< Plaè 5 >
1 Rozpomeň se, Hospodine, co se nám děje; popatř a viz pohanění naše.
Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
2 Dědictví naše obráceno jest k cizím, domové naši k cizozemcům.
Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
3 Sirotci jsme a bez otce, matky naše jsou jako vdovy.
Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
4 Vody své za peníze pijeme, dříví naše za záplatu přichází.
A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
5 Na hrdle svém protivenství snášíme, pracujeme, nedopouští se nám odpočinouti.
Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
6 Egyptským podáváme ruky i Assyrským, abychom nasyceni byli chlebem.
Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
7 Otcové naši hřešili, není jich, my pak trestáni po nich neseme.
Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
8 Služebníci panují nad námi; není žádného, kdo by vytrhl z ruky jejich.
Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
9 S opovážením se života svého hledáme chleba svého, pro strach meče i na poušti.
Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
10 Kůže naše jako pec zčernaly od náramného hladu.
Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
11 Ženám na Sionu i pannám v městech Judských násilé činí.
Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
12 Knížata rukou jejich zvěšena jsou, osoby starých nemají v poctivosti.
Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
13 Mládence k žernovu berou, a pacholata pod dřívím klesají.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
14 Starci sedati v branách přestali a mládenci od zpěvů svých.
Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
15 Přestala radost srdce našeho, obrátilo se v kvílení plésání naše.
Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
16 Spadla koruna s hlavy naší; běda nám již, že jsme hřešili.
Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
17 Protoť jest mdlé srdce naše, pro tyť věci zatměly se oči naše,
Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
18 Pro horu Sion, že zpuštěna jest; lišky chodí po ní.
Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
19 Ty Hospodine, na věky zůstáváš, a stolice tvá od národu do pronárodu.
Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
20 Proč se zapomínáš na věky na nás, a opouštíš nás za tak dlouhé časy?
Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
21 Obrať nás, ó Hospodine, k sobě, a obráceni budeme; obnov dny naše, jakž byly za starodávna.
Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
22 Nebo zdali všelijak zavržeš nás, a hněvati se budeš na nás velice?
àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.