< 2 Mosebog 13 >

1 Og Herren talede til Mose og sagde:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Du skal hellige mig alle førstefødte; det som aabner hver Moders Liv iblandt Israels Børn, iblandt Folk og iblandt Kvæg, det hører mig til.
“Ẹ ya àwọn àkọ́bí yín ọkùnrin sọ́tọ̀ fún mi. Èyí ti ó bá jẹ́ àkọ́bí láàrín àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ tèmi, ìbá à ṣe ènìyàn tàbí ẹranko.”
3 Og Mose sagde til Folket: Kom denne Dag ihu, paa hvilken I ere udgangne af Ægypten, af Trælles Hus; thi med en vældig Haand udførte Herren eder herfra. Og syret Brød skal ikke ædes.
Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ rántí ọjọ́ òní, ọjọ́ ti ẹ jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, kúrò ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin ti ń ṣe ẹrú, nítorí Olúwa mú un yín jáde kúrò ni inú rẹ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára. Ẹ má ṣe jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú.
4 Paa denne Dag udgaa I, i Abid Maaned.
Òní, ní oṣù Abibu (oṣù kẹta ọdún tiwa) lónìí ẹ̀yin ń jáde kúrò ní Ejibiti.
5 Og det skal ske, naar Herren har indført dig i Kananitens og Hethitens og Amoritens og Hevitens og Jebusitens Land, hvilket han svor dine Fædre at ville give dig, et Land som flyder med Mælk og Honning, da skal du varetage denne Tjeneste i denne Maaned:
Ní ìgbà tí Olúwa mú un yín jáde wá sí ilẹ̀ Kenaani, Hiti, Amori, Hifi àti ilẹ̀ àwọn Jebusi; ilẹ̀ tí ó ti ṣe búra láti fi fún àwọn baba ńlá yín, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ẹ ni láti pa ìsìn yìí mọ́ ní oṣù yìí.
6 Syv Dage skal du æde usyrede Brød, og paa den syvende Dag er Højtid for Herren.
Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà nínú àti pé ní ọjọ́ keje ni àjọ yóò wà fún Olúwa.
7 Usyrede Brød skulle ædes syv Dage, og der skal ikke ses syret Brød hos dig, og ikke ses Surdejg hos dig i hele dit Landemærke.
Kí ẹ̀yin ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà fún ọjọ́ méje yìí; kó má ṣe sí ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe ní sàkání yín.
8 Og du skal forkynde for din Søn paa den samme Dag og sige: Dette sker for det, som Herren gjorde mig, der jeg drog ud af Ægypten.
Ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò sì sọ fún àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin, ‘Mo ń ṣe èyí nítorí ohun tí Olúwa ṣe fún mi nígbà tí èmi jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.’
9 Og det skal være dig til et Tegn paa din Haand og til en Ihukommelse imellem dine Øjne, for at Herrens Lov skal være i din Mund; thi Herren udførte dig af Ægypten med en stærk Haand.
Ṣíṣe èyí yóò wà fún àmì ní ọwọ́ rẹ, àti bí àmì ìrántí ni iwájú orí rẹ, tí yóò máa rán ọ létí òfin Olúwa ní ẹnu rẹ. Nítorí Olúwa mú ọ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá rẹ̀.
10 Og du skal tage Vare paa denne Skik til dens bestemte Tid, hvert Aar.
Ìwọ gbọdọ̀ pa òfin náà mọ́ ní àkókò tí a yàn bí ọdún tí ń gorí ọdún.
11 Og det skal ske, naar Herren har indført dig i Kananitens Land, som han svor dig og dine Fædre, og har givet dig det,
“Lẹ́yìn tí Olúwa tí mú ọ wá sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani tí ó sì fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí pẹ̀lú ìbúra fún ọ àti fún àwọn baba ńlá rẹ̀,
12 da skal du overgive til Herren alt det, som aabner Moders Liv; og alt det førstefødte, der falder af Kvæg, som hører dig til, hvad som er en Han, hører Herren til.
ìwọ yóò fi àkọ́bí inú rẹ fún Olúwa. Gbogbo àkọ́bí ti ó jẹ́ akọ ti ẹran ọ̀sìn rẹ ní ó jẹ́ ti Olúwa.
13 Og alt førstefødt af Asener skal du løse med et Lam, men dersom du ikke løser det, da skal du bryde Halsen paa det; men alle førstefødte af Mennesker iblandt dine Sønner skal du løse.
Ìwọ yóò fi ọ̀dọ́-àgùntàn ra àkọ́bí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ padà, ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá rà á padà, ǹjẹ́ kí ìwọ ṣẹ́ ẹ ní ọrùn, gbogbo àkọ́bí ọkùnrin ni kí ìwọ kí ó rà padà.
