< Første Kongebog 22 >

1 Og de sade stille tre Aar; der var ingen Krig imellem Syrerne og Israel.
Fún ọdún mẹ́ta kò sì sí ogun láàrín Aramu àti Israẹli.
2 Men det skete i det tredje Aar, da drog Josafat, Judas Konge, ned til Israels Konge.
Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, Jehoṣafati ọba Juda sọ̀kalẹ̀ lọ láti rí ọba Israẹli.
3 Og Israels Konge sagde til sine Tjenere: Vide I, at Ramoth i Gilead hører os til? og vi tie stille om at tage den tilbage af Syriens Konges Haand!
Ọba Israẹli sì ti wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ti wa ni Ramoti Gileadi, àwa sì dákẹ́ síbẹ̀, a kò sì gbà á padà lọ́wọ́ ọba Aramu?”
4 Derefter sagde han til Josafat: Vil du drage med mig til Krig imod Ramoth i Gilead? og Josafat sagde til Israels Konge: Jeg vil være som du, mit Folk skal være som dit Folk, mine Heste som dine Heste.
Ó sì béèrè lọ́wọ́ Jehoṣafati pé, “Ṣé ìwọ yóò bá mi lọ láti lọ bá Ramoti Gileadi jà?” Jehoṣafati sì dá ọba Israẹli lóhùn pé, “Èmi bí ìwọ, ènìyàn mi bí ènìyàn rẹ, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
5 Fremdeles sagde Josafat til Israels Konge: Kære, adspørg i Dag Herrens Ord!
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
6 Da samlede Israels Konge Profeterne, ved fire Hundrede Mænd, og sagde til dem: Skal jeg drage til Krig imod Ramoth i Gilead eller lade det være? og de sagde: Drag op, og Herren skal give den i Kongens Haand.
Nígbà náà ni ọba Israẹli kó àwọn wòlíì jọ, bí irinwó ọkùnrin. Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé kí n lọ sí Ramoti Gileadi lọ jagun, tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ̀?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
7 Men Josafat sagde: Er her ikke endnu en Herrens Profet, at vi kunde spørge ham ad?
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ǹjẹ́ wòlíì Olúwa kan kò sí níhìn-ín, tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
8 Og Israels Konge sagde til Josafat: Her er endnu een Mand, ved hvem man kan adspørge Herren, men jeg hader ham, fordi han spaar ikke godt over mig, men ondt, det er Mika, Jimlas Søn; og Josafat sagde: Kongen sige ikke saa!
Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan ṣì wà, lọ́dọ̀ ẹni tí àwa lè béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n mo kórìíra rẹ̀ nítorí kì í sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kan nípa mi, bí kò ṣe ibi. Mikaiah ọmọ Imla ni.” Jehoṣafati sì wí pé, “Kí ọba má ṣe sọ bẹ́ẹ̀.”
9 Da kaldte Israels Konge ad en af Kammertjenerne og sagde: Hent hurtigt Mika, Jimlas Søn!
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli sì pe ìránṣẹ́ kan, ó sì wí pé, “Lọ yára mú Mikaiah, ọmọ Imla wá.”
10 Og Israels Konge og Josafat, Judas Konge, sade hver paa sin Trone, iførte Kongedragt, paa en fri Plads ved Indgangen til Samarias Port, og alle Profeterne spaaede for deres Ansigt.
Ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda jókòó lórí ìtẹ́ wọn, wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn ní ìta ẹnu ibodè Samaria, gbogbo àwọn wòlíì náà sì ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
11 Og Zedekia, Knaanas Søn, havde gjort sig Jernhorn, og han sagde: Saaledes sagde Herren: Med disse skal du stange Syrerne, indtil de aldeles udryddes.
Sedekiah ọmọ Kenaana sì ṣe ìwo irin fún ara rẹ̀, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Wọ̀nyí ni ìwọ yóò fi kan àwọn ará Aramu títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’”
12 Og alle Profeterne spaaede saaledes og sagde: Drag op imod Ramoth i Gilead og vær lykkelig, og Herren skal give den i Kongens Haand.
Gbogbo àwọn wòlíì tókù sì ń sọtẹ́lẹ̀ ohun kan náà wí pé, “Kọlu Ramoti Gileadi, kí o sì ṣẹ́gun.” Wọ́n sì wí pé, “Nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
13 Og Budet, som var gaaet bort for at kalde paa Mika, talte til ham sigende: Kære, se, Profeternes Ord ere som af een Mund gunstige for Kongen; kære, lad dit Ord være ligesom Ordet af en af dem og tal gunstigt!
