< Žalmy 132 >

1 Píseň stupňů. Pamětliv buď, Hospodine, na Davida i na všecka trápení jeho,
Orin fún ìgòkè. Olúwa, rántí Dafidi nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
2 Jak se přísahou zavázal Hospodinu, a slib učinil Nejmocnějšímu Jákobovu, řka:
Ẹni tí ó ti búra fún Olúwa, tí ó sì ṣe ìlérí fún alágbára Jakọbu pé.
3 Jistě že nevejdu do stánku domu svého, a nevstoupím na postel ložce svého,
Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ, bẹ́ẹ̀ èmi kì yóò gun orí àkéte mi.
4 Aniž dám očím svým usnouti, ani víčkám svým zdřímati,
Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi, tàbí òògbé fún ìpéǹpéjú mi,
5 Dokudž nenajdu místa Hospodinu, k příbytkům Nejmocnějšímu Jákobovu.
títí èmi ó fi rí ibi fún Olúwa, ibùjókòó fún alágbára Jakọbu.
6 Aj, uslyšavše o ní, že byla v kraji Efratském, našli jsme ji na polích Jaharských.
Kíyèsi i, àwa gbúròó rẹ̀ ni Efrata: àwa rí i nínú oko ẹgàn náà.
7 Vejdemeť již do příbytků jeho, a skláněti se budeme u podnoží noh jeho.
Àwa ó lọ sínú àgọ́ rẹ̀: àwa ó máa sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
8 Povstaniž, Hospodine, a vejdi do odpočinutí svého, ty i truhla velikomocnosti tvé.
Olúwa, dìde sí ibi ìsinmi rẹ: ìwọ, àti àpótí agbára rẹ.
9 Kněží tvoji ať se zobláčejí v spravedlnost, a svatí tvoji ať vesele prozpěvují.
Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà rẹ: kí àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ kí ó máa hó fún ayọ̀.
10 Pro Davida služebníka svého neodvracejž tváři pomazaného svého.
Nítorí tí Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, má ṣe yí ojú ẹni òróró rẹ padà.
11 Učinilť jest Hospodin pravdomluvnou přísahu Davidovi, aniž se od ní uchýlí, řka: Z plodu života tvého posadím na trůn tvůj.
Olúwa ti búra nítòótọ́ fún Dafidi, Òun kì yóò yípadà kúrò nínú rẹ̀, nínú irú-ọmọ inú rẹ ni èmi ó gbé kalẹ̀ sí orí ìtẹ́ rẹ.
12 Budou-li ostříhati synové tvoji smlouvy mé a svědectví mých, kterýmž je vyučovati budu, také i synové jejich až na věky seděti budou na stolici tvé.
Bí àwọn ọmọ rẹ̀ yóò bá pa májẹ̀mú mi mọ́ àti ẹ̀rí mi tí èmi yóò kọ́ wọn, àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ láéláé.
13 Neboť jest vyvolil Hospodin Sion, oblíbil jej sobě za svůj příbytek, řka:
Nítorí tí Olúwa ti yan Sioni: ó ti fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀.
14 Toť bude obydlí mé až na věky, tuť přebývati budu, nebo jsem sobě to oblíbil.
Èyí ni ibi ìsinmi mi láéláé: níhìn-ín ni èmi yóò máa gbé: nítorí tí mo fẹ́ ẹ.
15 Potravu jeho hojným požehnáním rozmnožím, chudé jeho chlebem nasytím,
Èmi yóò bùkún oúnjẹ rẹ̀ púpọ̀púpọ̀: èmi yóò fi oúnjẹ tẹ́ àwọn tálákà rẹ̀ lọ́rùn.
16 A kněží jeho v spasení zobláčím, a svatí jeho vesele prozpěvovati budou.
Èmi yóò sì fi ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀: àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ yóò máa hó fún ayọ̀.
17 Tuť způsobím, aby zkvetl roh Davidův; připravím svíci pomazanému svému.
Níbẹ̀ ni èmi yóò gbé mú ìwo Dafidi yọ̀, èmi ti ṣe ìlànà fìtílà kan fún ẹni òróró mi.
18 Nepřátely jeho v hanbu zobláčím, nad ním pak kvésti bude koruna jeho.
Àwọn ọ̀tá rẹ̀ ni èmi yóò fi ìtìjú wọ̀: ṣùgbọ́n lára òun tìkára rẹ̀ ni adé yóò máa gbilẹ̀.

< Žalmy 132 >