< 1 Mojžišova 50 >

1 Tedy padl Jozef na tvář otce svého, a plakal nad ním, líbaje ho.
Josẹfu sì ṣubú lé baba rẹ̀, ó sọkún, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu.
2 A poručil služebníkům svým lékařům, aby vonnými věcmi pomazali otce jeho. I pomazali lékaři vonnými věcmi Izraele.
Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún àwọn oníṣègùn tí ó wà ní ìkáwọ́ rẹ̀ pé kí wọn kí ó ṣe òkú Israẹli baba rẹ̀ lọ́jọ̀, àwọn oníṣègùn náà sì ṣe bẹ́ẹ̀.
3 A vyplnilo se při něm čtyřidceti dní; (nebo tak vyplňují se dnové těch, kteříž mazáni bývají vonnými věcmi). I plakali ho Egyptští za sedmdesáte dní.
Fún ogójì ọjọ́ ni wọ́n fi ṣe èyí, nítorí èyí ni àsìkò tí a máa ń fi ṣe ẹ̀ǹbáàmù òkú. Àwọn ará Ejibiti sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀ fún àádọ́rin ọjọ́.
4 Když pak dnové pláče toho pominuli, mluvil Jozef k domu Faraonovu, řka: Jestliže jsem nyní nalezl milost před očima vašima, mluvte, prosím, v uši Faraonovy, a rcete:
Nígbà tí ọjọ́ ìṣọ̀fọ̀ náà kọjá. Josẹfu wí fún àwọn ará ilé Farao pé, “Bí mo bá bá ojúrere yín pàdé, ẹ bá mi sọ fún Farao.
5 Otec můj přísahou mne zavázal, řka: Aj, já umírám; v hrobě mém, kterýž jsem sobě vykopal v zemi Kananejské, tam mne pochovej. Nyní tedy, prosím, nechť vstoupím a pochovám otce svého, a navrátím se zase.
‘Baba mi mú mi búra ó sì wí fún mi pé, “Mo ti fẹ́rẹ kú: sinmi sínú ibojì tí mo gbẹ́ fún ara mi ní ilẹ̀ Kenaani.” Nísinsin yìí, jẹ́ kí n lọ kí n sì sìnkú baba mi, lẹ́yìn náà èmi yóò padà wa.’”
6 I řekl Farao: Vstup a pochovej otce svého tak, jakž tě přísahou zavázal.
Farao wí pé, “Gòkè lọ, kí o sì sin baba rẹ, bí ó tí mú ọ búra.”
7 Tedy vstoupil Jozef, aby pochoval otce svého, a vstoupili s ním všickni služebníci Faraonovi, starší domu jeho a všickni starší země Egyptské,
Báyìí ni Josẹfu gòkè lọ láti sìnkú baba rẹ̀. Gbogbo àwọn ìjòyè Farao ni ó sìn ín lọ—àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀, àti gbogbo àwọn àgbàgbà ilẹ̀ Ejibiti.
8 Všecken také dům Jozefův, a všickni bratří jeho i dům otce jeho; toliko dětí svých, ovec a volů nechali v zemi Gesen.
Yàtọ̀ fún gbogbo àwọn ará ilé Josẹfu àti ti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti àwọn tí ó jẹ́ ilé baba rẹ̀, àwọn ọmọ wọn nìkan àti agbo ẹran pẹ̀lú agbo màlúù ni ó sẹ́ kù ní Goṣeni.
9 Vstoupili s ním také i vozové a jezdci, a bylo vojsko to veliké velmi.
Kẹ̀kẹ́-ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin pẹ̀lú gòkè lọ. Àìmoye ènìyàn ni ó lọ.
10 I přišli až k místu Atád, kteréž jest při brodu Jordánském, a kvílili tam kvílením velikým a velmi žalostným; i držel tu zámutek po otci svém za dnů sedm.
Nígbà tí wọ́n dé ilẹ̀ ìpakà Atadi, ní ẹ̀bá Jordani, wọn pohùnréré ẹkún, níbẹ̀ ni Josẹfu sì tún dúró ṣọ̀fọ̀ baba rẹ̀ fún ọjọ́ méje.
11 Vidouce pak obyvatelé země té, totiž Kananejští, zámutek na místě tom Atád, řekli: Těžký to mají zámutek Egyptští. Protož nazváno jest jméno jeho Abel Mizraim, a to jest při brodu Jordánském.
Nígbà tí àwọn ará Kenaani tí ń gbé níbẹ̀ rí i bí wọ́n ti ń ṣọ̀fọ̀ náà ni ilẹ̀ ìpakà Atadi, wọ́n wí pé, “Ọ̀fọ̀ ńlá ni àwọn ará Ejibiti ń ṣe yìí.” Ìdí èyí ni a fi ń pe ibẹ̀ ní Abeli-Misraimu. Kò sì jìnnà sí Jordani.
12 Učinili tedy s ním synové jeho tak, jakž jim byl poručil.
Báyìí ni àwọn ọmọ Jakọbu ṣe ohun tí baba wọn pàṣẹ fún wọn.
13 A donesše ho do země Kananejské, pochovali ho v jeskyni na poli Machpelah, kterouž byl koupil Abraham s tím polem k dědičnému pohřbu od Efrona Hetejského, naproti Mamre.
