< Daniel 9 >
1 Idet første Aar under Darius, Ahasverus's Søn, som var af Medernes Æt og var sat til Konge over Kaldæernes Rige,
Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ọmọ Ahaswerusi, ẹni tí a bí ní Media, òun ló jẹ ọba lórí ìjọba Babeli.
2 i det første Aar, der han regerede, gav jeg, Daniel, i Bøgerne Agt paa Aarenes Tal, hvorom Herrens Ord var kommet til Profeten Jeremias, at nemlig halvfjerdsindstyve Aar skulde gaa hen over det ødelagte Jerusalem.
Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, èmi Daniẹli fi iyè sí i láti inú ìwé, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí wòlíì Jeremiah, wá pé, àádọ́rin ọdún ni Jerusalẹmu yóò fi wà ní ahoro.
3 Og jeg vendte mit Ansigt til Gud Herren for at søge Bøn og ydmyge Begæringer i Faste og Sæk og Aske.
Nígbà náà, ni mo yípadà sí Olúwa Ọlọ́run, mo bẹ̀ ẹ́ pẹ̀lú àdúrà àti ẹ̀bẹ̀, pẹ̀lú àwẹ̀, aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú.
4 Og jeg bad til Herren min Gud, og bekendte og sagde: Ak, Herre, du store og forfærdelige Gud, som bevarer Pagt og Miskundhed imod dem, som elske ham, og imod dem, som holde hans Bud!
Mo gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run mi, mo sì jẹ́wọ́ wí pé: “Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó ní ìfẹ́ rẹ̀ àti àwọn tí ó ń pa àwọn òfin rẹ̀ mọ́.
5 Vi have syndet og gjort ilde, og have handlet ugudeligt og været genstridige, og vi ere vegne fra dine Bud og fra dine Love.
Àwa ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú. Àwa ti hu ìwà búburú, a sì ti ṣe ọ̀tẹ̀, a ti yí padà kúrò nínú àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà rẹ̀.
6 Og vi hørte ikke paa dine Tjenere, Profeterne, som talte i dit Navn til vore Konger, vore Fyrster og vore Fædre og til alt Folket i Landet.
Àwa kò fetí sí àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ rẹ sí àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé àti àwọn baba wa, àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà.
7 Herre! dig hører Retfærdighed til, men Ansigts Blusel, saaledes som paa denne Dag, er for os, for Judas-Mænd og Jerusalems Indbyggere og hele Israel, dem, som ere nær, og dem, som ere langt borte, i alle de Lande, hvorhen du har fordrevet dem for deres Troløsheds Skyld, som de have begaaet imod dig.
“Olúwa ìwọ ni olódodo, ṣùgbọ́n báyìí ìtìjú dé bá àwọn ènìyàn Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti gbogbo Israẹli ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti fọ́n wa ká sí nítorí àìṣòótọ́ ọ wa sí ọ.
8 Herre! Ansigts Blusel er for os, for vore Konger, for vare Fyrster og for vore Fædre, fordi vi have syndet imod dig.
Háà! Olúwa, àwa àti àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé, àti àwọn baba wa, ìtìjú dé bá wa nítorí àwa ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ.
9 Hos Herren vor Gud er Barmhjertighed og Forladelse, thi vi have været genstridige imod ham,
Olúwa Ọlọ́run wa ní àánú, ó sì ń dáríjì, bí àwa tilẹ̀ ti ṣe ọ̀tẹ̀ sí i;
10 og vi have ikke hørt paa Herren vor Guds Røst, saa at vi vandrede i hans Love, som han gav for vort Ansigt ved sine Tjenere, Profeterne.
àwa kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, a kò sì pa àwọn òfin rẹ mọ́, èyí tí ó fún wa nípasẹ̀ àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
11 Men al Israel har overtraadt din Lov og er afveget, idet de ikke hørte paa din Røst; derfor er der udøst over os den Forbandelse og den Ed, som er skrevet i Mose, Guds Tjeners, Lov; thi vi have syndet imod ham.
Gbogbo Israẹli ti ṣẹ̀ sí òfin rẹ, wọ́n ti yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, wọ́n kọ̀ láti ṣe ìgbọ́ràn sí ọ. “Nígbà náà ni ègún àti ìdájọ́ tí a kọ sílẹ̀ pẹ̀lú ìbúra nínú òfin Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run dà sórí i wa, nítorí tí àwa ti sẹ̀ sí ọ.
12 Og han har holdt sine Ord, som han talte over os og over vore Dommere, der dømte os, idet han lod en stor Ulykke komme over os, som ikke var sket under hele Himmelen, saaledes som den er sket i Jerusalem.
