< Jeremiáš 16 >
1 I stalo se slovo Hospodinovo ke mně, řkoucí:
Bákan náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Nepojímej sobě ženy, aniž měj synů neb dcer na místě tomto.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ ní ìyàwó, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ní ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin níbí yìí.”
3 Nebo takto praví Hospodin o synech i dcerách zplozených v místě tomto, a o matkách jejich, kteréž zrodily je, i o jejich otcích, kteříž zplodili je v zemi této:
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tí wọ́n bá bí nílẹ̀ yìí, àti ìyá tí ó bí wọn àti baba wọn.
4 Smrtmi přebolestnými pomrou, nebudou oplakáni, ani pochováni; místo hnoje na svrchku země budou, a mečem i hladem do konce zhubeni budou. I budou mrtvá těla jejich za pokrm ptactvu nebeskému a šelmám zemským.
“Wọn yóò kú ikú ààrùn, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ fún wọn. Wọn ó dàbí ìdọ̀tí lórí ilẹ̀; wọn ó ṣègbé pẹ̀lú idà àti ìyàn. Òkú wọn yóò sì di oúnjẹ fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.”
5 Nebo takto praví Hospodin: Nevcházej do domu smutku, aniž choď kvíliti, aniž jich lituj; odjal jsem zajisté pokoj svůj od lidu tohoto, dobrotivost i slitování, dí Hospodin.
Nítorí báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe wọ ilé tí oúnjẹ ìsìnkú wà, má ṣe lọ síbẹ̀ láti káàánú tàbí ṣọ̀fọ̀, nítorí mo ti mú àlàáfíà, ìfẹ́ àti àánú mi kúrò lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” ni Olúwa wí.
6 Když pomrou velicí i malí v zemi této, nebudou pochováni, aniž kvíliti budou nad nimi, aniž se zřeží, aniž sobě lysiny zdělají pro ně.
“Àti ẹni ńlá àti kékeré ni yóò ṣègbé ní ilẹ̀ yìí, wọn kò ní sin wọ́n tàbí ṣọ̀fọ̀ wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí yóò fá irun orí wọn nítorí wọn.
7 Aniž jim dadí jísti, aby v truchlosti potěšovali jich nad mrtvým, aniž jich napojí z číše potěšení po otci jejich neb matce jejich.
Kò sí ẹni tí yóò fi oúnjẹ tu àwọn tí í ṣọ̀fọ̀ nínú, kódà kì í ṣe fún baba tàbí fún ìyá, kì yóò sí ẹni tí yóò fi ohun mímu tù wọ́n nínú.
8 Tolikéž do domu hodování nechoď, abys sedati měl s nimi při jídle a pití.
“Ìwọ kò gbọdọ̀ lọ sí ilé tí àjọyọ̀ wà, má ṣe jókòó jẹun tàbí mu ohun mímu.
9 Nebo takto praví Hospodin zástupů, Bůh Izraelský: Aj, já způsobím, aby nebývalo na místě tomto před očima vašima a za dnů vašich hlasu radosti, ani hlasu veselé, hlasu ženicha, ani hlasu nevěsty.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, Ní ojú yín ní ọjọ́ yín ni òpin yóò dé bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú, àti sí ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó ní ibí yìí.
10 Když pak oznámíš lidu tomuto všecka slova tato, a řeknou-liť: Proč vyřkl Hospodin proti nám všecko zlé veliké toto, a jaká jest nepravost naše, aneb jaký hřích náš, jímž jsme hřešili proti Hospodinu Bohu svému?
“Nígbà tí o bá sọ nǹkan wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn yìí, tí wọ́n bá sì bi ọ́ wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe mú búburú yìí bá wa? Kí ni àṣìṣe tí àwa ṣe? Kín ni ẹ̀ṣẹ̀ tí àwa ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa?’
11 Tedy rci jim: Proto že opustili mne otcové vaši, dí Hospodin, a chodíce za bohy cizími, sloužili jim, a klaněli se jim, mne pak opustili, a zákona mého neostříhali.
Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ fún wọn wí pé, ‘Nítorí tí àwọn baba yín ti kọ̀ mí sílẹ̀,’ ni Olúwa wí, ‘tí wọ́n sì tẹ̀lé àwọn òrìṣà mìíràn tí wọ́n ń bọ, tí wọ́n ń sìn, wọ́n kọ̀ mí sílẹ̀ wọn kò sì tẹ̀lé òfin mi mọ́.
