< Príslovia 2 >

1 Synu můj, přijmeš-li slova má, a přikázaní má schováš-li u sebe;
Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
2 Nastavíš-li moudrosti ucha svého, a nakloníš-li srdce svého k opatrnosti;
tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
3 Ovšem, jestliže na rozumnost zavoláš, a na opatrnost zvoláš-li;
àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
4 Budeš-li jí hledati jako stříbra, a jako pokladů pilně vyhledávati jí:
bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
5 Tehdy porozumíš bázni Hospodinově, a známosti Boží nabudeš;
Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
6 Nebo Hospodin dává moudrost, z úst jeho umění a opatrnost.
Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
7 Chová upřímým dlouhověkosti, pavézou jest chodícím v sprostnosti,
Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
8 Ostříhaje stezek soudu; on cesty svatých svých ostříhá.
Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
9 Tehdy porozumíš spravedlnosti a soudu, a upřímosti i všeliké cestě dobré,
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
10 Když vejde moudrost v srdce tvé, a umění duši tvé se zalíbí.
Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
11 Prozřetelnost ostříhati bude tebe, a opatrnost zachová tě,
Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
12 Vysvobozujíc tě od cesty zlé, a od lidí mluvících věci převrácené,
Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
13 Kteříž opouštějí stezky přímé, aby chodili po cestách tmavých,
ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
14 Kteříž se veselí ze zlého činění, plésají v převrácenostech nejhorších,
ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
15 Jejichž stezky křivolaké jsou, anobrž zmotaní jsou na cestách svých;
ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
16 Vysvobozujíc tě i od ženy postranní, od cizí, kteráž řečmi svými lahodí,
Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
17 Kteráž opouští vůdce mladosti své, a na smlouvu Boha svého se zapomíná;
ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
18 K smrti se zajisté nachyluje dům její, a k mrtvým stezky její;
Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
19 Kteřížkoli vcházejí k ní, nenavracují se zase, aniž trefují na cestu života;
Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
20 Abys chodil po cestě dobrých, a stezek spravedlivých abys ostříhal.
Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
21 Nebo upřímí bydliti budou v zemi, a pobožní zůstanou v ní;
Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
22 Bezbožní pak z země vyťati budou, a přestupníci vykořeněni budou z ní.
Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.

< Príslovia 2 >