< Žalmy 90 >

1 Modlitba Mojžíše, muže Božího. Pane, ty jsi býval příbytek náš od národu do pronárodu.
Àdúrà Mose ènìyàn Ọlọ́run. Olúwa, ìwọ ti jẹ́ ibùgbé wa ní gbogbo ìran dé ìran.
2 Prvé, než hory stvořeny byly, nežlis sformoval zemi, a okršlek světa, ano hned od věků a až na věky, ty jsi Bůh silný.
Kí a tó bí àwọn òkè ńlá àti kí ìwọ tó dá ilẹ̀ àti ayé, láti ayérayé dé ayérayé ìwọ ni Ọlọ́run.
3 Ty přivodíš člověka na to, aby setřín byl, říkaje: Navraťtež se zase, synové lidští.
Ìwọ yí ènìyàn padà sí erùpẹ̀, wí pé, “Padà sí erùpẹ̀, ìwọ ọmọ ènìyàn.”
4 Nebo by tisíc let přetrval, jest to před očima tvýma jako den včerejší, a bdění noční.
Nítorí pé ìgbà tí ẹgbẹ̀rún ọdún bá kọjá lójú rẹ, bí àná ni ó rí, bí ìgbà ìṣọ́ kan lóru.
5 Povodní zachvacuješ je; jsou sen, a jako bylina hned v jitře pomíjející.
Ìwọ gbá ènìyàn dànù nínú oorun ikú; wọ́n dàbí koríko tuntun ní òwúrọ̀.
6 Toho jitra, kteréhož vykvetne, mění se, u večer pak jsuc podťata, usychá.
Lóòtítọ́, ní òwúrọ̀, ó yọ tuntun ní àṣálẹ́ ni yóò gbẹ, tí yóò sì rẹ̀ dànù.
7 Ale my hyneme od hněvu tvého, a prochlivostí tvou jsme zděšeni.
A pa wá run nípa ìbínú rẹ nípa ìbínú rẹ ara kò rọ̀ wá.
8 Nebo jsi položil nepravosti naše před sebe, a tajnosti naše na světlo oblíčeje svého.
Ìwọ ti gbé ẹ̀ṣẹ̀ wa ka iwájú rẹ, àti ohun ìkọ̀kọ̀ wa nínú ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ.
9 Pročež všickni dnové naši v náhle přebíhají pro tvé rozhněvání; k skončení let svých docházíme jako řeč.
Gbogbo ọjọ́ wa ń kọjá lọ lábẹ́ ìbínú rẹ; àwa ń lo ọjọ́ wa lọ bí àlá tí à ń rọ́.
10 Všech dnů let našich jest let sedmdesáte, aneb jest-li kdo silnějšího přirození, osmdesát let, a i to, což nejzdárnějšího v nich, jest práce a bída, a když to pomine, tožť ihned rychle zaletíme.
Àádọ́rin ọdún ni iye ọjọ́ ọdún wá, bi ó sì ṣe pé nípa agbára tí wọn bá tó ọgọ́rin ọdún, agbára nínú làálàá pẹ̀lú ìbànújẹ́ ni, nítorí pé a kò ní pẹ́ gé e kúrò, àwa a sì fò lọ.
11 Ale kdo jest, ješto by znal přísnost hněvu tvého, a ostýchal se zůřivosti tvé?
Ta ni ó mọ agbára ìbínú rẹ? Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ.
12 Naučiž nás počítati dnů našich, abychom uvodili moudrost v srdce.
Kọ́ wa bí a ti ń kaye ọjọ́ wa dáradára, kí àwa ba à lè fi ọkàn wa sípa ọgbọ́n.
13 Navrať se zase, Hospodine, až dokud prodléváš? Mějž lítost nad služebníky svými.
Yípadà, Olúwa! Yóò ti pẹ́ tó? Ṣàánú fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ.
14 Nasyť nás hned v jitře svým milosrdenstvím, tak abychom prozpěvovati, a veseliti se mohli po všecky dny naše.
Tẹ́ wa lọ́rùn ní òwúrọ̀ nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ, kí àwa kí ó lè kọrin fún ayọ̀ kí inú wa sì dùn ní gbogbo ọjọ́.
15 Obveseliž nás podlé dnů, v nichž jsi nás ssužoval, a let, v nichž jsme okoušeli zlého.
Mú inú wa dùn bí ọjọ́ tí ìwọ ti pọ́n wa lójú, fún ọjọ́ púpọ̀ tí àwa ti rí wàhálà.
16 Budiž zřejmé při služebnících tvých dílo tvé, a okrasa tvá při synech jejich.
Jẹ́ kí a fi iṣẹ́ rẹ̀ han àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ògo rẹ̀ sí àwọn ọmọ wọn.
17 Budiž nám přítomná i ochotnost Hospodina Boha našeho, a díla rukou našich potvrď mezi námi, díla, pravím, rukou našich potvrď.
Jẹ́ kí ẹwà Olúwa Ọlọ́run wa wà lára wa; fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀ lára wa, bẹ́ẹ̀ ni, kí ó sì fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀.

< Žalmy 90 >