< Ezekiel 23 >

1 Og Herrens Ord kom til mig saaledes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Du Menneskesøn! der var to Kvinder, Døtre af een Moder,
“Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà.
3 og de bolede i Ægypten, i deres Ungdom bolede de; der trykkedes deres Bryster, og der befølte man deres jomfruelige Barm.
Wọn ń ṣe panṣágà ní Ejibiti, wọn ń ṣe panṣágà láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn.
4 Og deres Navne vare: Ohola, den store, og Oholiba, hendes Søster; og de bleve mine og fødte Sønner og Døtre; og hvad deres Navne angaar, er Ohola Samaria, og Oholiba er Jerusalem.
Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Ohola, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Oholiba. Tèmi ni wọ́n, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Ohola ni Samaria, Oholiba sì ni Jerusalẹmu.
5 Og Ohola bolede og antog fremmede i mit Sted og brændte af Kærlighed til sine Bolere, til Assyrerne, som stode hende nær,
“Ohola ń ṣe panṣágà nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Asiria.
6 til dem, som vare klædte i blaat Purpur, Fyrster og Befalingsmænd, alle sammen yndige unge Karle, Ryttere, som rede paa Heste.
Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹṣin.
7 Og hun vendte sine bolerske Lyster til dem, til alle de udvalgte af Assurs Børn; og ved alle dem, til hvilke hun brændte af Kærlighed, ved alle deres Afguder besmittede hun sig.
O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Asiria gẹ́gẹ́ bí panṣágà obìnrin, o fi òrìṣà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́,
8 Og hun opgav ikke sit bolerske Væsen, som hun førte med sig fra Ægypten; thi de havde ligget hos hende i hendes Ungdom og havde befølt hendes jomfruelige Barm, og de havde udøst deres bolerske Lyster over hende.
kò fi ìwà panṣágà tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Ejibiti sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
9 Derfor gav jeg hende i hendes Boleres Haand, i Assurs Børns Haand, imod hvilke hun brændte af Kærlighed.
“Nítorí náà mo fi i sílẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, ará Asiria, tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
10 De blottede hendes Blusel, borttoge hendes Sønner og hendes Døtre og ihjelsloge hende selv med Sværdet; og hun fik Navn iblandt Kvinderne, da man havde holdt Dom over hende.
Wọ́n bọ́ ọ sí ìhòhò, wọ́n sì gba àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọn sì pa wọn pẹ̀lú idà. Ó di ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ láàrín àwọn obìnrin wọ́n sì fi ìyà jẹ ẹ́.
11 Der hendes Søster Oholiba saa det, da drev hun det værre med sin Elskov end den anden og med sin Bolen værre end hendes Søsters Bolen.
“Àbúrò rẹ̀ Oholiba rí èyí, síbẹ̀ nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ̀, Ó ba ara rẹ jẹ́ ju ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ.
12 Hun brændte af Kærlighed til Assyriens Børn, til Fyrster og Befalingsmænd, som stode hende nær og vare klædte paa det pragtfuldeste, Ryttere, som rede paa Heste, alle sammen yndige unge Karle.
Òun náà ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ará Asiria àwọn gómìnà àti àwọn balógun, jagunjagun nínú aṣọ ogun, àwọn tí ń gun ẹṣin, gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà.
13 Og jeg saa, at hun var besmittet, de gik begge een Vej.
Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.
14 Og hun drev sin Bolen end videre; der hun saa Mænd malede paa Væggen, Billeder af Kaldæer, malede med rødt,
“Ṣùgbọ́n ó tẹ̀síwájú nínú ṣíṣe panṣágà. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kaldea àwòrán pupa,
15 ombundne med Bælte om deres Lænder, med farvede Huer paa deres Hoveder, alle sammen af Anseelse som Høvedsmænd, efter Babels Børns Lignelse, hvis Fødeland er Kaldæa:
pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Babeli ọmọ ìlú Kaldea.
16 Da brændte hun af Kærlighed til dem, saa snart hun saa dem med sine Øjne, og hun sendte Bud til dem til Kaldæa.
Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán oníṣẹ́ sí wọn ni Kaldea.
