< 3 Mojžišova 18 >

1 I mluvil Hospodin k Mojžíšovi, řka:
Olúwa sọ fún Mose pé:
2 Mluv synům Izraelským a rci jim: Já jsem Hospodin Bůh váš.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé: ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
3 Vedlé skutků země Egyptské, v níž jste bydlili, nečiňte, ani podlé skutků země Kananejské, do kteréž já vás uvozuji, činiti budete, a v ustanoveních jejich nechoďte.
Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe bí wọ́n ti ń ṣe ní Ejibiti níbi tí ẹ ti gbé rí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe bí wọ́n ti ń ṣe ní ilẹ̀ Kenaani níbi tí èmi ń mú yín lọ. Ẹ kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ìṣe wọn.
4 Soudy mé čiňte a ustanovení mých ostříhejte, abyste chodili v nich: Já jsem Hospodin Bůh váš.
Kí ẹ̀yin kí ó sì máa ṣe òfin mi, kí ẹ̀yin sì máa pa ìlànà mi mọ́, láti máa rìn nínú wọn, Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
5 Ostříhejte ustanovení mých a soudů mých. Èlověk ten, kterýž by je činil, živ bude v nich: Já jsem Hospodin.
Ẹ̀yin ó sì máa pa ìlànà mi mọ́ àti òfin mi; Ẹni tí ó ba ṣe, yóò yè nípa wọn. Èmi ni Olúwa.
6 Nižádný člověk k žádné přítelkyni krevní nepřistupuj k obnažení hanby její: Já jsem Hospodin.
“‘Ẹnikẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ súnmọ́ ìbátan rẹ̀ láti bá a lòpọ̀. Èmí ni Olúwa.
7 Hanby otce svého a matky své neodkryješ; matka tvá jest, neodkryješ hanby její.
“‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù baba rẹ nípa bíbá ìyá rẹ lòpọ̀, ìyá rẹ̀ ni, ìwọ kò gbọdọ̀ bá a lòpọ̀.
8 Hanby ženy otce svého neodkryješ; nebo hanba otce tvého jest.
“‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù baba rẹ nípa bíbá ìyàwó baba rẹ lòpọ̀, nítorí ìhòhò baba rẹ ni.
9 Hanby sestry své, dcery otce svého aneb dcery matky své, kteráž doma zplozena aneb vně zplozena jest, neodkryješ hanby jejich.
“‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin rẹ tí ó jẹ́ ọmọ ìyá rẹ lòpọ̀, yálà a bí i nílé yín tàbí lóde.
10 Hanby vnučky své, buď po synu neb dceři své, neodkryješ; nebo hanba tvá jsou.
“‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin, ọmọ rẹ ọkùnrin lòpọ̀ tàbí ọmọbìnrin ọmọ rẹ obìnrin lòpọ̀ nítorí pé ìhòhò wọn, ìhòhò ìwọ fúnra rẹ̀ ni.
11 Hanby dcery manželky otce svého, kteráž jest zplozena od otce tvého, tvá sestra jest, neodkryješ hanby její.
“‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin aya baba rẹ lòpọ̀; èyí tí a bí fún baba rẹ nítorí pé arábìnrin rẹ ni.
12 Hanby sestry otce svého neodkryješ; nebo krevní přítelkyně otce tvého jest.
“‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin baba rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan baba rẹ ni.
13 Hanby sestry matky své neodkryješ; nebo krevní přítelkyně matky tvé jest.
“‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá arábìnrin màmá rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan ìyá rẹ ni.
14 Hanby bratra otce svého neodkryješ; k manželce jeho nevejdeš, stryna tvá jest.
“‘Ìwọ kò gbọdọ̀ tàbùkù arákùnrin baba rẹ nípa sísún mọ́ aya rẹ̀ láti bá a lòpọ̀ nítorí pé ìyàwó ẹ̀gbọ́n baba rẹ ni.
15 Hanby nevěsty své neodkryješ; manželka jest syna tvého, neodkryješ hanby její.
“‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọ àna obìnrin rẹ lòpọ̀ nítorí pé aya ọmọ rẹ ni. Má ṣe bá a lòpọ̀.
16 Hanby manželky bratra svého neodkryješ; nebo hanba bratra tvého jest.
“‘Má ṣe bá aya ẹ̀gbọ́n rẹ ọkùnrin lòpọ̀ nítorí pé yóò tàbùkù ẹ̀gbọ́n rẹ.
17 Hanby ženy a dcery její neodkryješ. Vnučky její po synu neb po dceři její nepojmeš, abys odkryl hanbu její; nebo krevní jsou, a nešlechetnost jest.
“‘Má ṣe bá ìyá àti ọmọ rẹ obìnrin lòpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọmọbìnrin ọmọkùnrin rẹ tàbí ọmọbìnrin ọmọbìnrin rẹ lòpọ̀ nítorí pé ìbátan rẹ tímọ́tímọ́ ni: nítorí àbùkù ni.
