< 5 Mosebog 29 >

1 Disse ere den Pagts Ord, som Herren befalede Mose at gøre med Israels Børn i Moabs Land, foruden den Pagt, som han gjorde med dem ved Horeb.
Èyí ni àwọn ìpinnu májẹ̀mú tí Olúwa pàṣẹ fún Mose láti ṣe pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní Moabu, ní àfikún májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú u wọn ní Horebu.
2 Og Mose kaldte ad al Israel og sagde til dem: I have set alt det, som Herren gjorde for eders Øjne i Ægyptens Land ved Farao og alle hans Tjenere og ved hans ganske Land,
Mose pàṣẹ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì wí fún wọn wí pé, ojú rẹ ti rí gbogbo ohun tí Olúwa ti ṣe ní Ejibiti sí Farao àti, sí gbogbo àwọn ìjòyè e rẹ̀ àti sí ilẹ̀ ẹ rẹ̀.
3 de store Forsøgelser, som dine Øjne have set, de Tegn og de store underlige Ting.
Pẹ̀lú ojú ara rẹ ni ìwọ rí àwọn ìdánwò ńlá náà, àwọn iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá.
4 Men Herren har ikke givet eder Hjerte til at forstaa eller Øjne til at se med eller Øren til at høre med indtil denne Dag.
Ṣùgbọ́n títí di àsìkò yìí Olúwa kò fi ọkàn ìmòye tàbí ojú tí ó ń rí tàbí etí tí ó n gbọ́ fún ọ.
5 Og fyrretyve Aar har jeg ladet eder vandre i Ørken; eders Klæder bleve ikke opslidte paa eder, og dine Sko bleve ikke opslidte paa din Fod.
Nígbà ogójì ọdún tí mò ń tọ́ yín ṣọ́nà ní aginjù, aṣọ ọ̀ rẹ kò gbó tàbí bàtà ẹsẹ̀ rẹ.
6 I have ikke ædet Brød og ej drukket Vin eller stærk Drik, for at I skulle vide, at jeg er Herren eders Gud.
O kò jẹ oúnjẹ tàbí mu wáìnì kankan tàbí rú ohun mímu mìíràn. Mo ṣe èyí kí o lè mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ.
7 Og der I kom til dette Sted, da uddrog Sihon, Kongen af Hesbon, og Og, Kongen af Basan, imod os til Krig, og vi sloge dem.
Nígbà tí o dé ibí yìí, Sihoni ọba Heṣboni àti Ogu ọba Baṣani jáde wá láti bá ọ jà, ṣùgbọ́n a ṣẹ́gun wọn.
8 Og vi indtoge deres Land, og vi gave Rubeniten og Gaditen og den halve Manasse Stamme det til Arv.
A gba ilẹ̀ wọn a sì fi fún àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase bí ogún.
9 Saa holder denne Pagts Ord og gører efter dem, at I kunne gøre viseligen alt det, som I skulle gøre.
Nítorí náà, ẹ pa májẹ̀mú yìí mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n, kí ẹ̀yin kí ó lè máa rí ire nínú gbogbo ohun tí o bá ń ṣe.
10 I staa i Dag alle sammen for Herren eders Guds Ansigt, eders Øverster, eders Stammer, eders Ældste og eders Fogeder, hver Mand i Israel,
Gbogbo yín ń dúró lónìí yìí níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ: àwọn olórí yín, àwọn ẹ̀yà yín, àwọn àgbàgbà yín àti àwọn ìjòyè yín, àní gbogbo àwọn ọkùnrin mìíràn ní Israẹli,
11 eders smaa Børn, eders Hustruer og din fremmede, som er midt i dine Lejre, baade din Vedhugger og din Vanddrager,
pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọ̀ rẹ àti ìyàwó ò rẹ àti àwọn àjèjì tí wọ́n ń gbé ní àgọ́ ọ̀ rẹ, tí ó ké pópòpó igi rẹ, tí ó sì gbé omi rẹ.
