< 5 Mosebog 12 >
1 Disse ere de Skikke og de Bud, som I skulle tage Vare paa at gøre efter i det Land, som Herren dine Fædres Gud har givet dig til Eje, alle de Dage, som I leve paa Jorden.
Wọ̀nyí ni àwọn ìlànà àti òfin tí ẹ gbọdọ̀ ṣọ́ra láti máa tẹ̀lé, ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, fi fún un yín láti gbà: ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá fi wà lórí ilẹ̀ náà.
2 I skulle ødelægge alle de Steder, hvor Hedningerne, hvilke I skulle eje, have tjent deres Guder, paa de høje Bjerge og paa Højene og under alle grønne Træer,
Gbogbo ibi gíga àwọn òkè ńlá, àti òkè kéékèèké àti lábẹ́ gbogbo igi tí ń gbilẹ̀ níbi tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ ó lé jáde, tí ń sin òrìṣà wọn ní kí ẹ mú kúrò pátápátá.
3 og I skulle nedbryde deres Altere og sønderslaa deres Støtter og opbrænde deres Astartebilleder med Ild og omhugge deres Guders udskaarne Billeder og udslette deres Navn fra dette Sted.
Ẹ wó àwọn pẹpẹ wọn, ẹ bi òpó ìsìn wọn ṣubú, kí ẹ sì sun òpó Aṣerah wọn ní iná. Ẹ gé gbogbo ère òrìṣà wọn lulẹ̀, kí ẹ sì pa orúkọ wọn rẹ́ ní gbogbo ààyè wọn.
4 I skulle ikke gøre saaledes mod Herren eders Gud;
Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí i tiwọn.
5 men paa det Sted, som Herren eders Gud udvælger af alle eders Stammer til der at sætte sit Navn, der hvor han vil bo, skulle I søge ham, og derhen skal du komme.
Ṣùgbọ́n ẹ wá ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà yín, láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀ bí i ibùgbé rẹ̀. Ibẹ̀ ni kí ẹ lọ.
6 Og derhen skulle I føre eders Brændofre, og eders Slagtofre og eders Tiender og eders Hænders Offergaver og eders Løfter og eders frivillige Ofre og de førstefødte af eders store Kvæg og af eders smaa Kvæg;
Níbẹ̀ ni kí ẹ mú ẹbọ sísun àti ẹbọ yín wá, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àwọn ẹ̀jẹ́ yín, ọrẹ àtinúwá yín, àti àwọn àkọ́bí gbogbo màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín.
7 og der skulle I æde for Herren eders Guds Ansigt, og I skulle være glade i alt det, som I udrække eders Hænder til, I og eders Huse, ved hvad Herren din Gud har velsignet dig med.
Níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, kí ẹ̀yin àti ìdílé yín jẹun kí ẹ sì yó, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín.
8 I skulle ikke i alt gøre efter det, som vi gøre her i Dag, saa at hver gør, hvad som helst er ret for hans Øjne.
Kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí a tí ṣe níhìn-ín lónìí yìí, tí olúkúlùkù ń ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
9 Thi I ere ikke endnu komne til Rolighed og til den Arv, som Herren din Gud giver dig.
Níwọ́n ìgbà tí ẹ ti dé ibi ìsinmi, àti ibi ogún tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín.
10 Naar I ere gangne over Jordanen og bo i Landet, som Herren eders Gud giver eder til Arv, og han giver eder Rolighed for alle eders Fjender trindt omkring, og I bo tryggeligen,
Ṣùgbọ́n ẹ ó la Jordani kọjá, ẹ ó sì máa gbé ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín bí ìní, yóò sì fún un yín ní ìsinmi, kúrò láàrín àwọn ọ̀tá a yín, tí ó yí i yín ká, kí ẹ ba à lè máa gbé láìléwu.
11 da skal der være et Sted, som Herren eders Gud skal udvælge til at lade sit Navn bo der; derhen skulle I føre alt det, som jeg byder eder, eders Brændofre og eders Slagtofre, eders Tiende og eders Hænders Offergaver og alle eders udvalgte Løfter, hvilke I love Herren;
Níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀. Níbẹ̀ ni kí ẹ mú gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún un yín wá: àwọn ọrẹ ẹ yín àti àwọn ẹbọ sísun, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àti gbogbo ohun ìní yín tí ẹ ti yàn, èyí tí ẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa.
