< Matouš 18 >

1 V ten čas přistoupili učedlníci k Ježíšovi, řkouce: Kdo pak jest větší v království nebeském?
Ní àkókò náà ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Jesu tọ̀ ọ́ wá, wọ́n bi í léèrè pé, “Ta ni ẹni ti ó pọ̀jù ní ìjọba ọ̀run?”
2 A zavolav Ježíš pacholete, postavil je uprostřed nich,
Jesu sì pe ọmọ kékeré kan sí ọ̀dọ̀ ara rẹ̀. Ó sì mú un dúró láàrín wọn.
3 A řekl: Amen pravím vám: Neobrátíte-li se a nebudete-li jako pacholátka, nikoli nevejdete do království nebeského.
Ó wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, àfi bí ẹ̀yin bá yí padà kí ẹ sì dàbí àwọn ọmọdé, ẹ̀yin kì yóò lè wọ ìjọba ọ̀run.
4 Protož kdož by se koli ponížil jako pacholátko toto, tenť jest větší v království nebeském.
Nítorí náà, ẹni tí ó bá rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọmọdé yìí, ni yóò pọ̀ jùlọ ní ìjọba ọ̀run.
5 A kdož by koli přijal pacholátko takové ve jménu mém, mneť přijímá.
Àti pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá gba ọmọ kékeré bí èyí nítorí orúkọ mi, gbà mí.
6 Kdo by pak pohoršil jednoho z maličkých těchto věřících ve mne, lépe by jemu bylo, aby zavěšen byl žernov osličí na hrdlo jeho, a pohřížen byl do hlubokosti mořské.
“Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni nínú yín tí ó bá mú ọ̀kan nínú àwọn ọmọ kékeré wọ̀nyí tí ó gbà mí gbọ́ ṣìnà, yóò sàn fún un kí a so òkúta ńlá mọ́ ọn ní ọrùn, kí a sì rì í sí ìsàlẹ̀ ibú omi Òkun.
7 Běda světu pro pohoršení. Ačkoli musí to býti, aby přicházela pohoršení, ale však běda člověku, skrze něhož přichází pohoršení.
Ègbé ni fún ayé nítorí gbogbo ohun ìkọ̀sẹ̀ rẹ̀! Ohun ìkọ̀sẹ̀ kò le ṣe kó má wà, ṣùgbọ́n ègbé ni fún ọkùnrin náà nípasẹ̀ ẹni tí ìkọ̀sẹ̀ náà ti wá!
8 Protož jestliže ruka tvá anebo noha tvá pohoršuje tě, utniž ji a vrz od sebe. Lépe jest tobě do života vjíti kulhavému anebo bezrukému, nežli dvě ruce aneb dvě noze majícímu uvrženu býti do věčného ohně. (aiōnios g166)
Nítorí náà, bí ọwọ́ tàbí ẹsẹ̀ rẹ yóò bá mú ọ dẹ́ṣẹ̀, gé e kúrò, kí o sì jù ú nù. Ó kúkú sàn fún ọ láti wọ ìjọba ọ̀run ní akéwọ́ tàbí akésẹ̀ ju pé kí o ni ọwọ́ méjì àti ẹsẹ̀ méjì ki a sì sọ ọ́ sínú iná ayérayé. (aiōnios g166)
9 A pakli oko tvé pohoršuje tebe, vylup je a vrz od sebe. Lépe jest tobě jednookému do života vjíti, nežli obě oči majícímu uvrženu býti do pekelného ohně. (Geenna g1067)
Bí ojú rẹ yóò bá sì mú kí o dẹ́ṣẹ̀, yọ ọ́ kúrò kí ó sì sọ ọ́ nù. Ó kúkú sàn fún ọ láti lọ sínú ìyè pẹ̀lú ojú kan, ju pé kí o ní ojú méjì, kí a sì jù ọ́ sí iná ọ̀run àpáàdì. (Geenna g1067)
10 Viztež, abyste nepotupovali ani jednoho z maličkých těchto. Neboť pravím vám, že andělé jejich v nebesích vždycky vidí tvář Otce mého, kterýž v nebesích jest.
“Ẹ rí i pé ẹ kò fi ojú tẹ́ńbẹ́lú ọ̀kan nínú àwọn kéékèèké wọ̀nyí. Lóòótọ́ ni mo wí fún yin pé, nígbà gbogbo ni ọ̀run ni àwọn angẹli ń wo ojú Baba mi tí ń bẹ ní ọ̀run.
11 Nebo přišel Syn člověka, aby spasil to, což bylo zahynulo.
12 Co se vám zdá? Kdyby některý člověk měl sto ovec, a zbloudila by jedna z nich, zdaliž nenechá devadesáti devíti, a jda na hory, nehledá té pobloudilé?
