< Rút 2 >

1 Měla pak Noémi přítele po manželu svém, muže mocného z čeledi Elimelechovy, jménem Bóza.
Naomi ní ìbátan kan láti ìdílé Elimeleki ọkọ rẹ̀, aláàánú ọlọ́rọ̀, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Boasi.
2 I řekla Rut Moábská Noémi: Nechť medle jdu na pole sbírati klasů za tím, kdož by mi toho přál. Jížto ona řekla: Jdi, dcero má.
Rutu ará Moabu sì wí fún Naomi pé, “Jẹ́ kí èmi kí ó lọ sí inú oko láti ṣá ọkà tí àwọn olùkórè fi sílẹ̀ ní ọ̀dọ̀ ẹnikẹ́ni tí èmi yóò bá ojúrere rẹ̀ pàdé.” Naomi sì sọ fún un pé, “Máa lọ, ọmọbìnrin mi.”
3 Šla tedy, a přišedši, sbírala klasy na poli za ženci. Přihodilo se pak, že přišla na díl pole toho, kteréž přináleželo Bózovi, jenž byl z čeledi Elimelechovy.
Rutu sì jáde lọ láti ṣá ọkà tí àwọn olùkórè fi sílẹ̀ lẹ́yìn wọn. Ó wá jẹ́ wí pé inú oko Boasi tí ó ti ìdílé Elimeleki wá ni ó lọ láìmọ̀-ọ́n-mọ̀.
4 A v tom přišel Bóz z Betléma, a řekl žencům: Hospodin s vámi. Kteříž odpověděli jemu: Požehnejž tobě Hospodin.
Nígbà náà ni Boasi dé láti Bẹtilẹhẹmu tí ó sì kí àwọn olùkórè wí pé, “Kí Olúwa wà pẹ̀lú yín.” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Kí Olúwa bùkún fún ọ.”
5 I řekl Bóz služebníku svému, kterýž postaven byl nad ženci: Èí jest tato mladice?
Boasi sì béèrè lọ́wọ́ olórí àwọn olùkórè wí pé, “Ti ta ni ọ̀dọ́mọbìnrin yẹn?”
6 Odpověděl služebník ten, kterýž postaven byl nad ženci, a řekl: Jest mladice Moábská, kteráž přišla s Noémi z země Moábské.
Ìránṣẹ́ tí ó jẹ́ olórí àwọn olùkórè náà sì fèsì pé, “Ọ̀dọ́mọbìnrin ará Moabu tí ó tẹ̀lé Naomi wá láti ilẹ̀ Moabu ni.
7 A řekla mi: Prosím, nechť sbírám a shromažďuji klasy mezi snopy za ženci. A přišedši, trvá od jitra až dosavad, kromě že na chvilku doma pobyla.
Ó sọ wí pé, ‘Kí ń jọ̀wọ́ jẹ́ kí òun máa ṣá ọkà lẹ́yìn àwọn olùkórè.’ Ó sì ti ń ṣe iṣẹ́ kárakára láti òwúrọ̀ títí di ìsinsin yìí nínú oko àyàfi ìgbà tí ó lọ láti sinmi fún ìgbà díẹ̀ lábẹ́ ibojì.”
8 Tedy řekl Bóz k Rut: Slyš, dcero má, nechoď sbírati na jiné pole, aniž odcházej odsud, ale přídrž se teď děvek mých.
Nígbà náà ni Boasi sọ fún Rutu pé, “Gbọ́ ọmọbìnrin mi, má ṣe lọ sí oko mìíràn láti ṣá ọkà, má sì ṣe kúrò ní ibi. Dúró níbí pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi.
9 Zůstávej na tom poli, na němž budou žíti, a choď za nimi, nebo jsem přikázal služebníkům svým, aby se tebe žádný nedotýkal. Bude-liť se chtíti píti, jdi k nádobám, a napí se té vody, kteréž by navážili služebníci moji.
