< Jeremiáš 1 >
1 Slova Jeremiáše syna Helkiášova, z kněží, kteříž byli v Anatot, v zemi Beniamin,
Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremiah ọmọ Hilkiah ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Anatoti ní agbègbè ilẹ̀ Benjamini.
2 K němuž se stalo slovo Hospodinovo za dnů Joziáše syna Amonova, krále Judského, třináctého léta kralování jeho.
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Josiah ọmọ Amoni ọba Juda,
3 Byl i za dnů Joakima syna Joziášova, krále Judského, až do vyplnění jedenáctého léta Sedechiáše syna Joziášova, krále Judského, až do zajetí Jeruzaléma měsíce pátého.
àti títí dé àsìkò Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, títí dé oṣù karùn-ún ọdún kọkànlá Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, nígbà tí àwọn ará Jerusalẹmu lọ sí ìgbèkùn.
4 Stalo se, pravím, slovo Hospodinovo ke mně, řkoucí:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,
5 Dříve než jsem tě sformoval v životě, znal jsem tebe, a dříve nežlis vyšel z života, posvětil jsem tě, za proroka národům dal jsem tebe.
“Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́n, kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀. Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀-èdè.”
6 I řekl jsem: Ach, Panovníče Hospodine, aj, neumím mluviti, nebo dítě jsem.
Mo sọ pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.”
7 Ale Hospodin řekl mi: Neříkej, dítě jsem, nýbrž k čemuž tě koli pošli, jdi, a vše, cožť přikáži, mluv.
Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe sọ pé, ‘Ọmọdé lásán ni mí.’ O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.”
8 Neboj se jich, neboť jsem s tebou, abych tě vysvobozoval, dí Hospodin.
Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.
9 A vztáhna ruku svou Hospodin, dotekl se úst mých, a řekl mi Hospodin: Aj, vložil jsem slova svá v ústa tvá.
Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsin yìí, mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ.
10 Hle, ustanovuji tě dnešního dne nad národy a nad královstvími, abys plénil a kazil, a hubil a bořil, abys stavěl a štěpoval.
Wò ó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀-èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, láti wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti máa kọ́, àti láti máa gbìn.
11 Potom se stalo slovo Hospodinovo ke mně, řkoucí: Co vidíš, Jeremiáši? I řekl jsem: Prut mandlový vidím.
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ mí wá wí pé: “Kí ni o rí Jeremiah?” Mo sì dáhùn wí pé, “Mo rí ẹ̀ka igi almondi.”
12 Tedy řekl mi Hospodin: Dobře vidíš; nebo pospíchám já s slovem svým, abych je vykonal.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Ó ti rí i bí ó ṣe yẹ, nítorí pé mo ti ń ṣọ láti rí i pé ọ̀rọ̀ mi wá sí ìmúṣẹ.”
13 Opět stalo se slovo Hospodinovo ke mně po druhé, řkoucí: Co vidíš? I řekl jsem: Vidím hrnec, an vře, a přední strana jeho k straně půlnoční.
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ mi wá ní ẹ̀ẹ̀kejì pé, “Kí ni o rí?” Mo sì dáhùn pé mo rí ìkòkò gbígbóná, tí ó ń ru láti apá àríwá.
14 Tedy řekl mi Hospodin: Od půlnoci přivalí se to zlé na všecky obyvatele této země.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Láti apá àríwá ni a ó ti mu ìdààmú wá sórí gbogbo àwọn tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà.
15 Nebo aj, já svolám všecky rodiny království půlnočních, dí Hospodin, aby přitáhnouce, postavili jeden každý stolici svou v branách Jeruzalémských, a při všech zdech jeho vůkol, a při všech městech Judských.
Mo sì ti ṣetán láti pe gbogbo àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè àríwá níjà,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọba wọn yóò wá gbé ìtẹ́ wọn ró ní ojú ọ̀nà àbáwọlé Jerusalẹmu. Wọn ó sì dìde sí gbogbo àyíká wọn àti sí gbogbo àwọn ìlú Juda.
16 A tak vypovím úsudky své proti nim, pro všelikou nešlechetnost těch, kteříž opustili mne, a kadili bohům cizím, a skláněli se dílu rukou svých.
Èmi yóò sì kéde ìdájọ́ mi lórí àwọn ènìyàn mi nítorí ìwà búburú wọn nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀, nípa rírúbọ sí ọlọ́run mìíràn àti sínsin àwọn ohun tí wọ́n fi ọwọ́ wọn ṣe.
17 Protož ty přepaš bedra svá, a vstana, mluv k nim, cožkoli já přikazuji tobě. Nelekej se jich, abych tě nepotřel před oblíčejem jejich.
“Wà ní ìmúrasílẹ̀! Dìde dúró kí o sì sọ fún wọn ohunkóhun tí mo bá pàṣẹ fún wọn. Má ṣe jẹ́ kí wọ́n dẹ́rùbà ọ́, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀rù níwájú wọn.
18 Nebo aj, já postavuji tě dnes jako město hrazené, a jako sloup železný, a jako zdi měděné proti vší této zemi, proti králům Judským, proti knížatům jejím, proti kněžím jejím, a lidu země této.
Ní òní èmi ti sọ ọ́ di ìlú alágbára, òpó irin àti odi idẹ sí àwọn ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀, sí àwọn àlùfáà àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà.
19 Kteříž bojovati budou proti tobě, ale neodolají proti tobě. Nebo já jsem s tebou, praví Hospodin, abych tě vysvobozoval.
Wọn yóò dojú ìjà kọ ọ́, wọn kì yóò borí rẹ, nítorí wí pé èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì gbà ọ́,” ni Olúwa wí.