< Esajas 3 >
1 Thi se, Herren, den Herre Zebaoth, skal borttage fra Jerusalem og fra Juda al Slags Støtte, hver Støtte af Brød og hver Støtte af Vand;
Kíyèsi i, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, fẹ́ mú ìpèsè àti ìrànlọ́wọ́ kúrò ní Jerusalẹmu àti Juda gbogbo ìpèsè oúnjẹ àti ìpèsè omi.
2 Vældige og Krigsmænd, Dommere og Profeter og Spaamænd og Ældste;
Àwọn akíkanjú àti jagunjagun, adájọ́ àti wòlíì, aláfọ̀ṣẹ àti alàgbà,
3 Øverster over halvtredsindstyve og anselige Personer og Raadsherrer og vise Mestre og Koglere.
balógun àádọ́ta àti àwọn ènìyàn, onípò gíga; olùdámọ̀ràn, oníṣọ̀nà tí ó dáńtọ́ àti ògbójú oníṣègùn.
4 Og jeg vil give dem Drenge til Fyrster, og barnagtige skulle regere over dem.
“Èmi ó sọ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin di aláṣẹ wọn, ọ̀dọ́mọdé lásán làsàn ni yóò sì máa jẹ ọba lórí i wọn.”
5 Og Folket skal trænges, den ene imod den anden og hver imod sin Næste; de skulle være overmodige, den unge iniod den gamle og den ringeagtede imod den ærede.
Àwọn ènìyàn yóò sì máa pọ́n ọmọnìkejì, wọn lójú ẹnìkan sí ẹnìkejì rẹ̀, aládùúgbò sí aládùúgbò rẹ̀. Àwọn ọ̀dọ́ yóò gbógun ti àwọn àgbàgbà, àwọn mẹ̀kúnnù yóò dìde sí ọlọ́lá.
6 Og naar en tager fat paa sin Broder i sin Faders Hus og siger: Du har Klæder, vær vor Fyrste; lad denne faldende Bygning være under din Haand:
Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin rẹ̀ mú, nínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé, “Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa, sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”
7 Saa skal han paa den Dag tage til Orde og sige: Jeg vil ikke læge eders Skade, og der er hverken Brød, ej heller Klæder i mit Hus, sætter ikke mig til Fyrste over Folket!
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé, “Èmi kò ní àtúnṣe kan. Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ó ní aṣọ nílé, ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”
8 Thi Jerusalem styrter, og Juda falder, efterdi deres Tunge og deres Idræt er imod Herren til at trodse hans Herligheds Øjne.
Jerusalẹmu ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n Juda ń ṣubú lọ, ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa, láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.
9 Deres Ansigters Forhærdelse vidner imod dem, og de bære deres Synd til Skue som Sodoma, de dølge den ikke. Ve deres Sjæl! thi de have ført sig selv Ulykke paa.
Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn, wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sodomu; wọn ò fi pamọ́! Ègbé ni fún wọn! Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.
10 Siger om de retfærdige, at det skal gaa dem vel; thi de skulle æde deres Idrætters Frugt.
Ẹ sọ fún olódodo pé yóò dára fún wọn, nítorí ní àjẹgbádùn ni wọn yóò jẹ èso iṣẹ́ ẹ wọn.
11 Ve den ugudelige! det skal gaa ham ilde; thi det, hans Hænder have gjort, skal gengældes ham.
Ègbé ni fún ènìyàn búburú! Ìparun wà lórí i wọn, a ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.
12 Børn trænge mit Folk, og Kvinder herske over det; mit Folk! dine Førere forføre dig, og Vejen, du vandrer paa, have de ødelagt.
Àwọn ọ̀dọ́mọdé ni o ń pọ́n àwọn ènìyàn mi lójú àwọn obìnrin ń jẹ ọba lé wọn lórí. Háà! Ènìyàn mi àwọn afinimọ̀nà yín ti ṣì yín lọ́nà, wọn sì mú yín kúrò ní ipa ọ̀nà yín.
