< 2 Korintským 5 >

1 Víme přece, že až zemřeme, ožijeme znovu v lepší a konečné podobě. (aiōnios g166)
Nítorí àwa mọ̀ pé, bi ilé àgọ́ wa ti ayé ba wó, àwa ní ilé kan láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run, ilé tí a kò fi ọwọ́ kọ́, ti ayérayé nínú àwọn ọ̀run. (aiōnios g166)
2 Toužíme po tom a zároveň kolísáme,
Nítorí nítòótọ́ àwa ń kérora nínú èyí, àwa sì ń fẹ́ gidigidi láti fi ilé wa ti ọ̀run wọ̀ wá.
3 protože bychom se rádi vyhnuli umírání a vstoupili přímo do nesmrtelného života,
Bí ó bá ṣe pé a ti fi wọ̀ wá, a kì yóò bá wa ní ìhòhò.
4 k němuž nás Bůh už nyní připravuje:
Nítorí àwa tí a ń bẹ nínú àgọ́ yìí ń kérora nítòótọ́, kì í ṣe nítorí tí àwa fẹ́ jẹ́ aláìwọṣọ, ṣùgbọ́n pé a ó wọ̀ wá ní aṣọ sí i, kí ìyè ba à lè gbé ara kíkú mì.
5 jako záruku nám dal svého Ducha.
Ǹjẹ́ ẹni tí ó ti pèsè wa fún nǹkan yìí ni Ọlọ́run, ẹni tí o sì ti fi Ẹ̀mí fún wa pẹ̀lú ni ẹ̀rí ìdánilójú ohun tí ń bọ̀.
6 Proto se můžeme důvěřivě těšit na náš nebeský domov; ve svých tělech tu vlastně žijeme v cizině, daleko od své vlasti, kde nás očekává Kristus.
Nítorí náà àwa ní ìgboyà nígbà gbogbo, àwa sì mọ̀ pé, nígbà tí àwa ń bẹ ní ilé nínú ara, àwa kò sí lọ́dọ̀ Olúwa.
7 Nevidíme ho, ale jsme s ním spojeni vírou.
Àwa ń gbé nípa ìgbàgbọ́, kì í ṣe nípa rí rí.
8 Proto s plnou důvěrou a rád opustím třeba hned toto tělo, abych získal domov u svého Pána.
Mo ní, àwa ní ìgboyà, àwa sì ń fẹ́ kí a kúkú ti inú ara kúrò, kí a sì lè wà ní ilé lọ́dọ̀ Olúwa.
9 V každém případě však chci dělat to, co se líbí jemu, ať už to znamená setrvat zde v cizině, nebo se vydat do své vlasti. Na ničem jiném totiž nezáleží.
Nítorí náà àwa ń ṣakitiyan, pé, bí àwa bá wà ní ilé tàbí bí a kò sí, kí àwa lè jẹ́ ẹni ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ rẹ̀.
10 Tak jako tak se nakonec všichni musíme postavit před Kristův soud, kde bude každý náš čin, dobrý i zlý, spravedlivě ohodnocen.
Nítorí pé gbogbo wa ni ó gbọdọ̀ fi ara hàn níwájú ìtẹ́ ìdájọ́ Kristi; kí olúkúlùkù lè gbà èyí tí ó ṣe gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó tọ́ sí i nígbà tí ó wà nínú ara ìbá à ṣe rere tàbí búburú.
11 Je to právě tahle bázeň před Bohem, která mě nutí vést lidi k víře. Bůh moje pohnutky zná a věřím, že ani vy mne nepodezíráte z něčeho postranního.
Nítorí náà bí àwa ti mọ ẹ̀rù Olúwa, àwa ń yí ènìyàn lọ́kàn padà; ṣùgbọ́n a ń fi wá hàn fún Ọlọ́run; mo sì gbàgbọ́ pé, a sì ti fì wá hàn ní ọkàn yín pẹ̀lú.
12 Ne, nechci znovu sebe vychvalovat. Chci vám jen ukázat, že se za mne nemusíte stydět, a tak můžete zavřít ústa těm, kdo si zakládají na vnějším projevu místo na vnitřní hodnotě. Poslouží-li to k Boží slávě, ať si mě lidé mají třeba za blázna. Jsem-li však při dobrých smyslech, poslouží to zase vám.
