẹ̀, àti òdodo òun tìkára rẹ̀ ló gbé e ró.
17 Og han iførte sig Retfærdighed som sit Panser, og Frelsens Hjelm var paa hans Hoved; og som Klædning tog han Hævnens Klæder paa og iførte sig Nidkærhed som en Kappe.
Ó gbé òdodo wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbàyà rẹ̀, àti àṣíborí ìgbàlà ní orí rẹ̀; ó gbé ẹ̀wù ẹ̀san wọ̀ ó sì yí ara rẹ̀ ní ìtara bí ẹ̀wù.
18 Efter Fortjeneste, „ja derefter skal han betale sine Modstandere med Vrede, sine Fjender med Vederlag; ja, dem paa Øerne skal han betale efter Fortjeneste.
Gẹ́gẹ́ bí ohun tí wọ́n ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni yóò san án ìbínú fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ àti ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá rẹ̀; òun yóò san án fún àwọn erékùṣù ẹ̀tọ́ wọn.
19 Og de fra Vesten skulle frygte Herrens Navn, og de fra Solens Opgang hans Herlighed; naar Fjenden kommer som en Flod, skal Herrens Aand oprette Banner imod ham.
Láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn ènìyàn yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa, àti láti ìlà-oòrùn, wọn yóò bọ̀wọ̀ fún ògo rẹ̀. Nítorí òun yóò wá gẹ́gẹ́ bí i rírú omi èyí tí èémí Olúwa ń tì lọ.
20 Og der skal komme en Genløser for Zion og for dem, som omvende sig fra Overtrædelse i Jakob, siger Herren.
“Olùdáǹdè yóò wá sí Sioni, sí àwọn tí ó wà ní Jakọbu tí ó ronúpìwàdà ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí.
21 Og jeg — dette er min Pagt med dem, siger Herren: Min Aand, som er over dig, og mine Ord, som jeg har lagt i din Mund, skulle ikke vige fra dia Mund, eller fra dine Børns Mund, eller fra dine Børnebørns Mund, siger Herren, fra nu og indtil evig Tid.
“Àti fún èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn nìyìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ̀mí mi, tí ó wà nínú yín, àti ọ̀rọ̀ mi tí mo ti fi sí ẹnu yín, kì yóò kúrò lẹ́nu yín, tàbí lẹ́nu àwọn ọmọ yín, tàbí láti ẹnu àwọn ìrandíran wọn láti àkókò yìí lọ àti títí láéláé,” ni Olúwa wí.