Wo ibi tí wọ́n ti ń kórè kí o sì máa tẹ̀lé àwọn obìnrin. Mo ti pàṣẹ fún àwọn ọkùnrin kí wọ́n má ṣe fi ọwọ́ kàn ọ́. Nígbàkígbà tí òǹgbẹ bá sì ń gbẹ ọ́, lọ kí ó sì mu omi nínú àmù èyí tí àwọn ọkùnrin ti pọn omi sí nínú.”
10 Tedy ona padla na tvář svou, a schýlivši se k zemi, řekla jemu: Odkudž mi to, že jsem nalezla milost před tebou, abys se známil ke mně, kteráž jsem cizozemka.
Rutu wólẹ̀, ó sì wí fún Boasi pé, “Èéṣe tí èmi fi bá ojúrere rẹ pàdé tó báyìí, tí o sì kíyèsi mi, èmi àjèjì àti àlejò?”
11 Odpověděl Bóz a řekl: O všemť mi oznámeno jest, co jsi koli činila svegruši své po smrti muže svého, a že opustivši otce svého a matku svou, i zemi, v kteréžs se narodila, šla jsi mezi lid, kteréhožs prvé neznala.
Boasi sì fèsì wí pé, “Èmi ti gbọ́ gbogbo bí o ti ń ṣe sí ìyá ọkọ ọ̀ rẹ láti ìgbà tí ọkọ rẹ ti kú àti bí o ti ṣe fi baba àti ìyá rẹ àti ilẹ̀ rẹ sílẹ̀, tí o sì wá láti gbé láàrín àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ̀ tẹ́lẹ̀ rí.
12 Odplatiž tobě Hospodin za skutek tvůj, a budiž mzda tvá dokonalá od Hospodina Boha Izraelského, poněvadž jsi přišla, abys pod křídly jeho doufala.
Kí Olúwa kí ó san ẹ̀san ohun tí ìwọ ṣe fún ọ. Kí o sì gba èrè kíkún láti ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, abẹ́ ìyẹ́ ẹni tí ìwọ sá wá fún ààbò.”
13 Kterážto řekla: Nalezla jsem milost před tebou, pane můj, poněvadž jsi mne potěšil, a mluvils k srdci děvky své, ješto nejsem podobná jedné z děvek tvých.
Rutu sì fèsì wí pé, “Kí èmi kí ó máa rí ojúrere láti ọ̀dọ̀ rẹ síwájú sí i olúwa mi. Ìwọ ti tù mí nínú nípa sísọ ọ̀rọ̀ rere sí ìránṣẹ́bìnrin rẹ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò tó ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ.”
14 Tedy řekl jí Bóz: Když bude čas jísti, přistup sem, a pojez chleba, a omoč skyvu svou v octě. I posadila se při žencích, a podal jí pražmy; ona pak jedla až do sytosti, a ještě jí zbylo.
Nígbà tí àkókò oúnjẹ sì tó, Boasi sọ fún Rutu pé, “Wá gba ìwọ̀n àkàrà yìí kí o sì fi run wáìnì kíkan.” Òun sì jókòó pẹ̀lú àwọn olùkórè, Boasi sì fún un ní ọkà yíyan. Òun sì jẹ́, ó yó, ó sì tún ṣẹ́kù.
15 I vstala, aby sbírala. Přikázal pak Bóz služebníkům svým, řka: Byť pak i mezi snopy sbírala, nezbraňujte jí.
Nígbà tí ó sì dìde láti máa ṣá ọkà, Boasi pàṣẹ fún àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀ wí pé, “Bí ó tilẹ̀ ń ṣà láàrín oko ọkà pàápàá, ẹ má ṣe dí i lọ́wọ́.
16 Nýbrž naschvál jí upouštějte z snopů a nechávejte, ať sbírá, a nedomlouvejte jí.
Bí kò ṣe pé kí ẹ mú lára àwọn ìtí sílẹ̀ fún láti ṣá, kí ẹ má sì ṣe ba a wí.”