Nítorí àwa kò sì ní máa tún yin ara wá sí i yín mọ́, ṣùgbọ́n àwa fi ààyè fún yín láti máa ṣògo nítorí wa, kí ẹ lè ní ohun tí ẹ̀yin yóò fi dá wọn lóhùn, àwọn ti ń ṣògo lóde ara kì í ṣe ní ọkàn.
Nítorí náà bí àwa bá ń sínwín, fún Ọlọ́run ni tàbí bí iyè wá bá ṣí pépé, fún yín ni.
14 Kristova láska nás zajala. Je přece zřejmé, že smrt toho, kdo zemřel za všechny, se rovná tomu, jako kdyby zemřeli všichni,
Nítorí ìfẹ́ Kristi ń rọ̀ wá, nítorí àwa mọ̀ báyìí pé, bí ẹnìkan bá kú fún gbogbo ènìyàn, ǹjẹ́ nígbà náà, gbogbo wọ́n ni ó ti kú.
15 takže naše životy nepatří už nám, ale tomu, kdo za nás zemřel a vstal z mrtvých.
Ó sì ti kú fún gbogbo wọn, pé kí àwọn tí ó wà láààyè má sì ṣe wà láààyè fún ara wọn mọ́, bí kò ṣe fún ẹni tí ó kú nítorí wọn, tí ó sì ti jíǹde.
16 Není tedy správné posuzovat někoho podle toho, co o něm soudí svět nebo jaký se navenek jeví. Takto chybně jsem se kdysi i já díval na Krista a posuzoval jej jako každého jiného člověka. Jak jsem se mýlil!
Nítorí náà láti ìsinsin yìí lọ, àwa kò mọ ẹnìkan nípa ti ara mọ́; bí àwa tilẹ̀ ti mọ Kristi nípa ti ara, ṣùgbọ́n nísinsin yìí àwa kò mọ̀ ọ́n bẹ́ẹ̀ mọ́.
17 Kdo se stane křesťanem, stává se úplně jiným člověkem. Už nikdy není takovým, jakým byl předtím. Začal docela nový život!
Nítorí náà bí ẹnìkan bá wà nínú Kristi, ó di ẹ̀dá tuntun: ohun àtijọ́ ti kọjá lọ; kíyèsi i, ohun tuntun ti dé.
18 To je změna, kterou působí sám Bůh. Ačkoliv jsme se nacházeli v nepřátelském táboře,
Ohun gbogbo sì ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, ẹni tí ó sì tipasẹ̀ Jesu Kristi bá wa làjà sọ́dọ̀ ara rẹ̀, tí ó sì ti fi iṣẹ́ ìránṣẹ́ ìlàjà fún wa.
19 Bůh s námi prostřednictvím Ježíše Krista uzavřel mír a pak nás pověřil, abychom jeho jménem předložili nabídku smíření všem lidem na této planetě.
Èyí ni pé, Ọlọ́run wà nínú Kristi, ó ń bá aráyé làjà sọ́dọ̀ ara rẹ̀, kò sí ka ìrékọjá wọn sí wọn lọ́rùn; ó sì ti fi ọ̀rọ̀ ìlàjà lé wa lọ́wọ́.
20 Z Kristova pověření – jako jeho velvyslanci – tedy provoláváme, aby to všichni slyšeli: Pojďte a přijměte přátelskou ruku, kterou vám Bůh v Kristu podává!
Nítorí náà àwa ni ikọ̀ fún Kristi, bí ẹni pé Ọlọ́run ń ti ọ̀dọ̀ wa ṣìpẹ̀ fún yín: àwa ń bẹ̀ yín ní ipò Kristi, “Ẹ bá Ọlọ́run làjà.”
21 Na toho, který se nikdy nedopustil ničeho špatného, přenesl Bůh všechnu naši špatnost a jeho spravedlnost přenesl na nás.
Nítorí ó tí fi í ṣe ẹ̀ṣẹ̀ nítorí wa, ẹni tí kò mọ ẹ̀ṣẹ̀kẹ́ṣẹ̀ rí, kí àwa lè di òdodo Ọlọ́run nínú rẹ̀.

< 2 Korintským 5 >