“Kí ni ẹ̀yin rò? Bí ọkùnrin kan bá ni ọgọ́rùn-ún àgùntàn, tí ẹyọ kan nínú wọn sì sọnù, ṣé òun kì yóò fi mọ́kàndínlọ́gọ́rùn-ún ìyókù sílẹ̀ sórí òkè láti lọ wá ẹyọ kan tó nù náà bí?
13 A nahodí-liť mu se nalézti ji, amen pravím vám, že se radovati bude nad ní více, než nad devadesáti devíti nepobloudilými.
Ǹjẹ́ bí òun bá sì wá á rí i, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ǹjẹ́ ẹ̀yin kò mọ̀ pé inú rẹ̀ yóò dùn nítorí rẹ̀ ju àwọn mọ́kàndínlọ́gọ́rùn-ún tí kò nù lọ?
14 Takť není vůle před Otcem vaším, kterýž jest v nebesích, aby zhynul jeden z maličkých těchto.
Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ni kì í ṣe ìfẹ́ Baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run, pé ọ̀kan nínú àwọn kékeré wọ̀nyí kí ó ṣègbé.
15 Zhřešil-li by pak proti tobě bratr tvůj, jdi a potresci ho mezi sebou a jím samým. Uposlechl-li by tebe, získal jsi bratra svého.
“Bí arákùnrin rẹ bá ṣẹ̀ ọ́, lọ ní ìkọ̀kọ̀ kí o sì sọ ẹ̀bi rẹ̀ fún un. Bí ó bá gbọ́ tìrẹ, ìwọ ti mú arákùnrin kan bọ̀ sí ipò.
16 Jestliže by pak neuposlechl, přijmi k sobě jednoho anebo dva, aby v ústech dvou nebo tří svědků stálo každé slovo.
Ṣùgbọ́n bí òun kò bá tẹ́tí sí ọ, nígbà náà mú ẹnìkan tàbí ẹni méjì pẹ̀lú rẹ, kí ẹ sì tún padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i, kí ọ̀rọ̀ náà bá le fi ìdí múlẹ̀ pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́rìí méjì tàbí mẹ́ta náà.
17 Pakliť by jich neuposlechl, pověz církvi. Jestliže pak i církve neuposlechne, budiž tobě jako pohan a publikán.
Bí òun bá sì tún kọ̀ láti tẹ́tí sí wọn, nígbà náà sọ fún ìjọ ènìyàn Ọlọ́run. Bí o bá kọ̀ láti gbọ́ ti ìjọ ènìyàn Ọlọ́run, jẹ́ kí ó dàbí kèfèrí sí ọ tàbí agbowó òde.
18 Amen pravím vám: Cožkoli svížete na zemi, budeť svázáno i na nebi; a cožkoli rozvížete na zemi, budeť rozvázáno i na nebi.
“Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ohunkóhun tí ẹ̀yin bá dè ní ayé, ni a dè ní ọ̀run. Ohunkóhun ti ẹ̀yin bá sì ti tú ni ayé, á ò tú u ní ọ̀run.
19 Opět pravím vám: Jestliže by dva z vás svolili se na zemi o všelikou věc, za kterouž by koli prosili, staneť se jim od Otce mého nebeského.
“Mo tún sọ èyí fún yín, bí ẹ̀yin méjì bá fi ohùn ṣọ̀kan ní ayé yìí, nípa ohunkóhun tí ẹ béèrè, Baba mi ti ń bẹ ní ọ̀run yóò sì ṣe é fún yín.
20 Nebo kdežkoli shromáždí se dva nebo tři ve jménu mém, tuť jsem já uprostřed nich.
Nítorí níbi ti ènìyàn méjì tàbí mẹ́ta bá kó ara jọ ni orúkọ mi, èmi yóò wà láàrín wọn níbẹ̀.”
21 Tedy přistoupiv k němu Petr, řekl: Pane, kolikrát zhřeší proti mně bratr můj, a odpustím jemu? Do sedmilikrát?
Nígbà náà ni Peteru wá sọ́dọ̀ Jesu, ó béèrè pé, “Olúwa, nígbà mélòó ni arákùnrin mi yóò ṣẹ̀ mi, tí èmi yóò sì dáríjì í? Tàbí ní ìgbà méje ni?”
22 I dí mu Ježíš: Nepravím tobě až do sedmikrát, ale až do sedmdesátikrát sedmkrát.
Jesu dáhùn pé, “Mo wí fún ọ, kì í ṣe ìgbà méje, ṣùgbọ́n ní ìgbà àádọ́rin méje.
23 A protož podobno jest království nebeské člověku králi, kterýž chtěl počet klásti s služebníky svými.
“Nítorí náà, ìjọba ọ̀run dàbí ọba kan tí ó fẹ́ ṣe ìṣirò pẹ̀lú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.