17 Sbírala tedy na poli tom až do večera, a což sebrala, to vymlátila; i byla téměř míra efi ječmene.
Rutu sì ń ṣá ọkà títí ó fi di ìrọ̀lẹ́, nígbà tí ó sì pa ọkà barle tí ó rí ṣà, tí ó sì fẹ́ ẹ tán, èyí tí ó rí sì tó ìwọ̀n garawa kan (lita méjìlélógún).
18 Kterýž vzavši, přišla do města, a viděla svegruše její to, což nasbírala. Vyňala také a dala jí to, což pozůstalo po nasycení jejím.
Ó sì gbé e, ó sì lọ sí ìlú, ìyá ọkọ rẹ sì rí ọkà tí ó rí ṣà bi o tí pọ̀ tó, Rutu sì mú oúnjẹ tí ó jẹ kù lẹ́yìn tí ó ti yó tan fún ìyá ọkọ rẹ̀.
19 I řekla jí svegruše její: Kdes sbírala dnes, a kdes pracovala? Budiž požehnaný ten, kterýž tě přijal. Tedy oznámila svegruši své, u koho pracovala, řkuci: Jméno muže, u kteréhož jsem pracovala dnes, jest Bóz.
Ìyá ọkọ rẹ̀ sì bi í léèrè wí pé, “Níbo ni ìwọ ti ṣá ọkà lónìí? Àti wí pé oko ta ni ìwọ gbé ṣiṣẹ́? Alábùkún fún ni ọkùnrin náà tí ó bojú wò ọ.” Rutu sì sọ ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ti ṣiṣẹ́ fún ìyá ọkọ rẹ̀ pé, “Ní oko ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Boasi ni mo ti ṣiṣẹ́ lónìí.”
20 I řekla Noémi nevěstě své: Požehnanýť jest od Hospodina, že nepřestal milosrdenství svého nad živými i mrtvými. I to ještě k ní řekla Noémi: Blízký přítel náš a z příbuzných našich jest muž ten.
Naomi sì wí fún un pé, “Kí Olúwa, kí ó bùkún fún ọkùnrin náà. Ọlọ́run kò dáwọ́ oore àti àánú ṣíṣe sí àwọn alààyè àti òkú dúró.” Naomi sì sọ síwájú sí i wí pé, “Ìbátan tí ó súnmọ́ wa pẹ́kípẹ́kí ni ọkùnrin náà ń ṣe, ó sì jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ra ohun ìní ìdílé padà.”
21 Řekla jí také Rut Moábská: I to mi ještě řekl: Èeládky mé přídrž se, dokavadž by všeho, což mého jest, nedožali.
Rutu, ará Moabu sì wí pé, “Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ó sọ fún mi pé, ‘Kí ń máa ṣá ọkà pẹ̀lú àwọn òṣìṣẹ́ òun, títí wọn yóò fi parí ìkórè.’”
22 Tedy řekla Noémi Rut nevěstě své: Dobré jest tedy, dcero má, abys vycházela s děvečkami jeho, ať by na jiném poli něco nepřekazili.
Naomi sì sọ fún Rutu, ìyàwó ọmọ rẹ̀ pé, “Ìbá dára bí ó bá le bá àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ ṣiṣẹ́. Nítorí pé wọ́n le è dà ọ́ láàmú bí o bá lọ sí oko ẹlòmíràn.”
23 A tak se přídržela Rut děvek Bózových, a sbírala klasy, dokudž nesžali ječmene a pšenice, a bydlela u svegruše své.
Rutu sì bá àwọn ìránṣẹ́bìnrin Boasi ṣiṣẹ́ títí tí wọ́n fi parí ìkórè ọkà barle àti ti jéró. Ó sì ń gbé pẹ̀lú ìyá ọkọ rẹ̀.

< Rút 2 >