Ìránṣẹ́ tí ó lọ pe Mikaiah wí fún un pé, “Wò ó, ẹnu kan náà ni ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì fi jẹ́ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ bá ti àwọn tókù mu, kí o sì sọ rere.”
14 Da sagde Mika: Saa vist som Herren lever, det som Herren siger mig, det vil jeg tale.
Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pé, “Bí Olúwa ti wà, ohun tí Olúwa bá sọ fún mi ni èmi yóò sọ fún un.”
15 Og han kom til Kongen, og Kongen sagde til ham: Mika! skulle vi drage imod Ramoth i Gilead til Krig eller lade være? Og han sagde til ham: Drag op og vær lykkelig, og Herren skal give den i Kongens Haand.
Nígbà tí ó sì dé, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Mikaiah, ṣé kí a lọ bá Ramoti Gileadi jagun, tàbí kí a jọ̀wọ́ rẹ̀?” Ó sì dáhùn wí pé, “Lọ, kí o sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
16 Og Kongen sagde til ham: Hvor mange Gange skal jeg besværge dig, at du intet siger mig uden Sandheden i Herrens Navn?
Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi yóò fi ọ bú pé kí o má ṣe sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
17 Da sagde han: Jeg saa al Israel adspredt paa Bjergene ligesom Faarene, der ingen Hyrde have; og Herren sagde: Disse have ingen Herre, lad dem vende tilbage hver til sit Hus med Fred!
Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
18 Da sagde Israels Konge til Josafat: Har jeg ikke sagt dig: Han spaar mig ikke godt, men ondt?
Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún ọ pé kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìre kan sí mi rí bí kò ṣe ibi?”
19 Og han sagde: Hør derfor Herrens Ord: Jeg saa Herren sidde paa sin Trone, og al Himmelens Hær staaende hos ham ved hans højre og ved hans venstre Side.
Mikaiah sì tún wí pé, “Nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ogun ọ̀run dúró ní apá ọ̀tún àti ní apá òsì rẹ̀.
20 Og Herren sagde: Hvo vil overtale Akab, at han skal drage op og falde ved Ramoth i Gilead? og den ene sagde saa, og den anden sagde saa.
Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu láti kọlu Ramoti Gileadi? Kí ó sì tọ ikú rẹ̀ lọ níbẹ̀?’ “Ẹnìkan wí báyìí, ẹlòmíràn sì sọ òmíràn.
21 Da gik en Aand ud og stod for Herrens Ansigt og sagde: Jeg vil overtale ham; og Herren sagde til ham: Hvormed?
Ẹ̀mí kan sì jáde wá, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’
22 Og han sagde: Jeg vil gaa ud og være en løgnagtig Aand i alle hans Profeters Mund; og han sagde: Du skal overtale ham, ja ogsaa formaa det; gak ud og gør saa!
“Olúwa sì béèrè pé, ‘Báwo?’ “Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò jáde lọ, èmi yóò sì di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ̀.’ “Olúwa sì wí pé, ‘Ìwọ yóò tàn án, ìwọ yóò sì borí, jáde lọ, kí o sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
23 Og nu, se, Herren har givet en løgnagtig Aand i alle disse dine Profeters Mund; men Herren har talt ondt over dig.
“Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ wọ̀nyí. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
24 Da gik Zedekia, Knaanas Søn, frem og slog Mika paa Kinden og sagde: Hvorledes? er Herrens Aand gaaet over fra mig for at tale med dig?
Nígbà náà ni Sedekiah ọmọ Kenaana sì dìde, ó sì gbá Mikaiah lójú, ó sì wí pé, “Ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
25 Og Mika sagde: Se, du skal se det paa den Dag, naar du gaar ind fra et Kammer til et andet for at skjule dig.
Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
26 Da sagde Israels Konge: Tag Mika og før ham tilbage til Amon, Stadens Befalingsmand, og til Joas, Kongens Søn.
Ọba Israẹli sì pàṣẹ pé, “Ẹ mú Mikaiah, kí ẹ sì mú un padà sọ́dọ̀ Amoni, olórí ìlú, àti sọ́dọ̀ Joaṣi ọmọ ọba
27 Og du skal sige: Saa siger Kongen: Sætter denne i Fængsels Hus og bespiser ham med Trængsels Brød og Trængsels Vand, indtil jeg kommer med Fred.
kí ẹ sì wí pé, ‘Báyìí ni ọba wí: Ẹ fi eléyìí sínú túbú, kí ẹ sì fi oúnjẹ ìpọ́njú àti omi ìpọ́njú bọ́ ọ, títí èmi yóò fi padà bọ̀ ní àlàáfíà.’”