12 for at du skal træde over i Herren din Guds Pagt og i hans edelige Forbund, som Herren din Gud gør med dig i Dag;
O dúró níhìn-ín yìí kí o lè wọ inú májẹ̀mú pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, májẹ̀mú tí Olúwa ń ṣe pẹ̀lú rẹ lónìí yìí àti tí òun dè pẹ̀lú ìbúra,
13 at han maa oprejse dig i Dag sig til et Folk, og han maa være dig til Gud, som han har talet til dig, og som han har tilsvoret dine Fædre, Abraham, Isak og Jakob.
láti jẹ́wọ́ rẹ lónìí yìí bí ènìyàn an rẹ̀, pé kí ó lè jẹ́ Ọlọ́run rẹ bí ó ti ṣèlérí àti bí ó ti ṣe ìbúra fún àwọn baba à rẹ Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
14 Og ikke med eder alene gør jeg denne Pagt og dette edelige Forbund,
Èmi ń ṣe májẹ̀mú yìí, pẹ̀lú ìbúra rẹ̀, kì í ṣe fún ìwọ nìkan
15 men med den, som her er og staar i Dag med os for Herren vor Guds Ansigt, og med den, som ikke er her i Dag med os.
tí ó dúró níbí pẹ̀lú wa lónìí níwájú Olúwa Ọlọ́run wa ṣùgbọ́n àti fún gbogbo àwọn tí kò sí níbí lónìí.
16 Thi I vide, at vi boede i Ægyptens Land, og at vi droge midt igennem hos Hedningerne, hvor I droge igennem;
Ìwọ fúnra à rẹ mọ bí a ṣe gbé ní Ejibiti àti bí a ṣe kọjá láàrín àwọn orílẹ̀-èdè nílẹ̀ ibí yìí.
17 og I saa deres Vederstyggeligheder og deres stygge Afguder: Træ og Sten, Sølv og Guld, som vare hos dem,
Ìwọ rí láàrín wọn ìríra wọn, àwọn ère àti àwọn òrìṣà igi àti ti òkúta, ti fàdákà àti ti wúrà.
18 for at der ikke skal være iblandt eder Mand eller Kvinde eller Slægt eller Stamme, som vender sit Hjerte i Dag fra Herren vor Gud til at gaa bort og tjene disse Hedningers Guder; at der ikke skal være en Rod iblandt eder, som bærer Gift og Malurt;
Rí i dájú pé kò sí ọkùnrin tàbí obìnrin, ìdílé tàbí ẹ̀yà láàrín yín lónìí tí ọkàn an rẹ̀ yóò yí kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa láti lọ àti láti sin àwọn ọlọ́run àwọn orílẹ̀-èdè náà; rí i dájú pé kò sí gbòǹgbò tí ó ń mú irú èso kíkan bẹ́ẹ̀ jáde láàrín yín.
19 og det skal ske, naar han hører denne Forbandelses Ord, han da velsigner sig i sit Hjerte og siger: Det skal gaa mig vel, endskønt jeg vandrer i mit Hjertets Stivhed, for at det vædede maa rives bort med det tørstige.
Nígbà tí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá gbọ́ ìbúra yìí, kí ó gbàdúrà ìbùkún sórí ara rẹ̀ nígbà náà ni kí ó ronú, “Èmi yóò wà ní àlàáfíà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fi àáké kọ́rí nípa lílọ nínú ọ̀nà ti ara à mi.” Èyí yóò mú àjálù wá sórí ilẹ̀ tútù àti sórí ilẹ̀ gbígbẹ bákan náà
20 Herren vil ikke forlade ham det; thi Herrens Vrede og hans Nidkærhed skal da ryge imod denne Mand, saa al den Forbandelse, som er skreven i denne Bog, skal ligge paa ham, og Herren skal udslette hans Navn under Himmelen,
Olúwa kì yóò ní ìfẹ́ sí àti dáríjì í; ìbínú àti ìtara rẹ̀ yóò jó ọkùnrin náà. Gbogbo àwọn ègún tí a kọ sínú ìwé yìí yóò wá sórí i rẹ̀, Olúwa yóò sì yọ orúkọ rẹ̀ kúrò lábẹ́ ọ̀run.