17 Og Babels Børn kom til hende, til Elskovsleje, og de besmittede hende med deres Bolen, og hun besmittede sig ved dem; derefter vendte hendes Sjæl sig fra dem.
Àwọn ará Babeli wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ibùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú.
18 Og hun drev sin Bolen aabenbart og blottede sin Blusel; og min Sjæl vendte sig fra hende, ligesom min Sjæl havde vendt sig fra hendes Søster.
Nígbà tí ó tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ panṣágà rẹ̀ ní gbangba wọ́n sì tú u sí ìhòhò, mo yí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ ní ìtìjú, gẹ́gẹ́ bí mo ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
19 Dog udvidede hun sin bolerske Handel, idet hun kom sin Ungdoms Dage i Hu, da hun bolede i Ægyptens Land.
Síbẹ̀síbẹ̀ ó ń pọ̀ sí i nínú ìdàpọ̀ rẹ̀ bí ó ti ń rántí ìgbà èwe rẹ̀ tí ó jẹ́ panṣágà ní Ejibiti.
20 Og hun brændte af Kærlighed til deres Bolere, hvis Kød var som Aseners Kød, og hvis Brynde var som Hestes Brynde.
Nítorí ó fẹ́ olùfẹ́ àwọn olùfẹ́ wọn ní àfẹ́jù, tí àwọn tí nǹkan ọkùnrin wọn dàbí ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ẹni tí ìtújáde ara wọn dàbí ti àwọn ẹṣin.
21 Saa søgte du igen til din Ungdoms Skændsel, da de fra Ægypten befølte din Barm for din Ungdoms Brysters Skyld.
Báyìí ni ìwọ pe ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ìgbà èwe rẹ wá sí ìrántí, ní ti rírin orí ọmú rẹ láti ọwọ́ àwọn ará Ejibiti, fún ọmú ìgbà èwe rẹ.
22 Derfor, Oholiba! saa siger den Herre, Herre: Se, jeg vil opvække dine Bolere imod dig, dem, fra hvilke din Sjæl har vendt sig bort, og lade dem komme over dig trindt omkring fra:
“Nítorí náà, Oholiba, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò gbé olólùfẹ́ rẹ dìde sí ọ, àwọn tí o kẹ́yìn si ní ìtìjú, èmi yóò sì mú wọn dojúkọ ọ́ ní gbogbo ọ̀nà
23 Babels Børn og alle Kaldæer, Pekod og Skoa og Koa, alle Assurs Børn med dem, yndige unge Karle, Fyrster og Befalingsmænd alle sammen, Høvedsmænd og ansete Mænd, som alle sammen ride paa Heste.
àwọn ará Babeli àti gbogbo ara Kaldea àwọn ọkùnrin Pekodi àti Ṣoa àti Koa àti gbogbo ará Asiria pẹ̀lú wọn, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà, gbogbo àwọn gómìnà àti balógun, olórí oníkẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn onípò gíga, gbogbo àwọn tí ń gun ẹṣin.
24 Og de skulle komme imod dig med Rustvogne, Vogne og Hjul og med en Skare af Folk med store Skjolde og smaa Skjolde og Hjelme; de skulle lejre sig imod dig trindt omkring; og jeg vil overgive dem Dommen, og de skulle dømme dig efter deres Ret.
Wọn yóò wa dojúkọ ọ pẹ̀lú ohun ìjà, kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ẹrù àti pẹ̀lú ìwọ́jọpọ̀ ènìyàn; wọn yóò mú ìdúró wọn lòdì sí ọ ní gbogbo ọ̀nà pẹ̀lú asà ńlá àti kékeré pẹ̀lú àṣíborí. Èmi yóò yí ọ padà sí wọn fun ìjìyà, wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ gẹ́gẹ́ bí wọn tí tó.
25 Og jeg vil rette min Nidkærhed imod dig, at de skulle handle med dig i Grumhed, de skulle borttage din Næse og dine Øren, og hvad der bliver tilovers af dig, skal falde for Sværdet; de skulle tage dine Sønner og dine Døtre, og hvad der bliver tilovers af dig, skal fortæres med Ild.
