< 5 Mosebog 14 >
1 Iere Herren eders Guds Børn, I skulle ikke saare eder selv eller rage eder imellem eders Øjne for en død.
Ọmọ Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́: nítorí náà, ẹ má ṣe ya ara yín ní abẹ. Ẹ má ṣe gé irun iwájú orí yín nítorí òkú.
2 Thi du er Herren din Gud et helligt Folk, og dig har Herren udvalgt at være ham et Ejendomsfolk fremfor alle Folk, som ere paa Jordens Kreds.
Nítorí pé ènìyàn mímọ́ ní ẹ jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ènìyàn tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, Ọlọ́run ti yàn yín láti jẹ́ ìṣúra iyebíye rẹ̀.
3 Du skal ikke æde noget, som er vederstyggeligt.
Ẹ má ṣe jẹ ohun ìríra kankan.
4 Disse ere de Dyr, som I maa æde: Okse, Lam af Faarene og Kid af Gederne;
Àwọn wọ̀nyí ni ẹranko tí ẹ lè máa jẹ: màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́,
5 Hjort og Raa og Bøffel og Stenbuk og Daadyr og Urnød og Stenged.
àgbọ̀nrín, èsúró, etu, àgóró, ẹfọ̀n, ìgalà àti àgùntàn igbó.
6 Og alt Kvæg, som har Klove, og som har de tvende Klove kløvede, og som tygger Drøv iblandt Dyrene, det maa I æde.
Ẹ lè jẹ gbogbo ẹranko tí pátákò ẹsẹ̀ rẹ̀ kì í ṣe méjì tí ó sì tún jẹ àpọ̀jẹ.
7 Dog dette maa I ikke æde af dem, som tygge Drøv, og af dem, som have helt adskilte Klove: Kamelen og Haren og Kaninen; thi de tygge Drøv, men skille dog ikke Kloven ad, de skulle være eder urene;
Síbẹ̀síbẹ̀ nínú gbogbo ẹran tí ń jẹ àpọ̀jẹ tí ó sì tún ya pátákò ẹsẹ̀ tí ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ni: ìbákasẹ, ehoro, àti ẹranko tí ó dàbí ehoro tí ń gbé inú àpáta. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n jẹ àpọ̀jẹ, ṣùgbọ́n wọn kò la pátákò ẹsẹ̀, a kà wọ́n sí àìmọ́ fún yín.
8 og Svinet, thi det har Klove, men tygger ikke Drøv, det skal være eder urent; I skulle ikke æde af deres Kød og ikke røre ved deres Aadsel.
Ẹlẹ́dẹ̀ jẹ́ àìmọ́; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ya pátákò ẹsẹ̀, kì í jẹ àpọ̀jẹ, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran rẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ fọwọ́ kan òkú rẹ̀.
9 Dette maa I æde af alt det, som er i Vandet: Alt det, som har Finne og Skæl, maa I æde.
Nínú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń gbé inú omi, ẹ lè jẹ èyíkéyìí tí ó ní lẹbẹ àti ìpẹ́.
10 Men alt det, som ikke har Finne og Skæl, maa I ikke æde; det er eder urent.
Ṣùgbọ́n èyíkéyìí tí kò bá ní lẹbẹ àti ìpẹ́, ẹ má ṣe jẹ ẹ́, nítorí pé àìmọ́ ni wọ́n jẹ́ fún yín.
11 I maa æde hver ren Fugl.
Ẹ lè jẹ ẹyẹ tí ó bá mọ́.
12 Men disse ere de, som I ikke maa æde af dem: Ørnen og Høgen og Strandørnen
Ṣùgbọ́n ìwọ̀nyí ní ẹ kò gbọdọ̀ jẹ: idì, igún, àkàlà,
13 og Kragen og Skaden og Glenten med dens Arter
onírúurú àṣá àti àṣá alátagbà,
14 og alle Ravne med deres Arter
onírúurú ẹyẹ ìwò,
15 og Strudsen og Natuglen og Maagen og Spurvehøgen med dens Arter,
ògòǹgò, òwìwí, pẹ́pẹ́yẹdò àti onírúurú àwòdì,
16 Falken og Hornuglen og Viben
onírúurú òwìwí,
17 og Rørdrummen og Pelikanen og Dykkeren
òwìwí ọ̀dàn, àkàlà, ìgò,
18 og Storken og Hejren med dens Arter og Urhanen og Aftenbakken.
àkọ̀, òòdẹ̀, onírúurú ẹyẹ odò mìíràn, atọ́ka àti àdán.