12 og I skulle være glade for Herren eders Guds Ansigt, I og eders Sønner og eders Døtre og eders Tjenere og eders Tjenestepiger og Leviten, som er i eders Porte; thi han har ingen Del eller Arv med eder.
Kí ẹ máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, ẹ̀yin, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, ìránṣẹ́bìnrin àti ìránṣẹ́kùnrin yín, àti àwọn Lefi láti ìlú u yín, tí wọn kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn.
13 Tag dig i Vare, at du ikke ofrer dine Brændofre paa hvert det Sted, som du udser:
Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe rú ẹbọ sísun yín ní ibikíbi tí ẹ̀yin fẹ́.
14 Men paa det Sted, som Herren udvælger, i en af dine Stammer, der skal du ofre dine Brændofre, og der skal du gøre alt det, som jeg byder dig.
Ibi tí Olúwa yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà a yín nìkan ni kí ẹ ti máa rú ẹbọ sísun yín, kí ẹ sì máa kíyèsi ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín níbẹ̀.
15 Dog maa du slagte og æde Kød efter al din Sjæls Lyst, efter Herren din Gudsvelsignelse, som han har givet dig, i alle dine Porte; den urene og den rene maa æde det, som var det en Raa eller en Hjort.
Síbẹ̀síbẹ̀, ẹ lọ pa àwọn ẹran yín ní èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín, kí ẹ sì jẹ ẹran náà tó bí ẹ ti fẹ́, bí ẹ ti ń ṣe sí àgbọ̀nrín àti èsúró, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún Olúwa Ọlọ́run yín tí ó fi fún un yín, àti ẹni mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ nínú àwọn ẹran náà.
16 Dog skulle I ikke æde Blodet; paa Jorden skal du udøse det som Vand.
Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
17 Du maa ikke æde inden dine Porte Tiende af dit Korn og din nye Vin og din Olie, ej heller det førstefødte af dit store Kvæg eller dit smaa Kvæg, ej heller af noget af dine Løfter, som du har lovet, eller af dine frivillige Ofre eller af din Haands Gaver.
Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àkọ́bí àwọn màlúù yín, tàbí ti ewúrẹ́ ẹ yín, ohunkóhun tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ àtinúwá, tàbí ẹ̀bùn pàtàkì ní ìlú ẹ̀yin tìkára yín.
18 Men du skal æde det for Herren din Guds Ansigt paa det Sted, som Herren din Gud udvælger, du og din Søn og din Datter og din Tjener og din Tjenestepige og Leviten, som er i dine Porte; og du skal være glad for Herren din Guds Ansigt i alt det, som du udrækker dine Hænder til.
Bí kò ṣe kí ẹ jẹ ẹ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín, yóò yàn: ìwọ, àwọn ọmọkùnrin rẹ, àwọn ọmọbìnrin rẹ, àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àwọn ọmọ Lefi láti ìlú u yín, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín.
19 Tag dig i Vare, at du ikke forlader Leviten, alle dine Dage i dit Land.
Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá ń gbé ní ilẹ̀ ẹ yín.
20 Naar Herren din Gud udvider dine Landemærker, som han har tilsagt dig, og du siger: Jeg vil æde Kød; thi din Sjæl har Lyst til at æde Kød: Saa maa du æde Kød efter al din Sjæls Lyst.
Bí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti fẹ́ agbègbè e yín bí ó ti ṣe ìlérí, fún un yín, tí ẹ sì wí pé, àwa yóò jẹ ẹran, nítorí tí ọkàn wa fẹ́ jẹran. Ẹ jẹ ẹran náà bí ẹ tí fẹ́.
21 Men er det Sted langt fra dig, hvilket Herren din Gud har udvalgt til der at sætte sit Navn, da maa du slagte af dit store Kvæg og af dit smaa Kvæg, som Herren har givet dig, ligesom jeg har budet dig, og du maa æde det inden dine Porte efter al din Sjæls Lyst.
Bí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín bá yàn fún orúkọ rẹ̀ bá jìnnà sí i yín, kí ẹ pa màlúù tàbí ewúrẹ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín tí fún un yín, bí mo ti pàṣẹ fún un yín ní ìlú u yín, ẹ lè jẹ ẹ́ bí ẹ ti fẹ́.
