< 1 Mosebog 14 >

1 Og det skete i de Dage, der Amrafel var Konge i Sinear, Ariok Konge i Elassar, Kedorlaomer Konge i Elam, og Thideal Konge over Gojim,
Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu
2 at de førte Krig mod Bera, Kongen af Sodoma, og imod Birsa, Kongen af Gomorra, Sineab, Kongen af Adma, og Semeber, Kongen af Zeboim, og Kongen af Bela, det er Zoar.
jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari) jagun.
3 Alle disse kom sammen i Siddims Dal, det er Salthavet.
Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí àfonífojì Siddimu (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀).
4 Tolv Aar havde de tjent Kedorlaomer, og i det trettende Aar vare de affaldne.
Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.
5 Og i det fjortende Aar kom Kedorlaomer og de Konger, som vare med ham, og sloge Refaiterne i Astharoth-Karnaim og Susiterne i Ham og Emiterne i Schaveh-Kirjathaim
Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu,
6 og Horiterne paa deres Bjerg Sejr indtil Parans Slette, som er ved Ørken.
àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù.
7 Derefter vendte de om og kom til den Kilde Mispat, det er Kades, og sloge Amalekiternes hele Land og Amoriterne, som boede i Hazezon-Thamar.
Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (ti o túmọ̀ sí Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.
8 Da drog Kongen af Sodoma ud og Kongen af Gomorra og Kongen af Adma og Kongen af Zeboim og Kongen af Bela, det er Zoar, og rustede sig mod dem til Strid udi Siddims Dal,
Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Seboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu,
9 imod Kedorlaomer, Kongen af Elam, og Thideal, Kongen over Gojim, og Amrafel, Kongen af Sinear, og Ariok, Kongen af Elassar, fire Konger mod fem.
láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún).
10 Og Siddims Dal var fuld af Jordbegsgruber, og Kongen af Sodoma og Gomorra flyede, og de faldt deri; og de, som overbleve, flyede paa Bjerget.
Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè.
11 Og de toge alt det Gods, som var i Sodoma og Gomorra, og al deres Føde og droge bort.
Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ.
12 Og de toge Abrams Brodersøn, Lot, og hans Gods og droge bort; men han boede i Sodoma.
Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.
13 Da kom en, som var undkommen, og forkyndte Hebræeren Abram det; men han boede i Amoriten Mamres Lund; denne var Broder til Eskol og Broder til Aner, og disse vare i Forbund med Abram.
Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀.
14 Der Abram hørte, at hans Broder var fangen, da væbnede han sine tre Hundrede og atten oplærte unge Karle, som vare fødte i hans Hus, og forfulgte dem til Dan.
Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó lé lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn, ó sì lépa wọn títí dé Dani.
15 Og han og hans Svende delte sig over dem om Natten og slog dem og forfulgte dem til Hoba, som ligger paa den venstre Side for Damaskus,
Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku.
16 og han førte alt Godset tilbage, og tilmed Lot, sin Broder, og hans Gods førte han tilbage og desligeste Kvinderne og Folket.
Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.
17 Og Kongen af Sodoma gik ud imod ham, efter at han var kommen tilbage fra det Slag imod Kedorlaomer og de Konger, som vare med ham, til Schave-Dal, som kaldes Kongens Dal.
Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní àfonífojì Ṣafe (èyí ni àfonífojì Ọba).
18 Og Melkisedek, Kongen af Salem, bragte Brød og Vin, og han var den højeste Guds Præst.
Melkisedeki ọba Salẹmu sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo.
19 Og han velsignede ham og sagde: Velsignet være Abram for den højeste Gud, som ejer Himmel og Jord,
Ó sì súre fún Abramu, wí pé, “Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
20 og velsignet være den højeste Gud, som gav dine Fjender i din Haand; og Abram gav ham Tiende af alt.
Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.” Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.
21 Og Kongen af Sodoma sagde til Abram: Giv mig Folket, og tag Godset til dig.
Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”
22 Men Abram sagde til Kongen af Sodoma: Jeg har opløftet min Haand til Herren, den højeste Gud, som ejer Himmel og Jord,
Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè,
23 at jeg ikke vil tage saa meget som en Traad eller Skotvinge af alt det, som tilhører dig, at du ikke skal sige: jeg har gjort Abram rig;
pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’
24 undtagen det alene, som de unge Karle have fortæret, og de Mænds Del, som gik med mig, Aner, Eskol og Mamre, de maa tage deres Del.
Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”

< 1 Mosebog 14 >