Wọ́n gbé e lọ sí ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì sin ín sínú ihò àpáta tí ó wà ní oko Makpela, ní tòsí i Mamre tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti, pẹ̀lú ilẹ̀ náà.
14 A když pochoval Jozef otce svého, navrátil se do Egypta s bratřími svými a se všemi, kteříž byli vstoupili s ním, aby pochovali otce jeho.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti sìnkú baba rẹ̀ tan, Josẹfu padà sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀ àti àwọn mìíràn tí ó tẹ̀lé e lọ láti sin baba rẹ̀.
15 Vidouce pak bratří Jozefovi, že umřel otec jejich, řekli: Snad v nenávisti nás míti bude Jozef, a vrchovatě nahradí nám všecko zlé, kteréž jsme jemu činili.
Nígbà tí àwọn arákùnrin Josẹfu rí i pé baba wọn kú, wọ́n wí fún ara wọn pé, “Ǹjẹ́ bí ó bá ṣe pé Josẹfu ṣì fi wá sínú ń kọ́, tí ó sì fẹ́ gbẹ̀san gbogbo aburú tí a ti ṣe sí i?”
16 Protož vzkázali Jozefovi, řkouce: Otec tvůj ještě před smrtí svou přikázal, řka:
Nítorí náà wọ́n ránṣẹ́ sí Josẹfu wí pé, “Baba rẹ fi àṣẹ yìí sílẹ̀ kí ó tó lọ wí pé,
17 Takto díte Jozefovi: Prosím, odpusť již bratřím svým přestoupení a hřích jejich; nebo zle učinili tobě. Protož již odpusť, prosím, přestoupení služebníkům Boha, jehož ctil otec tvůj. I rozplakal se Jozef, když k němu mluvili.
‘Èyí ni kí ẹ̀yin kí ó sọ fún Josẹfu, mo bẹ̀ ọ́ kí o dáríjì àwọn arákùnrin rẹ, gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àti aburú tí wọ́n ṣe sí ọ, èyí tí ó mú ibi bá ọ’. Nísinsin yìí, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run baba rẹ jì wọ́n.” Nígbà tí iṣẹ́ ti wọ́n rán dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Josẹfu sọkún.
18 Přistoupili potom také bratří jeho, a padše před ním, řekli: Aj, my jsme služebníci tvoji.
Àwọn arákùnrin rẹ̀ wá, wọ́n sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, wọ́n wí pé, “Ẹrú rẹ ni a jẹ́.”
19 Jimž odpověděl Jozef: Nebojte se; nebo zdaliž jsem já vám za Boha?
Ṣùgbọ́n Josẹfu wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù, èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run bí?
20 Vy zajisté skládali jste proti mně zlé; ale Bůh obrátil to v dobré, aby učinil to, což vidíte nyní, a při životu zachoval lid mnohý.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ gbèrò láti ṣe mi ní ibi, ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbèrò láti fi ṣe rere tí ń ṣe lọ́wọ́ yìí; ni gbígba ẹ̀mí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn là.
21 Protož nebojte se již; já chovati vás budu i děti vaše. A tak těšil je, a mluvil k srdci jejich.
Nítorí náà, ẹ má ṣe bẹ̀rù. Èmi yóò pèsè fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín.” Ó tún fi wọ́n lọ́kàn balẹ̀, ó sì sọ ọ̀rọ̀ rere fun wọn.
22 Bydlil pak Jozef v Egyptě, on i dům otce jeho, a živ byl Jozef sto a deset let.
Josẹfu sì ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ìdílé baba rẹ̀. Ó sì wà láààyè fún àádọ́fà ọdún.
23 A viděl Jozef syny Efraimovy až do třetího pokolení; ano i synové Machira, syna Manassesova, vychováni jsou u Jozefa.
Ó sì rí ìran kẹta ọmọ Efraimu-Àwọn ọmọ Makiri, ọmọkùnrin Manase ni a sì gbé le eékún Josẹfu nígbà tí ó bí wọn.
24 Mluvil potom Jozef bratřím svým: Já tudíž umru; Bůh pak jistotně navštíví vás, a vyvede vás z země této do země, kterouž přisáhl Abrahamovi, Izákovi a Jákobovi.
Nígbà náà ni Josẹfu wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Mo ti fẹ́rẹ kú, ṣùgbọ́n dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, yóò sì mú un yín jáde kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí ó ti ṣèlérí ní ìbúra fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.”
25 Protož přísahou zavázal Jozef syny Izraelovy, řka: Když navštíví vás Bůh, vynestež kosti mé odsud.
Josẹfu sì mú kí àwọn ọmọ Israẹli búra májẹ̀mú kan wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, nígbà náà ni ẹ gbọdọ̀ kó egungun mi lọ́wọ́ kúrò ní ìhín.”
26 I umřel Jozef, když byl ve stu a v desíti letech; a pomazán jsa vonnými věcmi, vložen jest do truhly v Egyptě.
Báyìí ni Josẹfu kú nígbà tí ó pé àádọ́fà ọdún. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ṣe òkú rẹ̀ lọ́jọ̀ tan, a gbé e sí inú pósí ní Ejibiti.

< 1 Mojžišova 50 >