28 Og Mika sagde: Dersom du kommer tilbage med Fred, da har Herren ikke talt ved mig; og han sagde: Hører, I Folk alle sammen!
Mikaiah sì wí pé, “Bí ìwọ bá padà bọ̀ ní àlàáfíà, Olúwa kò ti ipa mi sọ̀rọ̀.” Ó sì tún wí pé, “Ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ mi, ẹ̀yin ènìyàn gbogbo!”
29 Saa drog Israels Konge og Josafat, Judas Konge, op imod Ramoth i Gilead.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda gòkè lọ sí Ramoti Gileadi.
30 Og Israels Konge sagde til Josafat: Jeg vil forklæde mig og saa gaa i Kampen, men tag du dine egne Klæder paa; og Israels Konge forklædte sig og gik i Slaget.
Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò pa aṣọ dà, èmi yóò sì lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
31 Men Kongen af Syrien bød sine to og tredive øverste for Vognene og sagde: I skulle ikke stride imod liden eller stor, uden imod Israels Konge alene.
Ọba Aramu ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ méjìlélọ́gbọ̀n wí pé, “Ẹ má ṣe bá ẹnìkankan jà, ẹni kékeré tàbí ẹni ńlá, bí kò ṣe ọba Israẹli nìkan.”
32 Og det skete, der de øverste for Vognene saa Josafat, da sagde de: Han er visselig Israels Konge, og de bøjede af for at stride imod ham. Da raabte Josafat.
Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí Jehoṣafati, wọ́n sì wí pé, “Dájúdájú ọba Israẹli ni èyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà láti bá a jà, ṣùgbọ́n nígbà tí Jehoṣafati sì kígbe sókè,
33 Og det skete, der de øverste for Vognene saa, at han ikke var Israels Konge, da vendte de tilbage fra ham.
àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí i pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì padà kúrò lẹ́yìn rẹ̀.
34 Og en Mand spændte Buen paa Lykke og Fromme og skød Israels Konge mellem Remmene og Panseret; da sagde denne til sin Køresvend: Vend din Haand om og før mig ud af Hæren; thi jeg er saaret.
Ṣùgbọ́n ẹnìkan sì fa ọrun rẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, ó sì ta ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin. Ọba Israẹli sì wí fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ dà, kí o sì mú mi jáde kúrò nínú ogun. Èmi ti gbọgbẹ́.”
35 Og Kampen tog til paa den samme Dag, og Kongen blev holdt staaende i Vognen over for Syrerne, og han døde om Aftenen, og Blodet flød af Saaret midt i Vognen.
Ogun náà sì le ní ọjọ́ náà, a sì dá ọba dúró nínú kẹ̀kẹ́ kọjú sí àwọn ará Aramu. Ẹ̀jẹ̀ sì sàn jáde láti inú ọgbẹ́ rẹ̀ sí àárín kẹ̀kẹ́ náà, ó sì kú ní àṣálẹ́.
36 Og man udraabte igennem Lejren, der Solen gik ned, og sagde: Hver gaa til sin Stad og hver til sit Land!
A sì kéde la ibùdó já ní àkókò ìwọ̀-oòrùn wí pé, “Olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀ àti olúkúlùkù sí ilẹ̀ rẹ̀!”
37 Saa døde Kongen og blev ført til Samaria, og de begrove Kongen i Samaria.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba kú, a sì gbé e wá sí Samaria, wọ́n sì sin ín ní Samaria.
38 Og man skyllede Vognen ved Samarias Dam; og Hundene slikkede hans Blod, hvor Skøgerne badede sig, efter Herrens Ord, som han havde talt.
Wọ́n sì wẹ kẹ̀kẹ́ náà ní adágún Samaria, àwọn ajá sì lá ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, àwọn àgbèrè sì wẹ ara wọn nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti sọ.
39 Men det øvrige af Akabs Handeler, og alt det han gjorde, og om det Elfenbens Hus, som han byggede, og om alle Stæderne, som han byggede, er det ikke skrevet i Israels Kongers Krønikers Bog?