Ìwọ ti mú ọ̀rọ̀ tí o sọ sí wa sẹ àti lórí àwọn alákòóso wa, nípa mímú kí ibi ńlá bá wa, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí lábẹ́ ọ̀run, bí ó ti ṣẹlẹ̀ sí Jerusalẹmu yìí.
13 Ligesom skrevet er i Moses Lov, saa er alt dette onde kommet over os; og vi have ikke formildet Herren vor Guds Ansigt ved at omvende os fra vore Misgerninger og blive forstandige i din Sandhed.
Bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Mose bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ibi yìí ti dé bá wa, síbẹ̀ a kò bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run wa, nípa yíyí padà kí a kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wa kí a sì mọ òtítọ́ rẹ.
14 Derfor vaagede Herren over Ulykken og lod den komme over os; thi Herren vor Gud er retfærdig i alle sine Gerninger, som han gør, men vi havde ikke hørt paa hans Røst.
Olúwa kò jáfara láti mú ibi náà wá sórí wa, nítorí olódodo ni Olúwa Ọlọ́run wa nínú u gbogbo ohun tí ó ń ṣe; síbẹ̀ àwa kò ṣe ìgbọ́ràn sí i.
15 Og nu, Herre, vor Gud! du, som udførte dit Folk af Ægyptens Land med en stærk Haand og indlagde dig et Navn, som det er paa denne Dag, vi have syndet, vi have handlet ugudeligt.
“Ní ìsinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, pẹ̀lú ọwọ́ agbára, tí ó fún ara rẹ̀ ní orúkọ tí ó wà títí di òní, a ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú.
16 Herre! efter alle din Retfærdigheds Bevisninger, lad dog din Vrede og din Harme vende sig bort fra din Stad Jerusalem, dit hellige Bjerg; thi for vore Synders Skyld og for vore Fædres Misgerningers Skyld er Jerusalem og dit Folk blevet til Forhaanelse for alle dem, som ere trindt omkring os.
Olúwa, ní ìbámu pẹ̀lú ìwà òdodo rẹ, yí ìbínú àti ìrunú rẹ padà kúrò ní Jerusalẹmu ìlú u rẹ, òkè mímọ́ rẹ. Ẹ̀ṣẹ̀ wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa ti mú Jerusalẹmu àti ènìyàn rẹ di ẹ̀gàn fún gbogbo àwọn tí ó yí wọn ká.
17 Og nu, vor Gud! hør din Tjeners Bøn og hans ydmyge Begæringer, og lad dit Ansigt lyse over din Helligdom, som er ødelagt, for Herrens Skyld.
“Nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, nítorí i tìrẹ Olúwa, fi ojú àánú wo ibi mímọ́ rẹ tí ó ti dahoro.
18 Bøj dit Øre, min Gud! og hør, oplad dine Øjne, og se Ødelæggelserne, som ere komne over os og Staden, over hvilken dit Navn kaldes; thi vi nedlægge vore ydmyge Begæringer for dit Ansigt, ikke for vore retfærdige Gerningers Skyld, men for din store Barmhjertigheds Skyld.
Tẹ́ etí rẹ sílẹ̀, Ọlọ́run, kí o gbọ́; ya ojú rẹ sílẹ̀, kí o sì wo ìdahoro ìlú tí a ń fi orúkọ rẹ pè. Àwa kò gbé ẹ̀bẹ̀ wa kalẹ̀ níwájú u rẹ nítorí pé a jẹ́ olódodo, bí kò ṣe nítorí àánú ńlá rẹ.
19 Herre, hør! Herre, forlad! Herre, giv Agt og gør det! tøv ikke! for din Skyld, min Gud! thi dit Navn kaldes over din Stad og over dit Folk.
Olúwa, fetísílẹ̀! Olúwa, dáríjì! Olúwa, gbọ́ kí o sì ṣe é! Nítorí i tìrẹ, Ọlọ́run mi, má ṣe pẹ́ títí, nítorí ìlú rẹ àti àwọn ènìyàn rẹ ń jẹ́ orúkọ mọ́ ọ lára.”
20 Og der jeg endnu talte og bad og bekendte min Synd og mit Folk Israels Synd og nedlagde min ydmyge Begæring for Herrens, min Guds, Ansigt, for min Guds hellige Bjergs Skyld,
Bí mo ṣe ń sọ̀rọ̀, tí mo sì ń gba àdúrà, tí mo ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi àti ẹ̀ṣẹ̀ àwọn Israẹli ènìyàn mi, tí mo sì ń mú ẹ̀bẹ̀ mi tọ Olúwa Ọlọ́run mi nítorí òkè mímọ́ rẹ.