22 Dog kun, som var det en Raa eller en Hjort man æder, saaledes maa du æde det; den urene saavel som den rene maa æde det.
Ẹ jẹ wọ́n bí ẹ ó ti jẹ èsúró tàbí àgbọ̀nrín, ẹni tí a kà sí mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ ẹ́.
23 Dog hold fast ved, at du ikke æder Blodet, thi Blodet er Sjælen; og du maa ikke æde Sjælen med Kødet.
Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé ẹ kò jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí, ẹ kò sì gbọdọ̀ jẹ ẹ̀mí pọ̀ mọ́ ẹran.
24 Du skal ikke æde det, du skal udøse det paa Jorden som Vand.
Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
25 Du skal ikke æde det, at det maa gaa dig vel og dine Børn efter dig, naar du har gjort det, som ret er for Herrens Øjne.
Ẹ má ṣe jẹ ẹ́, kí ó bá à lè dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín, tí ń bọ̀ lẹ́yìn in yín. Nígbà yí ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó tọ̀nà lójú Olúwa.
26 Dog de Ting, som du helliger, som hørmer dig til, og dine Løfter, dem skal du tage og komme med til det Sted, som Herren skal udvælge.
Ẹ mú àwọn ohun tí ẹ yà sọ́tọ̀ àti àwọn ẹ̀jẹ́ yín, kí ẹ sì lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
27 Og du skal bringe dine Brændofre, Kødet og Blodet, paa Herren din Guds Alter, og Blodet af dine Ofre skal udøses paa Herren din Guds Alter, og Kødet maa du æde.
Ẹ fi ẹbọ sísun yín kalẹ̀ lórí i pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, àti ẹran àti ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Ẹ̀jẹ̀ ọrẹ yín ni ki ẹ dà sí pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ ẹran.
28 Tag Vare paa og hør alle disse Ord, som jeg byder dig, at det maa gaa dig vel og dine Børn efter dig evindeligen, naar du har gjort det, som godt og ret er for Herren din Guds Øjne.
Ẹ kíyèsára láti máa gbọ́rọ̀ sí gbogbo ìlànà tí mò ń fún un yín, kí o bá à dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín nígbà gbogbo, nítorí pé nígbà náà ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà níwájú Olúwa Ọlọ́run yín.
29 Naar Herren din Gud faar udryddet Hedningerne for dit Ansigt, der hvor du drager hen at eje dem, og du ejer dem og bor i deres Land:
Olúwa Ọlọ́run yín yóò gé àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ fẹ́ lé kúrò tí ẹ sì fẹ́ gba ilẹ̀ wọn kúrò níwájú u yín. Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ bá ti lé wọn jáde tí ẹ sì ń gbé ilẹ̀ wọn.
30 Saa forvar dig, at du ikke falder i Snaren efter dem, efter at de ere ødelagte for dit Ansigt, og at du ikke søger deres Guder og siger: Ligesom disse Folk tjente deres Guder, saa vil jeg ogsaa gøre.
Lẹ́yìn ìgbà tí a bá ti pa wọ́n run níwájú u yín, ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ba à bọ́ sínú àdánwò nípa bíbéèrè nípa àwọn òrìṣà wọn wí pé, “Báwo ni àwọn orílẹ̀-èdè yìí ṣe ń sin àwọn òrìṣà wọn? Àwa náà yóò ṣe bẹ́ẹ̀”.
31 Du skal ikke gøre saaledes for Herren din Gud; thi de gjorde for deres Guder alt det, som er vederstyggeligt for Herren, det som han hader; thi de have endog brændt deres Sønner og deres Døtre i Ilden for deres Guder.
Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí àwọn, torí pé, nípa sínsin ọlọ́run wọn, wọ́n ń ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìríra tí Ọlọ́run kórìíra. Wọ́n ń dáná sun àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn láti fi rú ẹbọ sí ère òrìṣà wọn.
32 I skulle holde hvert Ord, som jeg byder eder, at gøre derefter; du skal ikke lægge dertil og ej tage derfra.
Ẹ rí i pé ẹ̀ ń ṣe gbogbo ohun tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ẹ má ṣe fi kún un, ẹ má sì ṣe yọ kúrò níbẹ̀.