Èmi yóò sì dojú ìbínú owú mi kọ ọ́, wọn yóò sì fìyà jẹ ọ́ ní ìrunú. Wọ́n yóò gé àwọn imú àti àwọn etí yín kúrò, àwọn tí ó kù nínú yín yóò ti ipá idà ṣubú. Wọn yóò mú àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin yín lọ, àwọn tí o kù nínú yín ni iná yóò jórun.
26 Og de skulle trække dine Klæder af dig og tage din Prydelses Tøj.
Wọn yóò sì kó àwọn aṣọ àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ iyebíye yín.
27 Saa vil jeg bringe din Skændsel til at høre op hos dig og din Bolen fra Ægyptens Land, og du skal ikke opløfte dine Øjne til dem og ikke ydermere komme Ægypten i Hu.
Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ panṣágà tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Ejibiti. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú ìpòùngbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Ejibiti mọ.
28 Thi saa siger den Herre, Herre: Se, jeg giver dig i deres Haand, som du hader, i deres Haand, som din Sjæl har vendt sig fra.
“Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó kórìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti ṣí kúrò.
29 Og de skulle handle med dig i Had og tage alt dit Erhverv og forlade dig nøgen og bar; og din bolerske Blusel og din Skændsel og din Bolen skal blive aabenbar.
Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ panṣágà rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti panṣágà rẹ.
30 Dette skal gøres imod dig, fordi du ved din Bolen er gaaet efter Hedningerne, fordi du besmittede dig ved deres Afguder.
Èmi yóò ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí sí ọ, nítorí ìwọ ti bá àwọn kèfèrí ṣe àgbèrè lọ, o sì fi àwọn òrìṣà wọn ba ara rẹ̀ jẹ́.
31 Du har gaaet paa din Søsters Vej, og jeg vil give hendes Bæger i din Haand.
Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn, Èmi yóò sì fi ago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
32 Saa siger den Herre, Herre: Du skal drikke af din Søsters Bæger, som er dybt og vidt; det skal blive til Latter og til Spot, da det holder meget i sig.
“Èyí yìí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ yóò mu nínú ago ẹ̀gbọ́n rẹ, ago tí ó tóbi tí ó sì jinnú: yóò mú ìfiṣẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá, nítorí tí ago náà gba nǹkan púpọ̀.
33 Du skal fyldes af Beruselse og Bedrøvelse; Forskrækkelses og Ødelæggelses Bæger er din Søsters, Samarias, Bæger.
Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́, ago ìparun àti ìsọdahoro ago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaria.
34 Og du skal drikke og udsuge det, og sønderbryde Skaarene deraf og afrive dine Bryster; thi jeg har talt det, siger den Herre, Herre.
Ìwọ yóò mú un ni àmugbẹ; ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya. Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
35 Derfor, saa siger den Herre, Herre: Fordi du glemte mig og kastede mig bag din Ryg, saa bær du nu ogsaa din Skændsel og din Bolen.
“Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí ìwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ.”
36 Og Herren sagde til mig: Du Menneskesøn! vil du dømme Ohola og Oholiba? forkynd dem dog deres Vederstyggeligheder;
Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Ohola àti Oholiba? Nítorí náà dojúkọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe,
37 thi de have bedrevet Hor, og der er Blod paa deres Hænder, og de have bedrevet Hor med deres Afguder; tilmed lode de deres Børn, som de havde født mig, gaa igennem Ilden for dem til at fortæres.
nítorí wọn ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn. Wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn; kódà wọ́n fi àwọn ọmọ wọn tí wọn bí fún ni ṣe ìrúbọ, gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún wọn.
38 Endnu dette have de gjort mig: De have besmittet min Helligdom paa den samme Dag og vanhelliget mine Sabbater.
Bákan náà ni wọ́n ti ṣe èyí náà sí mi. Ní àkókò kan náà wọn ba ibi mímọ́ mi jẹ́, wọ́n sì lo ọjọ́ ìsinmi mi ní àìmọ́.
39 Og der de havde slagtet deres Børn for deres Afguder, da gik de samme Dag i min Helligdom til at vanhellige den; og se, saaledes have de gjort midt udi mit Hus.