21 og Herren skal fraskille ham til det onde fra alle Israels Stammer, efter al den Pagts Forbandelser, som er skreven i denne Lovbog.
Olúwa yóò sì yọ òun nìkan kúrò nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli fún àjálù, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ègún májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé òfin yìí.
22 Og den følgende Slægt skal sige, ja eders Børn, som skulle opstaa efter eder, og den fremmede, som skal komme fra et langt bortliggende Land, naar de se dette Lands Plager og de Sygdomme, med hvilke Herren har hjemsøgt det,
Àwọn ọmọ rẹ tí ó tẹ̀lé ìran rẹ lẹ́yìn àti àwọn àjèjì tí ó wá láti ilẹ̀ jíjìn yóò rí wàhálà tí ó wá sórí ilẹ̀ àti àwọn ààrùn pẹ̀lú tí Olúwa mú bá ọ.
23 Svovl og Salt, Brand over hele Landet, saa at det ikke kan besaas, ej heller give Grøde, og ingen Urt kan opvokse derudi, ligesom Sodoma og Gomorra, Adma og Zeboim bleve omkastede, hvilke Herren omkastede i sin Vrede og i sin Hastighed;
Gbogbo ilẹ̀ náà yóò di imí-oòrùn, àti iyọ̀, àti ìjóná tí a kò lè fi ọkàn sí, tàbí tí kò lè so èso tàbí tí koríko kò lè hù nínú u rẹ̀, yóò dàbí ìbìṣubú Sodomu àti Gomorra, Adma àti Seboimu, tí Olúwa bì ṣubú nínú ìbínú rẹ̀, àti ìkáàánú rẹ̀.
24 ja, da skulle alle Folk sige: Hvorfor har Herren gjort saaledes imod dette Land? hvad er dette for en stor brændende Vrede?
Gbogbo orílẹ̀-èdè yóò béèrè pé, “Kí ló dé tí Olúwa fi ṣe èyí sí ilẹ̀ yìí? Kí ni a lè mọ ooru ìbínú ńlá yìí sí?”
25 Da skal man sige: Fordi de have forladt Herrens, deres Fædres Guds, Pagt, som han gjorde med dem, der han udførte dem af Ægyptens Land;
Ìdáhùn yóò sì jẹ́ báyìí: “Nítorí tí ènìyàn yìí kọ Olúwa Ọlọ́run baba wọn sílẹ̀, májẹ̀mú tí ó ti bá wọn dá nígbà tí ó mú wọn jáde wá láti Ejibiti.
26 og de gik bort og tjente andre Guder og tilbade dem, de Guder, som de ikke kendte, og som han ikke havde tildelt dem:
Wọ́n lọ wọ́n sì sin ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún wọn, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀, ọlọ́run tí kò fi fún wọn.
27 Derfor er Herrens Vrede optændt imod dette Land, saa at han har ført al den Forbandelse over det, som er skrevet i denne Bog,
Nígbà náà ni ìbínú Olúwa ru sí ilẹ̀ wọn, dé bi pé ó mú gbogbo ègún tí a kọ sínú ìwé yìí wá sórí i rẹ̀.
28 og Herren har oprykket dem af deres Land i Vrede og i Hastighed og i stor Fortørnelse og bortkastet dem til et andet Land, som det ses paa denne Dag;
Ní ìbínú àti ní ìkáàánú, àti ní ìrunú ńlá, Olúwa sì fà wọ́n tu kúrò ní ilẹ̀ wọn, ó sì lé wọn lọ sí ilẹ̀ mìíràn, bí ó ti rí ní òní yìí.”
29 de skjulte Ting ere for Herren vor Gud; men de aabenbare ere for os og for vore Børn evindeligen, at vi skulle gøre efter alle denne Lovs Ord.
Ohun ìkọ̀kọ̀ jẹ́ ti Olúwa Ọlọ́run wa, ṣùgbọ́n ohun tí a fihàn jẹ́ ti wa àti ti àwọn ọmọ wa títí láé, kí a lè tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.

< 5 Mosebog 29 >