< Príslovia 20 >

1 Víno činí posměvače, a nápoj opojný nepokojného; pročež každý, kdož se kochá v něm, nebývá moudrý.
Ẹlẹ́yà ni ọtí wáìnì, aláriwo sì ní ọtí líle; ẹnikẹ́ni tí ó bá fi tànjẹ kò gbọ́n.
2 Hrůza královská jako řvání mladého lva; kdož ho rozhněvá, hřeší proti životu svému.
Ìbẹ̀rù ọba dàbí kíké e kìnnìún; ẹnikẹ́ni tí ó bá mú un bínú ba ayé ara rẹ̀ jẹ́.
3 Přestati od sváru jest to každému ku poctivosti, ale kdožkoli se do nich zapletá, blázen jest.
Iyì ni ó jẹ́ fún ènìyàn láti sá fún ìjà, ṣùgbọ́n gbogbo aláìgbọ́n a máa tètè wá ìjà.
4 Lenoch neoře pro zimu, pročež žebrati bude ve žni, ale nadarmo.
Ọ̀lẹ kì í ṣiṣẹ́ oko nígbà tí ó yẹ, nítorí náà ní àsìkò ìkórè, yóò wá kò sì ní rì nǹkan.
5 Rada v srdci muže voda hluboká, muž však rozumný dosáhne jí.
Ète ọkàn ènìyàn dàbí omi jíjìn; ṣùgbọ́n ènìyàn olóye á wá wọn jáde.
6 Větší díl lidí honosí se účinností svou, ale v pravdě takového kdo nalezne?
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni wọ́n máa ń sọ pe àwọn ní ìfẹ́ àìṣẹ̀tàn, ṣùgbọ́n kò rọrùn láti rí ènìyàn olóòtítọ́.
7 Spravedlivý ustavičně chodí v upřímnosti své; blažení synové jeho po něm.
Olódodo ènìyàn a máa gbé ìgbé ayé àìlábùkù ìbùkún ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
8 Král sedě na soudné stolici, rozhání očima svýma všecko zlé.
Nígbà tí ọba bá jókòó sórí ìtẹ́ rẹ̀ láti ṣe ìdájọ́ yóò fẹ́ gbogbo ibi dànù pẹ̀lú ojú rẹ̀.
9 Kdo může říci: Očistil jsem srdce své? Èist jsem od hříchu svého?
Ta ni ó le è wí pé, “Mo ti ṣe ọkàn mi ní mímọ́, mo mọ́, n kò sì lẹ́ṣẹ̀”?
10 Závaží rozdílná a míra rozdílná, obé to ohavností jest Hospodinu.
Ìwọ̀n èké àti òsùwọ̀n ìrẹ́jẹ Olúwa kórìíra méjèèjì.
11 Po skutcích svých poznáno bývá také i pachole, jest-li upřímé a pravé dílo jeho.
Kódà a mọ ọmọdé nípa iṣẹ́ rẹ̀ nípa pe bóyá iṣẹ́ rẹ mọ́ tàbí pé ó tọ̀nà.
12 Ucho, kteréž slyší, a oko, kteréž vidí, obé to učinil Hospodin.
Etí tí ó ń gbọ́ àti ojú tí ó ń ríran Olúwa ni ó dá méjèèjì.
13 Nemiluj snu, abys nezchudl, otevři oči své, a nasytíš se chlebem.
Má ṣe fẹ́ràn oorun, àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò di tálákà. Ma ṣe sùn ìwọ yóò sì ní oúnjẹ láti tún fi tọrọ.
14 Zlé, zlé, říká ten, kdož kupuje, a odejda, tedy se chlubí.
“Kò dára, kò dára!” ní ẹni tó ra ọjà máa ń wí; nígbà tí ó bá kúrò níbẹ̀ tán, yóò máa yangàn bí òun tí ṣe rí rà sí.
15 Zlato a množství perel, a nejdražší klínot jsou rtové umělí.
Wúrà wà, iyùn sì wà rẹpẹtẹ, ṣùgbọ́n, ahọ́n tí ń sọ ìmọ̀ gan an ni ọ̀ṣọ́ iyebíye.
