< 1 Mosebog 9 >

1 Og Gud velsignede Noa og hans Sønner og sagde til dem: Vorder frugtbare og mangfoldige, og opfylder Jorden!
Ọlọ́run sì súre fún Noa àti àwọn ọmọ rẹ̀ wí pé, “Ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì pọ̀ ní iye, kí ẹ sì kún ayé.
2 Og Frygt for eder og Rædsel for eder skal være over alle vilde Dyr paa Jorden og over alle Fugle under Himmelen, over alt det, som kryber paa Jorden, og over alle Fiske i Havet, de skulle være givne i eders Hænder.
Ẹ̀rù yín yóò mú ojo wà lára gbogbo ẹranko àti gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹ̀dá tí ń rìn nílẹ̀; àti gbogbo ẹja òkun; a fi wọ́n lé e yín lọ́wọ́.
3 Alt det, som vrimler, som lever, skal være eder til Spise, ligesom grønne Urter har jeg givet eder alt dette.
Gbogbo ohun tó wà láààyè tí ó sì ń rìn, ni yóò jẹ́ oúnjẹ fún un yín, bí mo ṣe fi ewéko fún un yín náà ni mo fi ohun gbogbo fún un yín.
4 Dog Kød med Sjælen, med Blodet i, maa I ikke æde.
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ ẹran tòun-tẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
5 Derimod eders Livs Blod vil jeg kræve, af alle Dyrs Haand vil jeg kræve det; og af Menneskenes Haand, af hvers Haand, endog af hans Broders, vil jeg kræve Menneskenes Sjæl.
Nítòótọ́ ẹ̀jẹ̀ yín, àní ẹ̀mí yín, ni èmi yóò sì béèrè; lọ́wọ́ gbogbo ẹranko ni èmí yóò béèrè rẹ̀, àti lọ́wọ́ ènìyàn, lọ́wọ́ arákùnrin olúkúlùkù ènìyàn ni èmi yóò béèrè ẹ̀mí ènìyàn.
6 Hvo som udøser Menneskenes Blod, ved Mennesket skal hans Blod udøses; thi i Guds Billede gjorde han Mennesket.
“Ẹnikẹ́ni tí ó bá ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀, láti ọwọ́ ènìyàn ni a ó gbà ta ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sílẹ̀. Nítorí ní àwòrán Ọlọ́run ni Ọlọ́run dá ènìyàn.
7 Og vorder frugtbare og mangfoldige, vrimler paa Jorden og vorder mangfoldige derpaa.
Ṣùgbọ́n ní tiyín, ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì máa pọ̀ sí i, ẹ máa gbá yìn lórí ilẹ̀, kí ẹ sì pọ̀ sí i lórí rẹ̀.”
8 Og Gud talede til Noa og til hans Sønner med ham og sagde:
Ọlọ́run sì wí fún Noa àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé,
9 Jeg, se, jeg opretter min Pagt med eder og med eders Afkom efter eder
“Mo dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín àti pẹ̀lú àwọn ìran yín tí ń bọ̀ lẹ́yìn.
10 og med hver levende Sjæl, som er hos eder af Fugle, af Kvæg og af alle vilde Dyr paa Jorden hos eder, af alle dem, som gik ud ad Arken, af alle Dyr, som ere paa Jorden.
Àti pẹ̀lú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú yín, ìbá à ṣe ẹyẹ, ẹja, ẹran ọ̀sìn, ẹranko igbó, gbogbo ohun tí ó jáde kúrò nínú ọkọ̀ pẹ̀lú yín, àní gbogbo ẹ̀dá alààyè ní ayé.
11 Og jeg opretter min Pagt med eder, at herefter skal intet Kød ødelægges af Flodens Vande, og der skal ikke komme Vandflod herefter at fordærve Jorden.
Mo dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú yín láéláé, Èmi kì yóò fi ìkún omi pa ayé run kúrò mọ láéláé, a kì yóò fi omi pa ayé run.”
12 Og Gud sagde: Dette er et Tegn paa den Pagt, som jeg gør imellem mig og imellem eder og imellem hver levende Sjæl, som er hos eder, til evig Tid.
Ọlọ́run sì wí pé, “Èyí ni àmì májẹ̀mú tí mo ń dá yìí láàrín èmi àti ẹ̀yin àti ẹ̀dá alààyè tí ó wà pẹ̀lú yín, májẹ̀mú àtìrandíran tó ń bọ̀:
13 Jeg har sat min Bue i Skyen, og den skal være til en Pagtes Tegn imellem mig og imellem Jorden.
Mo ti fi òṣùmàrè sí àwọsánmọ̀, yóò sì jẹ́ àmì májẹ̀mú láàrín èmi àti ayé.
14 Og det skal ske, naar jeg fører Skyen over Jorden, da skal Buen ses i Skyen.
Nígbàkígbà tí mo bá mú kí òjò ṣú, tí òṣùmàrè bá farahàn ní àwọsánmọ̀.
