< Ezra 8 >

1 Og disse ere Øversterne for deres Fædrenehuse og deres Slægt, de som droge op med mig under Kong Artakserkses's Regering, fra Babel:
Wọ̀nyí ni àwọn olórí ìdílé àti àwọn tí ó fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn tì wọn gòkè pẹ̀lú mi láti Babeli ní àkókò ìjọba Artasasta ọba:
2 Af Pinehas's Børn, Gersom; af Ithamars Børn, Daniel; af Davids Børn, Hattus;
nínú àwọn ọmọ Finehasi: Gerṣomu; nínú àwọn ọmọ Itamari: Daniẹli; nínú àwọn ọmọ Dafidi: Hattusi,
3 af Sekanias Børn, af Pareos's Børn, Sakaria og med ham hans Slægt hundrede og halvtredsindstyve Mandspersoner;
nínú àwọn ọmọ Ṣekaniah; nínú àwọn ọmọ Paroṣi: Sekariah, àti pé àádọ́jọ ọkùnrin fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú rẹ;
4 af Pahath-Moabs Børn, Elioenaj, Serakias Søn, og med ham to Hundrede Mandspersoner;
nínú àwọn ọmọ Pahati-Moabu: Elihoenai ọmọ Serahiah àti àwọn igba ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
5 af Sekanias Børn, Jehasiels Søn, og med ham tre Hundrede Mandspersoner;
nínú àwọn ọmọ Sattu: Ṣekaniah ọmọ Jahasieli àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
6 af Adins Børn, Ebed, Jonathans Søn, og med ham halvtredsindstyve Mandspersoner;
nínú àwọn ọmọ Adini: Ebedi ọmọ Jonatani, àti àádọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
7 og af Elams Børn, Jesaja, Athalias Søn, og med ham halvfjerdsindstyve Mandspersoner;
nínú àwọn ọmọ Elamu: Jeṣaiah ọmọ Ataliah àwọn àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
8 og af Sefatjas Børn, Sebadja, Mikaels Søn, og med ham firsindstyve Mandspersoner;
nínú àwọn ọmọ Ṣefatia: Sebadiah ọmọ Mikaeli, àti ọgọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
9 af Joabs Børn, Obadja, Jehiels Søn, og med ham to Hundrede og atten Mandspersoner;
nínú àwọn ọmọ Joabu: Obadiah ọmọ Jehieli àti ogún ó lé nígba ó dín méjì ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
10 af Selomiths Børn, Josifjas Søn, og med ham hundrede og tresindstyve Mandspersoner;
nínú àwọn ọmọ Bani: Ṣelomiti ọmọ Josafiah, àti ọgọ́jọ ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
11 og af Bebajs Børn, Sakaria, Bebajs Søn, og med ham otte og tyve Mandspersoner;
nínú àwọn ọmọ Bebai: Sekariah ọmọ Bebai àti ọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n pẹ̀lú rẹ̀;
12 og af Asgads Børn, Johanan, Hakkatans Søn, og med ham hundrede og ti Mandspersoner;
nínú àwọn ọmọ Asgadi: Johanani ọmọ Hakatani, àti àádọ́fà ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
13 og af Adonikams Børn vare nogle senere, og deres Navne vare disse: Elifelet, Jeiel og Semaja, og med dem tresindstyve Mandspersoner;
nínú àwọn ọmọ Adonikami: àwọn ti ó gbẹ̀yìn, tì orúkọ wọn ń jẹ́ Elifaleti, Jeieli àti Ṣemaiah, àti ọgọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú wọn;
14 og af Bigevajs Børn, Uthaj og Sabbud, og med dem halvfjerdsindstyve Mandspersoner.
nínú àwọn ọmọ Bigfai: Uttai àti Sakkuri, àti àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú wọn.
15 Og jeg samlede dem ved Floden, som løber til Ahava, og der lejrede vi os tre Dage; og der jeg gav Agt paa Folket og paa Præsterne, da fandt jeg ingen af Levis Børn der.
Èmi kó wọn jọ pọ̀ si etí odò ti ń sàn lọ sí Ahafa, a pàgọ́ síbẹ̀ fún odidi ọjọ́ mẹ́ta, nígbà ti mo wo àárín àwọn ènìyàn àti àárín àwọn àlùfáà, ń kò rí ọmọ Lefi kankan níbẹ̀.
