< Žalmy 118 >

1 Oslavujte Hospodina, nebo jest dobrý, nebo na věky trvá milosrdenství jeho.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
2 Rciž nyní, Izraeli, že na věky milosrdenství jeho.
Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
3 Rciž nyní, dome Aronův, že na věky milosrdenství jeho.
Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
4 Rcetež nyní bojící se Hospodina, že na věky milosrdenství jeho.
Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
5 V úzkosti vzýval jsem Hospodina, a vyslyšev, uprostrannil mi Hospodin.
Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
6 Hospodin se mnou, nebudu se báti. Co mi může učiniti člověk?
Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
7 Hospodin se mnou jest mezi pomocníky mými, pročež já podívám se těm, kteříž mne mají v nenávisti.
Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
8 Lépe jest doufati v Hospodina, než naději skládati v člověku.
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
9 Lépe jest doufati v Hospodina, nežli naději skládati v knížatech.
Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
10 Všickni národové obklíčili mne, ale ve jménu Hospodinovu vyplénil jsem je.
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
11 Mnohokrát obklíčili mne, ale ve jménu Hospodinovu vyplénil jsem je.
Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
12 Ssuli se na mne jako včely, však zhasli jako oheň z trní: nebo ve jménu Hospodinovu vyplénil jsem je.
Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
13 Velmi jsi ztuha na mne dotíral, abych padl, ale Hospodin spomohl mi.
Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
14 Síla má a písnička má jest Hospodin, on byl můj vysvoboditel.
Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
15 Hlas prokřikování a spasení v staních spravedlivých. Pravice Hospodinova dokázala síly,
Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
16 Pravice Hospodinova vyvýšila se, pravice Hospodinova dokázala síly.
Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
17 Neumruť, ale živ budu, abych vypravoval skutky Hospodinovy.
Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
18 Trestaltě mne přísně Hospodin, ale smrti mne nevydal.
Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
19 Otevřetež mi brány spravedlnosti, a vejda do nich, oslavovati budu Hospodina.
Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
20 Tať jest brána Hospodinova, kterouž spravedliví vcházejí.
Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
21 Tuť já tě oslavovati budu, nebo jsi mne vyslyšel, a byls můj vysvoboditel.
Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
22 Kámen, kterýž zavrhli stavitelé, učiněn jest v hlavu úhelní.
Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
23 Od Hospodina stalo se to, a jest divné před očima našima.
Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
24 Tentoť jest den, kterýž učinil Hospodin, a protož radujme se a veselme se v něm.
Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
25 Prosím, Hospodine, zachovávejž již; prosím, Hospodine, dávej již šťastný prospěch.
Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
26 Požehnaný, jenž se béře ve jménu Hospodinovu; dobrořečíme vám z domu Hospodinova.
Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
27 Bůh silný Hospodin, onť se zasvítil nám, važte beránky až k rohům oltáře.
Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
28 Bůh silný můj ty jsi, protož slaviti tě budu, Bože můj, vyvyšovati tě budu.
Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
29 Oslavujtež Hospodina, neboť jest dobrý, nebo na věky milosrdenství jeho.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.

< Žalmy 118 >