< 5 Mosebog 21 >

1 Naar der bliver funden en ihjelslagen i Landet, hvilket Herren din Gud giver dig at eje, liggende paa Marken, og det ikke er vitterligt, hvo der har slaaet ham ihjel:
Tí a bá rí ọkùnrin tí a pa, ní ìdùbúlẹ̀ ní pápá nínú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ láti jogún, tí a kò sì mọ ẹni tí ó pa á,
2 Da skulle dine Ældste og dine Dommere gaa ud, og de skulle maale til de Stæder, som ere rundt omkring den ihjelslagne.
àwọn àgbàgbà yín yóò jáde lọ láti wọn jíjìnnà ibi òkú sí ìlú tí ó wà nítòsí.
3 Og den Stad, som er næst ved den ihjelslagne, den Stads Ældste skulle tage en Kvie af Kvæget, som man ikke har arbejdet med, og som ikke har draget i Aag;
Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí òkú yóò mú ẹgbọrọ abo màlúù tí kò ì ṣiṣẹ́ rí àti tí kò sì fà nínú àjàgà rí,
4 og de Ældste af samme Stad skulle føre Kvien ned til en Dal med stedse rindende Vand, i hvilken der ikke arbejdes eller saas; og der i Dalen skulle de bryde Nakken paa Kvien.
kí àwọn àgbàgbà ìlú náà kí wọn mú ẹgbọrọ abo màlúù náà sọ̀kalẹ̀ wá sí àfonífojì tí ó ní omi ṣíṣàn kan, tí a kò ro, tí a kò sì gbìn, kí wọn kí ó sì ṣẹ́ ọrùn ẹgbọrọ màlúù náà níbẹ̀ ní àfonífojì náà.
5 Saa skulle Præsterne, Levi Sønner, gaa frem; thi Herren din Gud har udvalgt dem til at tjene sig og til at velsigne i Herrens Navn; og al Trætte og al Plage skal afgøres efter deres Ord.
Àwọn àlùfáà, ọmọ Lefi yóò wá síwájú, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n láti ṣe ìránṣẹ́ fún un àti láti bùkún ní orúkọ Olúwa àti láti parí gbogbo ẹjọ́ àríyànjiyàn àti ọ̀rọ̀ ìlú.
6 Og alle de Ældste af den samme Stad, de som ere næst ved den ihjelslagne, skulle to deres Hænder over Kvien, som Nakken er brudt paa i Dalen.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí yóò wẹ ọwọ́ wọn lórí ẹgbọrọ abo màlúù tí a ti kan ọrùn rẹ̀ ní àfonífojì,
7 Og de skulle vidne og sige: Vore Hænder have ikke udøst dette Blod, og vore Øjne have ikke set det.
wọn yóò sì sọ pé, “Ọwọ́ wa kò ta ẹ̀jẹ̀ yìí sílẹ̀, tàbí kí ojú wa rí i ní títa sílẹ̀.”
8 Son dit Folk Israel, som du, Herre! har forløst, og læg ikke uskyldigt Blod paa dit Folk Israel; saa bliver Blodet sonet for dem.
Dáríjì, Olúwa, àwọn ènìyàn rẹ ni Israẹli, tí ìwọ ti dá sílẹ̀, àti kí ìwọ má ṣe gba ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ ní àárín àwọn ènìyàn rẹ ní Israẹli. Ṣùgbọ́n kí a dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ yìí jì.
9 Og du skal borttage det uskyldige Blod af din Midte; thi du skal gøre det, som er ret for Herrens Øjne.
Nígbà náà ni ìwọ wẹ̀ kúrò láàrín rẹ ẹ̀bi títa ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí o ti ṣe èyí tí ó tọ́ níwájú Olúwa.
10 Naar du uddrager i Krigen imod dine Fjender, og Herren din Gud giver dem i din Haand, saa at du fører dem i Fangenskab,
Nígbà tí o bá lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá rẹ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ tí o sì mú àwọn ìgbèkùn,
11 og du ser iblandt Fangerne en Kvinde, som er dejlig af Skikkelse, og du faar Lyst til hende, og du tager dig hende til Hustru:
tí o sì rí obìnrin tí ó dára lára àwọn ìgbèkùn, tí o sì ní ìfẹ́ sí i, o lè mu u gẹ́gẹ́ bí aya à rẹ.
12 Da skal du føre hende midt ind i dit Hus, og hun skal lade sit Hoved rage og skære sine Negle,
Mú u wá sí ilé e rẹ kí o sì jẹ́ kí ó fá irun orí rẹ̀, gé èékánná an rẹ̀,
13 og hun skal bortlægge sit Fangenskabs Klæder fra sig, og hun skal blive i dit Hus og begræde sin Fader og sin Moder en Maanedstid; og derefter maa du gaa til hende og ægte hende, og hun skal blive dig til Hustru.
kí o sì mú aṣọ tí ó wọ̀ nígbà tí ó di ìgbèkùn sí ẹ̀gbẹ́ kan. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ń gbé ilé rẹ tí ó sì ti ṣọ̀fọ̀ baba àti ìyá rẹ̀ fún odidi oṣù kan, nígbà náà ni o lè tọ̀ ọ́ lọ kí o sì ṣe ọkọ rẹ̀ kí ó jẹ́ aya rẹ.
