< 5 Mosebog 20 >

1 Naar du uddrager til Krig imod din Fjende, og du ser Heste og Vogne, ja Folk, flere end du, da skal du ikke frygte for dem; thi Herren din Gud er med dig, han, som førte dig op af Ægyptens Land.
Nígbà tí o bá lọ sí ogun pẹ̀lú ọ̀tá rẹ, tí o sì rí ẹṣin àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti ológun tí ó jù ọ́ lọ, má ṣe bẹ̀rù u wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ń mú ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, yóò wà pẹ̀lú rẹ.
2 Og det skal ske, naar I nærme eder Striden, da skal Præsten gaa frem og tale til Folket.
Nígbà tí o bá fẹ́ lọ jagun, àlùfáà yóò wá síwájú, yóò sì bá ọmọ-ogun sọ̀rọ̀,
3 Og han skal sige til dem: Hør, Israel! I nærme eder i Dag til Striden imod eders Fjender, lader eders Hjerte ikke blive modløst, frygter ikke og forfærdes ikke og gruer ikke for deres Ansigt!
yóò sì wí pé, “Gbọ́, ìwọ Israẹli, lónìí ò ń jáde lọ sójú ogun sí ọ̀tá rẹ. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín ṣojo tàbí bẹ̀rù; ẹ má ṣe jáyà tàbí kí ẹ fi ààyè fún ìjayà níwájú u wọn.
4 Thi Herren eders Gud er den, som gaar med eder, at stride for eder imod eders Fjender for at frelse eder.
Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín ní bá yín lọ, láti bá àwọn ọ̀tá yín jà fún yín, láti gbà yín là.”
5 Men Fogederne skulle tale til Folket og sige: Er der en Mand, som har bygget et nyt Hus og ikke indviet det, han gaa hen og vende tilbage til sit Hus, at han ikke skal dø i Krigen, og en anden Mand skal indvie det.
Àwọn olórí ogun yóò sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó kọ́ ilé tuntun tí kò sì tì ì yà á sọ́tọ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí ó lè kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbà á.
6 Og er der en Mand, som har plantet en Vingaard og ikke nydt Frugten af den, han gaa hen og vende tilbage til sit Hus, at han ikke skal dø i Krigen, og en anden Mand skal nyde den første Frugt af den.
Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó gbin ọgbà àjàrà kan tí kò sì tí ì bẹ̀rẹ̀ sí ń gbádùn rẹ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbádùn rẹ̀.
7 Og er der en Mand, som har trolovet sig en Hustru og ikke har taget hende til Ægte, han gaa hen og vende tilbage til sit Hus, at han ikke skal dø i Krigen, og en anden Mand skal tage hende.
Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó wá ògo obìnrin kan tí kò ì tí ì fẹ́ ẹ? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì fẹ́ ẹ.”
8 Og Fogederne skulle blive ved at tale til Folket og sige: Er der en Mand, som er frygtagtig og blødhjertet, han gaa hen og vende tilbage til sit Hus, at han ikke skal gøre sine Brødres Hjerte mistrøstigt, som hans eget Hjerte er.
Nígbà náà ni olórí yóò tún fi kún un pé, “Ǹjẹ́ ọkùnrin kankan ń bẹ̀rù tàbí páyà? Jẹ́ kí ó lọ ilé nítorí kí arákùnrin rẹ̀ má ba à wá tún dáyà fò ó.”
9 Og det skal ske, naar Fogederne have endt at tale til Folket, da skulle de beskikke Hærførere i Spidsen for Folket.
Nígbà tí olórí ogun bá ti dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ sí àwọn ènìyàn, wọn yóò yan olórí ogun lórí i rẹ̀.
10 Naar du nærmer dig til en Stad til at stride imod den, da skal du tilbyde den Fred.
Nígbà tí ó bá súnmọ́ iwájú láti dojúkọ ìlú kan láti bá a jà, nígbà náà ni kí ó fi àlàáfíà lọ̀ ọ́.
11 Og det skal ske, om den svarer dig fredelig og lader op for dig, da skal alt det Folk, som findes i den, være dig skatskyldigt og tjene dig.