19 Og alt flyvende Vrimmel, det skal være eder urent, de skulle ikke ædes.
Àti gbogbo kòkòrò tí ń fò tí wọ́n ń kọ́wọ̀ọ́ rìn jẹ́ aláìmọ́ fun un yín, ẹ má ṣe jẹ wọ́n.
20 I maa æde hver ren Fugl.
Ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ èyíkéyìí ẹ̀dá abìyẹ́ tí ó bá mọ́.
21 I maa ikke æde noget Aadsel; du kan give det til den fremmede, som er inden dine Porte, og han maa æde det, eller sælge den fremmede det; thi du er Herren din Gud et helligt Folk. Du skal ikke koge et Kid i sin Moders Mælk.
Ẹ má ṣe jẹ ohun tí ó ti kú sílẹ̀. Ẹ lè fún àwọn àjèjì tí ń gbé ní èyíkéyìí nínú ìlú yín. Òun lè jẹ ẹ́ tàbí kí ẹ tà á fún àwọn àjèjì. Ṣùgbọ́n ènìyàn mímọ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́. Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ewúrẹ́ nínú wàrà ìyá rẹ̀.
22 Du skal tiende af al din Sæds Grøde, som fremkommer af Marken hvert Aar.
Ẹ rí i dájú pé ẹ̀ ń fi ìdákan nínú mẹ́wàá nínú ìre oko yín lọ́dọọdún pamọ́ sí apá kan.
23 Og du skal æde for Herren din Guds Ansigt paa det Sted, som han udvælger til der at lade sit Navn bo, Tienden af dit Korn, din nye Vin og din Olie og de førstefødte af dit store Kvæg og af dit smaa Kvæg, at du maa lære at frygte Herren din Gud alle Dage.
Ẹ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àti àkọ́bí àwọn màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín, níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ibi tí yóò yàn bí ibùgbé orúkọ rẹ̀. Kí ẹ lè kọ́ bí a ṣé ń bu ọlá fún Olúwa Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
24 Men naar Vejen er dig for lang, at du ikke formaar at bære det derhen, fordi det Sted er for langt fra dig, som Herren din Gud har udvalgt til der at sætte sit Navn, naar Herren din Gud velsigner dig:
Bí ibẹ̀ bá jì tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì ti bùkún fún ọ, tí o kò sì le ru àwọn ìdámẹ́wàá rẹ (nítorí pé ibi tí Olúwa yóò yàn láti fi orúkọ rẹ̀ sí jìnnà jù).
25 Saa skal du sælge det for Penge og tage Pengene i din Haand og gaa til det Sted, som Herren din Gud skal udvælge.
Ẹ pààrọ̀ àwọn ìdámẹ́wàá yín sí owó, ẹ mú owó náà lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
26 Og du skal give samme Penge ud for alt, hvad din Sjæl har Lyst til af stort Kvæg og af smaat Kvæg, af Vin og af stærk Drik, eller for alt, som din Sjæl begærer af dig; og du skal æde det for Herren din Guds Ansigt og være glad, du og dit Hus.
Fi owó náà ra ohunkóhun tí o bá fẹ́, màlúù, àgùntàn, wáìnì, tàbí ọtí líle, tàbí ohunkóhun tí o bá fẹ́. Kí ìwọ àti ìdílé rẹ sì jẹ ẹ́ níwájú Olúwa níbẹ̀ kí ẹ sì máa yọ̀.
27 Men Leviten, som er inden dine Porte, ham skal du ikke forlade; thi han har ingen Del eller Arv med dig.
Ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi tí ó ń gbé nì ìlú yín, nítorí pé wọn kò ní ìpín kan tàbí ogún kan tí í ṣe tiwọn.
28 Naar tre Aar ere til Ende, skal du udføre hele Tienden af din Afgrøde i samme Aar, og den skal du lade blive inden dine Porte.
Ní òpin ọdún mẹ́ta mẹ́ta, ẹ̀yin yóò mú gbogbo ìdámẹ́wàá ìre oko àwọn ọdún náà, kí ẹ kó wọn jọ ní ìlú yín.
29 Saa skal Leviten komme, fordi han har ingen Del eller Arv med dig, og den fremmede og den faderløse og Enken, som ere inden dine Porte, og de skulle æde og mættes, paa det at Herren din Gud skal velsigne dig i al din Haands Gerning, som du skal gøre.
Kí àwọn Lefi (tí kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn) àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé ìlú yín lè wá, kí wọn sì jẹ kí wọn sì yó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ le è bùkún fún ọ, nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.