14 Men det skal ske, om du ikke har Behagelighed til hende, da skal du lade hende fare efter hendes Sjæls Begæring og ikke sælge hende for Penge; du skal ikke behandle hende som Trælkvinde, fordi du har krænket hende.
Bí inú rẹ̀ kò bá sì dùn sí i, jẹ́ kí ó lọ sí ibikíbi tí ó bá fẹ́. O kò gbọdọ̀ tà á tàbí lò ó bí ẹrú, lẹ́yìn ìgbà tí o ti dójútì í.
15 Om en Mand har to Hustruer, een, som han elsker, og een, som han hader, og de have født ham Børn, baade den, han elsker, og den, han hader, og den førstefødte Søn er den forhadtes:
Bí ọkùnrin kan bá ní ìyàwó méjì, tí ó sì fẹ́ ọ̀kan ṣùgbọ́n tí kò fẹ́ èkejì, tí àwọn méjèèjì sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un ṣùgbọ́n tí àkọ́bí jẹ́ ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn.
16 Da skal det ske paa den Dag, han lader sine Børn arve det, han har, at han ikke skal have Magt til at gøre Sønnen af hende, som han elsker, til den førstefødte, i Stedet for den førstefødte Søn af hende, som han hader;
Nígbà tí ó bá ń pín ohun ìní rẹ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, kò gbọdọ̀ fi ẹ̀tọ́ àkọ́bí fún ọmọ ìyàwó tí kò fẹ́ràn.
17 men han skal kendes ved den førstefødte Søn af hende, som han hader, og give ham dobbelt Lod af alt det, der findes hos ham; thi han er hans første Kraft, ham hører Førstefødsels Ret til.
Ó ní láti fi ipò ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn fun un gẹ́gẹ́ bí àkọ́bí i rẹ̀ nípa fífún un ní ìlọ́po ìpín gbogbo ohun tí ó ní. Ọmọ yẹn ni àmì àkọ́kọ́ agbára baba rẹ̀. Ẹ̀tọ́ àkọ́bí jẹ́ tirẹ̀.
18 Om en Mand har en modvillig og genstridig Søn, som ikke lyder sin Faders Røst og sin Moders Røst, og de tugte ham, og han vil ikke lyde dem,
Bí ọkùnrin kan bá ní aláìgbọ́ràn tàbí ọlọ̀tẹ̀ ọmọ tí kò gbọ́rọ̀ sí baba àti ìyá rẹ̀ tí kò sì ní í gbà tí wọ́n bá ń bá a wí,
19 da skulle hans Fader og hans Moder tage fat paa ham og føre ham frem til de Ældste i hans Stad og til hans Steds Port,
baba àti ìyá rẹ̀ yóò gbá a mú, wọn yóò mu wá fún àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú u rẹ̀.
20 og de skulle sige til de Ældste i hans Stad: Denne vor Søn er modvillig og genstridig, han vil ikke lyde vor Røst, en Fraadser og Dranker;
Wọn yóò sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ọmọ wa yìí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀. Kò ní gbọ́rọ̀ sí wa lẹ́nu. Ọ̀jẹun àti ọ̀mùtípara ni.”
21 saa skulle alle Mændene i hans Stad stene ham med Stene, og han skal dø; og du skal borttage den onde af din Midte, at al Israel maa høre det og frygte.
Nígbà náà ni gbogbo ọkùnrin ìlú rẹ̀ yóò sọ ọ́ ní òkúta pa. Ìwọ yóò sì mú ìwà ibi kúrò láàrín yín, gbogbo Israẹli yóò gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n.
22 Og naar en Mand har gjort en Synd, som har fortjent Dødsdom, og han dødes, og du hænger ham paa et Træ,
Bí ọkùnrin kan tí ó jẹ̀bi ẹ̀sùn bá ní láti kú tí ó sì kú, tí a sì gbé òkú rẹ̀ kọ́ sára igi,
23 da skal hans Krop ikke blive Natten over paa Træet, men du skal begrave ham paa den samme Dag; thi den, som bliver hængt, er en Guds Forbandelse; og du skal ikke gøre dit Land urent, som Herren din Gud giver dig til Arv.
o kò gbọdọ̀ fi òkú rẹ̀ sílẹ̀ sára igi ní gbogbo òru. Gbìyànjú láti sin ín ní ọjọ́ náà gan an, nítorí ẹni tí a bá gbé kọ́ sórí igi wà lábẹ́ ègún Ọlọ́run. Ìwọ kò gbọdọ̀ ba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún jẹ́.

< 5 Mosebog 21 >