18 Nevezmeš sobě ženy k ženě první, abys ssoužil ji, odkrývaje hanbu její za života jejího.
“‘Má ṣe fẹ́ àbúrò ìyàwó rẹ obìnrin ní aya gẹ́gẹ́ bí orogún tàbí bá a lòpọ̀, nígbà tí ìyàwó rẹ sì wà láààyè.
19 Také k ženě, když jest v své nemoci nečisté, nepřistoupíš, odkrývaje hanbu její.
“‘Má ṣe súnmọ́ obìnrin láti bá a lòpọ̀ nígbà tí ó bá ń ṣe nǹkan oṣù, nítorí àkókò àìmọ́ ni.
20 S manželkou bližního svého nebudeš obcovati, poškvrňuje se s ní.
“‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá aya aládùúgbò rẹ lòpọ̀, kí ìwọ má ba à ba ara rẹ jẹ́ pẹ̀lú rẹ̀.
21 Nedopustíš, aby kdo z semene tvého proveden byl skrze oheň modly Moloch, abys nepoškvrnil jména Boha svého: Já jsem Hospodin.
“‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fi èyíkéyìí nínú àwọn ọmọ rẹ rú ẹbọ lórí pẹpẹ sí òrìṣà Moleki, kí o sì tipa bẹ́ẹ̀ ba orúkọ Ọlọ́run rẹ jẹ́. Èmi ni Olúwa.
22 Nebudeš obcovati s mužským pohlavím, scházeje se s ním jako s ženou; nebo ohavnost jest.
“‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ọkùnrin lòpọ̀ bí ìgbà tí ènìyàn ń bá obìnrin lòpọ̀: ìríra ni èyí jẹ́.
23 A s žádným hovadem nebudeš obcovati, poškvrňuje se s ním; ani žena nepoddá se hovadu, aby s ním obývala; nebo mrzkost jest.
“‘Ìwọ kò gbọdọ̀ bá ẹranko lòpọ̀ kí ìwọ má ba à ba ara rẹ jẹ́. Obìnrin kò sì gbọdọ̀ jọ̀wọ́ ara rẹ̀ sílẹ̀ fún ẹranko láti bá a lòpọ̀, ohun tó lòdì ni.
24 A protož nepoškvrňujtež se žádnou touto věcí; nebo těmito všemi věcmi poškvrnili se pohané, kteréž já vyvrhu od tváři vaší.
“‘Má ṣe fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ba ara rẹ jẹ́, torí pé nínú àwọn nǹkan wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè tí mo lé kúrò níwájú yín ti ba ara wọn jẹ́.
25 Nebo poškvrnila se země, a navštívím nepravost její na ní, a vyvrátí země obyvatele své.
Nítorí pé ilẹ̀ náà di àìmọ́ nítorí náà mo fi ìyà jẹ ẹ́ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Ilẹ̀ náà sì pọ àwọn olùgbé ibẹ̀ jáde.
26 Ale vy ostříhejte ustanovení mých a soudů mých, a nečiňte nižádných ohavností těchto, tak domácí jako příchozí, kterýž jest pohostinu u prostřed vás.
Ṣùgbọ́n kí ẹ máa pa àṣẹ àti òfin mi mọ́. Onílé tàbí àjèjì tó ń gbé láàrín yín kò gbọdọ̀ ṣe ọ̀kan nínú àwọn ohun ìríra wọ̀nyí.
27 (Nebo všecky ty ohavnosti činili lidé země té, kteříž byli před vámi, čímž poškvrněna jest země.)
Nítorí pé gbogbo ohun ìríra wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn tí wọ́n ti gbé ilẹ̀ náà ṣáájú yín ti ṣe tí ó sì mú kí ilẹ̀ náà di aláìmọ́.
28 Aby nevyvrátila vás země, proto že byste jí poškvrnili, jako vyvrátila národ, kterýž byl před vámi.
Bí ẹ bá sọ ilẹ̀ náà di àìmọ́ yóò pọ̀ yín jáde bí ó ti pọ àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ti wá ṣáájú yín jáde.
29 Nebo kdož by koli dopustil se některé ze všech ohavností těch: duše zajisté, kteréž by činily to, vyhlazeny budou z prostředku lidu svého.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe ohun ìríra wọ̀nyí, kí ẹ gé irú ẹni náà kúrò láàrín àwọn ènìyàn.
30 Protož ostříhejte přikázání mých, abyste nečinili ničeho z obyčejů ohavných, kteříž činěni jsou před vámi, aniž sebe jimi poškvrňujte: Já jsem Hospodin Bůh váš.
Nítorí náà ẹ gbọdọ̀ ṣe ohun tí mo fẹ́, kí ẹ má sì lọ́wọ́ nínú àṣà ìríra wọ̀nyí, tí wọn ń ṣe kí ẹ tó dé. Ẹ má ṣe fi wọ́n ba ara yín jẹ́. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”

< 3 Mojžišova 18 >