< Príslovia 29 >

1 Èlověk, kterýž často kárán bývaje, zatvrzuje šíji, rychle potřín bude, tak že neprospěje žádné lékařství.
Ẹni tí ó sì ń ṣorí kunkun lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìbáwí yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.
2 Když se množí spravedliví, veselí se lid; ale když panuje bezbožník, vzdychá lid.
Nígbà tí olódodo bá ń gbilẹ̀, àwọn ènìyàn a yọ̀ nígbà tí ènìyàn búburú ń ṣàkóso, àwọn ènìyàn ń kórìíra.
3 Muž, kterýž miluje moudrost, obveseluje otce svého; ale kdož se přitovaryšuje k nevěstkám, mrhá statek.
Ènìyàn tí ó fẹ́ràn ọgbọ́n mú kí baba rẹ̀ láyọ̀ ṣùgbọ́n ẹni ti ń bá panṣágà kẹ́gbẹ́ ba ọrọ̀ ọ rẹ̀ jẹ́.
4 Král soudem upevňuje zemi, muž pak, kterýž béře dary, boří ji.
Nípa ìdájọ́ òdodo ni ọba fi í mú ìlú tòrò nini, ṣùgbọ́n èyí tí ń ṣe ojúkòkòrò àbẹ̀tẹ́lẹ̀ fà á lulẹ̀.
5 Èlověk, kterýž pochlebuje příteli svému, rozprostírá sít před nohama jeho.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá tan aládùúgbò rẹ̀ ó ń dẹ àwọ̀n de ẹsẹ̀ ẹ rẹ̀.
6 Výstupek bezbožného jest jemu osídlem, spravedlivý pak prozpěvuje a veselí se.
Ẹ̀ṣẹ̀ ènìyàn ibi ni ó jẹ́ ìdẹ̀kùn rẹ̀ ṣùgbọ́n olódodo le è kọrin kí ó sì máa yọ̀.
7 Spravedlivý vyrozumívá při nuzných, ale bezbožník nemá s to rozumnosti ani umění.
Olódodo ń máa ro ọ̀rọ̀ tálákà, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kò sú sí i láti rò ó.
8 Muži posměvači zavozují město, ale moudří odvracují hněv.
Àwọn ẹlẹ́yà a máa ru ìlú sókè, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn máa ń mú ìbínú kúrò.
9 Muž moudrý, kterýž se nesnadní s mužem bláznivým, buď že se pohne, buď že se směje, nemá pokoje.
Bí ọlọ́gbọ́n ènìyàn bá lọ sí ilé ẹjọ́ pẹ̀lú aláìgbọ́n aláìgbọ́n a máa bínú a sì máa jà, kò sì ní sí àlàáfíà.
10 Vražedlníci v nenávisti mají upřímého, ale upřímí pečují o duši jeho.
Àwọn tí ó ń tàjẹ̀ sílẹ̀ kò rí ẹni dídúró ṣinṣin wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa olódodo.
11 Všecken duch svůj vypouští blázen, ale moudrý na potom zdržuje jej.
Aláìgbọ́n ènìyàn fi gbogbo ẹnu rẹ̀ bínú ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa kó ìbínú rẹ̀ ní ìjánu.
12 Pána toho, kterýž rád poslouchá slov lživých, všickni služebníci jsou bezbožní.
Bí olórí bá fetí sí irọ́, gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ a di ènìyàn búburú lójú rẹ̀.
13 Chudý a dráč potkávají se, obou dvou však oči osvěcuje Hospodin.
Tálákà ènìyàn àti aninilára jọ ní àbùdá yìí, Olúwa jẹ́ kí ojú àwọn méjèèjì máa ríran.
14 Krále toho, kterýž soudí právě nuzné, trůn na věky bývá utvrzen.
Bí ọba kan bá ń ṣe ìdájọ́ tálákà pẹ̀lú òtítọ́ ìtẹ́ ìjọba rẹ yóò fìdímúlẹ̀ nígbà gbogbo.
15 Metla a kárání dává moudrost, ale dítě sobě volné k hanbě přivodí matku svou.
Ọ̀pá ìbániwí ń fún ni ní ọgbọ́n ṣùgbọ́n ọmọ tí a fi sílẹ̀ fúnra rẹ̀ a dójútì ìyá rẹ̀.
16 Když se rozmnožují bezbožní, rozmnožuje se převrácenost, a však spravedliví spatřují pád jejich.
Nígbà tí ènìyàn búburú ń gbilẹ̀, bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀ṣẹ̀ ń gbilẹ̀ ṣùgbọ́n olódodo yóò rí ìṣubú wọn.
17 Tresci syna svého, a přineseť odpočinutí, a způsobí rozkoš duši tvé.
Bá ọmọ rẹ wí, yóò sì fún ọ ní àlàáfíà yóò sì mú inú dídùn wá sí inú ọkàn rẹ.
18 Když nebývá vidění, rozptýlen bývá lid; kdož pak ostříhá zákona, blahoslavený jest.
Níbi tí kò ti sí ìfihàn, àwọn ènìyàn a gbé ìgbé ayé àìbìkítà, ṣùgbọ́n ìbùkún ní fún àwọn tí ń pa òfin mọ́.
19 Slovy nebývá napraven služebník; nebo rozuměje, však neodpoví.
A kò le fi ọ̀rọ̀ lásán kìlọ̀ fún ìránṣẹ́ bí ó tilẹ̀ yé e, kò ní kọbi ara sí i.
20 Spatřil-li bys člověka, an jest kvapný v věcech svých, lepší jest naděje o bláznu, než o takovém.
Ǹjẹ́ ó rí ènìyàn tí ń kánjú sọ̀rọ̀? Ìrètí wà fún aláìgbọ́n jù ú lọ.
21 Kdo rozkošně chová z dětinství služebníka svého, naposledy bude syn.
Bí ènìyàn kan bá kẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ lákẹ̀ẹ́jù láti kékeré yóò mú ìbànújẹ́ wá ní ìgbẹ̀yìn.
22 Èlověk hněvivý vzbuzuje svár, a prchlivý mnoho hřeší.
Oníbìínú ènìyàn a ru ìjà sókè, onínú-fùfù ènìyàn a sì máa dá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀.
23 Pýcha člověka snižuje jej, ale chudý duchem dosahuje slávy.
Ìgbéraga ènìyàn a máa sọ ọ́ di ẹni ilẹ̀ ṣùgbọ́n onírẹ̀lẹ̀ ènìyàn a máa gba iyì kún iyì.
24 Kdo má spolek s zlodějem, v nenávisti má duši svou; zlořečení slyší, však neoznámí.
Ẹni tí ó ń kó ẹgbẹ́, olè kórìíra ọkàn ara rẹ̀, ó ń gbọ́ èpè olóhun kò sì le è fọhùn.
25 Strašlivý člověk klade sobě osídlo, ale kdo doufá v Hospodina, bývá povýšen.
Ìbẹ̀rù ènìyàn kan yóò sì di ìdẹ̀kùn ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bẹ̀rù Olúwa wà láìléwu.
26 Mnozí hledají tváři pánů, ješto od Hospodina jest soud jednoho každého.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ń wá ojúrere alákòóso, ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ènìyàn tí ń gba ìdájọ́ òdodo.
27 Ohavností spravedlivým jest muž nepravý, ohavností pak bezbožnému, kdož upřímě kráčí.
Olódodo kórìíra àwọn aláìṣòótọ́: ènìyàn búburú kórìíra olódodo.

< Príslovia 29 >