Ní ọjọ́ náà gan an wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà, wọn wọ ibi mímọ́ mi lọ wọn sì lò ó ní ìlòkulò. Ìyẹn ní wọn ṣe ní ilé mi.
40 Og de sendte ogsaa Bud efter Mænd, som kom langvejs fra; til hvilke der var sendt Bud, og se, de kom, for hvilke du badede dig, sminkede dine Øjne og prydede dig dejligt;
“Wọn tilẹ̀ rán oníṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn, nígbà tí wọ́n dé, ìwọ wẹ ara rẹ fún wọn, ìwọ kún ojú rẹ, ìwọ sì fi ọ̀ṣọ́ iyebíye sára.
41 og du satte dig paa en herlig Seng, og der var et Bord dækket foran den, og du havde sat min Røgelse og min Olie derpaa.
Ìwọ jókòó lórí ibùsùn ti o lẹ́wà, pẹ̀lú tábìlì tí a tẹ́ ní iwájú rẹ lórí, èyí tí o gbé tùràrí àti òróró tí ó jẹ́ tèmi kà.
42 Og Lyden af Bulderet blev stille der, og til Mændene af Folkehoben bragtes Drankere fra Ørken, og de satte Armbaand paa deres Hænder og en dejlig Krone paa deres Hoveder.
“Ariwo ìjọ ènìyàn tí kò bìkítà wà ní àyíká rẹ̀; a mú àwọn ara Sabeani láti aginjù pẹ̀lú àwọn ọkùnrin láti ara àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀gbà ọrùn ọwọ́ sí àwọn ọwọ́ obìnrin náà àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀, adé dáradára sì wà ní orí wọn.
43 Og jeg sagde om hende, som var for gammel til Hor: Nu skal man til Gavns bole med hende, ja, med hende.
Lẹ́yìn náà mo sọ̀rọ̀ nípa èyí tí ó lo ara rẹ̀ sá nípa panṣágà ṣíṣe, ‘Nísinsin yìí jẹ kí wọn lo o bí panṣágà, nítorí gbogbo ohun tí ó jẹ́ nìyẹn.’
44 Og man kom til hende, som man kommer til en bolersk Kvinde; saaledes kom de til Ohola og til Oholiba, de skændige Kvinder.
Wọn ba sùn bí ọkùnrin ti bá panṣágà sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe sùn pẹ̀lú obìnrin onífẹ̀kúfẹ̀ẹ́, Ohola àti Oholiba.
45 Og retfærdige Mænd, de skulle dømme dem, som Horkvinder dømmes, og som de Kvinder dømmes, der udøse Blod; thi de ere Horkvinder, og der er Blod paa deres Hænder.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin olódodo yóò pàṣẹ pé kí wọ́n fi ìyà jẹ àwọn obìnrin tí ó dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè tí ó sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nítorí pé panṣágà ni wọ́n ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn.
46 Thi saa siger den Herre, Herre: Jeg fører en Forsamling op imod dem og giver dem hen til Ustadighed og til Rov,
“Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Mú àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn wá sọ́dọ̀ wọn ki ó sì fi wọn lé ọwọ́ ìpayà àti ìkógun.
47 og de forsamlede skulle stene dem med Stene og sønderhugge dem med deres Sværd; de skulle ihjelslaa deres Sønner og deres Døtre og opbrænde deres Huse med Ild.
Àwọn ènìyànkénìyàn náà yóò sọ wọ́n ni òkúta, yóò sì gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà wọn; wọn ó sì pa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n ó sì jó àwọn ilé wọn kanlẹ̀.”
48 Og jeg vil udrydde Skændsel af Landet, og alle Kvinder skulle lade sig advare, at de ikke gøre efter eders Skændsel.
“Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ni ilẹ̀ náà, kí gbogbo àwọn obìnrin le gba ìkìlọ̀ kí wọn kí ó ma sì ṣe fi ara wé ọ.
49 Og de skulle lægge eders Skændsel paa eder, og I skulle bære Synderne, I begik med eders Afguder, og I skulle fornemme, at jeg er den Herre, Herre.
Ìwọ yóò sì jìyà fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì gba àbájáde àwọn ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà tí o dá. Nígbà náà ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.”

< Ezekiel 23 >