16 Da sendte jeg Elieser, Ariel, Semaja og Elnathan og Jarib og Elnathan og Nathan og Sakaria og Messullam, de Øverste, og Jojarib og Elnathan, som vare forstandige Mænd,
Nígbà náà ni mo pe Elieseri, Arieli, Ṣemaiah, Elnatani, Jaribi, Elnatani, Natani, Sekariah, àti Meṣullamu, tí wọ́n jẹ́ olórí, àti Joiaribu àti Elnatani tí wọ́n jẹ́ onímọ̀ ìjìnlẹ̀,
17 og jeg sendte dem til Iddo, som var den Øverste i det Sted Kasfia; og jeg lagde Ordene i deres Mund, som de skulde tale med Iddo, Ahio og de livegne i det Sted Kasfia, for at bringe os Tjenere til vor Guds Hus.
mo sì rán wọn tí àwọn ti àṣẹ sí ọ̀dọ̀ Iddo, tí ó jẹ́ olórí ní ibi ti a ń pè ni Kasifia, mo sì sọ fún wọn ohun tí wọn yóò wí fun Iddo àti àwọn Lefi arákùnrin rẹ̀, tí wọ́n jẹ́ òṣìṣẹ́ tẹmpili ní Kasifia pé, kí wọn mú àwọn ìránṣẹ́ wá sí ọ̀dọ̀ wa fún ilé Ọlọ́run wa.
18 Og de bragte os, efterdi vor Guds gode Haand var over os, en forstandig Mand af Mahelis Børn, som nedstammede fra Levi, Israels Søn, nemlig Serebia og hans Sønner og hans Brødre, atten Mænd.
Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run wa wà lára wa, wọ́n sì mú Ṣerebiah wá fún wa, ẹni tí ó kún ojú òsùwọ̀n láti ìran Mahili, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli, àti àwọn ọmọ Ṣerebiah àti àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n jẹ́ ọkùnrin méjìdínlógún.
19 Og Hasabia og tillige med ham Jesaja, af Meraris Børn, hans Brødre og deres Sønner, tyve Mænd.
Àti Haṣabiah, pẹ̀lú Jeṣaiah láti ìran Merari, pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ọmọ wọ́n jẹ́ ogún ọkùnrin.
20 Og af de livegne, som David og Fyrsterne gav til Leviternes Tjeneste, to Hundrede og tyve livegne; alle disse vare nævnede ved Navn.
Wọ́n sì tún mú ogún lé nígba àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili wá—àwọn ènìyàn tí Dafidi àti àwọn ìjòyè rẹ̀ gbé kalẹ̀ láti ran àwọn ọmọ Lefi lọ́wọ́. Gbogbo wọn ni a ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.
21 Og jeg lod der udraabe en Faste ved den Flod Ahava for at ydmyge os for vor Guds Ansigt for at bede ham om en lykkelig Rejse for os og vore smaa Børn og alt vort Gods.
Níbẹ̀, ní ẹ̀bá odò Ahafa, mo kéde àwẹ̀, kí a ba à le rẹ ara wa sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run, kí a sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ fún ìrìnàjò àìléwu fún wa àti àwọn ọmọ wa àti fún gbogbo ohun ìní wa.
22 Thi jeg skammede mig ved at begære Krigsmagt og Ryttere af Kongen til at hjælpe os imod Fjenden paa Vejen; thi saaledes havde vi sagt til Kongen: Vor Guds Haand er over alle dem, som søge ham, til det gode, og hans Styrke og hans Vrede er over alle dem, som forlade ham.
Mo tijú láti béèrè lọ́wọ́ ọba fún àwọn jagunjagun orí ilẹ̀, àti ti orí ẹṣin láti dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá ní ọ̀nà wa, nítorí àti sọ fún ọba pé, “Ọwọ́ àánú Ọlọ́run wà ní ara gbogbo ẹni tí ó gbé ojú sókè sí i, ṣùgbọ́n ìbínú ńlá rẹ wà lórí ẹni tó kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
23 Saa fastede vi og bade til vor Gud derom, og han bønhørte os.
Bẹ́ẹ̀ ni a sì gbààwẹ̀, a sì bẹ̀bẹ̀ fún èyí lọ́dọ̀ Ọlọ́run wa, òun sì gbọ́ àdúrà wa.
24 Og jeg udskilte tolv af Præsternes Øverster, nemlig Serebia, Hasabia og med dem ti af deres Brødre,
Nígbà náà ni mo ya àwọn àlùfáà tó jẹ́ aṣáájú méjìlá sọ́tọ̀, pẹ̀lú Ṣerebiah, Haṣabiah àti mẹ́wàá lára àwọn arákùnrin wọn,
25 og jeg tilvejede dem Sølvet og Guldet og Karrene, som vare en Gave til vor Guds Hus, som Kongen og hans Raadsherrer og hans Fyrster og al Israel, som fandtes, havde givet.
mo sì fi òsùwọ̀n wọn ọrẹ fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò tí ọba, àti ti àwọn ìgbìmọ̀, àti ti àwọn ìjòyè, àti ti gbogbo ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀, tí wọ́n gbe sílẹ̀ fún ilé Ọlọ́run wa.
