< Ezekiel 28 >

1 Og Herrens Ord kom til mig saalunde:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
2 Du Menneskesøn! sig til Tyrus's Fyrste: Saa siger den Herre, Herre: Fordi dit Hjerte ophøjede sig, og du sagde: Jeg er en Gud, jeg sidder paa Guds Sæde midt i Havet, medens du er et Menneske og ikke Gud og dog agtede dit Hjerte som Guds Hjerte;
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún ọmọ-aládé Tire pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí tí ọkàn rẹ gbé sókè sí mi, ìwọ wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run; Èmi jókòó sí orí ìtẹ́ òrìṣà, ní àárín gbùngbùn Òkun.” Ṣùgbọ́n ènìyàn ni ọ́, kì i ṣe òrìṣà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ rò pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
3 — se, du er visere end Daniel; intet lønligt er skjult for dig;
Ìwọ gbọ́n ju Daniẹli lọ bí? Ṣé kò sí àṣírí kan tí ó pamọ́ fún ọ?
4 du har forhvervet dig Formue ved din Visdom og ved din Forstand og bragt Guld og Sølv i dine Skatkamre;
Pẹ̀lú ọgbọ́n àti ìmọ̀ rẹ, ìwọ tí jèrè ọrọ̀ fún ara rẹ, àti àkójọpọ̀ wúrà àti fàdákà, nínú àwọn ilé ìṣúra rẹ.
5 du har formeret din Formue ved din megen Visdom i dit Købmandsskab, og dit Hjerte har ophøjet sig for din Formues Skyld: —
Nípa ọgbọ́n rẹ ńlá àti nípa òwò rẹ, ìwọ ti sọ ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, àti nítorí ọrọ̀ rẹ di púpọ̀, ọkàn rẹ gbé sókè, nítorí ọrọ̀ rẹ.
6 Derfor, saa siger den Herre, Herre: Efterdi du agtede dit Hjerte som Guds Hjerte,
“‘Nítorí náà èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Nítorí pé ìwọ rò pé o gbọ́n, pé ìwọ gbọ́n bí Ọlọ́run.
7 se, derfor vil jeg lade fremmede, de forfærdelige iblandt Folkene, komme over dig, og de skulle uddrage deres Sværd imod din Visdoms skønne Værk og vanhellige din Herlighed.
Èmi yóò mú kí àwọn àjèjì dìde sí ọ, ẹlẹ́rù nínú àwọn orílẹ̀-èdè; wọn yóò yọ idà wọn sí ọ, ẹwà rẹ àti ọgbọ́n rẹ, wọn yóò sì ba dídán rẹ̀ jẹ́.
8 De skulle kaste dig ned i Hulen, og du skal dø, som de gennemstungne dø midt i Havet.
Wọn yóò mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá sínú ihò, ìwọ yóò sì kú ikú gbígbóná, àwọn tí a pa ní àárín Òkun.
9 Mon du vel kan sige over for den, som ihjelslaar dig: Jeg er en Gud? medens du dog er et Menneske og ikke en Gud i hans Haand, som ihjelslaar dig.
Ṣé ìwọ yóò wá wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run,” ní ojú àwọn tí ó pa ọ́? Ìwọ yóò jẹ́ ènìyàn, kì í ṣe Ọlọ́run, ní ọwọ́ àwọn ti yóò pa ọ́.
10 Du skal dø, som de uomskaarne dø, ved fremmedes Haand; thi jeg har talt det, siger den Herre, Herre.
Ìwọ yóò kú ikú aláìkọlà, ní ọwọ́ àwọn àjèjì. Èmi ni ó ti sọ ọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
11 Og Herrens Ord kom til mig saaledes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
12 Du Menneskesøn! opløft et Klagemaal over Kongen af Tyrus, og sig til ham: Saa siger den Herre, Herre: Du, som paatrykker den afpassede Ordning Seglet, du, som er fuld af Visdom og fuldkommen i Skønhed,
“Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún sórí ọba Tire kí ó sì sọ fún un pé: ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ìwọ jẹ́ àpẹẹrẹ ìjẹ́pípé náà, o kún fún ọgbọ́n, o sì pé ní ẹwà.
13 du var i Eden, i Guds Have, alle Haande kostbare Stene bedækkede dig: Karneol, Topas og Demant, Krysolith, Onyks og Jaspis, Safir, Karbunkel og Smaragd og Guld; dine Trommer og dine Piber vare til Tjeneste hos dig, de vare beredte paa den Dag, du blev skabt.
Ìwọ ti wà ní Edeni, ọgbà Ọlọ́run; onírúurú òkúta oníyebíye ni ìbora rẹ; sardiu, topasi àti diamọndi, berili, óníkìsì, àti jasperi, safire, emeradi, turikuose, àti karbunkili, àti wúrà, ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ àti àwọn òkè rẹ ní a dà, láti ara wúrà, ní ọjọ́ tí á dá ọ ní a pèsè wọn.
14 Du var en salvet Kerub, som skærmede; og jeg havde sat dig dertil, du var paa Guds hellige Bjerg, du vandrede midt imellem gloende Stene.
A fi àmì òróró yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí olùtọ́jú kérúbù, torí èyí ni mo fi yàn ọ́. Ìwọ wà lórí òkè mímọ́ Ọlọ́run; ìwọ rìn ni àárín òkúta a mú bí iná.
15 Du var fuldkommen i dine Veje fra den Dag af, du blev skabt, indtil Uretfærdighed blev funden i dig.
Ìwọ pé ní ọ̀nà rẹ, láti ọjọ́ tí a ti dá ọ, títí a fi rí àìṣedéédéé ní inú rẹ.