Tí wọ́n bá dá ọ lóhùn àlàáfíà, tí wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn, gbogbo àwọn tó wà níbẹ̀ yóò máa jẹ́ olùsìn fún ọ, wọn ó sì máa sìn ọ́.
12 Men dersom den ikke vil gøre Fred med dig, men føre Krig imod dig, da skal du belejre den.
Tí wọ́n bá kọ̀ láti bá ọ ṣe àlàáfíà ṣùgbọ́n tí wọ́n bá gbóguntì ọ́, nígbà náà ni kí ìwọ gbà á.
13 Og Herren din Gud skal give den i din Haand, og du skal slaa alt Mandkøn i den med skarpe Sværd.
Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá fi lé ọ lọ́wọ́, kí ẹ̀yin kí ó fi ojú idà pa gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà níbẹ̀.
14 Kun Kvinderne og de smaa Børn og Kvæget og alt det, som er i Staden, alt Byttet deraf maa du røve for dig, og du skal nyde dine Fjenders Bytte, som Herren din Gud har givet dig.
Ní ti obìnrin, àwọn ọmọdé, ohun ọ̀sìn àti gbogbo ohun tí ó kù nínú ìlú náà, o lè mú ìwọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìkógun fún ara rẹ. O sì lè lo ìkógun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá rẹ.
15 Saaledes skal du gøre mod alle Stæderne, som ere saare langt fra dig, og som ikke ere af disse Hedningers Stæder.
Báyìí ni ìwọ yóò ṣe sí gbogbo ìlú tí wọ́n wà ní ọ̀nà jíjìn sí ọ tí wọn kò sì tara àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ rẹ.
16 Kun i disse Folks Stæder, som Herren din Gud giver dig til Arv, skal du ikke lade leve noget, som drager Aande.
Ṣùgbọ́n, nínú àwọn ìlú ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, má ṣe dá ohun ẹlẹ́mìí kankan sí.
17 Thi du skal bandlyse dem, nemlig Hethiterne og Amoriterne, Kananiterne og Feresiterne, Heviterne og Jebusiterne, som Herren din Gud har budet dig,
Pa wọ́n run pátápátá, àwọn ọmọ Hiti, ọmọ Amori, ọmọ Kenaani, ọmọ Peresi, ọmọ Hifi, ọmọ Jebusi gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pa á láṣẹ fún ọ.
18 paa det at de ikke skulle lære eder at gøre efter alle deres Vederstyggeligheder, som de have gjort for deres Guder, og I skulle synde mod Herren eders Gud.
Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kọ́ ọ láti tẹ̀lé gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ń ṣe nínú sí sin àwọn ọlọ́run wọn, ìwọ yóò sì ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
19 Naar du belejrer en Stad mange Dage og strider imod den for at indtage den, da skal du ikke ødelægge dens Træer ved at hugge ned paa dem med Øksen, thi du skal æde af dem og ikke afhugge dem; thi mon Markens Træer ere Mennesker, som af dig skulle belejres?
Nígbà tí o bá dó ti ìlú kan láti ọjọ́ pípẹ́, ẹ bá wọn jà láti gbà á, má ṣe pa àwọn igi ibẹ̀ run nípa gbígbé àáké lé wọn, nítorí o lè jẹ èso wọn. Má ṣe gé wọn lulẹ̀. Nítorí igi igbó ha á ṣe ènìyàn bí, tí ìwọ ó máa dó tì rẹ̀.
20 Kun de Træer, som du ved om, at det ikke er Frugttræer, dem maa du ødelægge og afhugge, at du kan bygge Bolværk imod Staden, som fører Krig imod dig, indtil den falder.
Ṣùgbọ́n ìwọ lè gé àwọn igi tí o mọ̀ pé wọn kì í ṣe igi eléso lulẹ̀ kí o sì lò wọ́n láti kọ́ ìṣọ́ sí ìlú tí ó ń bá ọ jagun, títí tí yóò fi ṣubú.

< 5 Mosebog 20 >