15 Og jeg vil komme min Pagt i Hu, som er imellem mig og imellem eder og imellem alle levende Sjæle af alt Kød, at Vandene ikke mere skulle blive til en Flod, at fordærve alt Kød.
Èmi yóò rántí májẹ̀mú mi, tí ó wà láàrín èmi àti ẹ̀yin àti gbogbo ẹ̀dá alààyè, kì yóò sì tún sí ìkún omi mọ́ láti pa gbogbo ẹ̀dá run.
16 Derfor skal Buen være i Skyen, og jeg vil se den for at ihukomme den evige Pagt imellem Gud og imellem alle levende Sjæle af alt Kød, som er paa Jorden.
Nígbàkígbà tí òṣùmàrè bá yọ ní àwọsánmọ̀, èmi yóò rí i, èmi yóò sì rántí májẹ̀mú ayérayé tí ń bẹ láàrín Ọlọ́run àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń bẹ ní ayé.”
17 Og Gud sagde til Noa: Dette skal være et Tegn paa den Pagt, som jeg har oprettet imellem mig og imellem alt Kød, som er paa Jorden.
Ọlọ́run sì wí fún Noa pé, “Èyí ni àmì májẹ̀mú tí mo ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ láàrín èmi àti gbogbo alààyè ní ayé.”
18 Og Noas Sønner, som gik ud ad Arken, vare Sem og Kam og Jafet; men Kam er Kanaans Fader.
Àwọn ọmọ Noa tí ó jáde nínú ọkọ̀ ni Ṣemu, Hamu àti Jafeti. (Hamu ni baba Kenaani.)
19 Disse tre ere Noas Sønner, og af disse blev hele Jorden befolket alle Vegne.
Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Noa mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí ni gbogbo ènìyàn ti tàn ká gbogbo ilẹ̀ ayé.
20 Men Noa begyndte at blive en Avlsmand og plantede en Vingaard.
Noa bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ àgbẹ̀, ó sì gbin ọgbà àjàrà.
21 Og han drak af Vinen og blev drukken og blottede sig midt i sit Telt.
Ó mu àmupara nínú ọtí wáìnì àjàrà rẹ̀, ó sì tú ara rẹ̀ sí ìhòhò, ó sì sùn nínú àgọ́ rẹ̀.
22 Der Kam, Kanaans Fader, saa sin Faders Blusel, forkyndte han begge sine Brødre det udenfor.
Hamu tí í ṣe baba Kenaani sì rí baba rẹ̀ ní ìhòhò bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀ méjèèjì ní ìta.
23 Da tog Sem og Jafet et Klæde og lagde det begge paa deres Skulder og gik baglæns og skjulte deres Faders Blusel; og deres Ansigter vare bortvendte, at de ikke saa deres Faders Blusel.
Ṣùgbọ́n Ṣemu àti Jafeti mú aṣọ lé èjìká wọn, wọ́n sì fi ẹ̀yìn rìn, wọ́n sì bo ìhòhò baba wọn. Wọ́n kọjú sẹ́yìn kí wọn kí ó má ba à rí ìhòhò baba wọn.
24 Og Noa vaagnede op af sin Vin og fik at vide, hvad hans yngste Søn havde gjort ham.
Nígbà tí Noa kúrò ní ojú ọtí, tí ó sì mọ ohun tí ọmọ rẹ̀ kékeré ṣe sí i.
25 Da sagde han: Forbandet være Kanaan, han skal være Trælles Træl for sine Brødre!
Ó wí pé, “Ègún ni fún Kenaani. Ìránṣẹ́ àwọn ìránṣẹ́ ni yóò máa ṣe fún àwọn arákùnrin rẹ̀.”
26 Og han sagde: Lovet være Herren, Sems Gud, og Kanaan skal være deres Træl!
Ó sì tún wí pé, “Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Ṣemu Kenaani yóò máa ṣe ẹrú fún Ṣemu.
27 Gud udbrede Jafet, og han skal bo i Sems Pauluner, og Kanaan skal være deres Træl!
Ọlọ́run yóò mú Jafeti gbilẹ̀, Jafeti yóò máa gbé ní àgọ́ Ṣemu Kenaani yóò sì jẹ́ ẹrú fún un.”
28 Og Noa levede efter Floden tre Hundrede Aar og halvtredsindstyve Aar.
Noa wà láààyè fún irinwó ọdún dín àádọ́ta lẹ́yìn ìkún omi.
29 Og alle Noas Dage vare ni Hundrede Aar og halvtredsindstyve Aar; og han døde.
Àpapọ̀ ọjọ́ ayé Noa jẹ́ ẹgbẹ̀rún ọdún dín làádọ́ta, ó sì kú.

< 1 Mosebog 9 >