12 Vy pak mnohem jste hůře činili nežli otcové vaši; nebo aj, vy chodíte jeden každý podlé zdání srdce svého zlého, neposlouchajíce mne.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti ṣe búburú ju ti àwọn baba yín lọ. Wò ó bí gbogbo yín ṣe ń rìn, olúkúlùkù yín nínú agídí ọkàn búburú rẹ̀, dípò kí ẹ fi gbọ́ tèmi.
13 Pročež hodím vámi z země této do země, o níž nevíte vy, ani otcové vaši, a sloužiti budete tam bohům cizím dnem i nocí, dokudž neučiním vám milosti.
Èmi yóò gbé yin kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí baba yín tàbí ẹ̀yin kò mọ̀ rí, níbẹ̀ ni ẹ̀yin yóò ti máa sìn ọlọ́run kéékèèké ní ọ̀sán àti òru nítorí èmi kì yóò fi ojúrere wò yín.’
14 Protož aj, dnové jdou, dí Hospodin, v nichž nebude říkáno více: Živť jest Hospodin, kterýž vyvedl syny Izraelské z země Egyptské,
“Nítorí náà, ọjọ́ náà ń bọ̀ wá,” ni Olúwa wí, “tí àwọn ènìyàn kò ní sọ pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè Olúwa ń bẹ, Ẹni tí ó mú Israẹli jáde kúrò ní Ejibiti.’
15 Ale: Živť jest Hospodin, kterýž vyvedl syny Izraelské z země půlnoční a ze všech zemí, do nichž je byl rozehnal, když je zase přivedu do země jejich, kterouž jsem dal otcům jejich.
Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Bí Olúwa ṣe wà nítòótọ́ tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ àríwá àti ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó ti lé wọn.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò dá wọn padà sí ilẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá wọn.
16 Aj, já pošli k rybářům mnohým, dí Hospodin, aby je vylovili; potom pošli i k mnohým lovcům, aby je zlapali na všeliké hoře, a na všelikém pahrbku, i v děrách skalních.
“Ṣùgbọ́n báyìí, Èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn apẹja púpọ̀,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì dẹ wọ́n lẹ́yìn èyí yìí èmi yóò ránṣẹ́ sí àwọn ọdẹ púpọ̀, wọn yóò dẹ wọ́n lórí gbogbo òkè ńlá àti òkè gíga, àti ní gbogbo pálapàla àpáta.
17 Hledím na všecky cesty jejich, nejsouť tajné přede mnou, aniž jest skryta nepravost jejich před očima mýma.
Ojú mi wà ní gbogbo ọ̀nà wọn, wọn kò pamọ́ fún mi bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀ṣẹ̀ wọn kò fi ara sin lójú mi.
18 I odplatím jim prvé dvojnásobně za nepravost jejich a hřích jejich, proto že zemi mnou poškvrnili těly mrtvými ohyzdnými, a ohavnostmi svými naplnili dědictví mé.
Èmi yóò san ẹ̀san ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn fún wọn ní ìlọ́po méjì, nítorí wọ́n ti ba ilẹ̀ mi jẹ́ pẹ̀lú àwọn ère wọn aláìlẹ́mìí, wọ́n sì fi òkú àti ohun ẹ̀gbin àti ìríra wọn kún ilẹ̀ ìní mi.”
19 Hospodine, sílo má a hrade můj, i útočiště mé v den ssoužení, k toběť přijdou národové od končin země, a řeknou: Jistě žeť se falše drželi otcové naši, marnosti a právě neužitečných věcí.
Olúwa, alágbára àti okun mi, ẹni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú, àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá láti òpin ayé wí pé, “Àwọn baba ńlá wa kò ní ohun kan bí kò ṣe ẹ̀gbin òrìṣà, ìríra tí kò dára fún wọn nínú rẹ̀.
20 Zdaliž udělá sobě člověk bohy, poněvadž sami nejsou bohové?
Ṣé àwọn ènìyàn lè dá Ọlọ́run fún ara wọn bí? Bẹ́ẹ̀ ni, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí kì í ṣe Ọlọ́run.”
21 Protož aj, já způsobím to, aby poznali té chvíle, způsobím, aby poznali ruku mou i moc mou, a zvědít, že jméno mé jest Hospodin.
“Nítorí náà, Èmi yóò kọ́ wọn ní àkókò yìí, Èmi yóò kọ́ wọn pẹ̀lú agbára àti títóbi mi. Nígbà náà ni wọn ó mọ pé orúkọ mi ní Olúwa.