26 Og jeg tilvejede dem i deres Haand seks Hundrede og halvtredsindstyve Centner Sølv og Sølvkar til hundrede Centner, Guld til hundrede Centner
Mo fi òsùwọ̀n wọn ẹgbẹ̀ta lé láàádọ́ta tálẹ́ǹtì fàdákà, àti ohun èlò fàdákà tí ó wọn ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì, ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì wúrà,
27 og tyve Guldbægere til tusinde Drakmer og to Kar af godt skinnende Kobber, kostelige som Guld.
ogún ago wúrà tí iye rẹ̀ tó ẹgbẹ̀rún dariki, àti ohun èlò idẹ dáradára méjì ti ó ni iye lórí bí i wúrà.
28 Og jeg sagde til dem: I ere Herren hellige, og Karrene ere hellige, og Sølvet og Guldet er en frivillig Gave til Herren, eders Fædres Gud.
Mo wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin àti àwọn ohun èlò wọ̀nyí ni a ti yà sí mímọ́ fún Olúwa. Fàdákà àti wúrà sì jẹ́ ọrẹ àtinúwá sí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín.
29 Værer aarvaagne og bevarer det, indtil I veje det ud for Præsternes og Leviternes Øverster og Øversterne for Fædrenehusene iblandt Israel i Jerusalem, i Herrens Hus's Kamre.
Ẹ máa tọ́jú wọn dáradára títí ẹ̀yin yóò fi fi òsùwọ̀n wọ̀n wọ́n jáde kúrò ni ilé Olúwa ni Jerusalẹmu ní iwájú àwọn aṣáájú, àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti ní iwájú olórí ìdílé gbogbo ni Israẹli.”
30 Da toge Præsterne og Leviterne imod samme Sølv og Guld og Kar efter Vægt for at føre det til Jerusalem, til vor Guds Hus.
Nígbà náà ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi gba fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ́ tí a ti wọ̀n jáde fún kíkó lọ sí ilé Ọlọ́run wa ní Jerusalẹmu.
31 Og vi rejste fra Ahavas Flod paa den tolvte Dag i den første Maaned for at drage til Jerusalem, og vor Guds Haand var over os og friede os for Fjendens Haand og dens, som lurede ved Vejen.
Ní ọjọ́ kejìlá oṣù kìn-ín-ní ni a gbéra kúrò ní ẹ̀bá odò Ahafa láti lọ sí Jerusalẹmu. Ọwọ́ Ọlọ́run wa wà lára wa, ó sì dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá àti àwọn adigunjalè ní ọ̀nà wa.
32 Og vi kom til Jerusalem, og vi bleve der tre Dage.
Bẹ́ẹ̀ ni a gúnlẹ̀ sí Jerusalẹmu, níbi tí a ti sinmi fún ọjọ́ mẹ́ta.
33 Men paa den fjerde Dag blev Sølvet og Guldet og Karrene i vor Guds Hus tilvejet Meremoth, Præsten Urias Søn, og med ham var Eleasar, Pinehas's Søn, og med dem vare Leviterne Josabad, Jesuas Søn, og Noadja, Binnuis Søn,
Ní ọjọ́ kẹrin, a wọn ohun èlò fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ lé àlùfáà Meremoti ọmọ Uriah lọ́wọ́, láti inú ilé Ọlọ́run wa, Eleasari ọmọ Finehasi wà pẹ̀lú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi; Josabadi ọmọ Jeṣua àti Noadiah ọmọ Binnui wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
34 efter Tal, efter Vægten paa det alt sammen; og hele Vægten blev samme Tid opskreven.
Gbogbo nǹkan ni a kà, tí a sì wọ̀n, gbogbo iye ìwọ̀n ni a sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú ìwé ní ìgbà náà.
35 Og de Folk, som havde været bortførte, de, som vare komne fra Fangenskabet, ofrede Israels Gud Brændofre, tolv Okser for al Israel, seks og halvfemsindstyve Vædre, syv og halvfjerdsindstyve Lam, tolv Bukke til Syndofre, alt sammen til Brændoffer for Herren.
Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn tí ó ti padà láti ilẹ̀ àjèjì rú ẹbọ sísun sí Ọlọ́run Israẹli: akọ màlúù méjìlá fún gbogbo Israẹli, àgbò mẹ́rìndínlọ́gọ́rùn-ún, ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́tàdínlọ́gọ́rin, àti òbúkọ méjìlá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Gbogbo èyí jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa.
36 Og de overgave Kongens Statholdere og Landshøvdingene paa denne Side Floden Kongens Love, og de hjalp højlig Folket og Guds Hus.
Wọ́n sì jíṣẹ́ àṣẹ ọba fún àwọn ìjòyè àti àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún àwọn ènìyàn àti ilé Ọlọ́run.

< Ezra 8 >