< 1 Mosebog 49 >

1 Og Jakob kaldte ad sine Sønner og sagde: Samler eder, og jeg vil forkynde eder, hvad eder skal vederfares i de sidste Dage.
Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.
2 Kommer til Hobe og hører, Jakobs Sønner! og hører paa Israel, eders Fader.
“Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu; ẹ fetí sí Israẹli baba yín.
3 Ruben, du er min førstefødte, min Magt og min første Kraft, ypperlig i Værdighed og ypperlig i Styrke!
“Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi, agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi, títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.
4 Du bruser op som Vandet; du skal ikke være ypperlig; thi du besteg din Faders Leje, da besmittede du det; han har besteget min Seng.
Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́, nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ, lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́ (ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).
5 Simeon og Levi ere Brødre; Volds Vaaben ere deres Sværd.
“Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin— idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.
6 Min Sjæl skal ikke komme i deres hemmelige Raad, min Ære skal ikke forenes med deres Forsamling; thi i deres Vrede have de slaget Mænd ihjel, og i deres Egenraadighed have de lemlæstet Oksen.
Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn, kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn, nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn, wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.
7 Forbandet være deres Vrede, thi den var streng, og deres Hastighed, thi den var haard; jeg vil fordele dem i Jakob og adsprede dem i Israel.
Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà! Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu, èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.
8 Juda, dig skulle dine Brødre love, din Haand skal være paa dine Fjenders Nakke; for dig skulle din Faders Sønner bøje sig.
“Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ, ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
9 Juda er en ung Løve; du opsteg fra Rov, min Søn! han har bøjet sig, han laa som en Løve og som en Løvinde; hvem tør jage ham op?
Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda, o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi. Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún, ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
10 Der skal ikke vige Kongespir fra Juda og ikke Herskerstav fra hans Fødder, førend Silo skal komme, og Folkene skulle hænge ved ham.
Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀, títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé, tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.
11 Han binder sit unge Asen til Vintræet og sin Asenindes Føl til Vinranken; han tor sit Klædebon i Vin, og sin Kjortel i Vindrueblod.
Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà, àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù. Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wù rẹ̀ nínú omi-pupa ti èso àjàrà.
12 Han er rødere i Øjnene end Vin, og hvidere paa Tænderne end Mælk.
Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ, eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.
13 Sebulon skal bo ved Havets Strand, og han skal være ved Skibenes Strand, og hans Side ligger op til Sidon.
“Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun, yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi, agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.
14 Isaskar skal være et knokkelstærkt Asen, som ligger imellem Kvægfoldene.
“Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.
15 Thi han saa, at Hvilen var god, og at Landet var dejligt, og han har bøjet sine Skuldre til at bære og er bleven en skatskyldig Tjener.
Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó, àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó, yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà, yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.
16 Dan skal dømme sit Folk, som en af Israels Stammer.
“Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
17 Dan skal være en Slange paa Vejen, en Hornslange paa Stien, som bider Hestens Hov, saa dens Rytter falder bag af.
Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà, tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀, kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.
18 Herre, jeg bier efter din Frelse!
“Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.
19 Gad — en Skare skal trænge ind paa ham, men han skal trænge den tilbage.
“Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi, ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.
20 Fra Aser kommer det fede, som er hans Brød; og han skal give kongelige Lækkerheder.
“Oúnjẹ Aṣeri yóò dára; yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.
21 Nafthali er en frit løbende Hind, han, som giver dejlig Tale.
“Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.
22 Josef er en Kvist paa det frugtbare Træ, en Kvist paa det frugtbare Træ ved Kilden; Grenene gaa op over Muren.
“Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso, àjàrà eléso ní etí odò, tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
23 Og Bueskytterne forbitrede ham og skøde og hadede ham.
Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́, wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra.
24 Og hans Bue blev dog stærk, og hans Hænders Arme smidige; det kom fra Jakobs mægtiges Hænder, hist fra, fra Hyrden, fra Israels Klippe.
Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára, ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le, nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu, nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,
25 Fra din Faders Gud — og han hjælpe dig! — og fra den Almægtige — og han velsigne dig! — komme Velsignelser fra Himmelen ovenfra og Velsignelser fra Dybet nedenfra, Brysters og Moderlivs Velsignelser.
nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́, nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ pẹ̀lú láti ọ̀run wá, ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀, ìbùkún ti ọmú àti ti inú.
26 Din Faders Velsignelser ere mægtigere end mine Forfædres Velsignelser, indtil de evige Højes Grænser; de skulle komme paa Josefs Hoved og paa hans Isse, som er en Fyrste iblandt sine Brødre.
Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀ ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì, ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé. Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu, lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.
27 Benjamin skal røve som en Ulv; om Morgenen skal han æde Rov, og om Aftenen skal han uddele Bytte.
“Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú; ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ, ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”
28 Alle disse ere de tolv Israels Stammer; og dette er det, som deres Fader talede til dem, da han velsignede dem, hver efter sin Velsignelse velsignede han dem.
Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.
29 Og han befalede dem og sagde til dem: Naar jeg er samlet til mit Folk, da begraver mig hos mine Fædre i den Hule, som er paa Efron den Hethiters Ager,
Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni.
30 i den Hule, som er paa den Ager Makpela, som er tvært over for Mamre i Kanaans Land, hvilken Ager Abraham købte af Efron den Hethiter til Begravelses Ejendom.
Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀.
31 Der have de begravet Abraham og Sara, hans Hustru; der have de begravet Isak og Rebekka, hans Hustru; og der har jeg begravet Lea.
Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí.
32 Den Agers Ejendom og den Hule, som er derpaa, er købt af Heths Børn.
Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”
33 Der Jakob var kommen til Ende med at byde sine Børn dette, da tog han sine Fødder til sig op paa Sengen og opgav sin Aand og blev samlet til sit Folk.
Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.

< 1 Mosebog 49 >