Ní ti ìyókù ìṣe Ahabu, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ilé eyín erin tí ó kọ́, àti gbogbo ìlú tí ó tẹ̀dó, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
40 Og Akab laa med sine Fædre, og Ahasia, hans Søn, blev Konge i hans Sted.
Ahabu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Ahasiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
41 Og Josafat, Asas Søn, blev Konge over Juda i Akabs, Israels Konges, fjerde Aar.
Jehoṣafati ọmọ Asa, sì bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba lórí Juda ní ọdún kẹrin Ahabu ọba Israẹli.
42 Josafat var fem og tredive Aar gammel, der han blev Konge, og regerede fem og tyve Aar i Jerusalem, og hans Moders Navn var Asuba, Silhis Datter.
Jehoṣafati sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba ní ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
43 Og han vandrede i alle sin Fader Asas Veje og veg ikke derfra, men gjorde det, som var ret for Herrens Øjne.
Ó sì rìn nínú gbogbo ọ̀nà Asa baba rẹ̀, kò sì yípadà kúrò nínú rẹ̀; ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa. Kìkì àwọn ibi gíga ni a kò mú kúrò, àwọn ènìyàn sì ń rú ẹbọ, wọ́n sì ń sun tùràrí níbẹ̀.
44 Dog bleve Højene ikke borttagne; Folket ofrede endnu og gjorde Røgelse paa Højene.
Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà pẹ̀lú ọba Israẹli.
45 Og Josafat holdt Fred med Israels Konge.
Ní ti ìyókù ìṣe Jehoṣafati àti ìṣe agbára rẹ̀ tí ó ṣe, àti bí ó ti jagun sí, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
46 Men det øvrige af Josafats Handeler og hans Magt, hvilken han skaffede sig, og hvorledes han har stridt, er det ikke skrevet i Judas Kongers Krønikers Bog?
Ó pa ìyókù àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà ní ọjọ́ Asa baba rẹ̀ run kúrò ní ilẹ̀ náà.
47 Og de øvrige af Skørlevnerne, som vare blevne tilbage fra Asas, hans Faders, Dage, borttog han af Landet.
Nígbà náà kò sí ọba ní Edomu; adelé kan ni ọba.
48 Og der var ingen Konge i Edom; men en Befalingsmand var Konge.
Jehoṣafati kan ọkọ̀ Tarṣiṣi láti lọ sí Ofiri fún wúrà, ṣùgbọ́n wọn kò lọ, nítorí àwọn ọkọ̀ náà fọ́ ní Esioni-Geberi.
49 Og Josafat havde ti Tharsisskibe, som skulde drage til Ofir efter Guld; men de droge ikke derhen, thi Skibene bleve sønderslagne i Ezion-Geber.
Ní ìgbà náà Ahasiah ọmọ Ahabu wí fún Jehoṣafati pé, “Jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ mi bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ nínú ọkọ̀,” ṣùgbọ́n Jehoṣafati kọ̀.
50 Da sagde Ahasia, Akabs Søn, til Josafat: Lad mine Tjenere fare med dine Tjenere paa Skibene; men Josafat vilde ikke.
Nígbà náà ni Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi, baba rẹ. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
51 Og Josafat laa med sine Fædre og blev begraven med sine Fædre i Davids, sin Faders, Stad; og Joram, hans Søn, blev Konge i hans Sted.
Ahasiah ọmọ Ahabu bẹ̀rẹ̀ sí jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún kẹtàdínlógún Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjì lórí Israẹli.
52 Ahasia, Akabs Søn, blev Konge over Israel i Samaria udi Josafats, Judas Konges, syttende Aar og var Konge over Israel to Aar.
Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, nítorí tí ó rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀, àti ní ọ̀nà ìyá rẹ̀, àti ní ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó mú Israẹli dẹ́ṣẹ̀.
53 Og han gjorde det, som ondt var for Herrens Øjne, og vandrede i sin Faders Vej og i sin Moders Vej og i Jeroboams, Nebats Søns, Vej, hans, som kom Israel tir at synde. Og han tjente Baal og tilbad ham og opirrede Herren, Israels Gud, alt ligesom hans Fader gjorde.
Ó sì sin Baali, ó sì ń bọ Baali, ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ ti ṣe.

< Første Kongebog 22 >