13 Herden er traadt frem for at gaa i Rette, og han staar for at dømme Folkene.
Olúwa bọ sí ipò rẹ̀ ní ìtẹ́ ìdájọ́ Ó dìde láti dá àwọn ènìyàn lẹ́jọ́.
14 Herren vil gaa til Doms over de ældste af sit Folk og over dets Fyrster: — „I have fortæret Vingaarden, Rov fra den fattige er i eders Huse.
Olúwa dojú ẹjọ́ kọ àwọn àgbàgbà àti àwọn olórí àwọn ènìyàn rẹ̀. “Ẹ̀yin ni ẹ ti run ọgbà àjàrà mi, ogún àwọn tálákà ń bẹ̀ nínú ilé yín.
15 Hvi nedtræde I mit Folk og sønderknuse de elendige? siger Herren, den Herre Zebaoth.”
Kín ni èrò yín láti máa run àwọn ènìyàn mi túútúú tí ẹ sì fojú àwọn tálákà ni gbolẹ̀?” ni Olúwa wí, Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
16 Og Herren sagde: Fordi Zions Døtre ophøje sig og gaa med knejsende Nakke og vinke med Øjnene og gaa frem med trippende Gang og rasle med Ankelringene:
Olúwa wí pé, “Àwọn obìnrin Sioni jẹ́ agbéraga, wọn ń rìn lọ pẹ̀lú ọrùn tí ó nà tàntàn, tí wọn ń fojú pe ọkùnrin, tí wọn ń sọ̀dí bí wọ́n ti ń yan lọ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ tí ń mì wọnjanwọnjan lọ́rùn ẹsẹ̀ wọn.
17 Saa skal Herren gøre Zions Døtres Hovedisse skabet, og Herren skal blotte deres Blusel.
Nítorí náà Olúwa yóò mú egbò wá sórí àwọn obìnrin Sioni, Olúwa yóò sì pá wọn ní agbárí.”
18 Paa den Dag skal Herren borttage Prydelsen: Ankelringene og de virkede Huer og Spænderne,
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò já ọ̀ṣọ́ wọn gbà kúrò ti ọwọ́ àti gèlè àti ẹ̀gbà ọrùn tí ó dàbí òṣùpá
19 Halskæderne og Armspannene og Hovedklæderne,
gbogbo yẹtí, ẹ̀gbà ọwọ́ àti ìbòjú,
20 de dejlige Huer og Armbaandene og Hovedbaandene og Desmerknapperne og Ørenringene,
gbogbo gèlè, ẹ̀gbà ọrùn, ẹsẹ̀ àti àyà, àwọn ìgò tùràrí àti òògùn,
21 Fingerringene og Næseringene,
òrùka ọwọ́ àti ti imú,
22 Helligdagsklæderne og Kaaberne og Forklæderne og Taskerne,
àwọn àtàtà aṣọ, àwọ̀lékè, agbádá àti àpamọ́wọ́,
23 Spejlene og de fine Linklæder og Hvivklæderne og Slørene.
dígí wọn, aṣọ funfun nigínnigín ìbòrí àti ìbòjú.
24 Og det skal ske, at der skal være Stank i Stedet for Vellugt og et Reb i Stedet for Bælte og et skaldet Hoved i Stedet for Haarfletninger og trang Sæk i Stedet for vid Kaabe, Brændemærke i Stedet for Skønhedsplet.
Dípò òórùn dídùn, òórùn búburú ni yóò wá, okùn ni yóò wà dípò àmùrè, orí pípá ni yóò dípò irun ti a ṣe ní ọ̀ṣọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ ni yóò dípò aṣọ ẹ̀yẹ ìjóná dípò ẹwà.
25 Dine Folk skulle falde ved Sværdet og din Styrke i Krigen.
Àwọn ọkùnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú, àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lójú ogun.
26 Og i hendes Porte skal være Bedrøvelse og Sorg, og hun selv skal sidde nøgen paa Jorden.
Àwọn bodè Sioni yóò sọkún kíkorò, wọn ó ṣọ̀fọ̀, nítorí ó dahoro, yóò jókòó ní orí ilẹ̀.