16 Formedelst din store Handel fyldtes dit Indre af Uret, og du syndede; derfor fjernede jeg dig som vanhelliget fra Guds Bjerg og lod dig omkomme, du skærmende Kerub, at du ikke forblev imellem de gloende Stene.
Nípa ìtànkálẹ̀ òwò rẹ, ìwọ kún fún ìwà ipá; ìwọ sì dẹ́ṣẹ̀. Nítorí náà ni mo ṣe sọ ọ nù, bí ohun àìlọ́wọ̀ kúrò lórí òkè Ọlọ́run. Èmi sì pa ọ run, ìwọ kérúbù, tí ó bọ́ kúrò ní àárín òkúta a mú bí iná.
17 Dit Hjerte ophøjede sig for din Skønheds Skyld, du ødelagde din Visdom tillige med din Herlighed! jeg henkastede dig paa Jorden, gav dig hen for Kongers Ansigt, at de skulle se paa dig.
Ọkàn rẹ gbéraga, nítorí ẹwà rẹ. Ìwọ sì ba ọgbọ́n rẹ jẹ́, nítorí dídára rẹ. Nítorí náà mo le ọ sórí ayé; mo sọ ọ di awòojú níwájú àwọn ọba.
18 Ved dine Misgerningers Mangfoldighed under din uretfærdige Handel vanhelligede du dine Helligdomme, og jeg lod en Ild gaa ud fra din Midte, den fortærede dig, og jeg gjorde dig til Aske paa Jorden for alles Øjne, som se dig.
Nípa ẹ̀ṣẹ̀ púpọ̀ rẹ àti òwò àìṣòótọ́ rẹ, ìwọ ti ba àwọn ibi mímọ́ rẹ jẹ́. Nítorí náà mo mú kí iná jáde wá, láti inú rẹ, yóò sì jó ọ run, èmi yóò sì sọ ọ́ di eérú lórí ilẹ̀, lójú gbogbo àwọn tí ó ń wò ọ́.
19 Alle som dig kendte iblandt Folkene, forfærdes over dig; du er bleven til Gru og skal i Evighed ikke være mere.
Gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó mọ̀ ọ́n, ní ẹnu ń yà sí ọ; ìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rù, ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́ láéláé.’”
20 Og Herrens Ord kom til mig saaledes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
21 Du Menneskesøn! vend dit Ansigt imod Zidon, og spaa imod den,
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú sí Sidoni; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ sí i,
22 og sig: Saa siger den Herre, Herre: Se, jeg kommer imod dig, Zidon! og jeg vil herliggøre mig i din Midte; og de skulle fornemme, at jeg er Herren, naar jeg holder Ret over den og helliggør mig ved den.
kí ó sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi lòdì sí ọ, ìwọ Sidoni, a ó sì ṣe mí lógo láàrín rẹ. Wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú ìdájọ́ mi ṣẹ nínú rẹ, tí a sì yá mí sí mímọ́ nínú rẹ.
23 Og jeg vil sende Pest i den og Blod paa dens Gader, og der skal falde ihjelslagne i dens Midte for Sværdet, som skal komme over den trindt omkring fra; og de skulle fornemme, at jeg er Herren.
Èmi yóò sì rán àjàkálẹ̀-ààrùn sínú rẹ, èmi yóò sì mú kí ẹ̀jẹ̀ sàn ní ìgboro rẹ, ẹni ti á pa yóò ṣubú ní àárín rẹ, pẹ̀lú idà lára rẹ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, nígbà náà wọn yóò mọ̀ wí pé èmi ni Olúwa.
24 Og for Israels Hus skal der ikke ydermere være en Torn, som stikker, eller en Tidsel, som smerter, af alle dem, som ere trindt omkring dem, som haane dem, og de skulle fornemme, at jeg er den Herre, Herre.
“‘Kì yóò sì ṣí ẹ̀gún tí ń gun ni ní ilẹ̀ Israẹli mọ́, tàbí ẹ̀gún bíbani nínú jẹ́ ti gbogbo àwọn tí wọn wà ní àyíká wọn, tí wọ́n sì ń fi ojú yẹpẹrẹ wò wọ́n, nígbà náà ni wọn yóò mọ́ wí pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.
25 Saa siger den Herre, Herre: Naar jeg samler Israels Hus hjem fra Folkene, iblandt hvilke de ere adspredte, da vil jeg helliggøre mig ved dem for Hedningernes Øjne, og de skulle bo i deres Land, som jeg har givet min Tjener Jakob.
“‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí èmi yóò bá sa àwọn ènìyàn Israẹli jọ kúrò ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti fọ́nká sí, tí a ó sì yà mí sí mímọ́ láàrín wọn lójú àwọn aláìkọlà. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ní ilẹ̀ àwọn tìkálára wọn, èyí tí mo fún ìránṣẹ́ mi Jakọbu.
26 Og de skulle bo tryggelig derudi og bygge Huse og plante Vingaarde, ja, bo tryggelig; naar jeg holder Ret over alle dem, som haanede dem trindt omkring dem; og de skulle fornemme, at jeg Herren er deres Gud.
Wọn yóò sì máa gbé ní inú rẹ̀ ní àìléwu, wọn yóò sì kọ́lé, wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà; nítòótọ́ wọn yóò wà ní ìbàlẹ̀ àyà, nígbà tí èmi bá ti mú ìdájọ́ mi ṣẹ̀ sí ara àwọn tí ń ṣátá wọn ní gbogbo àyíká wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn.’”

< Ezekiel 28 >