< Žalmy 89 >
1 Vyučující, složený od Etana Ezrachitského. O milosrdenstvích Hospodinových na věky zpívati budu, od národu do pronárodu zvěstovati budu pravdu tvou ústy svými.
Maskili ti Etani ará Esra. Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé; pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
2 Nebo jsem řekl: Na věky milosrdenství vzdělávati se bude, na nebi utvrdíš pravdu svou, o nížs řekl:
Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé, pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnra rẹ̀.
3 Učinil jsem smlouvu s vyvoleným svým, přisáhl jsem Davidovi služebníku svému,
Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.
4 Že až na věky utvrdím símě tvé, a vzdělám od národu do národu trůn tvůj. (Sélah)
‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’”
5 Protož oslavují nebesa div tvůj, Hospodine, i pravdu tvou v shromáždění svatých.
Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa, òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.
6 Nebo kdo na nebi přirovnán býti může Hospodinu? Kdo jest podobný Hospodinu mezi syny silných?
Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa? Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?
7 Bůh i v shromáždění svatých strašlivý jest náramně, a hrozný nade všecky vůkol něho.
Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi; ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.
8 Hospodine Bože zástupů, kdo jest jako ty, silný Hospodin? Nebo pravda tvá tobě přístojí všudy vůkol.
Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.
9 Ty panuješ nad dutím moře; když se zdvihají vlny jeho, ty je skrocuješ.
Ìwọ ń darí ríru omi Òkun; nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.
10 Ty jsi jako raněného potřel Egypt, a silným ramenem svým rozptýlil jsi nepřátely své.
Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ bí ẹni tí a pa; ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.
11 Tváť jsou nebesa, tvá také i země, okršlek i plnost jeho ty jsi založil.
Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ: ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀: ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.
12 Půlnoční i polední strana, kteréž jsi ty stvořil, i Tábor a Hermon o tvém jménu zpívají.
Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn; Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.
13 Tvé rámě jest přemocné, silná ruka tvá, a vyvýšená pravice tvá.
Ìwọ ní apá agbára; agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
14 Spravedlnost a soud jsou základem trůnu tvého, milosrdenství a pravda předcházejí tvář tvou.
Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ: ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.
15 Blahoslavený lid, kterýž zná zvuk tvůj; tiť, Hospodine, v světle oblíčeje tvého choditi budou.
Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì, Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.
16 Ve jménu tvém plésati budou každého dne, a v spravedlnosti tvé vyvýší se.
Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́, wọn ń yin òdodo rẹ.
17 Nebo sláva síly jejich ty jsi, a z milosti tvé k zvýšení přijde roh náš.
Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn; nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.
18 Nebo štít náš jest Hospodinův, a svatého Izraelského král náš.
Nítorí ti Olúwa ni asà wa, ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
19 Tehdy mluvě u vidění k svatému svému, řekl jsi: Složil jsem pomoc v reku udatném, zvýšil jsem vybraného z lidu.
Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé, “Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára, èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.
20 Nalezl jsem Davida služebníka svého, olejem svým svatým pomazal jsem ho.
Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi; pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án.
21 A protož budeť s ním stále ruka má, ano i ramenem svým posilovati ho budu.
Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀ apá mí yóò sì fi agbára fún un.
22 Nebudeť ho moci nuziti nepřítel, ani člověk nešlechetný trápiti.
Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀, àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
23 Nebo potru před tváří jeho protivníky jeho, a ty, kteříž ho nenávidí, porazím.
Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀.
24 Nadto pravda má a milosrdenství mé s ním bude, a ve jménu mém vyvýšen bude roh jeho.
Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.
25 A vložím na moře ruku jeho, a na řeky pravici jeho.
Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí òkun, àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá.
26 On volaje ke mně, dí: Ty jsi otec můj, Bůh silný můj a skála spasení mého.
Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘Ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
27 Já také za prvorozeného vystavím jej, a za vyššího králů zemských.
Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi, ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.
28 Na věky zachovám jemu milosrdenství své, a smlouva s ním stálá bude.
Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un, àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
29 Učiním i to, aby na věky trvalo símě jeho, a trůn jeho jako dnové nebes.
Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé, àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.
30 Jestliže by pak synové jeho opustili zákon můj, a v soudech mých nechodili,
“Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀ tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
31 Jestliže by ustanovení mých poškvrnili, a přikázaní mých neostříhali:
Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́ tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
32 Tedy navštívím metlou přestoupení jejich, a trestáním nepravost jejich,
nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò; àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán;
33 Ale milosrdenství svého neodejmu od něho, aniž klamati budu proti pravdě své.
ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
34 Nepoškvrnímť smlouvy své, a toho, což vyšlo z úst mých, nezměním.
Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.
35 Jednou jsem přisáhl skrze svatost svou, nesklamámť Davidovi,
Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra; èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.
36 Že símě jeho na věky bude, a trůn jeho jako slunce přede mnou,
Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé, àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.
37 Jako měsíc utvrzeno bude na věky, a jako svědkové na obloze hodnověrní.
A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá, àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run.” (Sela)
38 Ale ty jsi jej zavrhl a potupil, rozhněvals se na pomazaného svého.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra; ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni àmì òróró rẹ.
39 Zavrhl jsi smlouvu s služebníkem svým, povrhls korunu jeho na zem.
Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo; ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku.
40 Roztrhal jsi všecky ohrady jeho, a bašty jeho jsi rozválel.
Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀ ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.
41 Derou jej všickni, kteříž tudy jdou; jest ku posměchu i sousedům svým.
Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ; ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.
42 Vyvýšil jsi pravici protivníků jeho, obveselils všecky nepřátely jeho.
Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè; ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.
43 Ztupils i ostří meče jeho, aniž jsi dal jemu, aby ostáti mohl v boji.
Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà, ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.
44 Učinils přítrž okrase jeho, a trůn jeho svrhl jsi na zem.
Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà, ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.
45 Ukrátil jsi dnů mladosti jeho, a hanbous jej přiodíl. (Sélah)
Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú; ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.
46 Až dokud, Hospodine? Na věky-liž se skrývati budeš? Tak-liž hořeti bude jako oheň prchlivost tvá?
Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa? Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé? Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?
47 Rozpomeniž se na mne, jak kratičký jest věk můj. Zdaliž jsi pak nadarmo stvořil všecky syny lidské?
Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!
48 Kdo z lidí může tak živ býti, aby neokusil smrti? Kdo vytrhne život svůj z hrobu? (Sélah) (Sheol )
Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀? Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú? (Sheol )
49 Kdež jsou milosrdenství tvá první, ó Pane? Přísahuť jsi učinil Davidovi, v pravdě své.
Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà, tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?
50 Pamatuj, Pane, na útržky činěné služebníkům tvým, a jak jsem já nosil v lůně svém potupu ode všech nejmocnějších národů,
Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ; bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,
51 Jak jsou utrhali nepřátelé tvoji, Hospodine, jak jsou utrhali šlepějím pomazaného tvého.
ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa, tí wọn gan ipasẹ̀ ẹni àmì òróró rẹ.
52 Budiž pochválen Hospodin na věky, Amen i Amen.
Olùbùkún ní Olúwa títí láé.