21 ja, der jeg endnu talte i Bønnen, da kom den Mand, Gabriel, hvilken jeg havde set tilforn i et Syn, der jeg var aldeles afmægtig, hen til mig ved Aftens Madoffers Tid.
Bí mo ṣe ń gba àdúrà náà lọ́wọ́, Gabrieli ọkùnrin tí mo rí nínú ìran ìṣáájú, yára kánkán wá sí ọ̀dọ̀ mi ní àkókò ẹbọ àṣálẹ́.
22 Og han underviste mig og talte med mig og sagde: Daniel! nu er jeg udgangen for at meddele dig Indsigt.
Ó jẹ́ kí ó yé mi, ó sì wí fún mi pé, “Daniẹli, mo wá láti jẹ́ kí o mọ̀ kí o sì ní òye.
23 Med Begyndelsen af dine ydmyge Begæringer udgik et Ord, og jeg er kommen for at kundgøre dig det, thi du er højlig elsket; saa agt da paa Ordet og giv Agt paa Synet!
Bí o ṣe bẹ̀rẹ̀ sí nígbà àdúrà, a fún ọ ní ìdáhùn kan, èyí tí mo wá láti sọ fún ọ, nítorí ìwọ jẹ́ àyànfẹ́ gidigidi. Nítorí náà, gba ọ̀rọ̀ náà yẹ̀ wò kí ìran náà sì yé ọ:
24 Der er halvfjerdsindstyve Uger bestemte over dit Folk og over din hellige Stad til at hindre Overtrædelsen og til at forsegle Synder og til at sone Misgerning og til at bringe en evig Retfærdighed og til at forsegle Syn og Profet og til at salve et Allerhelligste.
“Àádọ́rin ọ̀sẹ̀ ni a pàṣẹ fún àwọn ènìyàn rẹ àti fún àwọn ìlú mímọ́ rẹ láti parí ìrékọjá, láti fi òpin sí ẹ̀ṣẹ̀, láti ṣe ètùtù sí ìwà búburú, láti mú òdodo títí ayé wá, láti ṣe èdìdì ìran àti wòlíì àti láti fi òróró yan Ibi Mímọ́ Jùlọ.
25 Saa vid og forstaa: Fra den Tid, da Ordet udgaar om at genoprette og om at bygge Jerusalem, indtil en Salvet, en Fyrste, er der syv Uger; og i to og tresindstyve Uger skal den genoprettes og bygges i vid Udstrækning og efter bestemt Maal, men under Tidernes Trængsel.
“Nítorí náà, mọ èyí pé, láti ìgbà tí a ti gbé ọ̀rọ̀ náà jáde wí pé kí a tún Jerusalẹmu ṣe, kí a sì tún kọ́, títí dé ìgbà ọmọ-aládé, ẹni òróró náà, alákòóso wa yóò fi dé, ó jẹ́ ọ̀sẹ̀ méje àti ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó sì tún ìgboro àti yàrá rẹ̀ mọ, ṣùgbọ́n ní àkókò wàhálà ni.
26 Men efter de to og tresindstyve Uger skal en Salvet udryddes, og der skal intet være for ham; og en kommende Fyrstes Folk skal ødelægge Staden og Helligdommen, og han skal ende i Oversvømmelsen, og indtil Enden skal der være Krig, og hvad der af Ødelæggelser er bestemt.
Lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó ké Ẹni òróró náà kúrò, kò sì ní ní ohun kan. Àwọn ènìyàn ọmọ-aládé náà tí yóò wá ni yóò pa ìlú náà àti ibi mímọ́ run. Òpin yóò dé bí ìkún omi, ogun yóò máa jà títí dé òpin, a sì ti pàṣẹ ìdahoro.
27 Og han skal befæste en Pagt med de mange i den ene Uge; og i den halve Uge skal han bringe Slagtoffer og Madoffer til at ophøre, og paa Vederstyggelighedernes Vinger kommer Ødelæggeren, og det indtil Undergang og det besluttede Raad udgyder sig over den ødelagte.
Yóò sì fi ìdí i májẹ̀mú kan múlẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún ọ̀sẹ̀ kan. Ní àárín ọ̀sẹ̀ ni yóò mú òpin bá ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ. Àti lórí apá kan ni yóò dà ìríra tí ó mú ìdahoro wá, títí tí òpin tí a ti pàṣẹ lórí asọnidahoro yóò fi padà fi dé bá a.”