14 Og det skal ske, naar din Søn spørger dig ad herefter, sigende: Hvad er det? da skal du sige til ham: Herren udførte os af Ægypten, af Trælles Hus, med en vældig Haand.
“Yóò sí ṣe ní àwọn ọjọ́ tí ń bọ̀, ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín yóò béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni èyí túmọ̀ sí?’ Kí ìwọ kí ó sọ fún wọn pé, ‘Pẹ̀lú ọwọ́ agbára ní Olúwa fi mú wa jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti, kúrò ní oko ẹrú.
15 Thi det skete, fordi Farao havde forhærdet sig, saa han ikke lod os fare, at Herren ihjelslog alle førstefødte i Ægyptens Land, fra Menneskets førstefødte indtil Kvægets førstefødte; derfor ofrer jeg Herren alt det, som aabner Moders Liv, og som er Han, og jeg skal løse hver førstefødt blandt mine Sønner.
Ní ìgbà ti Farao ṣe orí kunkun, ti ó kọ̀ láti jẹ́ kí a lọ, Olúwa pa gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, àti ènìyàn àti ẹranko. Ìdí èyí ni àwa fi ń fi gbogbo àkọ́bí tí í ṣe akọ rú ẹbọ sí Olúwa láti fi ṣe ìràpadà fún àwọn àkọ́bí wa ọkùnrin.’
16 Og det skal være til et Tegn paa din Haand og til Span imellem dine Øjne, at Herren udførte os af Ægypten med en vældig Haand.
Èyí yóò sì jẹ́ àmì ni ọwọ́ yín àti àmì ní iwájú orí yín pé Olúwa mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá.”
17 Og det skete, der Farao lod Folket fare, da førte Gud dem ikke ad Vejen til Filistrene, skønt den var nærmest; thi Gud sagde: Maaske det kunde fortryde Folket, naar de se Striden, og de kunde vende tilbage til Ægypten.
Ní ìgbà tí Farao jẹ́ kí àwọn ènìyàn ó lọ, Ọlọ́run kò mú wọn tọ ojú ọ̀nà ti ó la orílẹ̀-èdè àwọn Filistini kọjá, bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ọ̀nà náà kúrú. Nítorí Ọlọ́run sọ pé, “Bí wọ́n bá dojúkọ ogun, wọ́n lè yí ọkàn wọn padà kí wọ́n padà sí ilẹ̀ Ejibiti.”
18 Og Gud førte Folket omkring ad Vejen igennem Ørkenen mod det røde Hav; og Israels Børn droge bevæbnede af Ægyptens Land.
Nítorí náà Ọlọ́run darí àwọn ènìyàn rọkọ gba ọ̀nà aginjù ní apá Òkun Pupa. Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú ìmúra fún ogun.
19 Og Mose tog Josefs Ben med sig; thi denne havde taget en stærk Ed af Israels Børn og sagt: Gud skal visselig besøge eder, og I skulle føre mine Ben op herfra med eder.
Mose kó egungun Josẹfu pẹ̀lú rẹ̀ nítorí Josẹfu tí mú kí àwọn ọmọ Israẹli búra. Ó ti wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò dìde fún ìrànlọ́wọ́ yín ẹ sì gbọdọ̀ kó egungun mi lọ pẹ̀lú yín kúrò níhìn-ín yìí.”
20 Saa rejste de fra Sukot, og de lejrede sig i Etham paa Grænsen af Ørken.
Wọ́n sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n láti Sukkoti lọ, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu ní etí aginjù.
21 Og Herren gik foran dem om Dagen i en Skystøtte for at lede dem paa Vejen, om Natten i en Ildstøtte for at lyse for dem, at de kunde vandre Dag og Nat.
Olúwa sì ń lọ níwájú wọn, nínú ọ̀wọ̀n ìkùùkuu ní ọ̀sán láti máa ṣe amọ̀nà wọn àti ní òru nínú ọ̀wọ̀n iná láti máa tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn, kí wọn lè máa lọ nínú ìrìnàjò wọn ní tọ̀sán tòru.
22 Han lod ikke Skystøtten vige om Dagen eller Ildstøtten om Natten, den blev for Folkets Aasyn.
Ìkùùkuu náà kò kúrò ní ààyè rẹ̀ ní ọ̀sán, bẹ́ẹ̀ ni, ọ̀wọ̀n iná kò kúrò ní ààyè rẹ̀ ni òru, ní iwájú àwọn ènìyàn náà.

< 2 Mosebog 13 >