< Amos 3 >
1 Hører dette Ord, som Herren taler over eder, Israels Børn! over hele den Slægt, som jeg førte op af Ægyptens Land, idet jeg sagde:
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:
2 Kun eder har jeg kendt af alle Slægter paa Jorden; derfor vil jeg hjemsøge eder for alle eders Misgerninger.
“Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí; nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”
3 Mon to gaa tilsammen, uden naar de have truffet Aftale?
Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀ láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?
4 Mon en Løve brøler i Skoven, naar der ikke er Rov for den? mon en ung Løve hæver sin Røst fra sin Hule, uden at den har fanget noget?
Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó, bí kò bá ní ohun ọdẹ? Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀ bí kò bá rí ohun kan mú?
5 Mon en Fugl falder i Snaren paa Jorden, naar der ikke er et Garn for den? mon Snaren springer op fra Jorden, uden at den har fanget noget?
Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀ nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un? Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀ nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?
6 Eller mon der stødes i Trompeten i en Stad, uden at Folket forfærdes? eller moh der sker en Ulykke i en Stad, og Herren ikke har gjort den?
Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú, àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù? Tí ewu bá wa lórí ìlú kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?
7 Thi den Herre, Herre gør ikke noget, uden at han har aabenbaret sin Hemmelighed for sine Tjenere, Profeterne.
Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan láìfi èrò rẹ̀ hàn fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
8 Løven har brølet, hvo skal ikke frygte? den Herre, Herre har talt, hvo skal ikke profetere?
Kìnnìún ti bú ramúramù ta ni kì yóò bẹ̀rù? Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀ ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?
9 Lader det høre over Paladserne i Asdod og over Paladserne i Ægyptens Land, og siger: Samler eder paa Samarias Bjerge og ser de store Forvirringer derudi og de undertrykte i dens Midte!
Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria; kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀ àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”
10 Og de vide ikke at gøre Ret, siger Herren, de, som opdynge Vold og Ødelæggelse i deres Paladser.
“Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí, “àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”
11 Derfor, saa siger den Herre, Herre: Der kommer Fjender, og det trindt omkring Landet, og han skal nedstyrte din Magt fra dig, og dine Paladser skulle plyndres.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run; yóò wó ibi gíga yín palẹ̀ a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”
12 Saa siger Herren: Saaledes som en Hyrde redder to Ben eller en Ørelap af Løvens Mund, saa skulle Israels Børn reddes, de, som sidde i Samaria, i Hjørnet af Løjbænken og paa Lejets Damaskhynder.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Bí olùṣọ́-àgùntàn ti ń gbà itan méjì kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli, tí ń gbé Samaria kúrò ní igun ibùsùn wọn ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”
13 Hører og vidner for Jakobs Hus, siger den Herre, Herre, Zebaoths Gud,
“Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.
14 at paa den Dag, naar jeg hjemsøger Israel for dets Overtrædelser, da vil jeg hjemsøge Bethels Altre, og Alterets Horn skulle afhugges og falde til Jorden.
“Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run; ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò yóò sì wó lulẹ̀.
15 Og jeg vil nedslaa Vinterhuset tillige med Sommerhuset, og Elfenbenshusene skulle forgaa, og de mange Huse skulle faa Ende, siger Herren.
Èmi yóò wó ilé òtútù lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru; ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé a ó sì pa ilé ńlá náà run,” ni Olúwa wí.