< Žalmy 103 >

1 Davidův. Dobrořeč duše má Hospodinu, a všecky vnitřnosti mé jménu svatému jeho.
Ti Dafidi. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi; àti gbogbo ohun tí ó wà nínú mi, yín orúkọ rẹ̀ mímọ́.
2 Dobrořeč duše má Hospodinu, a nezapomínej se na všecka dobrodiní jeho,
Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi, kí o má ṣe gbàgbé gbogbo oore rẹ̀,
3 Kterýž odpouští tobě všecky nepravosti, kterýž uzdravuje všecky nemoci tvé,
ẹni tí ó dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jì ọ́ tí ó sì wo gbogbo ààrùn rẹ̀ sàn,
4 Kterýž vysvobozuje od zahynutí život tvůj, kterýž tě korunuje milosrdenstvím a mnohým slitováním,
ẹni tí ó ra ẹ̀mí rẹ padà kúrò nínú kòtò ikú ẹni tí ó fi ìṣeun ìfẹ́ àti ìyọ́nú dé ọ ní adé,
5 Kterýž nasycuje dobrými věcmi ústa tvá, tak že se obnovuje jako orlice mladost tvá.
ẹni tí ó fi ohun dídára tẹ́ ọ lọ́rùn kí ìgbà èwe rẹ̀ lè di ọ̀tún bí ti ẹyẹ idì.
6 Èiní, což spravedlivého jest, Hospodin, a soudy všechněm utištěným.
Olúwa ń ṣe òdodo àti ìdájọ́ fún gbogbo àwọn tí a ni lára.
7 Známé učinil Mojžíšovi cesty své, synům Izraelským skutky své.
Ó fi ọ̀nà rẹ̀ hàn fún Mose, iṣẹ́ rẹ̀ fun àwọn ọmọ Israẹli;
8 Lítostivý a milostivý jest Hospodin, dlouhoshovívající a mnohého milosrdenství.
Olúwa ni aláàánú àti olóore, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́.
9 Nebudeť ustavičně žehrati, ani na věky hněvu držeti.
Òun kì í bá ni wí ní ìgbà gbogbo bẹ́ẹ̀ ni kì í pa ìbínú rẹ mọ́ láéláé,
10 Ne podlé hříchů našich nakládá s námi, ani vedlé nepravostí našich odplacuje nám.
Òun kì í ṣe sí wa gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ṣẹ̀ wa bẹ́ẹ̀ ni kì í san án fún wa gẹ́gẹ́ bí àìṣedéédéé wa.
11 Nebo jakož jsou vysoko nebesa nad zemí, tak jest vyvýšené milosrdenství jeho nad těmi, kteříž se ho bojí.
Nítorí bí ọ̀run ṣe ga sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìfẹ́ rẹ̀ tóbi sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
12 A jak daleko jest východ od západu, tak daleko vzdálil od nás přestoupení naše.
Bí ìlà-oòrùn ti jìnnà sí ìwọ̀-oòrùn bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe mú ìrékọjá wá jìnnà sí wa.
13 Jakož se slitovává otec nad dítkami, tak se slitovává Hospodin nad těmi, kteříž se hobojí.
Bí baba ti ń ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ń ṣe ìyọ́nú sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,
14 Onť zajisté zná slepení naše, v paměti má, že prach jsme.
nítorí tí ó mọ dídá wa, ó rántí pé erùpẹ̀ ni wá.
15 Dnové člověka jsou jako tráva, a jako květ polní, tak kvete.
Bí ó ṣe ti ènìyàn ni, ọjọ́ rẹ̀ dàbí koríko, ó gbilẹ̀ bí ìtànná ewéko igbó,
16 Jakž vítr na něj povane, anť ho není, aniž ho již více pozná místo jeho.
afẹ́fẹ́ fẹ́ kọjá lọ lórí rẹ̀, kò sì rántí ibùjókòó rẹ̀ mọ́.
17 Milosrdenství pak Hospodinovo od věků až na věky nad těmi, kteříž se ho bojí, a spravedlnost jeho nad syny synů,
Ṣùgbọ́n láti ayérayé ni ìfẹ́ Olúwa ti wà pẹ̀lú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti òdodo rẹ̀ wà láti ọmọdọ́mọ,
18 Kteříž ostříhají smlouvy jeho, a pamatují na přikázaní jeho, aby je činili.
sí àwọn tí ó pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́ àti àwọn tí ó rántí òfin rẹ̀ láti ṣe wọ́n.
19 Hospodin na nebesích utvrdil trůn svůj, a kralování jeho nade vším panuje.
Olúwa ti pèsè ìtẹ́ rẹ̀ nínú ọ̀run, ìjọba rẹ̀ ní ó sì borí ohun gbogbo.
20 Dobrořečte Hospodinu andělé jeho, kteříž jste mocní v síle, a činíte slovo jeho, poslušní jsouc hlasu slova jeho.
Yin Olúwa, ẹ̀yin angẹli rẹ̀, tí ó ní ipá, tí ó pa òfin ọ̀rọ̀ rẹ̀ mọ́, tì ó sì ń se ìfẹ́ rẹ̀.
21 Dobrořečte Hospodinu všickni zástupové jeho, služebníci jeho, kteříž činíte vůli jeho.
Yin Olúwa, ẹ̀yin ogun ọ̀run rẹ̀ gbogbo, ẹ̀yin ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ń ṣe ìfẹ́ rẹ̀.
22 Dobrořečte Hospodinu všickni skutkové jeho, na všech místech panování jeho. Dobrořeč duše má Hospodinu.
Yin Olúwa, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ní ibi gbogbo ìjọba rẹ̀. Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.

< Žalmy 103 >