24 A když počal počtu klásti, podán mu jeden, kterýž byl dlužen deset tisíců hřiven.
Bí ó ti ń ṣe èyí, a mú ajigbèsè kan wá sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó jẹ ẹ́ ní ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá tálẹ́ǹtì.
25 A když neměl čím zaplatiti, kázal jej pán jeho prodati, i ženu jeho i děti i všecko, což měl, a zaplatiti.
Nígbà tí kò tì í ní agbára láti san án, nígbà náà ni olúwa rẹ̀ pàṣẹ pé kí a ta òun àti ìyàwó àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó ní láti fi san gbèsè náà.
26 Tedy padna služebník ten, prosil ho, řka: Pane, poshověj mi, a všeckoť zaplatím tobě.
“Nígbà náà ni ọmọ ọ̀dọ̀ náà wólẹ̀ lórí eékún níwájú rẹ. ‘Ó bẹ̀bẹ̀ pé, mú sùúrù fún mi, èmi yóò sì san gbogbo rẹ̀ fún ọ.’
27 I slitovav se pán nad služebníkem tím, propustil ho a dluh jemu odpustil.
Nígbà náà, ni olúwa ọmọ ọ̀dọ̀ náà sì ṣàánú fún un. Ó tú u sílẹ̀, ó sì fi gbèsè náà jì í.
28 Vyšed pak služebník ten, nalezl jednoho z spoluslužebníků svých, kterýž mu byl dlužen sto peněz, a chopiv se ho, hrdloval se s ním, řka: Zaplať mi, cos dlužen.
“Ṣùgbọ́n bí ọmọ ọ̀dọ̀ náà ti jáde lọ, ó rí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ẹgbẹ́ rẹ̀ tí ó jẹ ẹ́ ní ọgọ́rùn-ún owó idẹ, ó gbé ọwọ́ lé e, ó fún un ní ọrùn, ó wí pé, ‘San gbèsè tí o jẹ mí lójú ẹsẹ̀.’
29 Tedy padna spoluslužebník ten k nohám jeho, prosil ho, řka: Poshověj mi, a všeckoť zaplatím tobě.
“Ọmọ ọ̀dọ̀ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ náà sì wólẹ̀ lórí eékún níwájú rẹ̀, ò ń bẹ̀ ẹ́ pé, ‘Mú sùúrù fún mi, èmi yóò sì san án fún ọ.’
30 On pak nechtěl, ale odšed, dal jej do žaláře, dokudž by nezaplatil dluhu.
“Ṣùgbọ́n òun kọ̀ fún un. Ó pàṣẹ kí a mú ọkùnrin náà, kí a sì jù ú sínú túbú títí tí yóò fi san gbèsè náà tán pátápátá.
31 Tedy vidouce spoluslužebníci, co se dálo, zarmoutili se velmi; a šedše, pověděli pánu svému všecko, co se bylo stalo.
Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ rí ohun tí ó ṣẹlẹ̀, inú bí wọn gidigidi, wọ́n lọ láti lọ sọ fún olúwa wọn, gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀.
32 Tehdy povolav ho pán jeho, dí mu: Služebníče zlý, všecken ten tvůj dluh odpustil jsem tobě, nebs mne prosil.
“Nígbà tí olúwa rẹ̀ pè ọmọ ọ̀dọ̀ náà wọlé, ó wí fún un pé, ‘Ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ búburú, níhìn-ín ni mo ti dárí gbogbo gbèsè rẹ jì ọ́ nítorí tí ìwọ bẹ̀ mi.
33 Zdaližs i ty neměl se smilovati nad spoluslužebníkem svým, jako i já smiloval jsem se nad tebou?
Kò ha ṣe ẹ̀tọ́ fún ọ láti ṣàánú fún àwọn ẹlòmíràn, gẹ́gẹ́ bí èmi náà ti ṣàánú fún ọ?’
34 I rozhněvav se pán jeho, dal jej katům, dokudž by nezaplatil všeho, což mu byl dlužen.
Ní ìbínú, olówó rẹ̀ fi í lé àwọn onítúbú lọ́wọ́ láti fi ìyà jẹ ẹ́, títí tí yóò fi san gbogbo gbèsè èyí ti ó jẹ ẹ́.
35 Takť i Otec můj nebeský učiní vám, jestliže neodpustíte jeden každý bratru svému z srdcí vašich jejich provinění.
“Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ sì ni Baba mi tí ń bẹ ní ọ̀run yóò sí ṣe sì ẹnìkọ̀ọ̀kan, bí ẹ̀yin kò bá fi tọkàntọkàn dárí ji àwọn arákùnrin yín.”

< Matouš 18 >