< Žalmy 145 >

1 Chvalitebná píseň Davidova. Vyvyšovati tě budu, Bože můj králi, a dobrořečiti jménu tvému na věky věků.
Saamu ìyìn. Ti Dafidi. Èmi yóò gbé ọ ga, Ọlọ́run ọba mi; èmi yóò yin orúkọ rẹ̀ láé àti láéláé.
2 Na každý den dobrořečiti budu tobě, a chváliti jméno tvé na věky věků.
Ní ojoojúmọ́ èmi yóò yìn ọ́ èmi yóò sì pòkìkí orúkọ rẹ láé àti láéláé.
3 Hospodin veliký jest, a vší chvály hodný, a velikost jeho nemůž vystižena býti.
Títóbi ni Olúwa. Òun sì ni ó yẹ láti fi ìyìn fún púpọ̀púpọ̀: kò sí ẹni tí ó lè wọn títóbi rẹ̀.
4 Rodina rodině vychvalovati bude skutky tvé, a předivnou moc tvou zvěstovati.
Ìran kan yóò máa yin iṣẹ́ rẹ dé ìran mìíràn; wọn yóò máa sọ iṣẹ́ agbára rẹ.
5 O slávě a kráse velebnosti tvé, i o věcech tvých předivných mluviti budu.
Wọn yóò máa sọ ìyìn ọláńlá rẹ tí ó lógo, èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú iṣẹ́ ìyanu rẹ.
6 A moc přehrozných skutků tvých rozhlašovati budou; i já důstojnost tvou budu vypravovati.
Wọn yóò sọ iṣẹ́ agbára rẹ tí ó ní ẹ̀rù èmi yóò kéde iṣẹ́ ńlá rẹ̀.
7 Pamět mnohé dobroty tvé hlásati budou, a o spravedlnosti tvé zpívati, řkouce:
Wọn yóò ṣe ìrántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwà rere rẹ àti orin ayọ̀ òdodo rẹ.
8 Milostivý a lítostivý jest Hospodin, dlouhoshovívající a velikého milosrdenství.
Olóore-ọ̀fẹ́ ni Olúwa àti aláàánú ó lọ́ra láti bínú ó sì ní ìfẹ́ púpọ̀.
9 Dobrotivý Hospodin všechněm, a slitování jeho nade všecky skutky jeho.
Olúwa dára sí ẹni gbogbo; ó ní àánú lórí ohun gbogbo tí ó dá.
10 Oslavujtež tebe, Hospodine, všickni skutkové tvoji, a svatí tvoji tobě dobrořečte.
Gbogbo ohun tí ìwọ ti dá ni yóò máa yìn ọ́ Olúwa; àwọn ẹni mímọ́ yóò máa pòkìkí rẹ.
11 Slávu království tvého ať vypravují, a o síle tvé mluví,
Wọn yóò sọ ògo ìjọba rẹ wọn yóò sì sọ̀rọ̀ agbára rẹ,
12 Aby v známost uvedli synům lidským moci jeho, a slávu i ozdobu království jeho.
kí gbogbo ènìyàn le mọ iṣẹ́ agbára rẹ̀ àti ọláńlá ìjọba rẹ tí ó lógo.
13 Království tvé jest království všech věků, a panování tvé nad jedním každým pokolením.
Ìjọba rẹ ìjọba ayérayé ni, àti ìjọba rẹ wà ní gbogbo ìrandíran.
14 Zdržujeť Hospodin všecky padající, a pozdvihuje všechněch sklíčených.
Olúwa mú gbogbo àwọn tí ó ṣubú ró ó sì gbé gbogbo àwọn tí ó tẹríba dìde.
15 Oči všechněch v tebe doufají, a ty dáváš jim pokrm jejich v čas příhodný.
Ojú gbogbo ènìyàn ń wò ọ́, ó sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àkókò tí ó yẹ.
16 Otvíráš ruku svou, a nasycuješ každý živočich podlé dobře líbezné vůle své.
Ìwọ ṣí ọwọ́ rẹ ìwọ sì tẹ́ ìfẹ́ gbogbo ohun alààyè lọ́rùn.
17 Spravedlivý jest Hospodin ve všech cestách svých, a milosrdný ve všech skutcích svých.
Olúwa jẹ́ olódodo ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìfẹ́ rẹ̀ sí gbogbo ohun tí o dá.
18 Blízký jest Hospodin všechněm, kteříž ho vzývají, všechněm, kteříž ho vzývají v pravdě.
Olúwa wà ní tòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é, sí gbogbo ẹni tí ń ké pè é ní òtítọ́.
19 Vůli těch, kteříž se ho bojí, činí, a křik jejich slyší, a spomáhá jim.
Ó mú ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ṣẹ; ó gbọ́ igbe wọn, ó sì gbà wọ́n.
20 Ostříhá Hospodin všech, kdož jej milují, ale všecky bezbožné zatratí.
Olúwa dá gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́ sẹ sí ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ẹni búburú ní yóò parun.
21 Chválu Hospodinovu vypravovati budou ústa má, a dobrořečiti bude všeliké tělo jménu svatému jeho od věků až na věky.
Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ìyìn Olúwa. Jẹ́ kí gbogbo ẹ̀dá yín orúkọ rẹ̀ mímọ́ láé àti láéláé.

< Žalmy 145 >