16 Vezmi roucho toho, kterýž slíbil za cizího, a kdo za cizozemku, základ jeho.
Gba abọ́ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àlejò; mú un lọ́wọ́ bí ìbúra bí ó bá ṣe é fún obìnrin onírìnkurìn.
17 Chutný jest někomu chléb falše, ale potom ústa jeho pískem naplněna bývají.
Oúnjẹ tí a fi ọ̀nà èrú rí máa ń dùn lẹ́nu ènìyàn, ṣùgbọ́n, a yọrí sí ibi ẹnu tí ó kún fún erùpẹ̀.
18 Myšlení radou upevňuj, a s opatrnou radou veď boj.
Pa ètè rẹ mọ́ nípa wíwá ìmọ̀ràn bí o bá ń jagun, gba ìtọ́sọ́nà.
19 Kdo vynáší tajnost, chodí neupřímě, pročež k lahodícímu rty svými nepřiměšuj se.
Olófòófó a máa tú àṣírí nítorí náà yẹra fún ènìyàn tí ń rojọ́ púpọ̀.
20 Kdo zlořečí otci svému neb matce své, zhasne svíce jeho v temných mrákotách.
Bí ènìyàn kan bá ṣépè fún baba tàbí ìyá rẹ̀, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ni a ó pa kú nínú òkùnkùn biribiri.
21 Dědictví rychle z počátku nabytému naposledy nebývá dobrořečeno,
Ogún tí a kójọ kíákíá ní ìbẹ̀rẹ̀ kì yóò ní ìbùkún ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín.
22 Neříkej: Odplatím se zlým; očekávej na Hospodina, a vysvobodí tě.
Má ṣe wí pé, “N ó sẹ̀san àṣìṣe rẹ yìí fún ọ.” Dúró de Olúwa yóò sì gbà ọ́ là.
23 Ohavností jsou Hospodinu závaží rozdílná, a váhy falešné neoblibuje.
Olúwa kórìíra òdínwọ̀n èké. Òsùwọ̀n ìrẹ́jẹ kò sì tẹ́ ẹ lọ́rùn.
24 Od Hospodina jsou krokové muže, ale člověk jak vyrozumívá cestě jeho?
Olúwa ni ó ń ṣe olùdarí ìgbésẹ̀ ènìyàn. Báwo wá ni òye gbogbo ọ̀nà ènìyàn ṣe le yé ni?
25 Osídlo jest člověku pohltiti věc posvěcenou, a po slibu zase toho vyhledávati.
Ìdẹ̀kùn ni fún ènìyàn láti ṣe ìlérí kíákíá nígbà tí ó bá sì yá kí ó máa ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wò.
26 Král moudrý rozptyluje bezbožné, a uvodí na ně pomstu.
Ọlọ́gbọ́n ọba tú ènìyàn búburú ká; Ó sì fi òòlọ ìpakà lọ̀ wọ́n.
27 Duše člověka jest svíce Hospodinova, kteráž zpytuje všecky vnitřnosti srdečné.
Àtùpà Olúwa ń ṣe àwárí ẹ̀mí ènìyàn a máa ṣàwárí ibi ìkọ̀kọ̀ inú.
28 Milosrdenství a pravda ostříhají krále, a milosrdenstvím podpírá se trůn jeho.
Ìfẹ́ àti òdodo pa ọba mọ́, nípa ìfẹ́, ìtẹ́ rẹ̀ wà láìléwu.
29 Ozdoba mládenců jest síla jejich, a okrasa starců šediny.
Ògo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ni agbára wọn, ewú orí ni iyì arúgbó.
30 Modřiny ran jsou lékařství při zlém, a bití vnitřnostem života.
Ìgbájú ìgbámú àti ìfarapa máa ń mú ibi lọ, pàṣán sì máa ń ṣe àfọ̀mọ́ ibi ìkọ̀kọ̀ inú.

< Príslovia 20 >